< Deuteronomy 14 >
1 Ọmọ Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́: nítorí náà, ẹ má ṣe ya ara yín ní abẹ. Ẹ má ṣe gé irun iwájú orí yín nítorí òkú.
I er Herrens, eders Guds barn; I skal ikke skjære eder i eders kjøtt og ikke rake eder skallet over pannen av sorg over en avdød;
2 Nítorí pé ènìyàn mímọ́ ní ẹ jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ènìyàn tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, Ọlọ́run ti yàn yín láti jẹ́ ìṣúra iyebíye rẹ̀.
for et hellig folk er du for Herren din Gud, og dig har Herren utvalgt av alle de folk som er på jorden, til å være ham et eiendomsfolk.
3 Ẹ má ṣe jẹ ohun ìríra kankan.
Du skal ikke ete noget som er en vederstyggelighet.
4 Àwọn wọ̀nyí ni ẹranko tí ẹ lè máa jẹ: màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́,
Dette er de firføtte dyr som I kan ete: oksen, fåret og gjeten,
5 àgbọ̀nrín, èsúró, etu, àgóró, ẹfọ̀n, ìgalà àti àgùntàn igbó.
hjorten og rådyret og dådyret og stenbukken og fjellgjeten og villoksen og villgjeten.
6 Ẹ lè jẹ gbogbo ẹranko tí pátákò ẹsẹ̀ rẹ̀ kì í ṣe méjì tí ó sì tún jẹ àpọ̀jẹ.
Alle de firføtte dyr som har klover og har dem tvekløvd helt igjennem, og som tygger drøv, dem kan I ete.
7 Síbẹ̀síbẹ̀ nínú gbogbo ẹran tí ń jẹ àpọ̀jẹ tí ó sì tún ya pátákò ẹsẹ̀ tí ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ni: ìbákasẹ, ehoro, àti ẹranko tí ó dàbí ehoro tí ń gbé inú àpáta. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n jẹ àpọ̀jẹ, ṣùgbọ́n wọn kò la pátákò ẹsẹ̀, a kà wọ́n sí àìmọ́ fún yín.
Det er bare disse I ikke skal ete blandt dem som tygger drøv, og blandt dem som har klover som er kløvd helt igjennem: kamelen og haren og fjellgrevlingen, for de tygger vel drøv, men har ikke klover, de skal være urene for eder,
8 Ẹlẹ́dẹ̀ jẹ́ àìmọ́; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ya pátákò ẹsẹ̀, kì í jẹ àpọ̀jẹ, ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹran rẹ̀, ẹ kò sì gbọdọ̀ fọwọ́ kan òkú rẹ̀.
og svinet, for det har vel klover, men tygger ikke drøv, det skal være urent for eder. Av disse dyrs kjøtt skal I ikke ete, og ved deres døde kropper skal I ikke røre.
9 Nínú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń gbé inú omi, ẹ lè jẹ èyíkéyìí tí ó ní lẹbẹ àti ìpẹ́.
Dette kan I ete av alt det som er i vannet: Alt det som har finner og skjell, kan I ete;
10 Ṣùgbọ́n èyíkéyìí tí kò bá ní lẹbẹ àti ìpẹ́, ẹ má ṣe jẹ ẹ́, nítorí pé àìmọ́ ni wọ́n jẹ́ fún yín.
men alt det som ikke har finner og skjell, skal I ikke ete, det skal være urent for eder.
11 Ẹ lè jẹ ẹyẹ tí ó bá mọ́.
Alle rene fugler kan I ete;
12 Ṣùgbọ́n ìwọ̀nyí ní ẹ kò gbọdọ̀ jẹ: idì, igún, àkàlà,
men disse fugler skal I ikke ete: landørnen og havørnen og fiskeørnen
13 onírúurú àṣá àti àṣá alátagbà,
og kråken og falken, og glenten efter sine arter,
og alle ravnene efter sine arter,
15 ògòǹgò, òwìwí, pẹ́pẹ́yẹdò àti onírúurú àwòdì,
og strutsen og gjøken og måken, og høken efter sine arter,
kattuglen og hubroen og nattravnen
17 òwìwí ọ̀dàn, àkàlà, ìgò,
og pelikanen og gribben og dykkeren
18 àkọ̀, òòdẹ̀, onírúurú ẹyẹ odò mìíràn, atọ́ka àti àdán.
og storken, og heiren efter sine arter, og hærfuglen og flaggermusen.
19 Àti gbogbo kòkòrò tí ń fò tí wọ́n ń kọ́wọ̀ọ́ rìn jẹ́ aláìmọ́ fun un yín, ẹ má ṣe jẹ wọ́n.
Alt kryp som har vinger, skal være urent for eder, det skal I ikke ete.
20 Ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ èyíkéyìí ẹ̀dá abìyẹ́ tí ó bá mọ́.
Men alt flyvende som er rent, kan I ete.
21 Ẹ má ṣe jẹ ohun tí ó ti kú sílẹ̀. Ẹ lè fún àwọn àjèjì tí ń gbé ní èyíkéyìí nínú ìlú yín. Òun lè jẹ ẹ́ tàbí kí ẹ tà á fún àwọn àjèjì. Ṣùgbọ́n ènìyàn mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ewúrẹ́ nínú wàrà ìyá rẹ̀.
I skal ikke ete noget selvdødt dyr; du kan gi det til den fremmede som bor hos dig, forat han kan ete det, eller du kan selge det til en utlending; for et hellig folk er du for Herren din Gud. Du skal ikke koke et kje i dets mors melk.
22 Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń fi ìdákan nínú mẹ́wàá nínú ìre oko yín lọ́dọọdún pamọ́ sí apá kan.
Du skal gi tiende av all din avgrøde, av sæden som vokser på marken år for år.
23 Ẹ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àti àkọ́bí àwọn màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín, níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ibi tí yóò yàn bí ibùgbé orúkọ rẹ̀. Kí ẹ lè kọ́ bí a ṣé ń bu ọlá fún Olúwa Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
Og for Herrens, din Guds åsyn, på det sted han utvelger til å la sitt navn bo der, skal du ete tienden av ditt korn og din most og din olje og det førstefødte av ditt storfe og av ditt småfe, forat du kan lære å frykte Herren din Gud alle dager.
24 Bí ibẹ̀ bá jì tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì ti bùkún fún ọ, tí o kò sì le ru àwọn ìdámẹ́wàá rẹ (nítorí pé ibi tí Olúwa yóò yàn láti fi orúkọ rẹ̀ sí jìnnà jù).
Men hvis veien er dig for lang, så du ikke makter å føre det dit, fordi det sted Herren din Gud utvelger til å la sitt navn bo der, er for langt borte fra dig, og har Herren din Gud velsignet dig rikelig,
25 Ẹ pààrọ̀ àwọn ìdámẹ́wàá yín sí owó, ẹ mú owó náà lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
så kan du selge det for penger, og pengene skal du knytte inn i et plagg og ta dem med dig til det sted som Herren din Gud utvelger.
26 Fi owó náà ra ohunkóhun tí o bá fẹ́, màlúù, àgùntàn, wáìnì, tàbí ọtí líle, tàbí ohunkóhun tí o bá fẹ́. Kí ìwọ àti ìdílé rẹ sì jẹ ẹ́ níwájú Olúwa níbẹ̀ kí ẹ sì máa yọ̀.
For disse penger skal du så kjøpe alt hvad du har lyst til, storfe og småfe og vin og sterk drikk - alt det ditt hjerte attrår - og du skal ete det der for Herrens, din Guds åsyn og være glad, du og ditt hus.
27 Ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi tí ó ń gbé nì ìlú yín, nítorí pé wọn kò ní ìpín kan tàbí ogún kan tí í ṣe tiwọn.
Og levitten som bor hos dig, må du ikke glemme; for han har ingen del eller arv med dig.
28 Ní òpin ọdún mẹ́ta mẹ́ta, ẹ̀yin yóò mú gbogbo ìdámẹ́wàá ìre oko àwọn ọdún náà, kí ẹ kó wọn jọ ní ìlú yín.
Hvert tredje år skal du legge til side hele tienden av din avling i det år og opsamle den i dine byer,
29 Kí àwọn Lefi (tí kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn) àti àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba, àti àwọn opó tí ń gbé ìlú yín lè wá, kí wọn sì jẹ kí wọn sì yó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ le è bùkún fún ọ, nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
og så skal levitten komme - for han har ingen del eller arv med dig - og den fremmede og den farløse og enken som bor hos dig, og de skal ete og bli mette, forat Herren din Gud må velsigne dig i alt det arbeid du tar dig fore.