< Deuteronomy 15 >

1 Ní òpin ọdún méje méje, ẹ̀yin gbọdọ̀ máa yọ̀ǹda àwọn gbèsè.
Po upływie [każdego] siódmego roku ustanowisz darowanie [długów].
2 Báyìí ni kí ẹ máa ṣe é. Gbogbo ẹni tí wọ́n jẹ ní gbèsè gbọdọ̀ fojú fo gbèsè tí ó ti yá ará Israẹli ènìyàn rẹ̀. Kò gbọdọ̀ béèrè ohun náà, lọ́dọ̀ ará Israẹli ènìyàn rẹ̀ tàbí lọ́dọ̀ arákùnrin rẹ̀: nítorí pé a ti kéde àkókò Olúwa láti fojú fo gbèsè.
A to jest sposób darowania: każdy wierzyciel daruje pożyczkę, jakiej udzielił swemu bliźniemu; nie będzie domagał się [zwrotu] od swego bliźniego lub od swego brata, ponieważ obwołano darowanie [długów] dla PANA.
3 Ẹ lè béèrè ìsanpadà lọ́dọ̀ àjèjì. Ṣùgbọ́n ẹ fa igi lé gbèsè yówù kó jẹ́ tí arákùnrin yín jẹ yín.
Od obcego możesz domagać się [zwrotu], lecz co będziesz miał u swego brata, twoja ręka daruje;
4 Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò tọ́ sí nínú yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín yóò bùkún un yín lọ́pọ̀lọ́pọ̀ nínú ilẹ̀ náà tí ó ń mú un yín lọ láti gbà bí ìní yín.
Do czasu, gdy nie będzie pośród was ubogich, ponieważ PAN będzie cię hojnie błogosławił w ziemi, którą PAN, twój Bóg, daje ci w dziedziczne posiadanie.
5 Kìkì bí ẹ bá gbọ́rọ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín tí ẹ sì kíyèsára láti máa rìn nínú gbogbo àṣẹ wọ̀nyí, tí èmi ń pa fún un yín lónìí.
Jeśli tylko będziesz uważnie słuchał głosu PANA, swego Boga, byś pilnował wypełniania wszystkich przykazań, które dziś ci nakazuję;
6 Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín yóò bùkún un yín bí ó ti ṣèlérí, ẹ̀yin yóò sì máa yá ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ẹ kì yóò sì tọrọ. Ẹ ó ṣàkóso ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n kò sí orílẹ̀-èdè tí yóò lè jẹ ọba lé e yín lórí.
Gdyż PAN, twój Bóg, będzie cię błogosławić, tak jak ci obiecał; będziesz pożyczał wielu narodom, a sam [od nikogo] nie będziesz pożyczał; będziesz panował nad wieloma narodami, a [one] nad tobą nie zapanują.
7 Bí tálákà kan bá wà láàrín àwọn arákùnrin yín ní èyíkéyìí àwọn ìlú, ilẹ̀ náà tí Olúwa yín yóò fún un yín. Ẹ má ṣe ṣe àìláàánú, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe háwọ́ sí arákùnrin yín tí ó jẹ́ tálákà.
Jeśli będzie u ciebie jakiś ubogi spośród twoich braci w którymkolwiek z twoich miast w ziemi, którą ci daje PAN, twój Bóg, nie zatwardzaj swego serca ani nie zamykaj swej ręki przed swoim ubogim bratem;
8 Ṣùgbọ́n ẹ lawọ́ kí ẹ sì fi tọkàntọkàn yá wọn ní ohun tí wọ́n nílò.
Ale hojnie otworzysz mu swoją rękę i chętnie pożyczysz mu tyle, ile będzie potrzebował, czego mu będzie brakowało.
9 Ẹ ṣọ́ra kí èrò búburú kan má ṣe sí nínú àyà rẹ wí pé, “Ọdún keje tí í ṣe ọdún ìyọ̀ǹda gbèsè ti súnmọ́,” nípa bẹ́ẹ̀, ojú rẹ a sì burú sí arákùnrin rẹ tálákà, tí ìwọ kò sì fun ní nǹkan, o kò sì fun ní nǹkan kan. Òun a si kígbe pe Olúwa nítorí rẹ, a si di ẹ̀ṣẹ̀ fún ọ.
Strzeż się, by nie powstała w twoim sercu niegodziwa myśl, byś nie mówił: Zbliża się rok siódmy, rok darowania [długów] – i abyś nie patrzył surowo na swego ubogiego brata i [nic] mu nie dał; wtedy [on] wołałby do PANA przeciwko tobie i obciążyłbyś się grzechem;
10 Fún un tọkàntọkàn, láìsí ìkùnsínú, nítorí èyí, Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò bùkún fún ọ nínú iṣẹ́ ọwọ́ rẹ, àti gbogbo ìdáwọ́lé rẹ.
Chętnie mu dasz i twoje serce nie będzie ubolewało, gdy mu dajesz, gdyż PAN, twój Bóg, będzie cię za to błogosławił w każdym twoim dziele i w każdym twoim przedsięwzięciu.
11 A kò lè fẹ́ tálákà kù ní ilẹ̀ náà ní ìgbà gbogbo, mo pàṣẹ fún un yín láti lawọ́ sí àwọn arákùnrin yín, sí àwọn tálákà àti sí àwọn aláìní, ní ilẹ̀ ẹ yín.
Ubogich bowiem nie zabraknie w [waszej] ziemi. Dlatego nakazuję ci: Otworzysz hojnie swoją rękę swemu bratu, nędznemu i ubogiemu w twej ziemi.
12 Bí Heberu ara yín kan, yálà ọkùnrin tàbí obìnrin bá ta ara rẹ̀ fún ọ, tí ó sì sìn ọ́ fún ọdún mẹ́fà. Ní ọdún keje, jẹ́ kí ó di òmìnira.
Jeśli zaprzeda ci się twój brat, Hebrajczyk lub Hebrajka, a będzie ci służyć przez sześć lat, to w siódmym roku wypuścisz go od siebie na wolność.
13 Nígbà tí ó bá dá a sílẹ̀ má ṣe jẹ́ kí ó lọ lọ́wọ́ òfo.
A gdy wypuścisz go od siebie na wolność, nie wypuścisz go z pustymi rękami.
14 Fi tọkàntọkàn fún un láti inú agbo ewúrẹ́ rẹ, ilẹ̀ ìpakà rẹ, àti ibi ìfúntí rẹ. Fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti bùkún fún ọ tó.
Hojnie go obdarujesz ze swego bydła, klepiska i tłoczni. Dasz mu [z tego], w czym pobłogosławił cię PAN, twój Bóg.
15 Ẹ rántí pé ẹ ti fi ìgbà kan jẹ́ ẹrú ní Ejibiti, Olúwa Ọlọ́run yín sì rà yín padà, ìdí nìyí tí mo fi pa àṣẹ yìí fún un yín lónìí.
I będziesz pamiętać, że sam byłeś niewolnikiem w ziemi Egiptu i że, PAN, twój Bóg, wykupił cię. Dlatego ja nakazuję ci to dziś.
16 Ṣùgbọ́n bí ìránṣẹ́ rẹ bá sọ fún ọ pé, “Èmi kò fẹ́ fi ọ́ sílẹ̀,” nítorí pé ó fẹ́ràn ìwọ àti ìdílé rẹ, tí ó sì tẹ́ ọ lọ́rùn,
Ale jeśli on ci powie: Nie odejdę od ciebie – bo miłuje ciebie i twój dom i ponieważ jest mu u ciebie dobrze;
17 kí ìwọ kí ó mú ìlu kan lu etí rẹ̀ mọ́ ara ìlẹ̀kùn, yóò sì di ẹrú rẹ láéláé. Bẹ́ẹ̀ náà ni kí o ṣe sí ìránṣẹ́ ẹrúbìnrin rẹ.
Wtedy weźmiesz szydło i przekłujesz mu ucho, [przykładając je] o drzwi, i będzie twoim sługą na wieki. Tak samo postąpisz ze swoją służącą.
18 Má ṣe kà á sí ohun ìnira láti dá ẹrú rẹ sílẹ̀, nítorí ìsìnrú rẹ̀ fún ọ, ní ọdún mẹ́fà náà tó ìlọ́po méjì iṣẹ́ alágbàṣe, Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò bùkún fún ọ nínú gbogbo ìdáwọ́lé rẹ.
Niech nie będzie ci przykro, że wypuścisz go od siebie na wolność, gdyż służąc ci przez sześć lat, wysłużył podwójną zapłatę najemnika. A PAN, twój Bóg, będzie cię błogosławił we wszystkim, co uczynisz.
19 Gbogbo àkọ́bí tí o jẹ́ akọ nínú agbo màlúù rẹ ni kí o yà sọ́tọ̀ fún Olúwa, àti nínú agbo ewúrẹ́ bákan náà. Ẹ má ṣe fi àkọ́bí màlúù yín ṣiṣẹ́ rárá. Má ṣe rẹ́ irun àkọ́bí àgùntàn rẹ pẹ̀lú.
Każdego pierworodnego samca ze swego bydła albo z owiec poświęcisz PANU, swemu Bogu. Nie będziesz używał do pracy pierworodnego z cielców ani nie będziesz strzygł pierworodnego ze swoich owiec.
20 Ní ọdọọdún ni kí ìwọ àti ìdílé rẹ máa jẹ ẹ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbi tí Òun yóò yàn.
Będziesz je spożywał każdego roku przed PANEM, swoim Bogiem, ty i twój dom, w miejscu, które wybierze PAN;
21 Bí ẹran ọ̀sìn kan bá ní àbùkù: bóyá ó yarọ, tàbí fọ́jú, tàbí tí ó ní èyíkéyìí àbùkù tó burú. Ẹ kò gbọdọ̀ fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run yín.
A gdyby miało jakąś wadę, [było] kulawe, ślepe [lub miało] jakąkolwiek inną wadę, nie złożysz go na ofiarę PANU, swemu Bogu.
22 Ẹ jẹ ẹ́ ní ìlú u yín. Àti ẹni tí a kà sí mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ ẹ́ bí ìgbà tí a ń jẹ èsúró tàbí àgbọ̀nrín.
Zjesz je w swoich bramach. Zarówno nieczysty, jak i czysty może je jeść, tak jak sarnę i jelenia;
23 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, ẹ dà á síta bí omi.
Tylko jego krwi nie będziesz spożywał; wylejesz ją na ziemię jak wodę.

< Deuteronomy 15 >