< Deuteronomy 14 >

1 Ọmọ Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́: nítorí náà, ẹ má ṣe ya ara yín ní abẹ. Ẹ má ṣe gé irun iwájú orí yín nítorí òkú.
Gyermekei vagytok ti az Örökkévalónak, a ti Isteneteknek; ne vagdaljátok meg magatokat és ne csináljatok kopaszságot szemeitek között a halottért.
2 Nítorí pé ènìyàn mímọ́ ní ẹ jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ènìyàn tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, Ọlọ́run ti yàn yín láti jẹ́ ìṣúra iyebíye rẹ̀.
Mert szent népe vagy te az Örökkévalónak, a te Istenednek és téged választott ki az Örökkévaló, hogy légy neki tulajdon népe mind a népek közül, melyek a föld színén vannak.
3 Ẹ má ṣe jẹ ohun ìríra kankan.
Ne egyél semmi utálatot.
4 Àwọn wọ̀nyí ni ẹranko tí ẹ lè máa jẹ: màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́,
Ez a barom, melyet megehettek: ökör, juh és kecske;
5 àgbọ̀nrín, èsúró, etu, àgóró, ẹfọ̀n, ìgalà àti àgùntàn igbó.
őz, szarvas és dámvad, a zerge, az antilop, a teó és a zemer.
6 Ẹ lè jẹ gbogbo ẹranko tí pátákò ẹsẹ̀ rẹ̀ kì í ṣe méjì tí ó sì tún jẹ àpọ̀jẹ.
Minden barmot, melynek hasadt patája van és kettéhasadt patája van, ami kérődző a barmok között, azt megehetitek.
7 Síbẹ̀síbẹ̀ nínú gbogbo ẹran tí ń jẹ àpọ̀jẹ tí ó sì tún ya pátákò ẹsẹ̀ tí ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ni: ìbákasẹ, ehoro, àti ẹranko tí ó dàbí ehoro tí ń gbé inú àpáta. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n jẹ àpọ̀jẹ, ṣùgbọ́n wọn kò la pátákò ẹsẹ̀, a kà wọ́n sí àìmọ́ fún yín.
De ezeket ne egyétek meg a kérődzők közül, és a hasadt patájúak közül: a tevét, a nyulat és tengeri nyulat, mert kérődzők azok, de patájuk nincs meghasadva, tisztátalanok azok nektek.
8 Ẹlẹ́dẹ̀ jẹ́ àìmọ́; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ya pátákò ẹsẹ̀, kì í jẹ àpọ̀jẹ, ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹran rẹ̀, ẹ kò sì gbọdọ̀ fọwọ́ kan òkú rẹ̀.
És a sertést, mert hasadt patájú az, de nem kérődző, tisztátalan az nektek: húsukból ne egyetek és dögükhöz ne nyúljatok.
9 Nínú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń gbé inú omi, ẹ lè jẹ èyíkéyìí tí ó ní lẹbẹ àti ìpẹ́.
Ezt ehetitek meg mindabból, ami a vízben van; mindazt; aminek úszószárnya van és pikkelye, megehetitek.
10 Ṣùgbọ́n èyíkéyìí tí kò bá ní lẹbẹ àti ìpẹ́, ẹ má ṣe jẹ ẹ́, nítorí pé àìmọ́ ni wọ́n jẹ́ fún yín.
Mindazt pedig, aminek nincs úszószárnya és pikkelye, ne egyétek meg; tisztátalan az nektek.
11 Ẹ lè jẹ ẹyẹ tí ó bá mọ́.
Minden tiszta madarat megehettek.
12 Ṣùgbọ́n ìwọ̀nyí ní ẹ kò gbọdọ̀ jẹ: idì, igún, àkàlà,
És ez az, amit ne egyetek meg közülük: A sas, a csonttörő sas és a fekete sas;
13 onírúurú àṣá àti àṣá alátagbà,
a keselyű, az ölyv és a saskeselyű a maga neme szerint;
14 onírúurú ẹyẹ ìwò,
minden holló a maga neme szerint;
15 ògòǹgò, òwìwí, pẹ́pẹ́yẹdò àti onírúurú àwòdì,
a strucc, a fecske, a sirály és a karvaly a maga maga szerint;
16 onírúurú òwìwí,
kuvik, a bagoly és a suholy;
17 òwìwí ọ̀dàn, àkàlà, ìgò,
a gödény, a héja és a búvár;
18 àkọ̀, òòdẹ̀, onírúurú ẹyẹ odò mìíràn, atọ́ka àti àdán.
a gólya és a gém a maga neme szerint; a banka és a denevér.
19 Àti gbogbo kòkòrò tí ń fò tí wọ́n ń kọ́wọ̀ọ́ rìn jẹ́ aláìmọ́ fun un yín, ẹ má ṣe jẹ wọ́n.
És minden szárnyas csúszó-mászó tisztátalan legyen nektek, ne egyétek meg azt.
20 Ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ èyíkéyìí ẹ̀dá abìyẹ́ tí ó bá mọ́.
Minden tiszta szárnyast megehettek.
21 Ẹ má ṣe jẹ ohun tí ó ti kú sílẹ̀. Ẹ lè fún àwọn àjèjì tí ń gbé ní èyíkéyìí nínú ìlú yín. Òun lè jẹ ẹ́ tàbí kí ẹ tà á fún àwọn àjèjì. Ṣùgbọ́n ènìyàn mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ewúrẹ́ nínú wàrà ìyá rẹ̀.
Ne egyetek semmi elhullottat, az idegennek, ki kapuidban van, add azt, hogy megegye; vagy add el az idegennek, mert szent népe vagy te az Örökkévalónak, a te Istenednek. Ne főzd meg a gödölyét anyja tejében.
22 Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń fi ìdákan nínú mẹ́wàá nínú ìre oko yín lọ́dọọdún pamọ́ sí apá kan.
Tizedet adj vetésednek minden terméséből, amely terem a mezőn évről évre.
23 Ẹ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àti àkọ́bí àwọn màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín, níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ibi tí yóò yàn bí ibùgbé orúkọ rẹ̀. Kí ẹ lè kọ́ bí a ṣé ń bu ọlá fún Olúwa Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
És edd meg az Örökkévaló, a te Istened színe előtt, azon a helyen, melyet kiválaszt, hogy ott lakoztassa nevét: tizedét gabonádnak, mustodnak és olajadnak, meg elsőszülötteit marhádnak és juhaidnak, hogy megtanuld félni az Örökkévalót, a te Istenedet minden időben.
24 Bí ibẹ̀ bá jì tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì ti bùkún fún ọ, tí o kò sì le ru àwọn ìdámẹ́wàá rẹ (nítorí pé ibi tí Olúwa yóò yàn láti fi orúkọ rẹ̀ sí jìnnà jù).
Ha pedig hosszabb neked az út, hogysem elvihetnéd azt, mert távol van tőled a hely, melyet kiválaszt az Örökkévaló, a te Istened, hogy odahelyezze nevét; mert megáld téged az Örökkévaló a te Istened,
25 Ẹ pààrọ̀ àwọn ìdámẹ́wàá yín sí owó, ẹ mú owó náà lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
akkor add pénzben; kösd össze a pénzt kezedben és menj arra a helyre, melyet kiválaszt az Örökkévaló, a te Istened.
26 Fi owó náà ra ohunkóhun tí o bá fẹ́, màlúù, àgùntàn, wáìnì, tàbí ọtí líle, tàbí ohunkóhun tí o bá fẹ́. Kí ìwọ àti ìdílé rẹ sì jẹ ẹ́ níwájú Olúwa níbẹ̀ kí ẹ sì máa yọ̀.
És adjad a pénzt mindazért, amire vágyik lelked: marháért, juhért, borért és részegítő italért, mindenért, amit kér tőled lelked; és egyél ott az Örökkévaló, a te Istened színe előtt és örvendj te és házad.
27 Ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi tí ó ń gbé nì ìlú yín, nítorí pé wọn kò ní ìpín kan tàbí ogún kan tí í ṣe tiwọn.
A levitát pedig, aki kapuidban van, ne hagyd el, mert neki nincs osztályrésze és birtoka nálad.
28 Ní òpin ọdún mẹ́ta mẹ́ta, ẹ̀yin yóò mú gbogbo ìdámẹ́wàá ìre oko àwọn ọdún náà, kí ẹ kó wọn jọ ní ìlú yín.
Három év végével vidd ki termésed minden tizedét, abban az évben és hagyd kapuidban,
29 Kí àwọn Lefi (tí kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn) àti àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba, àti àwọn opó tí ń gbé ìlú yín lè wá, kí wọn sì jẹ kí wọn sì yó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ le è bùkún fún ọ, nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
hogy jöjjön a levita, mert neki nincs osztályrésze és birtoka nálad, meg az idegen, az árva és az özvegy, kik kapuidban vannak, hogy egyenek és jóllakjanak, hogy megáldjon az Örökkévaló, a te Istened kezed minden munkájában, amit végzel.

< Deuteronomy 14 >