< Deuteronomy 12 >

1 Wọ̀nyí ni àwọn ìlànà àti òfin tí ẹ gbọdọ̀ ṣọ́ra láti máa tẹ̀lé, ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, fi fún un yín láti gbà: ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá fi wà lórí ilẹ̀ náà.
Desse äro de bud och rätter, som I hålla skolen, så att I gören derefter uti landena, som Herren dina fäders Gud dig gifvit hafver till att intaga, så länge I på jordene lefven.
2 Gbogbo ibi gíga àwọn òkè ńlá, àti òkè kéékèèké àti lábẹ́ gbogbo igi tí ń gbilẹ̀ níbi tí àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ ó lé jáde, tí ń sin òrìṣà wọn ní kí ẹ mú kúrò pátápátá.
Förgörer all de rum, der Hedningarna, som I intagen, sina gudar tjent hafva, vare sig på hög berg, på backar, eller under grön trä;
3 Ẹ wó àwọn pẹpẹ wọn, ẹ bi òpó ìsìn wọn ṣubú, kí ẹ sì sun òpó Aṣerah wọn ní iná. Ẹ gé gbogbo ère òrìṣà wọn lulẹ̀, kí ẹ sì pa orúkọ wọn rẹ́ ní gbogbo ààyè wọn.
Och bryter neder deras altare, och slår sönder deras stodar; och deras lundar uppbränner med eld, och deras afgudabeläte kaster bort, och tager bort deras namn utu det rummet.
4 Ẹ kò gbọdọ̀ sin Olúwa Ọlọ́run yín bí i tiwọn.
I skolen icke så göra Herranom edrom Gud;
5 Ṣùgbọ́n ẹ wá ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn láàrín àwọn ẹ̀yà yín, láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀ bí i ibùgbé rẹ̀. Ibẹ̀ ni kí ẹ lọ.
Utan på det rum, som Herren edar Gud utväljer af allom edrom slägtom, att han vill låta sitt Namn der bo, der skolen I fråga, och dit komma;
6 Níbẹ̀ ni kí ẹ mú ẹbọ sísun àti ẹbọ yín wá, ìdámẹ́wàá yín àti ọrẹ àkànṣe, àwọn ẹ̀jẹ́ yín, ọrẹ àtinúwá yín, àti àwọn àkọ́bí gbogbo màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín.
Och göra edart bränneoffer, och edor annor offer, och edor tiond, och edra händers häfoffer, och edor löfte, och edor friviljoga offer, och förstfödningena af edart fä och får.
7 Níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbẹ̀, kí ẹ̀yin àti ìdílé yín jẹun kí ẹ sì yó, nínú gbogbo ìdáwọ́lé e yín, torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín.
Och der skolen I äta för Herranom edrom Gud, och vara glade öfver allt det I och edor hus förvärfven, der Herren din Gud dig uti välsignat hafver.
8 Kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí a tí ṣe níhìn-ín lónìí yìí, tí olúkúlùkù ń ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú ara rẹ̀.
I skolen intet göra af det vi i dag här görom, hvar och en som honom tycker rätt vara;
9 Níwọ́n ìgbà tí ẹ ti dé ibi ìsinmi, àti ibi ogún tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín.
Ty I ären ännu härtilldags icke komne till ro, eller till arfvedelen, som Herren din Gud dig gifva skall;
10 Ṣùgbọ́n ẹ ó la Jordani kọjá, ẹ ó sì máa gbé ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín bí ìní, yóò sì fún un yín ní ìsinmi, kúrò láàrín àwọn ọ̀tá a yín, tí ó yí i yín ká, kí ẹ ba à lè máa gbé láìléwu.
Men I måsten gå öfver Jordan, och bo i de landena, som Herren edar Gud eder till arfs utskiftandes varder; och han skall låta eder få ro för alla edra fiendar omkring eder, och I skolen bo trygge.
11 Níbi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀. Níbẹ̀ ni kí ẹ mú gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún un yín wá: àwọn ọrẹ ẹ yín àti àwọn ẹbọ sísun, ìdámẹ́wàá yín àti ọrẹ àkànṣe, àti gbogbo ohun ìní yín tí ẹ ti yàn, èyí tí ẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa.
När nu Herren din Gud utväljer ett rum, att hans Namn der bo skall, dit skolen I bära allt det jag bjuder eder: edart bränneoffer, edor annor offer, edor tiond, edra händers häfoffer, och all edor fri löfte, som I Herranom lofven;
12 Kí ẹ máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbẹ̀, ẹ̀yin, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, ìránṣẹ́bìnrin àti ìránṣẹ́kùnrin yín, àti àwọn Lefi láti ìlú u yín, tí wọn kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn.
Och skolen vara glade för Herranom edrom Gud, I och edre söner, och edra döttrar, och edre tjenare, och edra tjenarinnor, och Leviterna, som i edra portar äro; förty de hafva ingen lott eller arfvedel med eder.
13 Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe rú ẹbọ sísun yín ní ibikíbi tí ẹ̀yin fẹ́.
Tag dig vara, att du icke offrar ditt bränneoffer i all de rum som du ser;
14 Ibi tí Olúwa yóò yàn láàrín àwọn ẹ̀yà a yín nìkan ni kí ẹ ti máa rú ẹbọ sísun yín, kí ẹ sì máa kíyèsi ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún un yín níbẹ̀.
Utan i det rum, som Herren utväljer, uti någro af dina slägter, der skall du offra ditt bränneoffer, och göra allt det jag bjuder dig.
15 Síbẹ̀síbẹ̀, ẹ lọ pa àwọn ẹran yín ní èyíkéyìí nínú àwọn ìlú u yín, kí ẹ sì jẹ ẹran náà tó bí ẹ ti fẹ́, bí ẹ ti ń ṣe sí àgbọ̀nrín àti èsúró, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún Olúwa Ọlọ́run yín tí ó fi fún un yín, àti ẹni mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ nínú àwọn ẹran náà.
Dock må du slagta, och äta kött i alla dina portar, efter all dine själs begärelse, efter Herrans dins Guds välsignelse, som han dig gifvit hafver; både rene och orene måga det äta, såsom en rå eller en hjort.
16 Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ wọn, ẹ dà á sílẹ̀ bí omi.
Men blodet skall du icke äta; utan gjuta det på jordena såsom vatten.
17 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àkọ́bí àwọn màlúù yín, tàbí ti ewúrẹ́ ẹ yín, ohunkóhun tí ó jẹ́ ẹ̀jẹ́, ọrẹ àtinúwá, tàbí ẹ̀bùn pàtàkì ní ìlú ẹ̀yin tìkára yín.
Men icke må du äta i dina portar utaf tionden af din säd, dino vine, dine oljo, ej heller af den förstfödning af dino fä, af din får, eller af något ditt löfte, som du lofvat hafver, eller af ditt friviljoge offer, eller af dine hands häfoffer;
18 Bí kò ṣe kí ẹ jẹ ẹ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, níbi tí Olúwa Ọlọ́run yín, yóò yàn: ìwọ, àwọn ọmọkùnrin rẹ, àwọn ọmọbìnrin rẹ, àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti àwọn ọmọ Lefi láti ìlú u yín, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ìdáwọ́lé e yín.
Utan för Herranom dinom Gud skall du sådant äta på de rumme, som Herren din Gud utväljer, du och dine söner, dina döttrar, dine tjenare, dina tjenarinnor, och Leviten, som i dina portar är; och skall vara glad för Herranom dinom Gud, öfver allt det du dig företager.
19 Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi, ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá ń gbé ní ilẹ̀ ẹ yín.
Och tag dig vara, att du icke öfvergifver Leviten, så länge du lefver på jordene.
20 Bí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti fẹ́ agbègbè e yín bí ó ti ṣe ìlérí, fún un yín, tí ẹ sì wí pé, àwa yóò jẹ ẹran, nítorí tí ọkàn wa fẹ́ jẹran. Ẹ jẹ ẹran náà bí ẹ tí fẹ́.
När nu Herren din Gud varder förvidgandes dina landsändar, såsom han dig sagt hafver, och du säger: Jag vill äta kött; efter din själ lyster äta kött, så ät kött efter alla dine själs begärelse.
21 Bí ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín bá yàn fún orúkọ rẹ̀ bá jìnnà sí i yín, kí ẹ pa màlúù tàbí ewúrẹ́ tí Olúwa Ọlọ́run yín tí fún un yín, bí mo ti pàṣẹ fún un yín ní ìlú u yín, ẹ lè jẹ ẹ́ bí ẹ ti fẹ́.
Är rummet långt ifrå dig, som Herren din Gud utvalt hafver, att han der vill låta bo sitt Namn, så slagta af ditt fä eller får, som Herren dig gifvit hafver, såsom jag dig budit hafver, och ät det i dinom portom, efter all dine själs begärelse.
22 Ẹ jẹ wọ́n bí ẹ ó ti jẹ èsúró tàbí àgbọ̀nrín, ẹni tí a kà sí mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ ẹ́.
Såsom man äter en rå eller en hjort, må du ätat; både rene och orene måga lika väl ätat.
23 Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé ẹ kò jẹ ẹ̀jẹ̀ wọn, nítorí pé ẹ̀jẹ̀ ni ẹ̀mí, ẹ kò sì gbọdọ̀ jẹ ẹ̀mí pọ̀ mọ́ ẹran.
Allenast vakta, att du icke äter blodet; ty blodet är själen, derföre skall du icke äta själena med köttet;
24 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, ẹ dà á sílẹ̀ bí omi.
Utan skall gjuta det på jordena såsom vatten;
25 Ẹ má ṣe jẹ ẹ́, kí ó bá à lè dára fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín, tí ń bọ̀ lẹ́yìn in yín. Nígbà yí ní ẹ tó ń ṣe ohun tí ó tọ̀nà lójú Olúwa.
Och skall fördenskull icke ätat, att dig må väl gå, och dinom barnom efter dig, deraf att du gjort hafver det som rätt är för Herranom.
26 Ẹ mú àwọn ohun tí ẹ yà sọ́tọ̀ àti àwọn ẹ̀jẹ́ yín, kí ẹ sì lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
Men när du helgar något det ditt är, eller lofvar, så skall du tagat, och bära till det rum, som Herren utvalt hafver;
27 Ẹ fi ẹbọ sísun yín kalẹ̀ lórí i pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run yín, àti ẹran àti ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Ẹ̀jẹ̀ ọrẹ yín ni ki ẹ dà sí pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ ẹran.
Och göra ditt bränneoffer, med kött och blod, på Herrans dins Guds altare; blodet af ditt offer skall du gjuta på Herrans dins Guds altare, och äta köttet.
28 Ẹ kíyèsára láti máa gbọ́rọ̀ sí gbogbo ìlànà tí mò ń fún un yín, kí o bá à dára fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín nígbà gbogbo, nítorí pé nígbà náà ní ẹ tó ń ṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà níwájú Olúwa Ọlọ́run yín.
Se till, och hör alla dessa orden, som jag bjuder dig; på det dig må väl gå, och dinom barnom efter dig till evig tid, deraf att du gjort hafver det rätt är, och Herranom dinom Gud behageligit.
29 Olúwa Ọlọ́run yín yóò gé àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ fẹ́ lé kúrò tí ẹ sì fẹ́ gba ilẹ̀ wọn kúrò níwájú u yín. Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ bá ti lé wọn jáde tí ẹ sì ń gbé ilẹ̀ wọn.
När Herren din Gud utrotar Hedningarna för dig, der du inkommer till att intaga dem, och du dem intagit hafver, och bor i deras land;
30 Lẹ́yìn ìgbà tí a bá ti pa wọ́n run níwájú u yín, ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ba à bọ́ sínú àdánwò nípa bíbéèrè nípa àwọn òrìṣà wọn wí pé, “Báwo ni àwọn orílẹ̀-èdè yìí ṣe ń sin àwọn òrìṣà wọn? Àwa náà yóò ṣe bẹ́ẹ̀”.
Så tag dig vara, att du icke faller i snarona efter dem, sedan de fördrefne äro för dig; och att du intet söker efter deras gudar, och säger: Såsom detta folk hafver tjent deras gudar, så vill jag ock göra.
31 Ẹ kò gbọdọ̀ sin Olúwa Ọlọ́run yín bí àwọn, torí pé, nípa sínsin ọlọ́run wọn, wọ́n ń ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ìríra tí Ọlọ́run kórìíra. Wọ́n ń dáná sun àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn láti fi rú ẹbọ sí ère òrìṣà wọn.
Du skall icke således göra Herranom dinom Gud; förty de hafva gjort sinom gudom allt det Herranom stygges vid, och det han hatar; ty de hafva ock uppbränt i elde sina söner och döttrar till sina gudar.
32 Ẹ rí i pé ẹ̀ ń ṣe gbogbo ohun tí mo ti pàṣẹ fún un yín. Ẹ má ṣe fi kún un, ẹ má sì ṣe yọ kúrò níbẹ̀.
Allt det jag bjuder eder, det skolen I hålla, så att I gören derefter. I skolen intet lägga dertill, och intet taga derifrå.

< Deuteronomy 12 >