< Deuteronomy 14 >

1 Ọmọ Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́: nítorí náà, ẹ má ṣe ya ara yín ní abẹ. Ẹ má ṣe gé irun iwájú orí yín nítorí òkú.
Voi sunteţi copiii DOMNULUI Dumnezeul vostru, să nu vă faceţi tăieturi, nici să nu faceţi chelie între ochi pentru un mort.
2 Nítorí pé ènìyàn mímọ́ ní ẹ jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ènìyàn tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, Ọlọ́run ti yàn yín láti jẹ́ ìṣúra iyebíye rẹ̀.
Pentru că tu eşti un popor sfânt pentru DOMNUL Dumnezeul tău şi pe tine te-a ales să îi fii un popor deosebit, mai mult decât toate naţiunile care sunt pe faţa pământului.
3 Ẹ má ṣe jẹ ohun ìríra kankan.
Să nu mănânci niciun lucru urâcios.
4 Àwọn wọ̀nyí ni ẹranko tí ẹ lè máa jẹ: màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́,
Acestea sunt animalele pe care să le mănânci: boul, oaia şi capra,
5 àgbọ̀nrín, èsúró, etu, àgóró, ẹfọ̀n, ìgalà àti àgùntàn igbó.
Cerbul şi căprioara şi antilopa şi capra sălbatică şi capra de munte şi boul sălbatic şi gazela.
6 Ẹ lè jẹ gbogbo ẹranko tí pátákò ẹsẹ̀ rẹ̀ kì í ṣe méjì tí ó sì tún jẹ àpọ̀jẹ.
Şi fiecare animal care are copita despicată şi piciorul complet despărţit în două copite şi care rumegă, pe acestea să le mâncaţi.
7 Síbẹ̀síbẹ̀ nínú gbogbo ẹran tí ń jẹ àpọ̀jẹ tí ó sì tún ya pátákò ẹsẹ̀ tí ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ni: ìbákasẹ, ehoro, àti ẹranko tí ó dàbí ehoro tí ń gbé inú àpáta. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n jẹ àpọ̀jẹ, ṣùgbọ́n wọn kò la pátákò ẹsẹ̀, a kà wọ́n sí àìmọ́ fún yín.
Totuşi pe acestea să nu le mâncaţi din cele care rumegă şi din cele care au copita despicată: cămila şi iepurele de câmp şi iepurele de stâncă, pentru că rumegă, dar nu au copita despicată, ele vă sunt necurate.
8 Ẹlẹ́dẹ̀ jẹ́ àìmọ́; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ya pátákò ẹsẹ̀, kì í jẹ àpọ̀jẹ, ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹran rẹ̀, ẹ kò sì gbọdọ̀ fọwọ́ kan òkú rẹ̀.
Şi porcul vă este necurat, pentru că are copita despicată, dar nu rumegă; să nu mâncaţi din carnea lor, nici să nu vă atingeţi de trupul lor mort.
9 Nínú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń gbé inú omi, ẹ lè jẹ èyíkéyìí tí ó ní lẹbẹ àti ìpẹ́.
Pe acestea să le mâncaţi dintre toate câte sunt în ape: să mâncaţi tot ce are aripioare şi solzi,
10 Ṣùgbọ́n èyíkéyìí tí kò bá ní lẹbẹ àti ìpẹ́, ẹ má ṣe jẹ ẹ́, nítorí pé àìmọ́ ni wọ́n jẹ́ fún yín.
Şi orice nu are aripioare şi solzi să nu mâncaţi; vă sunt necurate.
11 Ẹ lè jẹ ẹyẹ tí ó bá mọ́.
Din toate păsările curate să mâncaţi.
12 Ṣùgbọ́n ìwọ̀nyí ní ẹ kò gbọdọ̀ jẹ: idì, igún, àkàlà,
Dar acestea sunt cele din care să nu mâncaţi: acvila şi vulturul bărbos şi vulturul pescar;
13 onírúurú àṣá àti àṣá alátagbà,
Şi şoimul şi uliul şi vulturul după felul său;
14 onírúurú ẹyẹ ìwò,
Şi orice corb după felul său;
15 ògòǹgò, òwìwí, pẹ́pẹ́yẹdò àti onírúurú àwòdì,
Şi bufniţa şi şoimul de noapte şi cucul şi şoimul după felul său;
16 onírúurú òwìwí,
Şi cucuveaua şi bufniţa mare şi lebăda;
17 òwìwí ọ̀dàn, àkàlà, ìgò,
Şi pelicanul şi vulturul egiptean şi cormoranul;
18 àkọ̀, òòdẹ̀, onírúurú ẹyẹ odò mìíràn, atọ́ka àti àdán.
Şi barza şi stârcul după felul său şi nagâţul şi liliacul.
19 Àti gbogbo kòkòrò tí ń fò tí wọ́n ń kọ́wọ̀ọ́ rìn jẹ́ aláìmọ́ fun un yín, ẹ má ṣe jẹ wọ́n.
Şi orice târâtoare care zboară vă este necurată; să nu se mănânce.
20 Ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ èyíkéyìí ẹ̀dá abìyẹ́ tí ó bá mọ́.
Dar din toate păsările curate puteţi să mâncaţi.
21 Ẹ má ṣe jẹ ohun tí ó ti kú sílẹ̀. Ẹ lè fún àwọn àjèjì tí ń gbé ní èyíkéyìí nínú ìlú yín. Òun lè jẹ ẹ́ tàbí kí ẹ tà á fún àwọn àjèjì. Ṣùgbọ́n ènìyàn mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ewúrẹ́ nínú wàrà ìyá rẹ̀.
Să nu mâncaţi din nimic ce moare de la sine; să îl dai străinului care este înăuntrul porţilor tale, ca să îl mănânce sau să îl vinzi unui străin, pentru că tu eşti un popor sfânt pentru DOMNUL Dumnezeul tău. Să nu fierbi un ied în laptele mamei sale.
22 Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń fi ìdákan nínú mẹ́wàá nínú ìre oko yín lọ́dọọdún pamọ́ sí apá kan.
Să dai cu adevărat zeciuială din tot venitul seminţei tale, pe care câmpul tău îl dă an de an.
23 Ẹ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àti àkọ́bí àwọn màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín, níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ibi tí yóò yàn bí ibùgbé orúkọ rẹ̀. Kí ẹ lè kọ́ bí a ṣé ń bu ọlá fún Olúwa Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
Şi să mănânci înaintea DOMNULUI Dumnezeul tău, în locul pe care îl va alege el să îşi pună numele acolo, zeciuiala din grânele tale, din vinul tău şi din untdelemnul tău şi întâii născuţi din cirezile tale şi din turmele tale, ca să înveţi să te temi de DOMNUL Dumnezeul tău în toate zilele.
24 Bí ibẹ̀ bá jì tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì ti bùkún fún ọ, tí o kò sì le ru àwọn ìdámẹ́wàá rẹ (nítorí pé ibi tí Olúwa yóò yàn láti fi orúkọ rẹ̀ sí jìnnà jù).
Şi dacă este prea lung drumul pentru tine, astfel încât nu le poţi duce, sau dacă locul pe care îl va alege DOMNUL Dumnezeul tău, să îşi pună numele acolo, va fi prea departe de tine, când te va binecuvânta DOMNUL Dumnezeul tău,
25 Ẹ pààrọ̀ àwọn ìdámẹ́wàá yín sí owó, ẹ mú owó náà lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
Atunci să le schimbi în bani şi banii să îi legi în mâna ta şi să mergi la locul pe care îl va alege DOMNUL Dumnezeul tău.
26 Fi owó náà ra ohunkóhun tí o bá fẹ́, màlúù, àgùntàn, wáìnì, tàbí ọtí líle, tàbí ohunkóhun tí o bá fẹ́. Kí ìwọ àti ìdílé rẹ sì jẹ ẹ́ níwájú Olúwa níbẹ̀ kí ẹ sì máa yọ̀.
Şi să dai acei bani pentru tot ce îţi pofteşte sufletul, pentru boi, sau pentru oi, pentru vin sau pentru băutură tare sau pentru orice îţi doreşte sufletul; şi să mănânci acolo înaintea DOMNULUI Dumnezeul tău şi să te bucuri, tu şi casa ta,
27 Ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi tí ó ń gbé nì ìlú yín, nítorí pé wọn kò ní ìpín kan tàbí ogún kan tí í ṣe tiwọn.
Şi să nu îl părăseşti pe levitul care este înăuntrul porţilor tale, pentru că el nu are nici parte nici moştenire cu tine.
28 Ní òpin ọdún mẹ́ta mẹ́ta, ẹ̀yin yóò mú gbogbo ìdámẹ́wàá ìre oko àwọn ọdún náà, kí ẹ kó wọn jọ ní ìlú yín.
La sfârşitul a trei ani să scoţi toată zeciuiala venitului tău din anul acela şi să o pui înăuntrul porţilor tale.
29 Kí àwọn Lefi (tí kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn) àti àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba, àti àwọn opó tí ń gbé ìlú yín lè wá, kí wọn sì jẹ kí wọn sì yó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ le è bùkún fún ọ, nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
Şi să vină levitul, (pentru că el nu are nici parte nici moştenire cu tine) şi străinul şi cel fără tată şi văduva, care sunt înăuntrul porţilor tale, şi să mănânce şi să se sature, ca DOMNUL Dumnezeul tău să te binecuvânteze în toată lucrarea mâinii tale pe care o faci.

< Deuteronomy 14 >