< Deuteronomy 13 >

1 Bí wòlíì tàbí alásọtẹ́lẹ̀ nípa àlá lílá bá farahàn láàrín yín, tí ó sì ń kéde iṣẹ́ àmì tàbí iṣẹ́ ìyanu,
اگر در میان تو نبی‌ای یا بیننده خواب ازمیان شما برخیزد، و آیت یا معجزه‌ای برای شما ظاهر سازد،۱
2 bí iṣẹ́ àmì tàbí iṣẹ́ ìyanu tí ó sọ̀rọ̀ rẹ̀ bá ṣẹ tí òun sì wí pé, “ẹ wá ẹ jẹ́ kí a tẹ̀lé ọlọ́run mìíràn” (àwọn ọlọ́run tí ẹ kò mọ̀ rí) “kí ẹ sì jẹ́ kí a máa sìn wọ́n,”
و آن آیت یا معجزه واقع شود که از آن تو را خبر داده، گفت خدایان غیر راکه نمی شناسی پیروی نماییم، و آنها را عبادت کنیم،۲
3 ẹ má fetí sí ọ̀rọ̀ wòlíì tàbí àlá náà, Olúwa Ọlọ́run yín ń dán an yín wò ni, láti mọ̀ bóyá ẹ fẹ́ràn rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àyà yín àti gbogbo ọkàn an yín.
سخنان آن نبی یا بیننده خواب را مشنو، زیرا که یهوه، خدای شما، شما را امتحان می‌کند، تا بداند که آیا یهوه، خدای خود را به تمامی دل وبه تمامی جان خود محبت می‌نمایید؟۳
4 Olúwa Ọlọ́run yín ni kí ẹ tẹ̀lé, Òun ni kí ẹ bu ọlá fún, ẹ pa òfin rẹ̀ mọ́ kí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, ẹ sìn ín, kí ẹ sì dìímú ṣinṣin.
یهوه خدای خود را پیروی نمایید و از او بترسید، واوامر او را نگاه دارید، و قول او را بشنوید و او راعبادت نموده، به او ملحق شوید.۴
5 Wòlíì náà tàbí alálàá náà ni kí ẹ pa, nítorí pé wàásù ìṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú yín jáde láti Ejibiti wá, tí ó sì rà yín padà lóko ẹrú. Ó ti gbìyànjú láti fà yín kúrò lójú ọ̀nà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín láti máa rìn. Ẹ gbọdọ̀ yọ ibi náà kúrò láàrín yín.
و آن نبی یابیننده خواب کشته شود، زیرا که سخنان فتنه انگیز بر یهوه خدای شما که شما را از زمین مصر بیرون آورد، و تو را از خانه بندگی فدیه داد، گفته است تا تو را از طریقی که یهوه خدایت به توامر فرمود تا با آن سلوک نمایی، منحرف سازد، پس به این طور بدی را از میان خود دور خواهی کرد.۵
6 Bí arákùnrin tìrẹ gan an ọmọ ìyá rẹ tàbí ọmọ rẹ ọkùnrin tàbí obìnrin, aya tí o fẹ́ràn jù, tàbí ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ bá tàn ọ́ jẹ níkọ̀kọ̀ wí pé, “Jẹ́ kí a lọ sin ọlọ́run mìíràn” (ọlọ́run tí ìwọ tàbí baba rẹ kò mọ̀,
و اگر برادرت که پسر مادرت باشد یا پسر یادختر تو یا زن هم آغوش تو یا رفیقت که مثل جان تو باشد، تو را در خفا اغوا کند، و گوید که برویم وخدایان غیر را که تو و پدران تو نشناختید عبادت نماییم،۶
7 ọlọ́run àwọn tí ó wà láyìíká yín, yálà wọ́n jìnnà tàbí wọ́n wà nítòsí, láti òpin ilẹ̀ kan dé òmíràn),
از خدایان امتهایی که به اطراف شمامی باشند، خواه به تو نزدیک و خواه از تو دورباشند، از اقصای زمین تا اقصای دیگر آن،۷
8 má ṣe fetí sí i, má sì dá sí i, má ṣe dáàbò bò ó.
او راقبول مکن و او را گوش مده، و چشم تو بر وی رحم نکند و بر او شفقت منما و او را پنهان مکن.۸
9 Ṣùgbọ́n pípa ni kí o pa á. Ọwọ́ rẹ ni yóò kọ́kọ́ wà lára rẹ̀ láti pa á, lẹ́yìn náà ọwọ́ gbogbo ènìyàn.
البته او را به قتل رسان، دست تو اول به قتل اودراز شود و بعد دست تمامی قوم.۹
10 Sọ ọ́ ní òkúta pa nítorí pé ó gbìyànjú láti fà ọ́ kúrò lẹ́yìn Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó mú ọ jáde ti Ejibiti wá kúrò ní oko ẹrú.
و او را به سنگ سنگسار نما تا بمیرد، چونکه می‌خواست تو را از یهوه، خدایت، که تو را از زمین مصر ازخانه بندگی بیرون آورد، منحرف سازد.۱۰
11 Gbogbo Israẹli yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, kò sì sí ẹnikẹ́ni nínú yín tí yóò dán irú ibi bẹ́ẹ̀ wò mọ́.
وجمیع اسرائیلیان چون بشنوند، خواهند ترسید وبار دیگر چنین امر زشت را در میان شما مرتکب نخواهند شد.۱۱
12 Bí ẹ̀yin bá gbọ́ tí a sọ nípa èyíkéyìí nínú àwọn ìlú u yín tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín láti máa gbé,
اگر درباره یکی از شهرهایی که یهوه خدایت به تو به جهت سکونت می‌دهد خبر یابی،۱۲
13 pé àwọn ènìyàn búburú, ti farahàn láàrín yín, tí ó sì ti mú kí àwọn ènìyàn ìlú wọn ṣìnà lọ, tí wọ́n wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a lọ sin ọlọ́run mìíràn.” (àwọn ọlọ́run tí ẹ kò mọ̀.)
که بعضی پسران بلیعال از میان تو بیرون رفته، ساکنان شهر خود را منحرف ساخته، گفته اندبرویم و خدایان غیر را که نشناخته‌اید، عبادت نماییم،۱۳
14 Kí ẹ wádìí, ẹ béèrè, kí ẹ sì tọpinpin ọ̀rọ̀ náà dájúṣáká, bí ó bá jẹ́ òtítọ́ ni, tí ó sì hàn dájú pé ìwà ìríra yìí ti ṣẹlẹ̀ láàrín yín.
آنگاه تفحص و تجسس نموده، نیکواستفسار نما. و اینک اگر این امر، صحیح و یقین باشد که این رجاست در میان تو معمول شده است،۱۴
15 Gbogbo àwọn tí ó ń gbé ìlú náà ni kí ẹ fi idà run pátápátá. Ẹ run ún pátápátá, àti ènìyàn àti ẹran ọ̀sìn inú rẹ̀.
البته ساکنان آن شهر را به دم شمشیربکش و آن را با هرچه در آن است و بهایمش را به دم شمشیر هلاک نما.۱۵
16 Ẹ kó gbogbo ìkógun ìlú náà, sí àárín gbogbo ènìyàn, kí ẹ sun ìlú náà àti gbogbo ìkógun rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Ó gbọdọ̀ wà ní píparun láéláé, ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ tún un kọ.
و همه غنیمت آن را در میان کوچه‌اش جمع کن و شهر را با تمامی غنیمتش برای یهوه خدایت به آتش بالکل بسوزان، و آن تا به ابد تلی خواهد بود و بار دیگربنا نخواهد شد.۱۶
17 A kò gbọdọ̀ rí ọ̀kan nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun wọ̀n-ọn-nì lọ́wọ́ yín, kí Olúwa ba à le yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀, yóò sì ṣàánú fún un yín, yóò sì bá a yín kẹ́dùn, yóò sì mú kí ẹ pọ̀ sí i, bí ó ti fì búra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá yín.
و از چیزهای حرام شده چیزی به‌دستت نچسبد تا خداوند از شدت خشم خود برگشته، برتو رحمت و رافت بنماید، و تو را بیفزاید بطوری که برای پدرانت قسم خورده بود.۱۷
18 Nítorí pé ẹ̀yin gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ̀yin sì ń pa òfin rẹ̀ mọ́, tí mo ń fún un yín lónìí yìí, tí ẹ̀yin sì ń ṣe ohun tí ó tọ́ lójú rẹ̀.
هنگامی که قول یهوه خدای خودرا شنیده، و همه اوامرش را که من امروز به تو امرمی فرمایم نگاه داشته، آنچه در نظر یهوه خدایت راست است، بعمل آورده باشی.۱۸

< Deuteronomy 13 >