< Deuteronomy 13 >

1 Bí wòlíì tàbí alásọtẹ́lẹ̀ nípa àlá lílá bá farahàn láàrín yín, tí ó sì ń kéde iṣẹ́ àmì tàbí iṣẹ́ ìyanu,
Når en Profet eller en, der har Drømme, opstår i din Midte og forkynd dig et Tegn eller et Under,
2 bí iṣẹ́ àmì tàbí iṣẹ́ ìyanu tí ó sọ̀rọ̀ rẹ̀ bá ṣẹ tí òun sì wí pé, “ẹ wá ẹ jẹ́ kí a tẹ̀lé ọlọ́run mìíràn” (àwọn ọlọ́run tí ẹ kò mọ̀ rí) “kí ẹ sì jẹ́ kí a máa sìn wọ́n,”
og det Tegn og Under, han talte til dig om, indtræffer, og han samtidig opfordrer eder til at holde eder til andre Guder, som I ikke før kendte til, og dyrke dem,
3 ẹ má fetí sí ọ̀rọ̀ wòlíì tàbí àlá náà, Olúwa Ọlọ́run yín ń dán an yín wò ni, láti mọ̀ bóyá ẹ fẹ́ràn rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àyà yín àti gbogbo ọkàn an yín.
så må du ikke høre på den Profets Tale eller på den, der har Drømmen; thi HERREN eders Gud sætter eder på Prøve for at se, om I elsker HERREN eders Gud af hele eders Hjerte og hele eders Sjæl.
4 Olúwa Ọlọ́run yín ni kí ẹ tẹ̀lé, Òun ni kí ẹ bu ọlá fún, ẹ pa òfin rẹ̀ mọ́ kí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, ẹ sìn ín, kí ẹ sì dìímú ṣinṣin.
HERREN eders Gud skal I holde eder til, ham skal I frygte, hans Bud skal I holde, hans Røst skal I adlyde, ham skal I tjene, og ved ham skal I bolde fast.
5 Wòlíì náà tàbí alálàá náà ni kí ẹ pa, nítorí pé wàásù ìṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú yín jáde láti Ejibiti wá, tí ó sì rà yín padà lóko ẹrú. Ó ti gbìyànjú láti fà yín kúrò lójú ọ̀nà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín láti máa rìn. Ẹ gbọdọ̀ yọ ibi náà kúrò láàrín yín.
Men hin Profet eller den, der har Drømmen, skal lide Døden; thi fra HERREN eders Gud, som førte eder ud af Ægypten og udløste dig af Trællehuset, har han prædiket Frafald for at drage dig bort fra den Vej, HERREN din Gud bød dig at vandre på; og du skal udrydde det onde af din Midte.
6 Bí arákùnrin tìrẹ gan an ọmọ ìyá rẹ tàbí ọmọ rẹ ọkùnrin tàbí obìnrin, aya tí o fẹ́ràn jù, tàbí ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ bá tàn ọ́ jẹ níkọ̀kọ̀ wí pé, “Jẹ́ kí a lọ sin ọlọ́run mìíràn” (ọlọ́run tí ìwọ tàbí baba rẹ kò mọ̀,
Dersom din Broder eller Halvbroder, din Søn eller Datter, din Hustru, som du favner, eller din Ven, der er dig kær som dit eget Liv, hemmeligt vil lokke dig til at gå hen og dyrke andre Guder, som hverken du eller dine Fædre før kendte til,
7 ọlọ́run àwọn tí ó wà láyìíká yín, yálà wọ́n jìnnà tàbí wọ́n wà nítòsí, láti òpin ilẹ̀ kan dé òmíràn),
af de Folkeslags Guder, der bor rundt om eder, være sig nær eller fjernt, fra den ene Ende af Jorden til den anden,
8 má ṣe fetí sí i, má sì dá sí i, má ṣe dáàbò bò ó.
så må du ikke føje ham eller høre på ham; og du må ikke have Medlidenhed med ham, vise ham Skånsel eller holde Hånd over ham,
9 Ṣùgbọ́n pípa ni kí o pa á. Ọwọ́ rẹ ni yóò kọ́kọ́ wà lára rẹ̀ láti pa á, lẹ́yìn náà ọwọ́ gbogbo ènìyàn.
men du skal slå ham ihjel; din Hånd skal være den første, der løfter sig imod ham for at slå ham ihjel, siden alle de andres Hånd.
10 Sọ ọ́ ní òkúta pa nítorí pé ó gbìyànjú láti fà ọ́ kúrò lẹ́yìn Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó mú ọ jáde ti Ejibiti wá kúrò ní oko ẹrú.
Du skal stene ham til Døde, fordi han søgte at forføre dig til Frafald fra HERREN din Gud, der førte dig ud af Ægypten, af Trællehuset.
11 Gbogbo Israẹli yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, kò sì sí ẹnikẹ́ni nínú yín tí yóò dán irú ibi bẹ́ẹ̀ wò mọ́.
Og det skal høres i hele Israel, så de gribes af Frygt og ikke mere øver en sådan Udåd i din Midte!
12 Bí ẹ̀yin bá gbọ́ tí a sọ nípa èyíkéyìí nínú àwọn ìlú u yín tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín láti máa gbé,
Kommer det dig for Øre, at der i en af dine Byer, som HERREN din Gud giver dig at bo i,
13 pé àwọn ènìyàn búburú, ti farahàn láàrín yín, tí ó sì ti mú kí àwọn ènìyàn ìlú wọn ṣìnà lọ, tí wọ́n wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a lọ sin ọlọ́run mìíràn.” (àwọn ọlọ́run tí ẹ kò mọ̀.)
er optrådt Niddinger af din egen Midte, som har forført deres Bysbørn til at gå hen og dyrke fremmede Guder, som I ikke før kendte til,
14 Kí ẹ wádìí, ẹ béèrè, kí ẹ sì tọpinpin ọ̀rọ̀ náà dájúṣáká, bí ó bá jẹ́ òtítọ́ ni, tí ó sì hàn dájú pé ìwà ìríra yìí ti ṣẹlẹ̀ láàrín yín.
så skal du omhyggeligt undersøge, efterforske og udgranske Sagen, og hvis det viser sig, at det virkelig forholder sig så, at der er øvet en sådan Vederstyggelighed i din Midte,
15 Gbogbo àwọn tí ó ń gbé ìlú náà ni kí ẹ fi idà run pátápátá. Ẹ run ún pátápátá, àti ènìyàn àti ẹran ọ̀sìn inú rẹ̀.
da skal du hugge indbyggerne i den By ned med Sværdet, idet du lægger Band på den og alt, hvad der er deri; også Kvæget der skal du hugge ned med Sværdet.
16 Ẹ kó gbogbo ìkógun ìlú náà, sí àárín gbogbo ènìyàn, kí ẹ sun ìlú náà àti gbogbo ìkógun rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Ó gbọdọ̀ wà ní píparun láéláé, ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ tún un kọ.
Og alt Byttet, der er taget der, skal du samle sammen midt på Torvet, og så skal du opbrænde Byen og Byttet, der er taget der, som et Heloffer til HERREN din Gud; derefter skal den for evigt ligge i Ruiner og aldrig mer bygges op.
17 A kò gbọdọ̀ rí ọ̀kan nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun wọ̀n-ọn-nì lọ́wọ́ yín, kí Olúwa ba à le yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀, yóò sì ṣàánú fún un yín, yóò sì bá a yín kẹ́dùn, yóò sì mú kí ẹ pọ̀ sí i, bí ó ti fì búra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá yín.
Og intet af det bandlyste må blive hængende ved din Hånd, for at HERREN må standse sin flammende Vrede og vise dig Barmhjertighed og i sin Barmhjertighed gøre dig mangfoldig, som han tilsvor dine Fædre,
18 Nítorí pé ẹ̀yin gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ̀yin sì ń pa òfin rẹ̀ mọ́, tí mo ń fún un yín lónìí yìí, tí ẹ̀yin sì ń ṣe ohun tí ó tọ́ lójú rẹ̀.
fordi du adlyder HERREN din Guds Røst, så du vogter på alle hans Bud, som jeg i Dag pålægger dig, og gør, hvad der er ret i HERREN din Guds Øjne!

< Deuteronomy 13 >