< Deuteronomy 14 >

1 Ọmọ Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́: nítorí náà, ẹ má ṣe ya ara yín ní abẹ. Ẹ má ṣe gé irun iwájú orí yín nítorí òkú.
You are the children of the Lord your God: you are not to make cuts on your bodies or take off the hair on your brows in honour of the dead;
2 Nítorí pé ènìyàn mímọ́ ní ẹ jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ènìyàn tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, Ọlọ́run ti yàn yín láti jẹ́ ìṣúra iyebíye rẹ̀.
For you are a holy people to the Lord your God, and the Lord has taken you to be his special people out of all the nations on the face of the earth.
3 Ẹ má ṣe jẹ ohun ìríra kankan.
No disgusting thing may be your food.
4 Àwọn wọ̀nyí ni ẹranko tí ẹ lè máa jẹ: màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́,
These are the beasts which you may have for food: the ox, the sheep, and the goat;
5 àgbọ̀nrín, èsúró, etu, àgóró, ẹfọ̀n, ìgalà àti àgùntàn igbó.
The hart, the gazelle, and the roe, the mountain goat and the pygarg and the antelope and the mountain sheep.
6 Ẹ lè jẹ gbogbo ẹranko tí pátákò ẹsẹ̀ rẹ̀ kì í ṣe méjì tí ó sì tún jẹ àpọ̀jẹ.
Any beast which has a division in the horn of its foot and whose food comes back into its mouth to be crushed again, may be used for food.
7 Síbẹ̀síbẹ̀ nínú gbogbo ẹran tí ń jẹ àpọ̀jẹ tí ó sì tún ya pátákò ẹsẹ̀ tí ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ni: ìbákasẹ, ehoro, àti ẹranko tí ó dàbí ehoro tí ń gbé inú àpáta. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n jẹ àpọ̀jẹ, ṣùgbọ́n wọn kò la pátákò ẹsẹ̀, a kà wọ́n sí àìmọ́ fún yín.
But even among these, there are some which may not be used for food: such as the camel, the hare, and the coney, which are unclean to you, because, though their food comes back, the horn of their feet is not parted in two.
8 Ẹlẹ́dẹ̀ jẹ́ àìmọ́; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ya pátákò ẹsẹ̀, kì í jẹ àpọ̀jẹ, ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹran rẹ̀, ẹ kò sì gbọdọ̀ fọwọ́ kan òkú rẹ̀.
And the pig is unclean to you, because though it has a division in the horn of its foot, its food does not come back; their flesh may not be used for food or their dead bodies touched by you.
9 Nínú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń gbé inú omi, ẹ lè jẹ èyíkéyìí tí ó ní lẹbẹ àti ìpẹ́.
And of the things living in the waters, you may take all those who have wings for swimming with and skins formed of thin plates.
10 Ṣùgbọ́n èyíkéyìí tí kò bá ní lẹbẹ àti ìpẹ́, ẹ má ṣe jẹ ẹ́, nítorí pé àìmọ́ ni wọ́n jẹ́ fún yín.
But any which have no skin-plates or wings for swimming, you may not take; they are unclean for you.
11 Ẹ lè jẹ ẹyẹ tí ó bá mọ́.
All clean birds may be used for food.
12 Ṣùgbọ́n ìwọ̀nyí ní ẹ kò gbọdọ̀ jẹ: idì, igún, àkàlà,
But these birds you may not take: the eagle and the gier-eagle and the ospray;
13 onírúurú àṣá àti àṣá alátagbà,
The falcon and the kite, and birds of that sort;
14 onírúurú ẹyẹ ìwò,
Every raven, and all birds of that sort;
15 ògòǹgò, òwìwí, pẹ́pẹ́yẹdò àti onírúurú àwòdì,
And the ostrich and the night-hawk and the sea-hawk and birds of that sort;
16 onírúurú òwìwí,
The little owl and the great owl and the water-hen;
17 òwìwí ọ̀dàn, àkàlà, ìgò,
And the pelican and the vulture and the cormorant;
18 àkọ̀, òòdẹ̀, onírúurú ẹyẹ odò mìíràn, atọ́ka àti àdán.
The stork and the heron and birds of that sort, and the hoopoe and the bat.
19 Àti gbogbo kòkòrò tí ń fò tí wọ́n ń kọ́wọ̀ọ́ rìn jẹ́ aláìmọ́ fun un yín, ẹ má ṣe jẹ wọ́n.
Every winged thing which goes flat on the earth is unclean to you and may not be used as food.
20 Ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ èyíkéyìí ẹ̀dá abìyẹ́ tí ó bá mọ́.
But all clean birds you may take.
21 Ẹ má ṣe jẹ ohun tí ó ti kú sílẹ̀. Ẹ lè fún àwọn àjèjì tí ń gbé ní èyíkéyìí nínú ìlú yín. Òun lè jẹ ẹ́ tàbí kí ẹ tà á fún àwọn àjèjì. Ṣùgbọ́n ènìyàn mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ewúrẹ́ nínú wàrà ìyá rẹ̀.
You may not have as food anything which has come to a natural death; the man from another country who is living with you may take it for food, or you may get a price for it from one of another nation; for you are a holy people to the Lord your God. The young goat is not to be cooked in its mother's milk.
22 Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń fi ìdákan nínú mẹ́wàá nínú ìre oko yín lọ́dọọdún pamọ́ sí apá kan.
Put on one side a tenth of all the increase of your seed, produced year by year.
23 Ẹ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àti àkọ́bí àwọn màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín, níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ibi tí yóò yàn bí ibùgbé orúkọ rẹ̀. Kí ẹ lè kọ́ bí a ṣé ń bu ọlá fún Olúwa Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
And make a feast before the Lord your God, in the place which is to be marked out, where his name will be for ever, of the tenth part of your grain and your wine and your oil, and the first births of your herds and your flocks; so that you may have the fear of the Lord your God in your hearts at all times.
24 Bí ibẹ̀ bá jì tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì ti bùkún fún ọ, tí o kò sì le ru àwọn ìdámẹ́wàá rẹ (nítorí pé ibi tí Olúwa yóò yàn láti fi orúkọ rẹ̀ sí jìnnà jù).
And if the way is so long that you are not able to take these things to the place marked out by the Lord your God for his name, when he has given you his blessing, because it is far away from you;
25 Ẹ pààrọ̀ àwọn ìdámẹ́wàá yín sí owó, ẹ mú owó náà lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
Then let these things be exchanged for money, and, taking the money in your hand, go to the place marked out by the Lord your God for himself;
26 Fi owó náà ra ohunkóhun tí o bá fẹ́, màlúù, àgùntàn, wáìnì, tàbí ọtí líle, tàbí ohunkóhun tí o bá fẹ́. Kí ìwọ àti ìdílé rẹ sì jẹ ẹ́ níwájú Olúwa níbẹ̀ kí ẹ sì máa yọ̀.
And with the money get whatever you have a desire for, oxen or sheep or wine or strong drink, whatever your soul's desire may be: and make a feast there before the Lord your God, and be glad, you and all your house;
27 Ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi tí ó ń gbé nì ìlú yín, nítorí pé wọn kò ní ìpín kan tàbí ogún kan tí í ṣe tiwọn.
And give a thought to the Levite who is living among you, for he has no part or heritage in the land.
28 Ní òpin ọdún mẹ́ta mẹ́ta, ẹ̀yin yóò mú gbogbo ìdámẹ́wàá ìre oko àwọn ọdún náà, kí ẹ kó wọn jọ ní ìlú yín.
At the end of every three years take a tenth part of all your increase for that year, and put it in store inside your walls:
29 Kí àwọn Lefi (tí kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn) àti àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba, àti àwọn opó tí ń gbé ìlú yín lè wá, kí wọn sì jẹ kí wọn sì yó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ le è bùkún fún ọ, nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
And the Levite, because he has no part or heritage in the land, and the man from a strange country, and the child who has no father, and the widow, who are living among you, will come and take food and have enough; and so the blessing of the Lord your God will be on you in everything you do.

< Deuteronomy 14 >