< Deuteronomy 13 >

1 Bí wòlíì tàbí alásọtẹ́lẹ̀ nípa àlá lílá bá farahàn láàrín yín, tí ó sì ń kéde iṣẹ́ àmì tàbí iṣẹ́ ìyanu,
When there shall arise in thy midst—a prophet, or a dreamer of dreams, —and he shall give unto thee a sign or a wonder;
2 bí iṣẹ́ àmì tàbí iṣẹ́ ìyanu tí ó sọ̀rọ̀ rẹ̀ bá ṣẹ tí òun sì wí pé, “ẹ wá ẹ jẹ́ kí a tẹ̀lé ọlọ́run mìíràn” (àwọn ọlọ́run tí ẹ kò mọ̀ rí) “kí ẹ sì jẹ́ kí a máa sìn wọ́n,”
and the sign or the wonder shall come in, whereof he spake unto thee, saying, —Let us go after other gods, which ye know not and let us serve them
3 ẹ má fetí sí ọ̀rọ̀ wòlíì tàbí àlá náà, Olúwa Ọlọ́run yín ń dán an yín wò ni, láti mọ̀ bóyá ẹ fẹ́ràn rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àyà yín àti gbogbo ọkàn an yín.
thou shalt not hearken unto the words of that prophet, or unto that dreamer of dreams, —for Yahweh your God, is putting you to the proof, to know whether ye do love Yahweh your God, with all your heart and with all your soul.
4 Olúwa Ọlọ́run yín ni kí ẹ tẹ̀lé, Òun ni kí ẹ bu ọlá fún, ẹ pa òfin rẹ̀ mọ́ kí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, ẹ sìn ín, kí ẹ sì dìímú ṣinṣin.
After Yahweh your God, shall ye walk And him, shall ye revere, —And his commandments, shall ye observe. And unto his voice, shall ye hearken, And him, shall ye serve And unto him, shall ye cleave.
5 Wòlíì náà tàbí alálàá náà ni kí ẹ pa, nítorí pé wàásù ìṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú yín jáde láti Ejibiti wá, tí ó sì rà yín padà lóko ẹrú. Ó ti gbìyànjú láti fà yín kúrò lójú ọ̀nà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín láti máa rìn. Ẹ gbọdọ̀ yọ ibi náà kúrò láàrín yín.
And that prophet or that dreamer of dreams, shall be put to death because he hath spoken revolt against Yahweh your God, —who brought you forth out of the land of Egypt and redeemed thee out of the house of servants, to seduce thee out of the way wherein Yahweh thy God hath commanded thee to walk, —so shalt thou consume the wicked thing out of thy midst.
6 Bí arákùnrin tìrẹ gan an ọmọ ìyá rẹ tàbí ọmọ rẹ ọkùnrin tàbí obìnrin, aya tí o fẹ́ràn jù, tàbí ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ bá tàn ọ́ jẹ níkọ̀kọ̀ wí pé, “Jẹ́ kí a lọ sin ọlọ́run mìíràn” (ọlọ́run tí ìwọ tàbí baba rẹ kò mọ̀,
When thy brother—son of thine own mother or thine own son or thine own daughter, or the wife of thy bosom, or thy friend who is as thine own soul, shall entice thee secretly, saying, —Let us go and serve other gods, whom thou hast not known, thou, nor thy fathers;
7 ọlọ́run àwọn tí ó wà láyìíká yín, yálà wọ́n jìnnà tàbí wọ́n wà nítòsí, láti òpin ilẹ̀ kan dé òmíràn),
of the gods of the peoples who are round about you, who are near unto thee, or who are far off from thee, —from one end of the earth even unto the other end of the earth,
8 má ṣe fetí sí i, má sì dá sí i, má ṣe dáàbò bò ó.
thou shalt not consent unto him, neither shalt thou hearken unto him, —neither shall thine eye look with pity upon him, neither shalt thou spare—neither shalt thou conceal him;
9 Ṣùgbọ́n pípa ni kí o pa á. Ọwọ́ rẹ ni yóò kọ́kọ́ wà lára rẹ̀ láti pa á, lẹ́yìn náà ọwọ́ gbogbo ènìyàn.
but thou shalt slay, him, thine own hand, shall be on him first, to put him to death, —and the hand of all the people afterwards.
10 Sọ ọ́ ní òkúta pa nítorí pé ó gbìyànjú láti fà ọ́ kúrò lẹ́yìn Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó mú ọ jáde ti Ejibiti wá kúrò ní oko ẹrú.
And thou shalt stone him with stones that he die, —for he hath sought to seduce thee from Yahweh thy God, who brought thee forth out of the land of Egypt, out of the house of servants.
11 Gbogbo Israẹli yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, kò sì sí ẹnikẹ́ni nínú yín tí yóò dán irú ibi bẹ́ẹ̀ wò mọ́.
And, all Israel, shall hear and fear, —and shall not again do according to this wickedness in thy midst.
12 Bí ẹ̀yin bá gbọ́ tí a sọ nípa èyíkéyìí nínú àwọn ìlú u yín tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín láti máa gbé,
When thou shalt hear—in one of thy cities which Yahweh thy God is giving unto thee to dwell there—saying:
13 pé àwọn ènìyàn búburú, ti farahàn láàrín yín, tí ó sì ti mú kí àwọn ènìyàn ìlú wọn ṣìnà lọ, tí wọ́n wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a lọ sin ọlọ́run mìíràn.” (àwọn ọlọ́run tí ẹ kò mọ̀.)
There have gone forth men sons of the Abandoned One, out of thy midst, and have seduced the inhabitants of their city, saying, —Let us go, and serve other gods which ye have not known;
14 Kí ẹ wádìí, ẹ béèrè, kí ẹ sì tọpinpin ọ̀rọ̀ náà dájúṣáká, bí ó bá jẹ́ òtítọ́ ni, tí ó sì hàn dájú pé ìwà ìríra yìí ti ṣẹlẹ̀ láàrín yín.
and thou shalt enquire, and search out, and ask diligently, —and lo! true—certain, is the thing, this abomination, hath been done, in thy midst,
15 Gbogbo àwọn tí ó ń gbé ìlú náà ni kí ẹ fi idà run pátápátá. Ẹ run ún pátápátá, àti ènìyàn àti ẹran ọ̀sìn inú rẹ̀.
then shalt thou smite, the inhabitants of that city with the edge of the sword, devoting it to destruction, and all that is therein and the cattle thereof: with the edge of the sword, —
16 Ẹ kó gbogbo ìkógun ìlú náà, sí àárín gbogbo ènìyàn, kí ẹ sun ìlú náà àti gbogbo ìkógun rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Ó gbọdọ̀ wà ní píparun láéláé, ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ tún un kọ.
and all the spoil thereof, shalt thou gather together into the midst of the broadway thereof, and shalt consume with fire the city and all the spoil thereof, every whit, unto Yahweh thy God, —and it shall be a heap unto times age-abiding, it shall be built no more.
17 A kò gbọdọ̀ rí ọ̀kan nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun wọ̀n-ọn-nì lọ́wọ́ yín, kí Olúwa ba à le yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀, yóò sì ṣàánú fún un yín, yóò sì bá a yín kẹ́dùn, yóò sì mú kí ẹ pọ̀ sí i, bí ó ti fì búra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá yín.
So shall there not cleave to thy hand aught of the devoted thing, —that Yahweh may turn away, from the glow of his anger and grant thee compassion and have compassion upon thee and multiply thee, as he sware unto thy fathers;
18 Nítorí pé ẹ̀yin gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ̀yin sì ń pa òfin rẹ̀ mọ́, tí mo ń fún un yín lónìí yìí, tí ẹ̀yin sì ń ṣe ohun tí ó tọ́ lójú rẹ̀.
so long as thou shalt hearken unto the voice of Yahweh thy God, to keep all his commandments, which I am commanding thee to-day, —to do what is right in the eyes of Yahweh thy God.

< Deuteronomy 13 >