< Deuteronomy 13 >

1 Bí wòlíì tàbí alásọtẹ́lẹ̀ nípa àlá lílá bá farahàn láàrín yín, tí ó sì ń kéde iṣẹ́ àmì tàbí iṣẹ́ ìyanu,
Ако се въздигне всред тебе пророк или съновидец и ти означи знамение или чудо,
2 bí iṣẹ́ àmì tàbí iṣẹ́ ìyanu tí ó sọ̀rọ̀ rẹ̀ bá ṣẹ tí òun sì wí pé, “ẹ wá ẹ jẹ́ kí a tẹ̀lé ọlọ́run mìíràn” (àwọn ọlọ́run tí ẹ kò mọ̀ rí) “kí ẹ sì jẹ́ kí a máa sìn wọ́n,”
и се сбъдне знамението или чудото, поради което той ти говори, казвайки: Да идем след други богове, (които ти не си знаел), и да им служим,
3 ẹ má fetí sí ọ̀rọ̀ wòlíì tàbí àlá náà, Olúwa Ọlọ́run yín ń dán an yín wò ni, láti mọ̀ bóyá ẹ fẹ́ràn rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àyà yín àti gbogbo ọkàn an yín.
да не слушаш думите на оня пророк или на оня съновидец; защото Господ вашият Бог ви изпитва, за да узнае дали любите Господа вашия Бог с цялото си сърце и с цялата си душа.
4 Olúwa Ọlọ́run yín ni kí ẹ tẹ̀lé, Òun ni kí ẹ bu ọlá fún, ẹ pa òfin rẹ̀ mọ́ kí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, ẹ sìn ín, kí ẹ sì dìímú ṣinṣin.
Господа вашия Бог да следвате, от Него да се боите, Неговите заповеди да пазите, Неговия глас да слушате, Нему да слугувате и Нему да сте привързани.
5 Wòlíì náà tàbí alálàá náà ni kí ẹ pa, nítorí pé wàásù ìṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú yín jáde láti Ejibiti wá, tí ó sì rà yín padà lóko ẹrú. Ó ti gbìyànjú láti fà yín kúrò lójú ọ̀nà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín láti máa rìn. Ẹ gbọdọ̀ yọ ibi náà kúrò láàrín yín.
А оня пророк или оня съновидец да се умъртви; защото е проповядвал, отстъпление от Господа вашия Бог, Който ви е извел из Египетската земя и ви е изкупил от дома на робството, за да те отклони от пътя в който Господ твоят Бог ти заповяда да ходиш. Така да отмахнеш злото отсред себе си.
6 Bí arákùnrin tìrẹ gan an ọmọ ìyá rẹ tàbí ọmọ rẹ ọkùnrin tàbí obìnrin, aya tí o fẹ́ràn jù, tàbí ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ bá tàn ọ́ jẹ níkọ̀kọ̀ wí pé, “Jẹ́ kí a lọ sin ọlọ́run mìíràn” (ọlọ́run tí ìwọ tàbí baba rẹ kò mọ̀,
Брат ти, син на майка ти, или синът ти, или дъщеря ти, или жената, която почива на пазухата ти, или приятелят, който ти е като душата ти, ако те изкуси тайно, като рече: Да идем да служим на други богове, - които нито ти си знаел, нито бащите ти,
7 ọlọ́run àwọn tí ó wà láyìíká yín, yálà wọ́n jìnnà tàbí wọ́n wà nítòsí, láti òpin ilẹ̀ kan dé òmíràn),
измежду боговете на племената, които са около вас, близо пре тебе, или далеч от тебе, от единия край на света до другия,
8 má ṣe fetí sí i, má sì dá sí i, má ṣe dáàbò bò ó.
да не се съгласиш с него нито да го слушаш, нито да го пощади окото ти, нито да го пожалиш нито да го укриеш;
9 Ṣùgbọ́n pípa ni kí o pa á. Ọwọ́ rẹ ni yóò kọ́kọ́ wà lára rẹ̀ láti pa á, lẹ́yìn náà ọwọ́ gbogbo ènìyàn.
но непременно да го умъртвиш; твоята ръка да бъде първа на него, за да го убиеш, и после ръката на всичките люде.
10 Sọ ọ́ ní òkúta pa nítorí pé ó gbìyànjú láti fà ọ́ kúrò lẹ́yìn Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó mú ọ jáde ti Ejibiti wá kúrò ní oko ẹrú.
Да го убиеш с камъни, за да умре, защото поиска да те отклони от Господа твоя Бог, Който те изведе из Египетската земя, из дома на робството.
11 Gbogbo Israẹli yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, kò sì sí ẹnikẹ́ni nínú yín tí yóò dán irú ibi bẹ́ẹ̀ wò mọ́.
И целият Израил като чуе ще се убои и няма да върши вече зло всред тебе.
12 Bí ẹ̀yin bá gbọ́ tí a sọ nípa èyíkéyìí nínú àwọn ìlú u yín tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín láti máa gbé,
Ако, между градовете, които Господ твоят Бог ти дава, за да се заселиш в тях, чуеш да се казва за един от тях:
13 pé àwọn ènìyàn búburú, ti farahàn láàrín yín, tí ó sì ti mú kí àwọn ènìyàn ìlú wọn ṣìnà lọ, tí wọ́n wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a lọ sin ọlọ́run mìíràn.” (àwọn ọlọ́run tí ẹ kò mọ̀.)
Някои подлеци, излезли изсред тебе, са отклонили жителите на града си, като са казали: Да идем да служим на други богове, които вие не сте знаели,
14 Kí ẹ wádìí, ẹ béèrè, kí ẹ sì tọpinpin ọ̀rọ̀ náà dájúṣáká, bí ó bá jẹ́ òtítọ́ ni, tí ó sì hàn dájú pé ìwà ìríra yìí ti ṣẹlẹ̀ láàrín yín.
тогава да изследваш, да изпиташ и добре да издириш; и, ето, ако това неща е истинно и е вярно, че такава мерзост е сторена всред тебе,
15 Gbogbo àwọn tí ó ń gbé ìlú náà ni kí ẹ fi idà run pátápátá. Ẹ run ún pátápátá, àti ènìyàn àti ẹran ọ̀sìn inú rẹ̀.
то непременно да поразиш жителите на оня град с острото на ножа, и с острото на ножа да обречеш на изтребление него и всички, които са в него, и добитъка му.
16 Ẹ kó gbogbo ìkógun ìlú náà, sí àárín gbogbo ènìyàn, kí ẹ sun ìlú náà àti gbogbo ìkógun rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Ó gbọdọ̀ wà ní píparun láéláé, ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ tún un kọ.
Тогава, като събереш всичките користи от него всред площада му, съвсем да изгориш с огън града и всичките користи от него за Господа твоя Бог; и той ще бъде могила до века, да се не съгради вече.
17 A kò gbọdọ̀ rí ọ̀kan nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun wọ̀n-ọn-nì lọ́wọ́ yín, kí Olúwa ba à le yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀, yóò sì ṣàánú fún un yín, yóò sì bá a yín kẹ́dùn, yóò sì mú kí ẹ pọ̀ sí i, bí ó ti fì búra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá yín.
Нищо от обреченото на изтребление да се не залепи за ръката ти; за да се върне Господ от яростния Си гняв и да ти покаже милост, да те пожали, и да те умножи, както се е клел на бащите ти,
18 Nítorí pé ẹ̀yin gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ̀yin sì ń pa òfin rẹ̀ mọ́, tí mo ń fún un yín lónìí yìí, tí ẹ̀yin sì ń ṣe ohun tí ó tọ́ lójú rẹ̀.
ако послушаш гласа на Иеова твоя Бог, да пазиш всичките Му заповеди, които днес ти заповядвам, да вършиш това, което е право пред Господа твоя Бог.

< Deuteronomy 13 >