< Deuteronomy 16 >
1 Ẹ kíyèsi oṣù Abibu, kí ẹ sì máa ṣe àjọ̀dún ìrékọjá ti Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí pé ní oṣù Abibu yìí ni ó mú un yín jáde ní Ejibiti lóru.
Observe le mois des épis pour faire la Pâque à l'Éternel, ton Dieu; car c'est dans le mois des épis que l'Éternel, ton Dieu, t'a retiré de l'Egypte, pendant la nuit.
2 Ẹ fi ẹran kan rú ẹbọ bí ìrékọjá sí Olúwa Ọlọ́run yín láti inú ọ̀wọ́ ẹran tàbí agbo màlúù yín ní ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀.
Et sacrifie comme Pâque à l'Éternel, ton Dieu, du menu et du gros bétail, dans le lieu que choisira l'Éternel, ton Dieu, pour y fixer son nom.
3 Ẹ má ṣe jẹ ẹ́ pẹ̀lú u àkàrà tí a fi ìwúkàrà ṣe, ṣùgbọ́n ọjọ́ méje ni kí ẹ fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà, àkàrà ìpọ́njú, nítorí pé pẹ̀lú ìkánjú ni ẹ kúrò ní Ejibiti: kí ẹ bá à lè rántí ìgbà tí ẹ kúrò ní Ejibiti ní gbogbo ọjọ́ ayé yín.
Et tu ne mangeras en même temps rien de fermenté; pendant sept jours tu y joindras des azymes, pain du malheur, parce que tu sortis à la précipitée du pays d'Egypte; afin que tu te souviennes toute ta vie du jour de ta sortie du pays d'Egypte.
4 Kí a má sì ṣe rí àkàrà wíwú ní ọ̀dọ̀ rẹ nínú ilẹ̀ rẹ ní ijọ́ méje. Kí ìwọ má ṣe jẹ́ kí nǹkan kan ṣẹ́kù nínú ẹran tí ìwọ ó fi rú ẹbọ ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kìn-ín-ní di àárọ̀ ọjọ́ kejì.
Et qu'il ne paraisse pas de levain chez toi dans tout ton territoire pendant sept jours, et que de la chair du sacrifice que tu feras le soir du premier jour, rien ne soit conservé au delà de la nuit jusqu'au matin.
5 Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe ìrékọjá náà ní ìlúkílùú kankan, tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín
Tu n'as pas la faculté de faire le sacrifice de la Pâque dans l'une de tes villes que l'Éternel, ton Dieu, te donne;
6 bí kò ṣe ibi tí yóò yàn gẹ́gẹ́ bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀, níbẹ̀ ni ki ẹ ti ṣe ìrúbọ ìrékọjá náà ní ìrọ̀lẹ́ nígbà tí oòrùn bá ń wọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìrántí ìgbà tí ẹ kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
mais c'est dans le lieu que choisira l'Éternel, ton Dieu, pour y fixer son nom, que tu feras le sacrifice de la Pâque, le soir au coucher du soleil, moment de ta sortie de l'Egypte.
7 Ẹ sun ún kí ẹ sì jẹ ẹ́ ní ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn. Ní àárọ̀, kí ẹ padà sí àgọ́ ọ yín.
Et fais-le cuire et le mange dans le lieu que choisira l'Éternel, ton Dieu, et le matin retourne-t'en et prends le chemin de tes tentes.
8 Ọjọ́ mẹ́fà ní kí ẹ fi jẹ àkàrà aláìwú, ní ọjọ́ keje, ẹ pe àjọ kan fún Olúwa Ọlọ́run yín, kí ẹ má sì ṣe iṣẹ́ kankan.
Pendant six jours tu mangeras des azymes, et le septième jour il y aura solennelle convocation en l'honneur de l'Éternel, ton Dieu, tu t'abstiendras de tout travail.
9 Ka ọ̀sẹ̀ méje láti ìgbà tí ẹ bá ti bẹ̀rẹ̀ sí fi dòjé ṣe ìkórè ọkà.
Tu compteras sept semaines; à partir du moment où la faux commence à être mise aux blés, tu commenceras à compter sept semaines.
10 Nígbà náà ni kí ẹ ṣe àjọ ọ̀sẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, nípa pípèsè ọrẹ àtinúwá, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín.
Puis célèbre la fête des Semaines en l'honneur de l'Éternel, ton Dieu, calculant l'oblation volontaire de ta main, que tu offriras, d'après la bénédiction que t'aura accordée l'Éternel, ton Dieu;
11 Kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín ní ibi tí yóò yàn ní ibùgbé fún orúkọ rẹ̀: ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin, àwọn ẹrú yín ọkùnrin àti àwọn ẹrú yín obìnrin, àwọn Lefi tí ó wà ní ìlú yín, àti àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba, àti àwọn opó tí ń gbé àárín yín.
et tu te réjouiras devant l'Éternel, ton Dieu, toi et ton fils et ta fille et ton serviteur et ta servante et le Lévite qui est dans tes Portes et l'étranger et l'orphelin et la veuve qui sont au milieu de toi, dans le lieu que choisira l'Éternel, ton Dieu, pour y fixer son nom;
12 Ẹ rántí pé, ẹ ti jẹ́ ẹrú ní Ejibiti rí, nítorí náà ẹ tẹ̀lé àwọn ìlànà wọ̀nyí dáradára.
et tu te rappelleras que tu fus esclave en Egypte, pour garder et mettre en pratique tous ces statuts.
13 Ẹ ṣe ayẹyẹ àgọ́ ìpàdé fún ọjọ́ méje lẹ́yìn ìgbà tí ẹ bá ti kórè oko yín tí ẹ ti pakà tí ẹ sì ti fún ọtí tán.
Tu célébreras la fête des loges pendant sept jours, lorsque tu auras retiré tes récoltes de ton aire et de ton pressoir.
14 Ẹ máa yọ̀ ní àkókò àjọ̀dún un yín, ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin, àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin yín, àti àwọn Lefi, àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba àti àwọn opó tí ń gbé ní àwọn ìlú u yín.
Et réjouis-toi dans cette fête, toi et ton fils et ta fille et ton serviteur et ta servante et le Lévite et l'étranger et l'orphelin et la veuve qui sont dans tes Portes.
15 Ọjọ́ méje ni kí ẹ̀yin kí ó fi ṣe ayẹyẹ fún Olúwa Ọlọ́run yín ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín yóò bùkún un yín ní gbogbo ìkórè e yín, àti ní gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín, ayọ̀ ọ yín yóò sì kún.
Tu fêteras sept jours en l'honneur de l'Éternel, ton Dieu, dans le lieu que choisira l'Éternel. Car l'Éternel, ton Dieu, te bénira dans toute ta récolte et dans tout le travail de tes mains, afin que tu n'aies que de la joie.
16 Ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lọ́dún ni kí gbogbo àwọn ọkùnrin rẹ kí ó farahàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ní ibi tí yóò yàn. Níbi àjọ àkàrà àìwú, níbi àjọ ọ̀sẹ̀, àti àjọ àgọ́ ìpàdé. Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá sí iwájú Olúwa ní ọwọ́ òfo.
Trois fois dans l'année, tous tes hommes se présenteront devant la face de l'Éternel, ton Dieu, dans le lieu qu'il choisira, à la fête des azymes, et à la fête des Semaines, et à la fête des loges, et l'on ne paraîtra pas devant l'Éternel, les mains vides,
17 Kí olúkúlùkù ó mú ọrẹ wá bí agbára rẹ̀ ti tó, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ó fi fún un ọ̀.
mais chacun selon ce qu'il peut offrir en raison de l'abondance dont l'Éternel, ton Dieu, t'aura béni.
18 Ẹ yan àwọn adájọ́ àti àwọn olóyè fún ẹ̀yà a yín kọ̀ọ̀kan, ní gbogbo ìlú tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín, wọ́n sì gbọdọ̀ máa fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn.
Tu établiras sur toi des Juges et des magistrats dans toutes tes Portes que te donnera l'Éternel, ton Dieu, d'après tes Tribus, afin qu'ils jugent le peuple d'un jugement juste.
19 Ìwọ kò gbọdọ̀ yí ìdájọ́ po, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúsàájú ènìyàn. Ìwọ kò gbọdọ̀ gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ nítorí pé àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ń fọ́ ojú ọlọ́gbọ́n, ó sì ń ba ọ̀rọ̀ olódodo jẹ́.
Tu ne feras pas fléchir le droit, et tu ne feras pas acception des personnes, et tu n'accepteras point de présents, car les présents aveuglent les yeux des sages et gâtent les causes des justes.
20 Ẹ tẹ̀lé ìdájọ́ òtítọ́ àní ìdájọ́ òtítọ́ nìkan, kí ẹ bá à lè gbé kí ẹ sì gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín ń fún un yín.
La justice, la justice est le but que tu as à poursuivre afin que tu vives et te rendes maître du pays que l'Éternel, ton Dieu, te donne.
21 Ẹ má ṣe ri ère òrìṣà Aṣerah sí ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ tí ẹ ti mọ fún Olúwa Ọlọ́run yín.
Tu ne planteras point d'Aschères d'aucune espèce d'arbres, à côté de l'Autel de l'Éternel, ton Dieu, que tu te construiras,
22 Ẹ kò gbọdọ̀ gbé òkúta òrìṣà gbígbẹ́ kan kalẹ̀ fún ara yín, nítorí èyí ni Olúwa Ọlọ́run yín kórìíra.
et n'élèveras point des statues que hait l'Éternel, ton Dieu.