< Deuteronomy 12 >

1 Wọ̀nyí ni àwọn ìlànà àti òfin tí ẹ gbọdọ̀ ṣọ́ra láti máa tẹ̀lé, ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, fi fún un yín láti gbà: ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá fi wà lórí ilẹ̀ náà.
Ici nĩcio irĩra cia watho wa kũrũmĩrĩrwo, na mawatho marĩa mwagĩrĩirwo nĩ kũmenyerera mũmarũmagĩrĩre mũrĩ bũrũri ũrĩa Jehova Ngai wa maithe manyu amũheete mũwĩgwatĩre, rĩrĩa rĩothe mũgũtũũra bũrũri-inĩ ũcio.
2 Gbogbo ibi gíga àwọn òkè ńlá, àti òkè kéékèèké àti lábẹ́ gbogbo igi tí ń gbilẹ̀ níbi tí àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ ó lé jáde, tí ń sin òrìṣà wọn ní kí ẹ mú kúrò pátápátá.
Mũkaananga biũ kũndũ guothe kũu igũrũ wa irĩma iria ndaaya na tũrĩma na rungu rwa mũtĩ o wothe mũruru kũrĩa ndũrĩrĩ icio mũkegwatĩra bũrũri wacio ihooyagĩra ngai ciacio.
3 Ẹ wó àwọn pẹpẹ wọn, ẹ bi òpó ìsìn wọn ṣubú, kí ẹ sì sun òpó Aṣerah wọn ní iná. Ẹ gé gbogbo ère òrìṣà wọn lulẹ̀, kí ẹ sì pa orúkọ wọn rẹ́ ní gbogbo ààyè wọn.
Mũkoinanga igongona ciacio, na mũharaganie mahiga mao marĩa maamũre, na mũcine itugĩ cia Ashera ciacio; mũtemange mĩhianano ya ngai ciao, na mũtharie marĩĩtwa ma cio mehere kũndũ kũu.
4 Ẹ kò gbọdọ̀ sin Olúwa Ọlọ́run yín bí i tiwọn.
Mũtikanahooe Jehova Ngai wanyu ta ũrĩa ndũrĩrĩ icio ihooyaga ngai ciacio.
5 Ṣùgbọ́n ẹ wá ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn láàrín àwọn ẹ̀yà yín, láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀ bí i ibùgbé rẹ̀. Ibẹ̀ ni kí ẹ lọ.
No rĩrĩ, no nginya mũgaacaria handũ harĩa Jehova Ngai wanyu agaathuura thĩinĩ wa mĩhĩrĩga yanyu yothe, nĩguo haamũrĩrwo rĩĩtwa rĩake, harĩ gĩikaro gĩake. Hau nĩho mũrĩthiiaga;
6 Níbẹ̀ ni kí ẹ mú ẹbọ sísun àti ẹbọ yín wá, ìdámẹ́wàá yín àti ọrẹ àkànṣe, àwọn ẹ̀jẹ́ yín, ọrẹ àtinúwá yín, àti àwọn àkọ́bí gbogbo màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín.
na nĩho mũrĩtwaraga maruta manyu ma njino na magongona manyu, na icunjĩ cianyu cia ikũmi na maruta ma mwanya, na kĩrĩa gĩothe mũrĩrutaga kĩa mĩĩhĩtwa yanyu, o na maruta manyu ma kwĩyendera, na marigithathi ma ndũũru cianyu cia ngʼombe na cia ngʼondu.
7 Níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbẹ̀, kí ẹ̀yin àti ìdílé yín jẹun kí ẹ sì yó, nínú gbogbo ìdáwọ́lé e yín, torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín.
Mũrĩ hau mbere ya Jehova Ngai wanyu, inyuĩ na andũ a nyũmba cianyu nĩmũkarĩĩaga na mũgakenera maũndũ mothe marĩa mũrĩĩkaga na moko manyu, nĩ ũndũ Jehova Ngai wanyu nĩamũrathimĩte.
8 Kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí a tí ṣe níhìn-ín lónìí yìí, tí olúkúlùkù ń ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú ara rẹ̀.
Mũtikaneke ta ũrĩa tũreka tũrĩ gũkũ ũmũthĩ, o ũrĩa mũndũ aroona kwagĩrĩire,
9 Níwọ́n ìgbà tí ẹ ti dé ibi ìsinmi, àti ibi ogún tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín.
tondũ mũtirĩ mũraakinya ũhurũko-inĩ kana igai-inĩ rĩrĩa Jehova Ngai wanyu aramũhe.
10 Ṣùgbọ́n ẹ ó la Jordani kọjá, ẹ ó sì máa gbé ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín bí ìní, yóò sì fún un yín ní ìsinmi, kúrò láàrín àwọn ọ̀tá a yín, tí ó yí i yín ká, kí ẹ ba à lè máa gbé láìléwu.
No nĩmũkaringa Rũũĩ rwa Jorodani mũtũũre bũrũri ũrĩa Jehova Ngai wanyu ekũmũhe ũtuĩke igai rĩanyu, na nĩakamũhurũkia harĩ thũ cianyu ciothe iria imũthiũrũrũkĩirie, nĩgeetha mũtũũre mũtarĩ na ũgwati.
11 Níbi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀. Níbẹ̀ ni kí ẹ mú gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún un yín wá: àwọn ọrẹ ẹ yín àti àwọn ẹbọ sísun, ìdámẹ́wàá yín àti ọrẹ àkànṣe, àti gbogbo ohun ìní yín tí ẹ ti yàn, èyí tí ẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa.
Hĩndĩ ĩyo handũ harĩa Jehova Ngai wanyu agaathuura haamũrwo ha gũtũũria Rĩĩtwa rĩake, nĩho mũgaatwaraga indo ciothe iria ngũmwatha mũtwarage: nacio nĩ maruta manyu ma njino, na magongona manyu, na icunjĩ cianyu cia ikũmi na maruta manyu ma mwanya, na indo ciothe njega iria mwĩrĩire Jehova na mwĩhĩtwa.
12 Kí ẹ máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbẹ̀, ẹ̀yin, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, ìránṣẹ́bìnrin àti ìránṣẹ́kùnrin yín, àti àwọn Lefi láti ìlú u yín, tí wọn kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn.
Na mũrĩ hau, mũkenage mũrĩ mbere ya Jehova Ngai wanyu, inyuĩ ene, na ariũ anyu, na airĩtu anyu, na ndungata cianyu cia arũme na cia andũ-a-nja, na Alawii a kuuma matũũra-inĩ manyu arĩa matarĩ na mĩgũnda kana igai rĩao ene.
13 Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe rú ẹbọ sísun yín ní ibikíbi tí ẹ̀yin fẹ́.
Mwĩmenyererei mũtikanarutĩre magongona manyu ma njino handũ harĩa hothe mũngĩenda.
14 Ibi tí Olúwa yóò yàn láàrín àwọn ẹ̀yà a yín nìkan ni kí ẹ ti máa rú ẹbọ sísun yín, kí ẹ sì máa kíyèsi ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún un yín níbẹ̀.
Marutagĩrei o handũ harĩa Jehova agaathuura mũhĩrĩga-inĩ ũmwe wa mĩhĩrĩga yanyu, nĩho mũgeekagĩra maũndũ marĩa mothe ndĩmwathĩte.
15 Síbẹ̀síbẹ̀, ẹ lọ pa àwọn ẹran yín ní èyíkéyìí nínú àwọn ìlú u yín, kí ẹ sì jẹ ẹran náà tó bí ẹ ti fẹ́, bí ẹ ti ń ṣe sí àgbọ̀nrín àti èsúró, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún Olúwa Ọlọ́run yín tí ó fi fún un yín, àti ẹni mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ nínú àwọn ẹran náà.
No rĩrĩ, no mũthĩnjĩre nyamũ cianyu itũũra-inĩ rĩanyu o rĩothe na mũrĩe nyama nyingĩ o ũrĩa mũngĩenda, o taarĩ nyama cia thwariga kana cia thiiya, mũrĩe kũringana na kĩrathimo kĩrĩa Jehova Ngai wanyu amũheete. Andũ othe, arĩa marĩ na thaahu o na arĩa matarĩ, no marĩe nyama icio.
16 Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ wọn, ẹ dà á sílẹ̀ bí omi.
No mũtikanarĩe thakame; mĩitagei thĩ o taarĩ maaĩ.
17 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àkọ́bí àwọn màlúù yín, tàbí ti ewúrẹ́ ẹ yín, ohunkóhun tí ó jẹ́ ẹ̀jẹ́, ọrẹ àtinúwá, tàbí ẹ̀bùn pàtàkì ní ìlú ẹ̀yin tìkára yín.
Mũtikanarĩĩre matũũra-inĩ manyu gĩcunjĩ gĩa ikũmi kĩa ngano yanyu, na ndibei ya mũhihano, na maguta, kana marigithathi ma ndũũru cianyu cia ngʼombe na cia ngʼondu, kana kĩndũ o gĩothe mwĩhĩtĩte kũrutaga, kana maruta manyu ma kwĩyendera, o na kana maruta ma mwanya.
18 Bí kò ṣe kí ẹ jẹ ẹ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, níbi tí Olúwa Ọlọ́run yín, yóò yàn: ìwọ, àwọn ọmọkùnrin rẹ, àwọn ọmọbìnrin rẹ, àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti àwọn ọmọ Lefi láti ìlú u yín, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ìdáwọ́lé e yín.
Handũ ha gwĩka ũguo-rĩ, mũrĩrĩĩagĩra indo icio mbere ya Jehova Ngai wanyu mũrĩ handũ harĩa Jehova Ngai wanyu agaathuura, inyuĩ ene, na ariũ anyu na airĩtu anyu, na ndungata cianyu cia arũme na cia andũ-a-nja, na Alawii a kuuma matũũra-inĩ manyu, na nĩmũrĩkenagĩra maũndũ mothe marĩa mũrĩĩkaga na moko manyu mũrĩ mbere ya Jehova Ngai wanyu.
19 Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi, ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá ń gbé ní ilẹ̀ ẹ yín.
Menyererai mũtikanarekererie Alawii hĩndĩ ĩrĩa yothe mũgũtũũra bũrũri ũcio wanyu.
20 Bí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti fẹ́ agbègbè e yín bí ó ti ṣe ìlérí, fún un yín, tí ẹ sì wí pé, àwa yóò jẹ ẹran, nítorí tí ọkàn wa fẹ́ jẹran. Ẹ jẹ ẹran náà bí ẹ tí fẹ́.
Rĩrĩa Jehova Ngai waku agaakwaramĩria bũrũri waku o ta ũrĩa aakwĩrĩire, nawe wende kũrĩa nyama na uuge atĩrĩ, “Nĩngwenda nyama,” hĩndĩ ĩyo no ũrĩe nyama nyingĩ o ũrĩa ũngĩenda.
21 Bí ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín bá yàn fún orúkọ rẹ̀ bá jìnnà sí i yín, kí ẹ pa màlúù tàbí ewúrẹ́ tí Olúwa Ọlọ́run yín tí fún un yín, bí mo ti pàṣẹ fún un yín ní ìlú u yín, ẹ lè jẹ ẹ́ bí ẹ ti fẹ́.
Kũngĩkorwo handũ harĩa Jehova Ngai waku athuurĩte haamũrĩrwo Rĩĩtwa rĩake nĩ hakũraihĩrĩirie-rĩ, no ũthĩnje nyamũ kuuma ndũũru-inĩ ciaku cia ngʼombe na cia ngʼondu iria Jehova akũheete, ta ũrĩa ngwathĩte, na ũrĩ o kũu matũũra-inĩ maku, no ũrĩe nyama nyingĩ o ũrĩa ũngĩenda.
22 Ẹ jẹ wọ́n bí ẹ ó ti jẹ èsúró tàbí àgbọ̀nrín, ẹni tí a kà sí mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ ẹ́.
Rĩa nyama icio o ta ũrĩa ũngĩrĩa nyama cia thwariga kana cia thiiya. Andũ arĩa marĩ na thaahu na arĩa matarĩ no marĩe nyama icio.
23 Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé ẹ kò jẹ ẹ̀jẹ̀ wọn, nítorí pé ẹ̀jẹ̀ ni ẹ̀mí, ẹ kò sì gbọdọ̀ jẹ ẹ̀mí pọ̀ mọ́ ẹran.
No ũmenyerere ndũkanarĩe thakame, tondũ thakame nĩyo muoyo, ndũkanarĩanĩrie muoyo ũcio na nyama.
24 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, ẹ dà á sílẹ̀ bí omi.
Ndũkanarĩe thakame; mĩite thĩ o ta maaĩ.
25 Ẹ má ṣe jẹ ẹ́, kí ó bá à lè dára fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín, tí ń bọ̀ lẹ́yìn in yín. Nígbà yí ní ẹ tó ń ṣe ohun tí ó tọ̀nà lójú Olúwa.
Ndũkanamĩrĩe, nĩguo maũndũ maku magĩrĩre, o na ma ciana ciaku iria igooka thuutha waku, tondũ ũrĩkoragwo ũgĩĩka maũndũ marĩa magĩrĩire maitho-inĩ ma Jehova.
26 Ẹ mú àwọn ohun tí ẹ yà sọ́tọ̀ àti àwọn ẹ̀jẹ́ yín, kí ẹ sì lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
No rĩrĩ, nĩũkoya indo ciaku iria nyamũre na kĩndũ kĩrĩa gĩothe wĩhĩtĩte atĩ nĩũkaruta, ũthiĩ handũ harĩa Jehova agaathuura.
27 Ẹ fi ẹbọ sísun yín kalẹ̀ lórí i pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run yín, àti ẹran àti ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Ẹ̀jẹ̀ ọrẹ yín ni ki ẹ dà sí pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ ẹran.
Rutĩra magongona maku ma njino, ma nyama na ma thakame kĩgongona-inĩ kĩa Jehova Ngai waku. Thakame ĩyo ya magongona macio maku no nginya ĩitwo hau mwena-inĩ wa kĩgongona kĩa Jehova Ngai waku, no nyama no ũcirĩe.
28 Ẹ kíyèsára láti máa gbọ́rọ̀ sí gbogbo ìlànà tí mò ń fún un yín, kí o bá à dára fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín nígbà gbogbo, nítorí pé nígbà náà ní ẹ tó ń ṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà níwájú Olúwa Ọlọ́run yín.
Menyerera wathĩkĩre mawatho maya mothe ndĩragwatha, nĩgeetha maũndũ maku na ma ciana ciaku iria igooka thuutha waku maagagĩrĩre hĩndĩ ciothe, tondũ ũrĩkoragwo ũgĩĩka wega na ũrĩa kwagĩrĩire maitho-inĩ ma Jehova Ngai waku.
29 Olúwa Ọlọ́run yín yóò gé àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ fẹ́ lé kúrò tí ẹ sì fẹ́ gba ilẹ̀ wọn kúrò níwájú u yín. Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ bá ti lé wọn jáde tí ẹ sì ń gbé ilẹ̀ wọn.
Jehova Ngai waku nĩakeheria mbere yaku ndũrĩrĩ iria ũkiriĩ kũhithũkĩra ũcitunye bũrũri. No rĩrĩa ũgaacingata na ũtũũre bũrũri wacio,
30 Lẹ́yìn ìgbà tí a bá ti pa wọ́n run níwájú u yín, ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ba à bọ́ sínú àdánwò nípa bíbéèrè nípa àwọn òrìṣà wọn wí pé, “Báwo ni àwọn orílẹ̀-èdè yìí ṣe ń sin àwọn òrìṣà wọn? Àwa náà yóò ṣe bẹ́ẹ̀”.
na ciarĩkia kũniinwo ciehere mbere yaku, wĩmenyerere ndũkanategwo na ũndũ wa gũtuĩria ũhoro wa ngai ciacio ũkĩũria atĩrĩ, “Ĩ ndũrĩrĩ ici itungatagĩra ngai ciacio atĩa? Tũgwĩka o ta ũrĩa ciĩkaga.”
31 Ẹ kò gbọdọ̀ sin Olúwa Ọlọ́run yín bí àwọn, torí pé, nípa sínsin ọlọ́run wọn, wọ́n ń ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ìríra tí Ọlọ́run kórìíra. Wọ́n ń dáná sun àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn láti fi rú ẹbọ sí ère òrìṣà wọn.
Ndũkanahooe Jehova Ngai waku na njĩra icio ciacio, nĩ ũndũ ikĩhooya ngai icio ciacio, nĩciĩkaga maũndũ mothe marĩa marĩ magigi marĩa Jehova athũire. O na nĩicinaga ariũ ao na airĩtu ao na mwaki marĩ magongona ma ngai ciacio.
32 Ẹ rí i pé ẹ̀ ń ṣe gbogbo ohun tí mo ti pàṣẹ fún un yín. Ẹ má ṣe fi kún un, ẹ má sì ṣe yọ kúrò níbẹ̀.
Tigĩrĩra atĩ nĩ weka maũndũ mothe marĩa ngwathĩte; ndũkanongerere ũndũ kana ũrutarute.

< Deuteronomy 12 >