< Deuteronomy 14 >

1 Ọmọ Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́: nítorí náà, ẹ má ṣe ya ara yín ní abẹ. Ẹ má ṣe gé irun iwájú orí yín nítorí òkú.
Inyuĩ nĩ inyuĩ ciana cia Jehova Ngai wanyu. Mũtikanetemange kana mwenjwo ihara ũthiũ-inĩ nĩ ũndũ wa mũndũ mũkuũ,
2 Nítorí pé ènìyàn mímọ́ ní ẹ jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ènìyàn tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, Ọlọ́run ti yàn yín láti jẹ́ ìṣúra iyebíye rẹ̀.
nĩgũkorwo mũrĩ andũ mamũrĩirwo Jehova Ngai wanyu. Kuuma ndũrĩrĩ-inĩ ciothe cia thĩ, Jehova nĩamũthuurĩte mũtuĩke andũ ake a bata.
3 Ẹ má ṣe jẹ ohun ìríra kankan.
Mũtikanarĩe kĩndũ o nakĩ kĩrĩ thaahu.
4 Àwọn wọ̀nyí ni ẹranko tí ẹ lè máa jẹ: màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́,
Ici nĩcio nyamũ iria mwagĩrĩirwo kũrĩa: nĩ ndegwa, na ngʼondu, na mbũri,
5 àgbọ̀nrín, èsúró, etu, àgóró, ẹfọ̀n, ìgalà àti àgùntàn igbó.
na thwariga, na thiiya, na thwara, na mbũri ya werũ, na ndoo, na ngondi, o na ngʼondu cia irĩma-inĩ.
6 Ẹ lè jẹ gbogbo ẹranko tí pátákò ẹsẹ̀ rẹ̀ kì í ṣe méjì tí ó sì tún jẹ àpọ̀jẹ.
No mũrĩe nyamũ o yothe ĩrĩ mahũngũ maatũku na makarekania na nĩĩcookagia ithagumia.
7 Síbẹ̀síbẹ̀ nínú gbogbo ẹran tí ń jẹ àpọ̀jẹ tí ó sì tún ya pátákò ẹsẹ̀ tí ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ni: ìbákasẹ, ehoro, àti ẹranko tí ó dàbí ehoro tí ń gbé inú àpáta. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n jẹ àpọ̀jẹ, ṣùgbọ́n wọn kò la pátákò ẹsẹ̀, a kà wọ́n sí àìmọ́ fún yín.
No rĩrĩ, harĩ nyamũ iria ĩcookagia ithagumia kana irĩ mahũngũ maatũku marekanĩtie biũ, mũtikanarĩe ngamĩĩra, kana mbũkũ, kana ikami. O na gũtuĩka nĩicookagia ithagumia, mahũngũ ma cio ti maatũku, icio irĩ thaahu harĩ inyuĩ.
8 Ẹlẹ́dẹ̀ jẹ́ àìmọ́; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ya pátákò ẹsẹ̀, kì í jẹ àpọ̀jẹ, ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹran rẹ̀, ẹ kò sì gbọdọ̀ fọwọ́ kan òkú rẹ̀.
Nayo ngũrwe, o na akorwo mahũngũ mayo nĩmarekanĩtie biũ-rĩ, ndĩcookagia ithagumia; ĩyo ĩrĩ thaahu harĩ inyuĩ. Mũtikanarĩe nyama ciacio kana mũhutie ciimba ciacio.
9 Nínú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń gbé inú omi, ẹ lè jẹ èyíkéyìí tí ó ní lẹbẹ àti ìpẹ́.
Thĩinĩ wa nyamũ ciothe iria itũũraga maaĩ-inĩ, no mũrĩĩage ĩrĩa yothe ĩrĩ mathagu manyiitaine na ĩrĩ ngaracũ mwĩrĩ.
10 Ṣùgbọ́n èyíkéyìí tí kò bá ní lẹbẹ àti ìpẹ́, ẹ má ṣe jẹ ẹ́, nítorí pé àìmọ́ ni wọ́n jẹ́ fún yín.
No ĩrĩa yothe ĩtarĩ tũthagu na ngaracũ, mũtikanamĩrĩe; nĩgũkorwo ĩrĩ thaahu harĩ inyuĩ.
11 Ẹ lè jẹ ẹyẹ tí ó bá mọ́.
No mũrĩe nyoni o yothe ĩrĩa ĩtarĩ thaahu.
12 Ṣùgbọ́n ìwọ̀nyí ní ẹ kò gbọdọ̀ jẹ: idì, igún, àkàlà,
No ici mũtikanarĩe: nderi, na ndiyũ, na ndiyũ iria njirũ,
13 onírúurú àṣá àti àṣá alátagbà,
na hũngũ ĩrĩa ndune na mũthemba o wothe wa hũngũ iria njirũ,
14 onírúurú ẹyẹ ìwò,
na mũthemba o wothe wa mahuru
15 ògòǹgò, òwìwí, pẹ́pẹ́yẹdò àti onírúurú àwòdì,
na ndundu ĩrĩa ĩrĩ rũhĩa, na ndundu ĩrĩa ĩgambaga, na nyoni ya iria-inĩ ĩrĩa ĩrĩ mathagu maraaya, na mũthemba o wothe wa rwĩgĩ,
16 onírúurú òwìwí,
na gatundu karĩa kanini, na ndundu ĩrĩa nene, o na ndundu ĩrĩa njerũ,
17 òwìwí ọ̀dàn, àkàlà, ìgò,
na ndundu ya werũ, na rwĩgĩ rũnene rũrĩa rũrĩĩaga thamaki, na nyoni ya iria-inĩ ĩrĩa ĩrĩ ngingo ndaaya,
18 àkọ̀, òòdẹ̀, onírúurú ẹyẹ odò mìíràn, atọ́ka àti àdán.
na karoga-ngunũ, na mĩthemba yothe ya cũcũ-wa-njoka, na hudihuda, o na rũhuhu.
19 Àti gbogbo kòkòrò tí ń fò tí wọ́n ń kọ́wọ̀ọ́ rìn jẹ́ aláìmọ́ fun un yín, ẹ má ṣe jẹ wọ́n.
Tũnyamũ tuothe tũrĩa tũrĩ mathagu tũmbũkaga tũrĩ gĩtutu tũrĩ thaahu harĩ inyuĩ, mũtikanatũrĩe.
20 Ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ èyíkéyìí ẹ̀dá abìyẹ́ tí ó bá mọ́.
No nyamũ yothe ĩrĩ mathagu na ndĩrĩ thaahu no mũmĩrĩe.
21 Ẹ má ṣe jẹ ohun tí ó ti kú sílẹ̀. Ẹ lè fún àwọn àjèjì tí ń gbé ní èyíkéyìí nínú ìlú yín. Òun lè jẹ ẹ́ tàbí kí ẹ tà á fún àwọn àjèjì. Ṣùgbọ́n ènìyàn mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ewúrẹ́ nínú wàrà ìyá rẹ̀.
Mũtikanarĩe kĩndũ o na kĩrĩkũ kĩrĩa mũgaakora gĩkuĩte. No mũkĩhe mũndũ wa kũngĩ ũrĩa ũtũũraga itũũra-inĩ o rĩothe rĩa matũũra manyu, nake no akĩrĩe, kana ũkĩenderie mũrũrĩrĩ. No inyuĩ mũrĩ andũ maamũrĩirwo Jehova Ngai wanyu. Mũtikanaruge koori na iria rĩa nyina.
22 Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń fi ìdákan nínú mẹ́wàá nínú ìre oko yín lọ́dọọdún pamọ́ sí apá kan.
Menyererai mũrutage gĩcunjĩ gĩa ikũmi kĩa maciaro mothe ma mĩgũnda yanyu mwaka o mwaka.
23 Ẹ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àti àkọ́bí àwọn màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín, níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ibi tí yóò yàn bí ibùgbé orúkọ rẹ̀. Kí ẹ lè kọ́ bí a ṣé ń bu ọlá fún Olúwa Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
Rĩagĩrai gĩcunjĩ gĩa ikũmi kĩa ngano yanyu, na ndibei yanyu ya mũhihano, na maguta manyu, na marigithathi manyu ma ndũũru cianyu cia ngʼombe na cia mbũri mbere ya Jehova Ngai wanyu mũrĩ handũ harĩa agaathuura ha gũtũũria Rĩĩtwa rĩake, nĩgeetha mwĩrute gwĩtigĩra Jehova Ngai wanyu hĩndĩ ciothe.
24 Bí ibẹ̀ bá jì tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì ti bùkún fún ọ, tí o kò sì le ru àwọn ìdámẹ́wàá rẹ (nítorí pé ibi tí Olúwa yóò yàn láti fi orúkọ rẹ̀ sí jìnnà jù).
No rĩrĩ, handũ hau hangĩkorwo nĩ haraihu mũno, na Jehova Ngai wanyu nĩamũrathimĩte na mũtingĩhota gũkuua gĩcunjĩ kĩanyu gĩa ikũmi mũtware handũ hau (nĩ ũndũ handũ hau Jehova agaathuura ha gũtũũria Rĩĩtwa rĩake nĩhamũraihĩrĩirie mũno-rĩ),
25 Ẹ pààrọ̀ àwọn ìdámẹ́wàá yín sí owó, ẹ mú owó náà lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
hĩndĩ ĩyo mũgaakũũrania gĩcunjĩ kĩanyu gĩa ikũmi na betha, na inyuĩ mũtware betha ĩyo handũ harĩa Jehova Ngai wanyu agaathuura.
26 Fi owó náà ra ohunkóhun tí o bá fẹ́, màlúù, àgùntàn, wáìnì, tàbí ọtí líle, tàbí ohunkóhun tí o bá fẹ́. Kí ìwọ àti ìdílé rẹ sì jẹ ẹ́ níwájú Olúwa níbẹ̀ kí ẹ sì máa yọ̀.
Hũthĩrai betha ĩyo na kũgũra kĩrĩa gĩothe mũngĩenda: ngʼombe, kana ngʼondu, kana ndibei o na kana kĩndũ kĩgagatie gĩa kũnyua, kana o kĩndũ gĩothe kĩrĩa mũngĩenda. Ningĩ inyuĩ na andũ a nyũmba cianyu mũkaarĩĩra indo icio o hau mbere ya Jehova Ngai wanyu mũkenete.
27 Ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi tí ó ń gbé nì ìlú yín, nítorí pé wọn kò ní ìpín kan tàbí ogún kan tí í ṣe tiwọn.
Na mũtikanarekererie Alawii arĩa matũũraga matũũra-inĩ manyu, nĩgũkorwo matirĩ gĩthaka kana igai rĩao ene.
28 Ní òpin ọdún mẹ́ta mẹ́ta, ẹ̀yin yóò mú gbogbo ìdámẹ́wàá ìre oko àwọn ọdún náà, kí ẹ kó wọn jọ ní ìlú yín.
Na rĩrĩ, o mĩaka ĩtatũ yathira, mũrutage icunjĩ cia ikũmi cia uumithio wanyu wothe wa mwaka ũcio, mũgaaciga kũu matũũra-inĩ manyu,
29 Kí àwọn Lefi (tí kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn) àti àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba, àti àwọn opó tí ń gbé ìlú yín lè wá, kí wọn sì jẹ kí wọn sì yó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ le è bùkún fún ọ, nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
nĩgeetha Alawii (arĩa matarĩ agaĩre gĩthaka kana igai rĩao ene), na andũ a kũngĩ, na ciana cia ngoriai, na atumia a ndigwa arĩa matũũraga matũũra-inĩ manyu, magookaga makarĩa na makahũũna, nĩguo Jehova Ngai wanyu amũrathimage wĩra-inĩ wothe wa moko manyu.

< Deuteronomy 14 >