< Deuteronomy 14 >

1 Ọmọ Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́: nítorí náà, ẹ má ṣe ya ara yín ní abẹ. Ẹ má ṣe gé irun iwájú orí yín nítorí òkú.
Sons, are ye unto Yahweh your God, —ye shall not cut yourselves, neither shall ye put baldness between your eyes for the dead.
2 Nítorí pé ènìyàn mímọ́ ní ẹ jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ènìyàn tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, Ọlọ́run ti yàn yín láti jẹ́ ìṣúra iyebíye rẹ̀.
For, a holy people, thou art unto Yahweh thy God, —and, of thee, did Yahweh make choice, that thou shouldest become his people as a treasure, above all the peoples that are on the face of the ground.
3 Ẹ má ṣe jẹ ohun ìríra kankan.
Thou shalt not eat any abominable thing.
4 Àwọn wọ̀nyí ni ẹranko tí ẹ lè máa jẹ: màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́,
These, are the beasts which ye may eat, —the ox, the young of sheep, and the young of goats;
5 àgbọ̀nrín, èsúró, etu, àgóró, ẹfọ̀n, ìgalà àti àgùntàn igbó.
the hart and the gazelle and the roebuck, —and the wild goat and the mountain goat, and the wild ox, and the mountain sheep.
6 Ẹ lè jẹ gbogbo ẹranko tí pátákò ẹsẹ̀ rẹ̀ kì í ṣe méjì tí ó sì tún jẹ àpọ̀jẹ.
And every beast that parteth the hoof and cleaveth the cleft into two claws, chewing the cud, among beasts, the same, shall ye eat.
7 Síbẹ̀síbẹ̀ nínú gbogbo ẹran tí ń jẹ àpọ̀jẹ tí ó sì tún ya pátákò ẹsẹ̀ tí ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ni: ìbákasẹ, ehoro, àti ẹranko tí ó dàbí ehoro tí ń gbé inú àpáta. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n jẹ àpọ̀jẹ, ṣùgbọ́n wọn kò la pátákò ẹsẹ̀, a kà wọ́n sí àìmọ́ fún yín.
Nevertheless these, shall ye not eat, of them that chew the cud, and of them that divide the cloven hoof, —the camel and the hare and the rabbit for, though they do chew the cud, yet the hoof, do they not part, unclean, they are unto you.
8 Ẹlẹ́dẹ̀ jẹ́ àìmọ́; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ya pátákò ẹsẹ̀, kì í jẹ àpọ̀jẹ, ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹran rẹ̀, ẹ kò sì gbọdọ̀ fọwọ́ kan òkú rẹ̀.
And, the swine, because though he doth divide the hoof, yet he cheweth not the cud, unclean, he is unto you, —of their flesh, shall ye not eat, and their carcases, shall ye not touch.
9 Nínú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń gbé inú omi, ẹ lè jẹ èyíkéyìí tí ó ní lẹbẹ àti ìpẹ́.
These, may ye eat of all that that are in the waters, —whatsoever hath fins and scales, ye may eat;
10 Ṣùgbọ́n èyíkéyìí tí kò bá ní lẹbẹ àti ìpẹ́, ẹ má ṣe jẹ ẹ́, nítorí pé àìmọ́ ni wọ́n jẹ́ fún yín.
and, whatsoever hath not, fins and scales, ye may not eat, —unclean, it is unto you.
11 Ẹ lè jẹ ẹyẹ tí ó bá mọ́.
Of every clean bird, ye may eat;
12 Ṣùgbọ́n ìwọ̀nyí ní ẹ kò gbọdọ̀ jẹ: idì, igún, àkàlà,
saving these, of which ye may not eat, —the eagle and the ossifrage and the osprey;
13 onírúurú àṣá àti àṣá alátagbà,
and the vulture and the kite, and the falcon after its kind;
14 onírúurú ẹyẹ ìwò,
and every raven after its kind;
15 ògòǹgò, òwìwí, pẹ́pẹ́yẹdò àti onírúurú àwòdì,
and the female ostrich, and the male ostrich and the sea-gull, —and the hawk, after its kind;
16 onírúurú òwìwí,
and the pelican and the bittern, and the swan;
17 òwìwí ọ̀dàn, àkàlà, ìgò,
and the vomiting pelican and the little vulture and the gannet;
18 àkọ̀, òòdẹ̀, onírúurú ẹyẹ odò mìíràn, atọ́ka àti àdán.
and the stork, and the parrot, after its kind, —and the mountain-cock, and the bat.
19 Àti gbogbo kòkòrò tí ń fò tí wọ́n ń kọ́wọ̀ọ́ rìn jẹ́ aláìmọ́ fun un yín, ẹ má ṣe jẹ wọ́n.
And, as for every creeping thing that flieth, unclean, it is unto you, —they, shall not be eaten.
20 Ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ èyíkéyìí ẹ̀dá abìyẹ́ tí ó bá mọ́.
All clean fowls, ye may eat.
21 Ẹ má ṣe jẹ ohun tí ó ti kú sílẹ̀. Ẹ lè fún àwọn àjèjì tí ń gbé ní èyíkéyìí nínú ìlú yín. Òun lè jẹ ẹ́ tàbí kí ẹ tà á fún àwọn àjèjì. Ṣùgbọ́n ènìyàn mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ewúrẹ́ nínú wàrà ìyá rẹ̀.
Ye shall not eat any thing that dieth of itself: to the sojourner who is within thy gates, mayest thou give it and he may eat it or thou mayest sell it to a foreigner, for a holy people, art thou unto Yahweh thy God. Thou shalt not boil a kid, in the milk of its dam.
22 Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń fi ìdákan nínú mẹ́wàá nínú ìre oko yín lọ́dọọdún pamọ́ sí apá kan.
Thou shalt surely tithe, all the increase of thy seed, —which the field bringeth forth year by year.
23 Ẹ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àti àkọ́bí àwọn màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín, níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ibi tí yóò yàn bí ibùgbé orúkọ rẹ̀. Kí ẹ lè kọ́ bí a ṣé ń bu ọlá fún Olúwa Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
And thou shalt eat before Yahweh thy God—in the place which he shall choose to make a habitation for his name there, —the tithe of thy corn thy new wine and thine oil, and the firstlings of thy herd and of thy flock, —that thou mayest learn to revere Yahweh thy God all the days.
24 Bí ibẹ̀ bá jì tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì ti bùkún fún ọ, tí o kò sì le ru àwọn ìdámẹ́wàá rẹ (nítorí pé ibi tí Olúwa yóò yàn láti fi orúkọ rẹ̀ sí jìnnà jù).
But, when the way becometh too long for thee because thou canst not carry it, because the place is too far for thee which Yahweh thy God shall choose to put his name there, —because Yahweh thy God blesseth thee,
25 Ẹ pààrọ̀ àwọn ìdámẹ́wàá yín sí owó, ẹ mú owó náà lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
then shalt thou turn it into silver, —and shalt bind up the silver in thy hand, and shalt journey unto the place, which Yahweh thy God shall choose;
26 Fi owó náà ra ohunkóhun tí o bá fẹ́, màlúù, àgùntàn, wáìnì, tàbí ọtí líle, tàbí ohunkóhun tí o bá fẹ́. Kí ìwọ àti ìdílé rẹ sì jẹ ẹ́ níwájú Olúwa níbẹ̀ kí ẹ sì máa yọ̀.
and shalt turn the silver into whatsoever thy soul desireth—of the herd or of the flock, or of wine or of strong drink, or of whatsoever thy soul shall ask thee for, —and shalt eat it there, before Yahweh thy God, and shalt rejoice, thou and thy household,
27 Ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi tí ó ń gbé nì ìlú yín, nítorí pé wọn kò ní ìpín kan tàbí ogún kan tí í ṣe tiwọn.
and, the Levite who is within thy gates, thou shalt not forsake him, —for he hath neither portion nor inheritance with thee.
28 Ní òpin ọdún mẹ́ta mẹ́ta, ẹ̀yin yóò mú gbogbo ìdámẹ́wàá ìre oko àwọn ọdún náà, kí ẹ kó wọn jọ ní ìlú yín.
At the end of three years, shalt thou bring forth all the tithe of thine increase in that year, —and shalt lay it up within thy gates;
29 Kí àwọn Lefi (tí kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn) àti àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba, àti àwọn opó tí ń gbé ìlú yín lè wá, kí wọn sì jẹ kí wọn sì yó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ le è bùkún fún ọ, nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
and the Levite shall come in—because he hath neither portion nor inheritance with thee—and the sojourner and the fatherless and the widow who are within thy gates, and they shall eat and be satisfied, —that Yahweh thy God may bless thee, in all the work of thy hand which thou shalt do.

< Deuteronomy 14 >