< Deuteronomy 14 >

1 Ọmọ Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́: nítorí náà, ẹ má ṣe ya ara yín ní abẹ. Ẹ má ṣe gé irun iwájú orí yín nítorí òkú.
You are the children of the Lord your God: you shall not make any baldness between you eyes for the dead.
2 Nítorí pé ènìyàn mímọ́ ní ẹ jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ènìyàn tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, Ọlọ́run ti yàn yín láti jẹ́ ìṣúra iyebíye rẹ̀.
For you are a holy people to the Lord your God, and the Lord your God has chosen you to be a peculiar people to himself of all the nations on the face of the earth.
3 Ẹ má ṣe jẹ ohun ìríra kankan.
You shall not eat any abominable thing.
4 Àwọn wọ̀nyí ni ẹranko tí ẹ lè máa jẹ: màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́,
These [are] the beasts which you shall eat; the calf of the herd, and lamb of the sheep, and kid of the goats;
5 àgbọ̀nrín, èsúró, etu, àgóró, ẹfọ̀n, ìgalà àti àgùntàn igbó.
the stag, and doe, and pygarg, and wild goat, and camelopard.
6 Ẹ lè jẹ gbogbo ẹranko tí pátákò ẹsẹ̀ rẹ̀ kì í ṣe méjì tí ó sì tún jẹ àpọ̀jẹ.
Every beast that divides the hoofs, and makes claws of two divisions, and that chews the cud among beasts, these you shall eat.
7 Síbẹ̀síbẹ̀ nínú gbogbo ẹran tí ń jẹ àpọ̀jẹ tí ó sì tún ya pátákò ẹsẹ̀ tí ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ni: ìbákasẹ, ehoro, àti ẹranko tí ó dàbí ehoro tí ń gbé inú àpáta. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n jẹ àpọ̀jẹ, ṣùgbọ́n wọn kò la pátákò ẹsẹ̀, a kà wọ́n sí àìmọ́ fún yín.
And these you shall not eat of them that chew the cud, and of those that divide the hoofs, and make distinct claws; the camel, and the hare, and the rabbit; because they chew the cud, and do not divide the hoof, these are unclean to you.
8 Ẹlẹ́dẹ̀ jẹ́ àìmọ́; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ya pátákò ẹsẹ̀, kì í jẹ àpọ̀jẹ, ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹran rẹ̀, ẹ kò sì gbọdọ̀ fọwọ́ kan òkú rẹ̀.
And as for the swine, because he divides the hoof, and makes claws of the hoof, yet he chews not the cud, he is unclean to you; you shall not eat of their flesh, you shall not touch their dead bodies.
9 Nínú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń gbé inú omi, ẹ lè jẹ èyíkéyìí tí ó ní lẹbẹ àti ìpẹ́.
And these you shall eat of all that are in the water, you shall eat all that have fins and scales.
10 Ṣùgbọ́n èyíkéyìí tí kò bá ní lẹbẹ àti ìpẹ́, ẹ má ṣe jẹ ẹ́, nítorí pé àìmọ́ ni wọ́n jẹ́ fún yín.
And all that have not fins and scales you shall not eat; they are unclean to you.
11 Ẹ lè jẹ ẹyẹ tí ó bá mọ́.
You shall eat every clean bird.
12 Ṣùgbọ́n ìwọ̀nyí ní ẹ kò gbọdọ̀ jẹ: idì, igún, àkàlà,
And these of them you shall not eat; the eagle, and the ossifrage, and the sea-eagle,
13 onírúurú àṣá àti àṣá alátagbà,
and the vulture, and the kite and the like to it,
14 onírúurú ẹyẹ ìwò,
15 ògòǹgò, òwìwí, pẹ́pẹ́yẹdò àti onírúurú àwòdì,
and the sparrow, and the owl, and the cormorant,
16 onírúurú òwìwí,
and the heron, and the swan, and the stork,
17 òwìwí ọ̀dàn, àkàlà, ìgò,
and the cormorant, and the hawk, and its like, and the hoopoe, and the raven,
18 àkọ̀, òòdẹ̀, onírúurú ẹyẹ odò mìíràn, atọ́ka àti àdán.
and the pelican, and the diver and the like to it, and the red-bill and the bat.
19 Àti gbogbo kòkòrò tí ń fò tí wọ́n ń kọ́wọ̀ọ́ rìn jẹ́ aláìmọ́ fun un yín, ẹ má ṣe jẹ wọ́n.
All winged animals that creep are unclean to you; you shall not eat of them.
20 Ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ èyíkéyìí ẹ̀dá abìyẹ́ tí ó bá mọ́.
You shall eat every clean bird.
21 Ẹ má ṣe jẹ ohun tí ó ti kú sílẹ̀. Ẹ lè fún àwọn àjèjì tí ń gbé ní èyíkéyìí nínú ìlú yín. Òun lè jẹ ẹ́ tàbí kí ẹ tà á fún àwọn àjèjì. Ṣùgbọ́n ènìyàn mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ewúrẹ́ nínú wàrà ìyá rẹ̀.
You shall eat nothing that dies of itself; it shall be given to the sojourner in your cities and he shall eat it, or you shall sell it to a stranger, because you are a holy people to the Lord your God. You shall not boil a lamb in his mother's milk.
22 Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń fi ìdákan nínú mẹ́wàá nínú ìre oko yín lọ́dọọdún pamọ́ sí apá kan.
You shall tithe a tenth of all the produce of your seed, the fruit of your field year by year.
23 Ẹ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àti àkọ́bí àwọn màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín, níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ibi tí yóò yàn bí ibùgbé orúkọ rẹ̀. Kí ẹ lè kọ́ bí a ṣé ń bu ọlá fún Olúwa Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
And you shall eat it in the place which the Lord your God shall choose to have his name called there; you shall bring the tithe of your corn and of your wine, and of your oil, the firstborn of your herd and of your flock, that you may learn to fear the Lord your God always.
24 Bí ibẹ̀ bá jì tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì ti bùkún fún ọ, tí o kò sì le ru àwọn ìdámẹ́wàá rẹ (nítorí pé ibi tí Olúwa yóò yàn láti fi orúkọ rẹ̀ sí jìnnà jù).
And if the journey be too far for you, and you are not able to bring them, because the place [is] far from you which the Lord your God shall choose to have his name called there, because the Lord your God will bless you;
25 Ẹ pààrọ̀ àwọn ìdámẹ́wàá yín sí owó, ẹ mú owó náà lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
then you shall sell them for money, and you shall take the money in your hands, and you shall go to the place which the Lord your God shall choose.
26 Fi owó náà ra ohunkóhun tí o bá fẹ́, màlúù, àgùntàn, wáìnì, tàbí ọtí líle, tàbí ohunkóhun tí o bá fẹ́. Kí ìwọ àti ìdílé rẹ sì jẹ ẹ́ níwájú Olúwa níbẹ̀ kí ẹ sì máa yọ̀.
And you shall give the money for whatever your soul shall desire, for oxen or for sheep, or for wine, or [you shall lay it out] on strong drink, or on whatever your soul may desire, and you shall eat there before the Lord your God, and you shall rejoice and your house,
27 Ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi tí ó ń gbé nì ìlú yín, nítorí pé wọn kò ní ìpín kan tàbí ogún kan tí í ṣe tiwọn.
and the Levite that is in your cities, because he has not a portion or inheritance with you.
28 Ní òpin ọdún mẹ́ta mẹ́ta, ẹ̀yin yóò mú gbogbo ìdámẹ́wàá ìre oko àwọn ọdún náà, kí ẹ kó wọn jọ ní ìlú yín.
After three years you shall bring out all the tithes of your fruits, in that year you shall lay it up in your cities.
29 Kí àwọn Lefi (tí kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn) àti àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba, àti àwọn opó tí ń gbé ìlú yín lè wá, kí wọn sì jẹ kí wọn sì yó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ le è bùkún fún ọ, nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
And the Levite shall come, because he has no part or lot with you, and the stranger, and the orphan, and the widow which is in your cities; and they shall eat and be filled, that the Lord your God may bless you in all the works which you shall do.

< Deuteronomy 14 >