< Deuteronomy 14 >

1 Ọmọ Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́: nítorí náà, ẹ má ṣe ya ara yín ní abẹ. Ẹ má ṣe gé irun iwájú orí yín nítorí òkú.
Dilia da Hina Gode Ea Fi dunu. Amaiba: le, dilia dunu bogobeba: le, didiga: sea, dilia da: i gobiheiga mae abigima amola dilia dialuma mae ougelema.
2 Nítorí pé ènìyàn mímọ́ ní ẹ jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ènìyàn tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, Ọlọ́run ti yàn yín láti jẹ́ ìṣúra iyebíye rẹ̀.
Dilia da Hina Gode Ea: dunu fi. E da dunu fifi asi gala amo huluane hodole, dilima fawane ilegei dagoi.
3 Ẹ má ṣe jẹ ohun ìríra kankan.
Hina Gode da ha: i manu da ledo gala ilegei galea, amo mae moma.
4 Àwọn wọ̀nyí ni ẹranko tí ẹ lè máa jẹ: màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́,
Ohe fi dilia manu da defea da bulamagau, sibi, goudi,
5 àgbọ̀nrín, èsúró, etu, àgóró, ẹfọ̀n, ìgalà àti àgùntàn igbó.
dia, soge sibi, soge goudi, a:deloubi amola
6 Ẹ lè jẹ gbogbo ẹranko tí pátákò ẹsẹ̀ rẹ̀ kì í ṣe méjì tí ó sì tún jẹ àpọ̀jẹ.
adi ohe fi ilia emo sasafo adobo amola ilia gisi hedesini esaga salawane aduga: le guda: le bu hi naha.
7 Síbẹ̀síbẹ̀ nínú gbogbo ẹran tí ń jẹ àpọ̀jẹ tí ó sì tún ya pátákò ẹsẹ̀ tí ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ni: ìbákasẹ, ehoro, àti ẹranko tí ó dàbí ehoro tí ń gbé inú àpáta. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n jẹ àpọ̀jẹ, ṣùgbọ́n wọn kò la pátákò ẹsẹ̀, a kà wọ́n sí àìmọ́ fún yín.
Be ohe fi ilia emo da sasafo adobo, be ilia gisi hedesini esaga salawane aduga: le guda: le bu hi hame naha, amo da sema - mae moma. ‘Ga: mele’, ‘la: bidi’ amola ‘igi ba: dege’ da ledoba: le mae moma. Ilia ha: i manu da hedesini esaga salawane aduga: le guda: le bu hi naha, be ilia emo da sasafo adobo hame.
8 Ẹlẹ́dẹ̀ jẹ́ àìmọ́; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ya pátákò ẹsẹ̀, kì í jẹ àpọ̀jẹ, ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹran rẹ̀, ẹ kò sì gbọdọ̀ fọwọ́ kan òkú rẹ̀.
Gebodafa mae moma. Ilia da ledo gala. Ilia da emo sasafo adobo gala be ilia ha: i manu da hedesini esaga salawane aduga: le guda: le bu hi naha hame hamosa. Agoaiwane ledo ohe fi amo mae moma amola ilia bogoi da: i hodo mae digili ba: ma.
9 Nínú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń gbé inú omi, ẹ lè jẹ èyíkéyìí tí ó ní lẹbẹ àti ìpẹ́.
Menabo amo da aiya galebe, amo dilia manu da defea.
10 Ṣùgbọ́n èyíkéyìí tí kò bá ní lẹbẹ àti ìpẹ́, ẹ má ṣe jẹ ẹ́, nítorí pé àìmọ́ ni wọ́n jẹ́ fún yín.
Be hano ganodini esalebe fi huluane da aiya hame gala amo mae moma. Amo da dilima ledo gala.
11 Ẹ lè jẹ ẹyẹ tí ó bá mọ́.
Ledo hamedei sio fi dilia manu da defea.
12 Ṣùgbọ́n ìwọ̀nyí ní ẹ kò gbọdọ̀ jẹ: idì, igún, àkàlà,
Be amo dedei sio mae moma - buhiba, sia, sedia, waialima sononi, wida, aowa ahea, ‘gala: ini’, ‘beliga: ne’ amola ganeba.
13 onírúurú àṣá àti àṣá alátagbà,
14 onírúurú ẹyẹ ìwò,
15 ògòǹgò, òwìwí, pẹ́pẹ́yẹdò àti onírúurú àwòdì,
16 onírúurú òwìwí,
17 òwìwí ọ̀dàn, àkàlà, ìgò,
18 àkọ̀, òòdẹ̀, onírúurú ẹyẹ odò mìíràn, atọ́ka àti àdán.
19 Àti gbogbo kòkòrò tí ń fò tí wọ́n ń kọ́wọ̀ọ́ rìn jẹ́ aláìmọ́ fun un yín, ẹ má ṣe jẹ wọ́n.
Amola agime, gugu, aowaba amola huluane agoaiwane liligi ougia galebe da dilima ledo gala. Amo huluane mae moma.
20 Ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ èyíkéyìí ẹ̀dá abìyẹ́ tí ó bá mọ́.
Be ledo hamedei agoaiwane liligi dilia manu da defea.
21 Ẹ má ṣe jẹ ohun tí ó ti kú sílẹ̀. Ẹ lè fún àwọn àjèjì tí ń gbé ní èyíkéyìí nínú ìlú yín. Òun lè jẹ ẹ́ tàbí kí ẹ tà á fún àwọn àjèjì. Ṣùgbọ́n ènìyàn mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ewúrẹ́ nínú wàrà ìyá rẹ̀.
Ohe fi da hi bogoi, amo mae moma. Ga fi dunu dilia fi amo ganodini esala amo ilia manu da defea. O hou eno dilia da ohe hisu bogoi amo ga fi dunu eno ilima bidi lama. Be dilia da Hina Gode Ea fidafa. Amaiba: le, mae moma. Dilia sibi o goudi mano amo ea ame ea dodo maga: me ganodini mae gobema.”
22 Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń fi ìdákan nínú mẹ́wàá nínú ìre oko yín lọ́dọọdún pamọ́ sí apá kan.
“Dilia ‘daide’ la: ididili ligisima. Amo da dilia ifabi ha: i manu legei nabuane fifili afadafa Godema ima.
23 Ẹ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àti àkọ́bí àwọn màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín, níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ibi tí yóò yàn bí ibùgbé orúkọ rẹ̀. Kí ẹ lè kọ́ bí a ṣé ń bu ọlá fún Olúwa Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
Amasea, Hina Gode Ea dilia Ema nodomusa: ilegei sogebi afae amoga asili, Ea midadi dilia gagoma, waini, olife susuligi, bulamagau magobo amola sibi magobo amo nabuane fifili afae moma. Dilia eso huluane Hina Godema nodoma: ne hamoma.
24 Bí ibẹ̀ bá jì tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì ti bùkún fún ọ, tí o kò sì le ru àwọn ìdámẹ́wàá rẹ (nítorí pé ibi tí Olúwa yóò yàn láti fi orúkọ rẹ̀ sí jìnnà jù).
Be Godema nodomu sogebi da dilia diasu baligili sedade ba: sea, amola ‘daide’ amo Gode da dima hahawane i amo da amoga gaguli masunu da hamedei ba: sea, agoane hamoma.
25 Ẹ pààrọ̀ àwọn ìdámẹ́wàá yín sí owó, ẹ mú owó náà lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
Dia ha: i manu ‘daide’ bidi lale, muni fawane Godema nodone sia: ne gadosu sogebi amoga gaguli masa.
26 Fi owó náà ra ohunkóhun tí o bá fẹ́, màlúù, àgùntàn, wáìnì, tàbí ọtí líle, tàbí ohunkóhun tí o bá fẹ́. Kí ìwọ àti ìdílé rẹ sì jẹ ẹ́ níwájú Olúwa níbẹ̀ kí ẹ sì máa yọ̀.
Amogawi, amo muniga dilia hanai lama. Ohe hu, sibi mano, waini hano o agoai hano - amo lale, dilia Hina Gode ba: ma: ne, dilia amola dilia sosogo fi da hahawane moma: mu.
27 Ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi tí ó ń gbé nì ìlú yín, nítorí pé wọn kò ní ìpín kan tàbí ogún kan tí í ṣe tiwọn.
Dilia Lifai dunu dilia moilai ganodini esala amo mae gogolema. Bai ilia da soge hame gagusa.
28 Ní òpin ọdún mẹ́ta mẹ́ta, ẹ̀yin yóò mú gbogbo ìdámẹ́wàá ìre oko àwọn ọdún náà, kí ẹ kó wọn jọ ní ìlú yín.
Ode osodayale huluane gidigisia, dilia ha: i manu legei ‘daide’ amo gaguli misini dilia moilai amo ganodini legema.
29 Kí àwọn Lefi (tí kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn) àti àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba, àti àwọn opó tí ń gbé ìlú yín lè wá, kí wọn sì jẹ kí wọn sì yó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ le è bùkún fún ọ, nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
Amo ha: i manu da Lifai (bai ilia da soge hame gagusa), ga fi, guluba: mano amola didalo dilia moilai ganodini esala amo moma: ne gilisima. Ilia da misini ilia hanaiga manu. Dilia da agoane hamosea, Hina Gode da dilia hawa: hamosu huluane hahawane dogolegelewane fidimu.

< Deuteronomy 14 >