< Deuteronomy 14 >

1 Ọmọ Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́: nítorí náà, ẹ má ṣe ya ara yín ní abẹ. Ẹ má ṣe gé irun iwájú orí yín nítorí òkú.
Vous êtes les enfants de Yahvé votre Dieu. Vous ne vous couperez pas, et vous ne ferez pas de calvitie entre vos yeux pour les morts.
2 Nítorí pé ènìyàn mímọ́ ní ẹ jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ènìyàn tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, Ọlọ́run ti yàn yín láti jẹ́ ìṣúra iyebíye rẹ̀.
Car vous êtes un peuple saint pour l'Éternel, votre Dieu, et l'Éternel vous a choisis pour être un peuple qui lui appartienne en propre, par-dessus tous les peuples qui sont sur la face de la terre.
3 Ẹ má ṣe jẹ ohun ìríra kankan.
Vous ne mangerez aucune chose abominable.
4 Àwọn wọ̀nyí ni ẹranko tí ẹ lè máa jẹ: màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́,
Voici les animaux que vous pourrez manger: le bœuf, le mouton, la chèvre,
5 àgbọ̀nrín, èsúró, etu, àgóró, ẹfọ̀n, ìgalà àti àgùntàn igbó.
le cerf, la gazelle, le chevreuil, la chèvre sauvage, le bouquetin, l'antilope et le chamois.
6 Ẹ lè jẹ gbogbo ẹranko tí pátákò ẹsẹ̀ rẹ̀ kì í ṣe méjì tí ó sì tún jẹ àpọ̀jẹ.
Vous pourrez manger de tous les animaux qui ont le sabot fendu en deux et qui ruminent.
7 Síbẹ̀síbẹ̀ nínú gbogbo ẹran tí ń jẹ àpọ̀jẹ tí ó sì tún ya pátákò ẹsẹ̀ tí ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ni: ìbákasẹ, ehoro, àti ẹranko tí ó dàbí ehoro tí ń gbé inú àpáta. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n jẹ àpọ̀jẹ, ṣùgbọ́n wọn kò la pátákò ẹsẹ̀, a kà wọ́n sí àìmọ́ fún yín.
Mais vous ne mangerez pas de ceux qui ruminent, ni de ceux qui ont le sabot fendu: le chameau, le lièvre et le lapin. Parce qu'ils ruminent mais n'ont pas le sabot fendu, ils sont impurs pour vous.
8 Ẹlẹ́dẹ̀ jẹ́ àìmọ́; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ya pátákò ẹsẹ̀, kì í jẹ àpọ̀jẹ, ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹran rẹ̀, ẹ kò sì gbọdọ̀ fọwọ́ kan òkú rẹ̀.
Le porc, parce qu'il a le sabot fendu mais ne rumine pas, vous est impur. Vous ne mangerez pas de leur viande. Vous ne toucherez pas leurs carcasses.
9 Nínú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń gbé inú omi, ẹ lè jẹ èyíkéyìí tí ó ní lẹbẹ àti ìpẹ́.
Voici ce que vous pourrez manger de tout ce qui se trouve dans les eaux: vous pourrez manger tout ce qui a des nageoires et des écailles.
10 Ṣùgbọ́n èyíkéyìí tí kò bá ní lẹbẹ àti ìpẹ́, ẹ má ṣe jẹ ẹ́, nítorí pé àìmọ́ ni wọ́n jẹ́ fún yín.
Vous ne mangerez pas ce qui n'a pas de nageoires et d'écailles. C'est une impureté pour vous.
11 Ẹ lè jẹ ẹyẹ tí ó bá mọ́.
Tu pourras manger de tous les oiseaux purs.
12 Ṣùgbọ́n ìwọ̀nyí ní ẹ kò gbọdọ̀ jẹ: idì, igún, àkàlà,
Mais voici ceux dont tu ne mangeras pas: l'aigle, le vautour, le balbuzard pêcheur,
13 onírúurú àṣá àti àṣá alátagbà,
le milan royal, le faucon, le milan de toute espèce,
14 onírúurú ẹyẹ ìwò,
le corbeau de toute espèce,
15 ògòǹgò, òwìwí, pẹ́pẹ́yẹdò àti onírúurú àwòdì,
l'autruche, le hibou, la mouette, le faucon de toute espèce,
16 onírúurú òwìwí,
la chouette, le hibou grand duc, le hibou des marais,
17 òwìwí ọ̀dàn, àkàlà, ìgò,
le pélican, le vautour, le cormoran,
18 àkọ̀, òòdẹ̀, onírúurú ẹyẹ odò mìíràn, atọ́ka àti àdán.
la cigogne, le héron selon son espèce, la huppe et la chauve-souris.
19 Àti gbogbo kòkòrò tí ń fò tí wọ́n ń kọ́wọ̀ọ́ rìn jẹ́ aláìmọ́ fun un yín, ẹ má ṣe jẹ wọ́n.
Tous les reptiles ailés sont impurs pour vous. Vous ne les mangerez pas.
20 Ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ èyíkéyìí ẹ̀dá abìyẹ́ tí ó bá mọ́.
Vous pourrez manger de tous les oiseaux purs.
21 Ẹ má ṣe jẹ ohun tí ó ti kú sílẹ̀. Ẹ lè fún àwọn àjèjì tí ń gbé ní èyíkéyìí nínú ìlú yín. Òun lè jẹ ẹ́ tàbí kí ẹ tà á fún àwọn àjèjì. Ṣùgbọ́n ènìyàn mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ewúrẹ́ nínú wàrà ìyá rẹ̀.
Tu ne mangeras pas de ce qui meurt de lui-même. Tu pourras le donner à l'étranger qui habite au milieu de toi et qui se trouve dans tes portes, pour qu'il en mange, ou tu pourras le vendre à un étranger, car tu es un peuple saint pour Yahvé ton Dieu. Tu ne feras pas bouillir un chevreau dans le lait de sa mère.
22 Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń fi ìdákan nínú mẹ́wàá nínú ìre oko yín lọ́dọọdún pamọ́ sí apá kan.
Tu prélèveras la dîme de tout le produit de ta semence, de ce qui sort des champs année après année.
23 Ẹ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àti àkọ́bí àwọn màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín, níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ibi tí yóò yàn bí ibùgbé orúkọ rẹ̀. Kí ẹ lè kọ́ bí a ṣé ń bu ọlá fún Olúwa Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
Tu mangeras devant l'Éternel, ton Dieu, dans le lieu qu'il choisira pour faire résider son nom, la dîme de ton blé, de ton moût et de ton huile, et des premiers-nés de ton gros et de ton menu bétail, afin que tu apprennes à craindre toujours l'Éternel, ton Dieu.
24 Bí ibẹ̀ bá jì tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì ti bùkún fún ọ, tí o kò sì le ru àwọn ìdámẹ́wàá rẹ (nítorí pé ibi tí Olúwa yóò yàn láti fi orúkọ rẹ̀ sí jìnnà jù).
Si le chemin est trop long pour toi, et que tu ne puisses pas le porter, parce que le lieu que l'Éternel, ton Dieu, choisira pour y fixer son nom est trop éloigné de toi, lorsque l'Éternel, ton Dieu, te bénira,
25 Ẹ pààrọ̀ àwọn ìdámẹ́wàá yín sí owó, ẹ mú owó náà lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
tu le transformeras en argent, tu lieras l'argent dans ta main, et tu iras au lieu que l'Éternel, ton Dieu, choisira.
26 Fi owó náà ra ohunkóhun tí o bá fẹ́, màlúù, àgùntàn, wáìnì, tàbí ọtí líle, tàbí ohunkóhun tí o bá fẹ́. Kí ìwọ àti ìdílé rẹ sì jẹ ẹ́ níwájú Olúwa níbẹ̀ kí ẹ sì máa yọ̀.
Tu échangeras cet argent contre tout ce que ton âme désirera: du bétail, des brebis, du vin, des boissons fortes, ou tout ce que ton âme te demandera. Tu y mangeras devant l'Éternel, ton Dieu, et tu te réjouiras, toi et ta famille.
27 Ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi tí ó ń gbé nì ìlú yín, nítorí pé wọn kò ní ìpín kan tàbí ogún kan tí í ṣe tiwọn.
Tu n'abandonneras pas le Lévite qui est dans tes portes, car il n'a ni part ni héritage avec toi.
28 Ní òpin ọdún mẹ́ta mẹ́ta, ẹ̀yin yóò mú gbogbo ìdámẹ́wàá ìre oko àwọn ọdún náà, kí ẹ kó wọn jọ ní ìlú yín.
A la fin de chaque période de trois ans, tu apporteras toute la dîme de ton revenu de la même année, et tu la conserveras dans tes portes.
29 Kí àwọn Lefi (tí kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn) àti àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba, àti àwọn opó tí ń gbé ìlú yín lè wá, kí wọn sì jẹ kí wọn sì yó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ le è bùkún fún ọ, nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
Le Lévite, parce qu'il n'a ni part ni héritage chez toi, ainsi que l'étranger qui habite au milieu de toi, l'orphelin et la veuve qui sont dans tes portes, viendront, mangeront et seront rassasiés, afin que Yahvé ton Dieu te bénisse dans tout le travail de tes mains que tu fais.

< Deuteronomy 14 >