< Deuteronomy 12 >

1 Wọ̀nyí ni àwọn ìlànà àti òfin tí ẹ gbọdọ̀ ṣọ́ra láti máa tẹ̀lé, ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, fi fún un yín láti gbà: ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá fi wà lórí ilẹ̀ náà.
These are the statutes and the regulations which ye must observe to do, in the land which Yahweh the God of thy fathers hath given unto thee, to possess it, —all the days that ye are living upon the soil:
2 Gbogbo ibi gíga àwọn òkè ńlá, àti òkè kéékèèké àti lábẹ́ gbogbo igi tí ń gbilẹ̀ níbi tí àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ ó lé jáde, tí ń sin òrìṣà wọn ní kí ẹ mú kúrò pátápátá.
Ye must utterly destroy, all the places where the nations whom ye are dispossessing have served their gods, —Upon the high mountains And upon the hills, And under every green tree;
3 Ẹ wó àwọn pẹpẹ wọn, ẹ bi òpó ìsìn wọn ṣubú, kí ẹ sì sun òpó Aṣerah wọn ní iná. Ẹ gé gbogbo ère òrìṣà wọn lulẹ̀, kí ẹ sì pa orúkọ wọn rẹ́ ní gbogbo ààyè wọn.
And ye must tear down their altars And break in pieces their pillars, And, their sacred stems, must ye consume with fire, And the carved images of their gods, must ye fell to the ground, —And destroy their name out of that place.
4 Ẹ kò gbọdọ̀ sin Olúwa Ọlọ́run yín bí i tiwọn.
Ye must not do thus unto Yahweh your God;
5 Ṣùgbọ́n ẹ wá ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn láàrín àwọn ẹ̀yà yín, láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀ bí i ibùgbé rẹ̀. Ibẹ̀ ni kí ẹ lọ.
but, unto the place which Yahweh your God shall choose out of all your tribes, to put his name there, —as his habitation, shall ye ask your way, and come in thither;
6 Níbẹ̀ ni kí ẹ mú ẹbọ sísun àti ẹbọ yín wá, ìdámẹ́wàá yín àti ọrẹ àkànṣe, àwọn ẹ̀jẹ́ yín, ọrẹ àtinúwá yín, àti àwọn àkọ́bí gbogbo màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín.
and bring in thither your ascending-offerings and your sacrifices, and your tithes, and the heave-offering of your hand, —and your vow-offerings and your freewill-offerings, and the firstlings of your herd and of your flock;
7 Níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbẹ̀, kí ẹ̀yin àti ìdílé yín jẹun kí ẹ sì yó, nínú gbogbo ìdáwọ́lé e yín, torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín.
and shall eat there before Yahweh your God, and rejoice in all whereunto ye are putting your hand, Ye, and your households, —wherewith Yahweh thy God hath blessed thee.
8 Kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí a tí ṣe níhìn-ín lónìí yìí, tí olúkúlùkù ń ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú ara rẹ̀.
Ye must not do according to all that we are doing here to-day, —every man, whatsoever is right in his own eyes.
9 Níwọ́n ìgbà tí ẹ ti dé ibi ìsinmi, àti ibi ogún tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín.
Because ye have not entered as yet, —into the resting-place and into the inheritance which Yahweh thy God is giving unto thee.
10 Ṣùgbọ́n ẹ ó la Jordani kọjá, ẹ ó sì máa gbé ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín bí ìní, yóò sì fún un yín ní ìsinmi, kúrò láàrín àwọn ọ̀tá a yín, tí ó yí i yín ká, kí ẹ ba à lè máa gbé láìléwu.
But, when ye shall pass over the Jordan, and settle down in the land which, Yahweh your God, is causing you to inherit, —and he shall give you rest from all your enemies round about, and ye shall dwell securely,
11 Níbi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀. Níbẹ̀ ni kí ẹ mú gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún un yín wá: àwọn ọrẹ ẹ yín àti àwọn ẹbọ sísun, ìdámẹ́wàá yín àti ọrẹ àkànṣe, àti gbogbo ohun ìní yín tí ẹ ti yàn, èyí tí ẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa.
then shall it be, that unto the place which Yahweh your God shall choose to make a habitation for his name there, thither, shall ye bring in all that I am commanding you, —your ascending-offerings and your sacrifices your tithes and the heave-offering of your hand, and all your chosen vow-offerings which ye shall vow unto Yahweh.
12 Kí ẹ máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbẹ̀, ẹ̀yin, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, ìránṣẹ́bìnrin àti ìránṣẹ́kùnrin yín, àti àwọn Lefi láti ìlú u yín, tí wọn kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn.
So shall ye rejoice before Yahweh your God, Ye, and your sons, and your daughters, and your servants and your handmaids, —and the Levite that is within your gates, forasmuch as he hath neither portion nor inheritance with you.
13 Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe rú ẹbọ sísun yín ní ibikíbi tí ẹ̀yin fẹ́.
Take heed to thyself, lest thou cause thine ascending-sacrifice to go up in just any place which thou shalt see;
14 Ibi tí Olúwa yóò yàn láàrín àwọn ẹ̀yà a yín nìkan ni kí ẹ ti máa rú ẹbọ sísun yín, kí ẹ sì máa kíyèsi ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún un yín níbẹ̀.
but, in the place which Yahweh shall choose in one of thy tribes, there, shalt thou cause thine ascending-sacrifice to go up, and, there, shalt thou do all that I am commanding thee.
15 Síbẹ̀síbẹ̀, ẹ lọ pa àwọn ẹran yín ní èyíkéyìí nínú àwọn ìlú u yín, kí ẹ sì jẹ ẹran náà tó bí ẹ ti fẹ́, bí ẹ ti ń ṣe sí àgbọ̀nrín àti èsúró, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún Olúwa Ọlọ́run yín tí ó fi fún un yín, àti ẹni mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ nínú àwọn ẹran náà.
Howbeit of anything thy soul desireth, mayest thou sacrifice and so eat flesh—according to the blessing of Yahweh thy God which he hath bestowed upon thee, in all thy gates, the unclean and the clean may eat thereof, —as the gazelle and as the hart,
16 Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ wọn, ẹ dà á sílẹ̀ bí omi.
Howbeit, the blood, shall ye not eat, —upon the earth, shalt thou pour it out, like water.
17 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àkọ́bí àwọn màlúù yín, tàbí ti ewúrẹ́ ẹ yín, ohunkóhun tí ó jẹ́ ẹ̀jẹ́, ọrẹ àtinúwá, tàbí ẹ̀bùn pàtàkì ní ìlú ẹ̀yin tìkára yín.
Thou mayest not eat within thy gates, the tithe of thy corn or of thy new wine or of thine oil, or the firstlings of thy herd, or of thy flock, —nor any of thy vow-offerings which thou shalt vow, nor thy freewill, offerings, nor the heave-offering of thy hand;
18 Bí kò ṣe kí ẹ jẹ ẹ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, níbi tí Olúwa Ọlọ́run yín, yóò yàn: ìwọ, àwọn ọmọkùnrin rẹ, àwọn ọmọbìnrin rẹ, àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti àwọn ọmọ Lefi láti ìlú u yín, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ìdáwọ́lé e yín.
but before Yahweh thy God, shalt thou eat it in the place which Yahweh thy God shall choose, thou and thy son and thy daughter, and thy servant and thy handmaid, and the Levite who is within thy gates, —so shalt thou rejoice before Yahweh thy God, in all whereunto thou puttest thy hand.
19 Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi, ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá ń gbé ní ilẹ̀ ẹ yín.
Take heed to thyself, lest thou forsake the Levite, —all thy days upon thy soil.
20 Bí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti fẹ́ agbègbè e yín bí ó ti ṣe ìlérí, fún un yín, tí ẹ sì wí pé, àwa yóò jẹ ẹran, nítorí tí ọkàn wa fẹ́ jẹran. Ẹ jẹ ẹran náà bí ẹ tí fẹ́.
When Yahweh thy God shall enlarge thy boundary—as he hath spoken unto thee—and thou shalt say. I would eat flesh because thy soul desireth to eat flesh, of whatsoever thy soul desireth, mayest thou eat flesh.
21 Bí ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín bá yàn fún orúkọ rẹ̀ bá jìnnà sí i yín, kí ẹ pa màlúù tàbí ewúrẹ́ tí Olúwa Ọlọ́run yín tí fún un yín, bí mo ti pàṣẹ fún un yín ní ìlú u yín, ẹ lè jẹ ẹ́ bí ẹ ti fẹ́.
When the place which Yahweh thy God shall choose to put his name there, shall be, too far for thee, then shalt thou sacrifice of thy herd or of thy flock which Yahweh hath given unto thee, as I have commanded thee, —and shalt eat, within thine own gates, of whatsoever thy soul desireth.
22 Ẹ jẹ wọ́n bí ẹ ó ti jẹ èsúró tàbí àgbọ̀nrín, ẹni tí a kà sí mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ ẹ́.
Even as the gazelle and the hart is eaten, so, shalt thou eat it, —the unclean and the clean, alike shall eat it.
23 Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé ẹ kò jẹ ẹ̀jẹ̀ wọn, nítorí pé ẹ̀jẹ̀ ni ẹ̀mí, ẹ kò sì gbọdọ̀ jẹ ẹ̀mí pọ̀ mọ́ ẹran.
Howbeit firmly refrain from eating the blood; for the blood, is the life, —therefore must thou not eat the life with the flesh.
24 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, ẹ dà á sílẹ̀ bí omi.
Thou shalt not eat it, —upon the earth, shalt thou pour it out, like water.
25 Ẹ má ṣe jẹ ẹ́, kí ó bá à lè dára fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín, tí ń bọ̀ lẹ́yìn in yín. Nígbà yí ní ẹ tó ń ṣe ohun tí ó tọ̀nà lójú Olúwa.
Thou shalt not eat it, —that it may be well with thee and with thy children after thee when thou shalt do that which is right in the eyes of Yahweh.
26 Ẹ mú àwọn ohun tí ẹ yà sọ́tọ̀ àti àwọn ẹ̀jẹ́ yín, kí ẹ sì lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
Howbeit, thy holy things which thou shalt have and thy vow-offerings, shalt thou take and come in, unto the place which Yahweh shall choose;
27 Ẹ fi ẹbọ sísun yín kalẹ̀ lórí i pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run yín, àti ẹran àti ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Ẹ̀jẹ̀ ọrẹ yín ni ki ẹ dà sí pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ ẹran.
and shalt offer thine ascending-sacrifices, the flesh and the blood, upon the altar of Yahweh thy God, —and the blood of thine [other] sacrifices, shall be poured out upon the altar of Yahweh thy God, and then the flesh, shalt thou eat.
28 Ẹ kíyèsára láti máa gbọ́rọ̀ sí gbogbo ìlànà tí mò ń fún un yín, kí o bá à dára fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín nígbà gbogbo, nítorí pé nígbà náà ní ẹ tó ń ṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà níwájú Olúwa Ọlọ́run yín.
Observe and hear all these things which I am commanding thee, —that it may be well with thee and with thy children after thee, —unto times age-abiding, so long as thou shalt do that which is pleasing and right in the eyes of Yahweh thy God.
29 Olúwa Ọlọ́run yín yóò gé àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ fẹ́ lé kúrò tí ẹ sì fẹ́ gba ilẹ̀ wọn kúrò níwájú u yín. Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ bá ti lé wọn jáde tí ẹ sì ń gbé ilẹ̀ wọn.
When Yahweh thy God shall cut off from before thee, the nations Whom thou art going in to dispossess, —and thou do dispossess them, and dwell in their land,
30 Lẹ́yìn ìgbà tí a bá ti pa wọ́n run níwájú u yín, ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ba à bọ́ sínú àdánwò nípa bíbéèrè nípa àwọn òrìṣà wọn wí pé, “Báwo ni àwọn orílẹ̀-èdè yìí ṣe ń sin àwọn òrìṣà wọn? Àwa náà yóò ṣe bẹ́ẹ̀”.
take heed to thyself lest thou be thrust after them, after they have been destroyed from before thee, —and lest thou enquire after their gods, saying—In what manner, did these nations serve their gods, that, I too, may do likewise?
31 Ẹ kò gbọdọ̀ sin Olúwa Ọlọ́run yín bí àwọn, torí pé, nípa sínsin ọlọ́run wọn, wọ́n ń ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ìríra tí Ọlọ́run kórìíra. Wọ́n ń dáná sun àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn láti fi rú ẹbọ sí ère òrìṣà wọn.
Thou shalt not do likewise unto Yahweh thy God, —for everything that is an abomination unto Yahweh which he doth hate, have they done unto their gods, for even their sons and their daughters, do they consume with fire unto their gods.
32 Ẹ rí i pé ẹ̀ ń ṣe gbogbo ohun tí mo ti pàṣẹ fún un yín. Ẹ má ṣe fi kún un, ẹ má sì ṣe yọ kúrò níbẹ̀.
Whatsoever be the thing which I am commanding you, the same, shall ye observe to do, —thou shalt neither add thereunto, nor take away therefrom.

< Deuteronomy 12 >