< Deuteronomy 13 >
1 Bí wòlíì tàbí alásọtẹ́lẹ̀ nípa àlá lílá bá farahàn láàrín yín, tí ó sì ń kéde iṣẹ́ àmì tàbí iṣẹ́ ìyanu,
Ha támad közepetted próféta vagy álomlátó, és ad neked jelt vagy csodát;
2 bí iṣẹ́ àmì tàbí iṣẹ́ ìyanu tí ó sọ̀rọ̀ rẹ̀ bá ṣẹ tí òun sì wí pé, “ẹ wá ẹ jẹ́ kí a tẹ̀lé ọlọ́run mìíràn” (àwọn ọlọ́run tí ẹ kò mọ̀ rí) “kí ẹ sì jẹ́ kí a máa sìn wọ́n,”
és bekövetkezik a jel és a csoda, amelyről neked szólt, mondván: Menjünk más istenek után, amelyeket te nem ismersz, és szolgáljuk azokat.
3 ẹ má fetí sí ọ̀rọ̀ wòlíì tàbí àlá náà, Olúwa Ọlọ́run yín ń dán an yín wò ni, láti mọ̀ bóyá ẹ fẹ́ràn rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àyà yín àti gbogbo ọkàn an yín.
ne hallgass annak a prófétának a szavára, vagy arra az álomlátóra, mert megkísért benneteket az Örökkévaló, a ti Istenetek, hogy megtudja, vajon szeretitek-e az Örökkévalót, a ti Isteneteket egész szívetekkel és egész lelketekkel.
4 Olúwa Ọlọ́run yín ni kí ẹ tẹ̀lé, Òun ni kí ẹ bu ọlá fún, ẹ pa òfin rẹ̀ mọ́ kí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, ẹ sìn ín, kí ẹ sì dìímú ṣinṣin.
Az Örökkévaló, a ti Istenetek után járjatok, őt féljétek, az ő parancsolatait őrizzétek meg, szavára hallgassatok, őt szolgáljátok és hozzá ragaszkodjatok.
5 Wòlíì náà tàbí alálàá náà ni kí ẹ pa, nítorí pé wàásù ìṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú yín jáde láti Ejibiti wá, tí ó sì rà yín padà lóko ẹrú. Ó ti gbìyànjú láti fà yín kúrò lójú ọ̀nà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín láti máa rìn. Ẹ gbọdọ̀ yọ ibi náà kúrò láàrín yín.
Az a próféta pedig vagy az az álomlátó ölessék meg, mert felszólított elpártolásra az Örökkévalótól, a ti Istenetektől, aki kivezetett benneteket Egyiptom országából és aki megváltott téged a rabszolgák házából; hogy eltántorítson téged arról az útról, melyet parancsolt neked az Örökkévaló, a te Istened, hogy azon járj. Így irtsd ki a rosszat közepedből.
6 Bí arákùnrin tìrẹ gan an ọmọ ìyá rẹ tàbí ọmọ rẹ ọkùnrin tàbí obìnrin, aya tí o fẹ́ràn jù, tàbí ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ bá tàn ọ́ jẹ níkọ̀kọ̀ wí pé, “Jẹ́ kí a lọ sin ọlọ́run mìíràn” (ọlọ́run tí ìwọ tàbí baba rẹ kò mọ̀,
Ha el akar csábítani testvéred, anyád fia, vagy fiad, vagy leányod, vagy kebleden levő feleséged, vagy felebarátod, ki olyan, mint a tenlelked, titokban, mondván: Menjünk és szolgáljunk más isteneteket, melyeket nem ismertél sem te, sem őseid;
7 ọlọ́run àwọn tí ó wà láyìíká yín, yálà wọ́n jìnnà tàbí wọ́n wà nítòsí, láti òpin ilẹ̀ kan dé òmíràn),
ama népek istenei közül, melyek körülöttetek vannak, közel hozzád, vagy távol tőled, a föld egyik szélétől a másik széléig
8 má ṣe fetí sí i, má sì dá sí i, má ṣe dáàbò bò ó.
ne engedj neki és ne hallgass rá és ne könyörüljön szemed rajta, ne kíméljed és ne leplezgesd őt,
9 Ṣùgbọ́n pípa ni kí o pa á. Ọwọ́ rẹ ni yóò kọ́kọ́ wà lára rẹ̀ láti pa á, lẹ́yìn náà ọwọ́ gbogbo ènìyàn.
hanem öld meg őt; a te kezed legyen rajta először, hogy megöld és az egész nép keze azután.
10 Sọ ọ́ ní òkúta pa nítorí pé ó gbìyànjú láti fà ọ́ kúrò lẹ́yìn Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó mú ọ jáde ti Ejibiti wá kúrò ní oko ẹrú.
Kövezd meg kövekkel, hogy meghaljon, mert el akart téged tántorítani az Örökkévalótól, a te Istenedtől, aki kivezetett téged Egyiptom országából, a rabszolgák házából.
11 Gbogbo Israẹli yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, kò sì sí ẹnikẹ́ni nínú yín tí yóò dán irú ibi bẹ́ẹ̀ wò mọ́.
Egész Izrael pedig hallja és féljen, hogy ne tegyenek többé ilyen gonosz dolgot közepedben.
12 Bí ẹ̀yin bá gbọ́ tí a sọ nípa èyíkéyìí nínú àwọn ìlú u yín tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín láti máa gbé,
Ha hallod városaid egyikében, melyet az Örökkévaló, a te Istened neked ad, hogy ott lakjál, mondván:
13 pé àwọn ènìyàn búburú, ti farahàn láàrín yín, tí ó sì ti mú kí àwọn ènìyàn ìlú wọn ṣìnà lọ, tí wọ́n wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a lọ sin ọlọ́run mìíràn.” (àwọn ọlọ́run tí ẹ kò mọ̀.)
Kijöttek alávaló emberek közepedből és eltántorították városuk lakóit, mondván: Menjünk és szolgáljunk más isteneket, melyeket ti nem ismertek;
14 Kí ẹ wádìí, ẹ béèrè, kí ẹ sì tọpinpin ọ̀rọ̀ náà dájúṣáká, bí ó bá jẹ́ òtítọ́ ni, tí ó sì hàn dájú pé ìwà ìríra yìí ti ṣẹlẹ̀ láàrín yín.
akkor keress, vizsgálj és kérdezz jól és íme igaz, bizonyos a dolog, megtörtént ez az utálat közepetted,
15 Gbogbo àwọn tí ó ń gbé ìlú náà ni kí ẹ fi idà run pátápátá. Ẹ run ún pátápátá, àti ènìyàn àti ẹran ọ̀sìn inú rẹ̀.
verd le ama város lakóit a kard élével, kiirtva azt és mindent, ami benne van, meg barmát, a kard élével.
16 Ẹ kó gbogbo ìkógun ìlú náà, sí àárín gbogbo ènìyàn, kí ẹ sun ìlú náà àti gbogbo ìkógun rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Ó gbọdọ̀ wà ní píparun láéláé, ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ tún un kọ.
Egész zsákmányát pedig gyűjtsd össze piacára; égesd el tűzben, a várost meg egész zsákmányát teljesen az Örökkévalónak, a te Istenednek és maradjon örök rom, ne építsétek többé föl.
17 A kò gbọdọ̀ rí ọ̀kan nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun wọ̀n-ọn-nì lọ́wọ́ yín, kí Olúwa ba à le yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀, yóò sì ṣàánú fún un yín, yóò sì bá a yín kẹ́dùn, yóò sì mú kí ẹ pọ̀ sí i, bí ó ti fì búra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá yín.
És ne tapadjon kezedhez semmi az átokból, hogy megtérjen az Örökkévaló fölgerjedt haragjától és kegyelmet adjon neked és megsokasítson téged, amint megesküdött őseidnek,
18 Nítorí pé ẹ̀yin gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ̀yin sì ń pa òfin rẹ̀ mọ́, tí mo ń fún un yín lónìí yìí, tí ẹ̀yin sì ń ṣe ohun tí ó tọ́ lójú rẹ̀.
hogyha hallgatsz az Örökkévaló, a te Istened szavára, hogy megőrizd mind az ő parancsolatait, melyeket én ma neked parancsolok, hogy azt tedd, ami helyes az Örökkévaló, a te Istened szemeiben.