< Deuteronomy 12 >

1 Wọ̀nyí ni àwọn ìlànà àti òfin tí ẹ gbọdọ̀ ṣọ́ra láti máa tẹ̀lé, ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, fi fún un yín láti gbà: ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá fi wà lórí ilẹ̀ náà.
Te są ustawy i sądy, których strzedz będziecie, abyście je czynili w ziemi, którą dawa Pan, Bóg ojców twoich, tobie, żebyście ją dziedzicznie trzymali po wszystkie dni, w których żyć będziecie na ziemi.
2 Gbogbo ibi gíga àwọn òkè ńlá, àti òkè kéékèèké àti lábẹ́ gbogbo igi tí ń gbilẹ̀ níbi tí àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ ó lé jáde, tí ń sin òrìṣà wọn ní kí ẹ mú kúrò pátápátá.
Zburzycie do szczętu wszystkie miejsca, na których służyli narodowie, które wy posiądziecie, bogom swoim, na górach wysokich, i na pagórkach, i pod każdem drzewem zielonem.
3 Ẹ wó àwọn pẹpẹ wọn, ẹ bi òpó ìsìn wọn ṣubú, kí ẹ sì sun òpó Aṣerah wọn ní iná. Ẹ gé gbogbo ère òrìṣà wọn lulẹ̀, kí ẹ sì pa orúkọ wọn rẹ́ ní gbogbo ààyè wọn.
I porozwalacie ołtarze ich, i połamiecie słupy ich, gaje też ich poświęcone spalicie ogniem, i bałwany bogów ich porąbiecie, a wygładzicie imię ich z miejsca onego.
4 Ẹ kò gbọdọ̀ sin Olúwa Ọlọ́run yín bí i tiwọn.
Nie uczynicie tak Panu Bogu waszemu;
5 Ṣùgbọ́n ẹ wá ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn láàrín àwọn ẹ̀yà yín, láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀ bí i ibùgbé rẹ̀. Ibẹ̀ ni kí ẹ lọ.
Ale miejsca, które obierze Pan, Bóg wasz, ze wszystkich pokoleń waszych, aby tam wystawił imię swoje, i mieszkał na niem, będziecie szukać i do niego się schadzać.
6 Níbẹ̀ ni kí ẹ mú ẹbọ sísun àti ẹbọ yín wá, ìdámẹ́wàá yín àti ọrẹ àkànṣe, àwọn ẹ̀jẹ́ yín, ọrẹ àtinúwá yín, àti àwọn àkọ́bí gbogbo màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín.
Tamże będziecie przynosić całopalenia wasze, i ofiary wasze, i dziesięciny wasze, i ofiary rąk waszych, i śluby wasze, i dobrowolne dary wasze, także pierworodztwa krów waszych, i owiec waszych.
7 Níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbẹ̀, kí ẹ̀yin àti ìdílé yín jẹun kí ẹ sì yó, nínú gbogbo ìdáwọ́lé e yín, torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín.
I tam będziecie jeść przed Panem, Bogiem waszym; i będziecie się weselić we wszystkiem, do czego ściągniecie ręce wasze, wy i domy wasze, w których ci pobłogosławi Pan, Bóg twój.
8 Kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí a tí ṣe níhìn-ín lónìí yìí, tí olúkúlùkù ń ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú ara rẹ̀.
Nie będziecie czynić według tego wszystkiego, jako my tu dziś czynimy, każdy, co mu się zda dobrego w oczach jego;
9 Níwọ́n ìgbà tí ẹ ti dé ibi ìsinmi, àti ibi ogún tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín.
Albowiemeście jeszcze nie przyszli do odpocznienia, i do dziedzictwa, które Pan, Bóg twój, dawa tobie.
10 Ṣùgbọ́n ẹ ó la Jordani kọjá, ẹ ó sì máa gbé ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín bí ìní, yóò sì fún un yín ní ìsinmi, kúrò láàrín àwọn ọ̀tá a yín, tí ó yí i yín ká, kí ẹ ba à lè máa gbé láìléwu.
Ale gdy przeszedłszy za Jordan, mieszkać będziecie w ziemi, którą Pan, Bóg wasz, dawa wam dziedzicznie osieść, i da wam odpoczynek od wszystkich nieprzyjaciół waszych w około, a mieszkać będziecie bezpiecznie:
11 Níbi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀. Níbẹ̀ ni kí ẹ mú gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún un yín wá: àwọn ọrẹ ẹ yín àti àwọn ẹbọ sísun, ìdámẹ́wàá yín àti ọrẹ àkànṣe, àti gbogbo ohun ìní yín tí ẹ ti yàn, èyí tí ẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa.
Tedy na miejsce, które obierze sobie Pan, Bóg wasz, aby tam mieszkało imię jego, tam znosić będziecie wszystko, co ja wam rozkazuję, całopalenia wasze, i ofiary wasze, dziesięciny wasze, i ofiary rąk waszych, i wszystko, co przedniego jest w ślubiech waszych, które ślubować będziecie Panu;
12 Kí ẹ máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbẹ̀, ẹ̀yin, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, ìránṣẹ́bìnrin àti ìránṣẹ́kùnrin yín, àti àwọn Lefi láti ìlú u yín, tí wọn kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn.
I weselić się będziecie przed Panem, Bogiem waszym, wy, i synowie wasi, i córki wasze, i słudzy wasi, i służebnice wasze, i Lewita, który jest w bramach waszych, ponieważ nie ma działu, ani dziedzictwa z wami.
13 Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe rú ẹbọ sísun yín ní ibikíbi tí ẹ̀yin fẹ́.
Strzeżże się, abyś nie ofiarował całopalenia twego na każdem miejscu, gdzie być się zdało:
14 Ibi tí Olúwa yóò yàn láàrín àwọn ẹ̀yà a yín nìkan ni kí ẹ ti máa rú ẹbọ sísun yín, kí ẹ sì máa kíyèsi ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún un yín níbẹ̀.
Ale tylko na miejscu, które by obrał Pan, w któremkolwiek pokoleniu twojem, tam ofiarować będziesz całopalenia twoje, i tam czynić będziesz wszystko, co ja rozkazuję tobie.
15 Síbẹ̀síbẹ̀, ẹ lọ pa àwọn ẹran yín ní èyíkéyìí nínú àwọn ìlú u yín, kí ẹ sì jẹ ẹran náà tó bí ẹ ti fẹ́, bí ẹ ti ń ṣe sí àgbọ̀nrín àti èsúró, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún Olúwa Ọlọ́run yín tí ó fi fún un yín, àti ẹni mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ nínú àwọn ẹran náà.
A wszakże, jeźli się upodoba duszy twojej, zabijesz sobie, i będziesz jadł mięso według błogosławieństwa Pana, Boga twego, które da tobie we wszystkich bramach twoich; nieczysty i czysty jeść je będzie, jako sarnę albo jelenia.
16 Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ wọn, ẹ dà á sílẹ̀ bí omi.
Krwi tylko jeść nie będziecie, na ziemię wylejecie ją, jako wodę.
17 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àkọ́bí àwọn màlúù yín, tàbí ti ewúrẹ́ ẹ yín, ohunkóhun tí ó jẹ́ ẹ̀jẹ́, ọrẹ àtinúwá, tàbí ẹ̀bùn pàtàkì ní ìlú ẹ̀yin tìkára yín.
Nie będziesz mógł jeść w bramach twoich dziesięciny zboża twego, i wina twego, i oliwy twojej, i pierworodztw krów twoich, i owiec twoich, i wszystkich ślubów twych, które byś ślubował, i dobrowolnych darów twoich, także i ofiary ręki twej.
18 Bí kò ṣe kí ẹ jẹ ẹ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, níbi tí Olúwa Ọlọ́run yín, yóò yàn: ìwọ, àwọn ọmọkùnrin rẹ, àwọn ọmọbìnrin rẹ, àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti àwọn ọmọ Lefi láti ìlú u yín, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ìdáwọ́lé e yín.
Ale przed Panem, Bogiem twoim, jeść je będziesz na miejscu, które obierze Pan, Bóg twój, ty i syn twój, i córka twoja, i sługa twój, i służebnica twoja, i Lewita, który jest w bramach twoich; i będziesz się weselił przed Panem, Bogiem twoim, we wszystkich rzeczach, do których ściągniesz ręce twoje.
19 Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi, ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá ń gbé ní ilẹ̀ ẹ yín.
A strzeż się, abyś snać nie opuszczał Lewity po wszystkie dni twoje w ziemi twojej.
20 Bí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti fẹ́ agbègbè e yín bí ó ti ṣe ìlérí, fún un yín, tí ẹ sì wí pé, àwa yóò jẹ ẹran, nítorí tí ọkàn wa fẹ́ jẹran. Ẹ jẹ ẹran náà bí ẹ tí fẹ́.
Gdy rozszerzy Pan, Bóg twój, granicę twoję, jakoć powiedział, i rzekłbyś: Będę jadł mięso, przeto że pożąda dusza twoja jeść mięsa; według wszystkiej żądności duszy twojej będziesz jadł mięso.
21 Bí ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín bá yàn fún orúkọ rẹ̀ bá jìnnà sí i yín, kí ẹ pa màlúù tàbí ewúrẹ́ tí Olúwa Ọlọ́run yín tí fún un yín, bí mo ti pàṣẹ fún un yín ní ìlú u yín, ẹ lè jẹ ẹ́ bí ẹ ti fẹ́.
A jeźliby dalekie było od ciebie miejsce, które obierze Pan, Bóg twój, aby tam przebywało imię jego, tedy zabijesz z wołów twoich, i z owiec twoich, któreć da Pan, jakom ci rozkazał, i będziesz jadł w bramach twoich według wszystkiej żądności duszy twojej.
22 Ẹ jẹ wọ́n bí ẹ ó ti jẹ èsúró tàbí àgbọ̀nrín, ẹni tí a kà sí mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ ẹ́.
Ale jako jedzą sarnę i jelenia, tak je jeść będziesz; nieczysty i czysty zarówno jeść je będą.
23 Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé ẹ kò jẹ ẹ̀jẹ̀ wọn, nítorí pé ẹ̀jẹ̀ ni ẹ̀mí, ẹ kò sì gbọdọ̀ jẹ ẹ̀mí pọ̀ mọ́ ẹran.
Tylko bądź statecznym, abyś krwi nie jadał, bo krew jest dusza; przetoż nie będziesz jadł duszy z mięsem jej.
24 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, ẹ dà á sílẹ̀ bí omi.
Nie jedzże jej, na ziemię ją wylej jako wodę.
25 Ẹ má ṣe jẹ ẹ́, kí ó bá à lè dára fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín, tí ń bọ̀ lẹ́yìn in yín. Nígbà yí ní ẹ tó ń ṣe ohun tí ó tọ̀nà lójú Olúwa.
Nie jedz jej, aby się dobrze działo tobie, i synom twoim po tobie, gdybyś czynił, co dobrego jest przed oczyma Pańskiemi.
26 Ẹ mú àwọn ohun tí ẹ yà sọ́tọ̀ àti àwọn ẹ̀jẹ́ yín, kí ẹ sì lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
Ale poświęcone rzeczy twoje, które będziesz miał, i śluby twoje, weźmiesz i przyniesiesz na miejsce, które obierze Pan;
27 Ẹ fi ẹbọ sísun yín kalẹ̀ lórí i pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run yín, àti ẹran àti ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Ẹ̀jẹ̀ ọrẹ yín ni ki ẹ dà sí pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ ẹran.
I będziesz ofiarował całopalenia twoje, mięso i krew, na ołtarzu Pana, Boga twego; ale krew inszych ofiar twoich wylana będzie na ołtarzu Pana, Boga twego: mięso jednak jeść będziesz.
28 Ẹ kíyèsára láti máa gbọ́rọ̀ sí gbogbo ìlànà tí mò ń fún un yín, kí o bá à dára fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín nígbà gbogbo, nítorí pé nígbà náà ní ẹ tó ń ṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà níwájú Olúwa Ọlọ́run yín.
Przestrzegajże, a słuchaj tych wszystkich słów, które ja przykazuję tobie, aby dobrze było tobie, i synom twoim po tobie, aż na wieki, gdy czynić będziesz to, co dobrego i prawego jest przed oczyma Pana, Boga twego.
29 Olúwa Ọlọ́run yín yóò gé àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ fẹ́ lé kúrò tí ẹ sì fẹ́ gba ilẹ̀ wọn kúrò níwájú u yín. Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ bá ti lé wọn jáde tí ẹ sì ń gbé ilẹ̀ wọn.
Gdy wytraci Pan, Bóg twój, przed obliczem twojem te narody, do których ty wnijdziesz, abyś je posiadł, i opanował je, i mieszkał w ziemi ich.
30 Lẹ́yìn ìgbà tí a bá ti pa wọ́n run níwájú u yín, ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ba à bọ́ sínú àdánwò nípa bíbéèrè nípa àwọn òrìṣà wọn wí pé, “Báwo ni àwọn orílẹ̀-èdè yìí ṣe ń sin àwọn òrìṣà wọn? Àwa náà yóò ṣe bẹ́ẹ̀”.
Strzeżże się, abyś się nie usidlił, idąc za nimi, gdy wytraceni będą przed twarzą twoją; ani się też pytaj na bogi ich, mówiąc: Jako ci narodowie służyli bogom swoim, tak i ja też uczynię.
31 Ẹ kò gbọdọ̀ sin Olúwa Ọlọ́run yín bí àwọn, torí pé, nípa sínsin ọlọ́run wọn, wọ́n ń ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ìríra tí Ọlọ́run kórìíra. Wọ́n ń dáná sun àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn láti fi rú ẹbọ sí ère òrìṣà wọn.
Nie uczynisz tak Panu, Bogu twemu; bo wszystko, czem się brzydzi Pan, i czego nienawidzi, czynili bogom swoim; także też i syny swoje, i córki swoje palili ogniem bogom swoim.
32 Ẹ rí i pé ẹ̀ ń ṣe gbogbo ohun tí mo ti pàṣẹ fún un yín. Ẹ má ṣe fi kún un, ẹ má sì ṣe yọ kúrò níbẹ̀.
Cokolwiek ja wam rozkazuję, tego strzedz będziecie, abyście czynili; nie przydasz nic do tego, ani też ujmiesz z tego.

< Deuteronomy 12 >