< Deuteronomy 11 >

1 Ẹ fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, kí ẹ sì pa ìfẹ́ rẹ̀, ìlànà rẹ̀, òfin rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ mọ́ ní ìgbà gbogbo.
Endaga Jehova Ngai waku na ũmenyagĩrĩre maũndũ marĩa endaga, arĩ kĩrĩra kĩa watho wake wa kũrũmĩrĩrwo, na mawatho make, na maathani make hĩndĩ ciothe.
2 Ẹ rántí lónìí pé, kì í ṣe àwọn ọmọ yín, ni ó rí ìbáwí Olúwa Ọlọ́run yín; títóbi rẹ̀, ọwọ́ agbára rẹ̀, nína ọwọ́ rẹ̀;
Ririkana ũmũthĩ atĩ ciana ciaku itionire na itiamenyire kũherithania kwa Jehova Ngai waku: o na itionire ũnene wake na guoko gwake kũrĩa kũrĩ hinya, o na guoko gwake gũtambũrũkĩtio;
3 iṣẹ́ àmì rẹ̀ àti ohun tí ó ṣe ní àárín àwọn ará Ejibiti, sí Farao ọba Ejibiti àti gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ̀.
o na ciama iria aaringire, na maũndũ marĩa eekire kũu bũrũri wa Misiri, na kũrĩ Firaũni mũthamaki wa bũrũri wa Misiri, na bũrũri wake wothe;
4 Ohun tí ó ṣe sí àwọn jagunjagun Ejibiti, sí kẹ̀kẹ́ ogun àti ẹlẹ́ṣin rẹ̀: bí ó ṣe rì wọ́n sínú Òkun Pupa, bí wọ́n ṣe ń lé e yín tí Olúwa fi pa wọ́n run pátápátá títí di òní olónìí yìí.
na ũrĩa eekire mbũtũ cia ita cia bũrũri wa Misiri, na mbarathi ciao, na ngaari ciao cia ita, na ũrĩa aamahubĩkanirie na maaĩ ma Iria Itune hĩndĩ ĩyo maathingatanĩte nao, na ũrĩa Jehova aamarehithĩirie mũthiro wa gũtũũra.
5 Kì í ṣe àwọn ọmọ yín ni ó rí ohun tí ó ṣe fún un yín ní aginjù, títí ẹ fi dé ìhín yìí,
Ciana cianyu ticio cionire ũrĩa aamwĩkĩire mũrĩ kũu werũ-inĩ, nginya rĩrĩa mwakinyire gũkũ;
6 ohun tí ó ṣe sí Datani àti Abiramu, àwọn ọmọ Eliabu, ẹ̀yà Reubeni, bí ilẹ̀ ti lanu ní ojú gbogbo ará Israẹli tí ó sì gbé wọn mì pẹ̀lú gbogbo ìdílé wọn, gbogbo àgọ́ ọ wọn àti gbogbo ohun alààyè tí ó jẹ́ tiwọn.
o na ũrĩa eekire Dathani na Abiramu, ariũ a Eliabu ũrĩa Mũrubeni, rĩrĩa thĩ yamaathamĩirie kanua kayo marĩ gatagatĩ ka andũ a Isiraeli othe, thĩ ĩkĩmameria hamwe na nyũmba ciao, na hema ciao, na kĩrĩa gĩothe maarĩ nakĩo.
7 Ṣùgbọ́n ojú u yín gan an ni ó rí gbogbo nǹkan ńlá wọ̀nyí tí Olúwa ti ṣe.
No nĩ maitho manyu meeyoneire maũndũ macio mothe manene marĩa Jehova ekĩte.
8 Nítorí náà, ẹ kíyèsi gbogbo àṣẹ tí mo ń fún yín lónìí, kí ẹ ba à lè lágbára àti lọ, kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí ẹ ó la Jordani kọjá lọ.
Nĩ ũndũ ũcio menyagĩrĩrai maathani mothe marĩa ndĩramũhe ũmũthĩ, nĩgeetha mũgĩe na hinya wa gũtoonya na wa gũtunyana bũrũri ũrĩa mũraringa Rũũĩ rwa Jorodani mũkawĩgwatĩre,
9 Kí ẹ ba à lè pẹ́ ní orí ilẹ̀ tí Olúwa ti búra fún àwọn baba ńlá a yín, láti fún àwọn àti àwọn ọmọ wọn: ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.
na nĩgeetha mũgaatũũra matukũ maingĩ bũrũri ũcio Jehova eehĩtire na mwĩhĩtwa atĩ nĩakahe maithe manyu ma tene na njiaro ciao, bũrũri ũrĩ bũthi wa iria na ũũkĩ.
10 Ilẹ̀ tí ẹ̀ ń wọ̀ lọ láti gbà kò rí bí ilẹ̀ Ejibiti, níbi tí ẹ ti wá, níbi tó jẹ́ wí pé ẹsẹ̀ yín ni ẹ fi ń rìn lọ bomirin irúgbìn tí ẹ gbìn bí oko ẹ̀fọ́.
Bũrũri ũrĩa mũrathiĩ mũkaũtunyane ndũhaana ta bũrũri wa Misiri, kũrĩa muumĩte, kũrĩa mwahaandaga mbegũ cianyu na mũgaciunithagĩria maaĩ na magũrũ taarĩ mũgũnda wa mboga.
11 Ṣùgbọ́n ilẹ̀ tí ẹ ó la Jordani kọjá láti gbà, jẹ́ ilẹ̀ olókè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀ tí òjò ń rọ̀ sí latọ̀run.
No rĩrĩ, bũrũri ũrĩa mũraringa Rũũĩ rwa Jorodani mũkegwatĩre nĩ bũrũri ũrĩ irĩma na cianda iria inyuuaga maaĩ ma mbura kuuma igũrũ.
12 Ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín ń mójútó ni, ojú Olúwa Ọlọ́run yín sì ń fi ìgbà gbogbo wà lórí rẹ̀, láti ìbẹ̀rẹ̀ ọdún dé òpin ọdún.
Nĩ bũrũri ũmenyagĩrĩrwo nĩ Jehova Ngai wanyu; maitho ma Jehova Ngai wanyu maikaraga maũcũthĩrĩirie kuuma kĩambĩrĩria kĩa mwaka nginya mũthia waguo.
13 Nítorí náà, bí ẹ bá gbọ́rọ̀ sí àṣẹ tí mo fún un yín lónìí tọkàntọkàn: tí ẹ fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì sìn ín, pẹ̀lú gbogbo àyà yín àti gbogbo ọkàn yín:
Nĩ ũndũ ũcio mũngĩathĩkĩra maathani marĩa ndĩramũhe ũmũthĩ mũrĩ na wĩhokeku, na mwendage Jehova Ngai wanyu, na mũmũtungatagĩre na ngoro cianyu ciothe na muoyo wanyu wothe-rĩ,
14 nígbà náà, èmi yóò rọ òjò sórí ilẹ̀ ẹ yín lákòókò rẹ̀, àti òjò àkọ́rọ̀ àti ti àrọ̀kẹ́yìn, kí ẹ ba à lè kórè oúnjẹ yín wọlé àní wáìnì tuntun àti òróró.
hĩndĩ ĩyo nĩngoiria mbura bũrũri wanyu kĩmera kĩayo gĩakinya, mbura ya mũringo na ya gũkũria irio, nĩgeetha mũgaacookagĩrĩria ngano yanyu, na ndibei ya mũhihano na maguta.
15 Èmi yóò mú kí koríko hù lórí ilẹ̀ yín fún àwọn ohun ọ̀sìn in yín, ẹ ó sì jẹ, ẹ ó sì yó.
Nĩngatũma kũgĩe na nyeki ithaka-inĩ nĩ ũndũ wa ngʼombe cianyu, na mũkarĩĩaga mũkahũũna.
16 Ẹ ṣọ́ra, kí a má ba à tàn yín jẹ láti yípadà kí ẹ sì sin ọlọ́run mìíràn àti láti máa foríbalẹ̀ fún wọn.
Mwĩmenyagĩrĩrei mũtikanaguucĩrĩrio, mũgarũrũke mũhooe ngai ingĩ na mũciinamĩrĩre.
17 Nígbà náà ni ìbínú Olúwa yóò sì ru sí i yín, Òun yóò ti ìlẹ̀kùn ọ̀run kí òjò má ba à rọ̀, ilẹ̀ kì yóò sì so èso kankan, ẹ ó sì ṣègbé ní ilẹ̀ rere tí Olúwa fi fún un yín.
Mũngĩkaguucĩrĩrio, marakara ma Jehova nĩmakamũũkĩrĩra mamũcine, na nĩakahinga igũrũ nĩgeetha gũtikoire nayo thĩ yage kũruta maciaro, na inyuĩ nĩmũgathira o narua mwehere bũrũri ũcio mwega Jehova aramũhe.
18 Ẹ fi gbogbo ọ̀rọ̀ mi wọ̀nyí sí àyà a yín, àti ọkàn an yín, ẹ so wọ́n bí àmì sórí ọwọ́ yín, kí ẹ sì so wọ́n mọ́ iwájú orí yín.
Igaai ciugo ici ciakwa ngoro-inĩ cianyu na meciiria-inĩ manyu; ciohagĩrĩrei moko-inĩ manyu irĩ imenyithia, na mũciohagĩrĩre mothiũ-inĩ manyu.
19 Ẹ máa fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ yín, ẹ máa sọ̀rọ̀ nípa wọn bí ẹ bá jókòó nínú ilé, àti ní ojú ọ̀nà bí ẹ bá ń rìn lọ, bí ẹ bá sùn àti bí ẹ bá jí.
Cirutagei ciana cianyu, na mũciaragie rĩrĩa mũikarĩte kwanyu mĩciĩ na rĩrĩa mũrathiĩ na njĩra, na rĩrĩa mũkomete na rĩrĩa muokĩra.
20 Kí ìwọ kí ó kọ wọ́n sára òpó ilé rẹ̀, àti sí ara ìlẹ̀kùn ọ̀nà òde rẹ.
Ciandĩkei hingĩro-inĩ cia mĩrango ya nyũmba cianyu o na mũciandĩke ihingo-inĩ cianyu,
21 Kí ọjọ́ ọ yín àti ti àwọn ọmọ yín lè pọ̀ ní ilẹ̀ tí Olúwa ti búra láti fi fún àwọn baba ńlá a yín, ní ìwọ̀n ìgbà tí ọ̀run wà lókè tí ayé sì ń bẹ ní ìsàlẹ̀.
nĩgeetha matukũ manyu na matukũ ma ciana cianyu maingĩhe kũu bũrũri-inĩ ũcio Jehova eehĩtire na mwĩhĩtwa atĩ nĩakahe maithe manyu ma tene; maingĩhe o ta matukũ marĩa igũrũ rĩgũtũũra rĩ igũrũ wa thĩ.
22 Bí ẹ bá fi ara balẹ̀ kíyèsi àwọn òfin tí mo ń fún un yín, láti tẹ̀lé, láti fẹ́ Olúwa Ọlọ́run yín, láti máa rìn ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti láti dìímú ṣinṣin:
Mũngĩmenyerera wega maathani maya mothe ndĩramũhe mũmarũmagĩrĩre, mwendage Jehova Ngai wanyu, na mũthiage na njĩra ciake ciothe na mũikarage mwĩgwatanĩtie nake-rĩ,
23 Olúwa yóò sì lé gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀nyí kúrò níwájú u yín. Ẹ ó sì gba orílẹ̀-èdè tí ó lágbára tí ó sì tóbi jù yín lọ.
hĩndĩ ĩyo Jehova nĩakaingata ndũrĩrĩ icio ciothe ciehere mbere yanyu, na inyuĩ mwĩgwatĩre kũndũ kũu kwa ndũrĩrĩ nene na irĩ hinya kũmũkĩra.
24 Gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹsẹ̀ ẹ yín tẹ̀ ni yóò jẹ́ tiyín, ilẹ̀ ẹ yín yóò gbilẹ̀ láti aginjù dé Lebanoni, àti láti odò Eufurate dé Òkun Ńlá.
Kũndũ guothe kũrĩa mũgaakinyithia makinya manyu gũgaatuĩka kwanyu; bũrũri wanyu ũkoima werũ-inĩ ũkinye Lebanoni, na uume Rũũĩ rwa Farati ũkinye iria-inĩ rĩa mwena wa ithũĩro.
25 Kò sí ẹni náà tí yóò lè kò yín lójú ìjà, Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi ẹ̀rù àti ìwárìrì i yín sórí gbogbo ilẹ̀ náà bí ó ti ṣèlérí fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá lọ.
Gũtirĩ mũndũ ũkaahota kũmwĩtiiria. O ta ũrĩa aamwĩrĩire, Jehova Ngai wanyu nĩagatũma mwĩtigĩrwo nĩ andũ a bũrũri wothe kũrĩa guothe mũgaathiĩ.
26 Ẹ kíyèsi i, mo fi ìbùkún àti ègún lélẹ̀ níwájú u yín lónìí:
Atĩrĩrĩ, ũmũthĩ ndĩramũigĩra kĩrathimo mbere yanyu na ngamũigĩra kĩrumi,
27 ìbùkún ni, bí ẹ bá pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín, tí mo ń fún un yín lónìí mọ́.
ndĩramũigĩra kĩrathimo angĩkorwo nĩmũgwathĩkĩra maathani ma Jehova Ngai wanyu marĩa ndĩramũhe ũmũthĩ;
28 Ègún ni, bí ẹ bá ṣàìgbọ́ràn, sí òfin Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì yapa kúrò ní ọ̀nà tí mo ti là sílẹ̀ fún yín lónìí, nípa títẹ̀lé ọlọ́run mìíràn, tí ẹ kò tí ì mọ̀.
na ngamũigĩra kĩrumi angĩkorwo nĩmũrĩagaga gwathĩkĩra maathani ma Jehova Ngai wanyu mũgatiga gũthiĩ na njĩra ĩrĩa ngũmwatha ũmũthĩ, na ũndũ wa kũrũmĩrĩra ngai ingĩ, iria mũtooĩ.
29 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti mú un yín dé ilẹ̀ náà tí ẹ ń wọ̀ láti gbà, kí ẹ kéde àwọn ìbùkún náà ní orí òkè Gerisimu, kí ẹ sì kéde àwọn ègún ní orí òkè Ebali.
Rĩrĩa Jehova Ngai wanyu akaamũkinyia bũrũri ũrĩa mũrathiĩ mũkawĩgwatĩre, nĩmũkanĩrĩra ũhoro wa kĩrathimo kĩu kĩrĩma-inĩ kĩa Gerizimu, nakĩo kĩrumi mũheanĩre ũhoro wakĩo kĩrĩma-inĩ kĩa Ebali.
30 Bí ẹ ti mọ̀ pé àwọn òkè wọ̀nyí wà ní ìkọjá a Jordani ní apá ìwọ̀-oòrùn lójú ọ̀nà lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, ní ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó More, ní ilẹ̀ àwọn ará a Kenaani, tí wọ́n ń gbé ní aginjù, ni agbègbè Gilgali.
O ta ũrĩa mũũĩ, irĩma icio irĩ kũu mũrĩmo wa Rũũĩ rwa Jorodani, mwena wa ithũĩro wa njĩra kwerekera na kũrĩa riũa rĩthũagĩra, gũkuhĩ na mĩtĩ ĩrĩa mĩnene ya More, kũu bũrũri wa andũ a Kaanani arĩa matũũraga Araba gũkuhĩ na Giligali.
31 Ẹ ti ṣetán láti la Jordani kọjá láti lè gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín ń fún un yín. Nígbà tí ẹ bá gbà á, tí ẹ bá sì ń gbé ibẹ̀,
Mũrĩ hakuhĩ kũringa Rũũĩ rwa Jorodani mũtoonye mũkegwatĩre bũrũri ũcio Jehova Ngai wanyu aramũhe. Rĩrĩa mũgaakorwo mũwoete na mũgatũũra kuo-rĩ,
32 ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń gbọ́rọ̀ sí gbogbo ìlànà àti òfin tí mo ń gbé kalẹ̀ fún un yín lónìí.
menyagĩrĩrai gwathĩkĩra kĩrĩra kĩa watho wa kũrũmĩrĩrwo, na mawatho marĩa ndĩramũhe ũmũthĩ.

< Deuteronomy 11 >