< Deuteronomy 11 >

1 Ẹ fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, kí ẹ sì pa ìfẹ́ rẹ̀, ìlànà rẹ̀, òfin rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ mọ́ ní ìgbà gbogbo.
Niin rakasta nyt Herraa sinun Jumalaas, ja pidä hänen lakinsa, säätynsä, oikeutensa ja käskynsä alinomaa.
2 Ẹ rántí lónìí pé, kì í ṣe àwọn ọmọ yín, ni ó rí ìbáwí Olúwa Ọlọ́run yín; títóbi rẹ̀, ọwọ́ agbára rẹ̀, nína ọwọ́ rẹ̀;
Ja tuntekaat te tänäpänä; sillä en minä teidän lastenne kanssa puhu, jotka ei tiedä, eikä ole nähneet Herran teidän Jumalanne kuritusta, hänen jalouttansa, voimallista kättänsä ja ojennettua käsivarttansa,
3 iṣẹ́ àmì rẹ̀ àti ohun tí ó ṣe ní àárín àwọn ará Ejibiti, sí Farao ọba Ejibiti àti gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ̀.
Ja hänen ihmeitänsä, ja tekojansa jotka hän teki Egyptiläisten seassa, Pharaolle Egyptin kuninkaalle, ja kaikelle hänen maakunnallensa,
4 Ohun tí ó ṣe sí àwọn jagunjagun Ejibiti, sí kẹ̀kẹ́ ogun àti ẹlẹ́ṣin rẹ̀: bí ó ṣe rì wọ́n sínú Òkun Pupa, bí wọ́n ṣe ń lé e yín tí Olúwa fi pa wọ́n run pátápátá títí di òní olónìí yìí.
Ja mitä hän teki Egyptiläisten sotaväelle, heidän hevosillensa ja vaunuillensa, kuin hän antoi Punaisen meren vedet juosta heidän päällensä, kuin he teitä ajoivat takaa, ja Herra hukutti heidät hamaan tähän päivään asti,
5 Kì í ṣe àwọn ọmọ yín ni ó rí ohun tí ó ṣe fún un yín ní aginjù, títí ẹ fi dé ìhín yìí,
Ja mitä hän teille korvessa tehnyt on, siihenasti kuin te tähän paikkaan tulitte,
6 ohun tí ó ṣe sí Datani àti Abiramu, àwọn ọmọ Eliabu, ẹ̀yà Reubeni, bí ilẹ̀ ti lanu ní ojú gbogbo ará Israẹli tí ó sì gbé wọn mì pẹ̀lú gbogbo ìdílé wọn, gbogbo àgọ́ ọ wọn àti gbogbo ohun alààyè tí ó jẹ́ tiwọn.
Ja mitä hän teki Datanille ja Abiramille Eliabin Rubenin pojan pojille, koska maa avasi suunsa ja nieli heidät, ja heidän perheensä ja majansa; niin myös kaikki heidän tavaransa, joka oli heidän hallussansa koko Israelin keskellä;
7 Ṣùgbọ́n ojú u yín gan an ni ó rí gbogbo nǹkan ńlá wọ̀nyí tí Olúwa ti ṣe.
Sillä teidän silmänne ovat nähneet kaikki ne suuret Herran teot, jotka hän tehnyt on.
8 Nítorí náà, ẹ kíyèsi gbogbo àṣẹ tí mo ń fún yín lónìí, kí ẹ ba à lè lágbára àti lọ, kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí ẹ ó la Jordani kọjá lọ.
Sentähden pitäkäät kaikki ne käskyt, jotka minä teille tänäpänä käsken, että te vahvistuisitte tulemaan ja omistamaan sitä maata, jota te menette omistamaan.
9 Kí ẹ ba à lè pẹ́ ní orí ilẹ̀ tí Olúwa ti búra fún àwọn baba ńlá a yín, láti fún àwọn àti àwọn ọmọ wọn: ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.
Että te kauvan siinä maassa eläisitte, jonka Herra sinun Jumalas vannoi teidän isillenne, heille antaaksensa ja heidän siemenellensä: sen maan, joka rieskaa ja hunajaa vuotaa.
10 Ilẹ̀ tí ẹ̀ ń wọ̀ lọ láti gbà kò rí bí ilẹ̀ Ejibiti, níbi tí ẹ ti wá, níbi tó jẹ́ wí pé ẹsẹ̀ yín ni ẹ fi ń rìn lọ bomirin irúgbìn tí ẹ gbìn bí oko ẹ̀fọ́.
Sillä se maa, johonkas menet omistamaan sitä, ei ole niinkuin Egyptin maa, josta te lähteneet olette; jossa sinä siemenes kylvit, ja kastoit sen jaloillas niinkuin kaalimaan.
11 Ṣùgbọ́n ilẹ̀ tí ẹ ó la Jordani kọjá láti gbà, jẹ́ ilẹ̀ olókè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀ tí òjò ń rọ̀ sí latọ̀run.
Vaan se maa, johonka te menette omistamaan sitä, on vuorinen ja laaksoinen maa, jonka sade taivaasta kastaa;
12 Ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín ń mójútó ni, ojú Olúwa Ọlọ́run yín sì ń fi ìgbà gbogbo wà lórí rẹ̀, láti ìbẹ̀rẹ̀ ọdún dé òpin ọdún.
Josta maasta Herra sinun Jumalas pitää vaarin; ja Herran sinun Jumalas silmät aina näkevät sen, vuoden alusta niin vuoden loppuun asti.
13 Nítorí náà, bí ẹ bá gbọ́rọ̀ sí àṣẹ tí mo fún un yín lónìí tọkàntọkàn: tí ẹ fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì sìn ín, pẹ̀lú gbogbo àyà yín àti gbogbo ọkàn yín:
Ja pitää tapahtuman, jos te hyvin kuuliaiset olette minun käskyilleni, jotka minä tänäpänä teille käsken; niin että te rakastatte Herraa teidän Jumalaanne, ja palvelette häntä kaikesta teidän sydämestänne ja kaikesta sielustanne,
14 nígbà náà, èmi yóò rọ òjò sórí ilẹ̀ ẹ yín lákòókò rẹ̀, àti òjò àkọ́rọ̀ àti ti àrọ̀kẹ́yìn, kí ẹ ba à lè kórè oúnjẹ yín wọlé àní wáìnì tuntun àti òróró.
Että minä annan teidän maallenne sateen ajallansa, varhain ja hiljain; että sinä korjaat jyväs, viinas ja öljys.
15 Èmi yóò mú kí koríko hù lórí ilẹ̀ yín fún àwọn ohun ọ̀sìn in yín, ẹ ó sì jẹ, ẹ ó sì yó.
Ja minä annan sinun karjalles ruohoa sinun kedoillas; että te syötte ja ravitaan.
16 Ẹ ṣọ́ra, kí a má ba à tàn yín jẹ láti yípadà kí ẹ sì sin ọlọ́run mìíràn àti láti máa foríbalẹ̀ fún wọn.
Varokaat ettei teidän sydämenne vieteltäisi, niin että poikkeette palvelemaan vieraita jumalia ja kumartamaan heitä.
17 Nígbà náà ni ìbínú Olúwa yóò sì ru sí i yín, Òun yóò ti ìlẹ̀kùn ọ̀run kí òjò má ba à rọ̀, ilẹ̀ kì yóò sì so èso kankan, ẹ ó sì ṣègbé ní ilẹ̀ rere tí Olúwa fi fún un yín.
Ja Herran viha julmistuis teidän päällenne, ja sulkis taivaan, ettei sadetta tulisi, ja maa ei antaisi hedelmäänsä: ja te kiiruusti hukkuisitte siitä hyvästä maasta, jonka Herra on teille antanut.
18 Ẹ fi gbogbo ọ̀rọ̀ mi wọ̀nyí sí àyà a yín, àti ọkàn an yín, ẹ so wọ́n bí àmì sórí ọwọ́ yín, kí ẹ sì so wọ́n mọ́ iwájú orí yín.
Niin pankaat nyt nämät minun sanani teidän sydämeenne, ja teidän mieleenne, ja sitokaat niitä merkiksi teidän käsiinne, että ne olisivat muistoksi teidän silmäinne edessä,
19 Ẹ máa fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ yín, ẹ máa sọ̀rọ̀ nípa wọn bí ẹ bá jókòó nínú ilé, àti ní ojú ọ̀nà bí ẹ bá ń rìn lọ, bí ẹ bá sùn àti bí ẹ bá jí.
Ja opettakaat niitä teidän lapsillenne, niin että sinä puhut niistä, huoneessa istuissas, tiellä käydessäs, levätä pannessas ja noustessas.
20 Kí ìwọ kí ó kọ wọ́n sára òpó ilé rẹ̀, àti sí ara ìlẹ̀kùn ọ̀nà òde rẹ.
Ja kirjoita ne sinun huonees pihtipieliin, ja sinun portteihis.
21 Kí ọjọ́ ọ yín àti ti àwọn ọmọ yín lè pọ̀ ní ilẹ̀ tí Olúwa ti búra láti fi fún àwọn baba ńlá a yín, ní ìwọ̀n ìgbà tí ọ̀run wà lókè tí ayé sì ń bẹ ní ìsàlẹ̀.
Että sinä ja sinun lapses kauvan eläisitte maan päällä, jonka Herra teidän isillenne vannoi antaaksensa heille, niinkauvan kuin päivät taivaasta maan päällä ovat.
22 Bí ẹ bá fi ara balẹ̀ kíyèsi àwọn òfin tí mo ń fún un yín, láti tẹ̀lé, láti fẹ́ Olúwa Ọlọ́run yín, láti máa rìn ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti láti dìímú ṣinṣin:
Sillä te kaikki nämät käskyt pidätte, jotka minä teille käsken, että te sen jälkeen teette; niin että te rakastatte Herraa teidän Jumalaanne, ja vaellatte kaikissa hänen teissänsä, ja riiputte hänessä kiinni;
23 Olúwa yóò sì lé gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀nyí kúrò níwájú u yín. Ẹ ó sì gba orílẹ̀-èdè tí ó lágbára tí ó sì tóbi jù yín lọ.
Niin Herra ajaa kaikki nämät kansat pois teidän kasvoinne edestä; niin että te omistatte suuremmat ja voimallisemmat kansat, kuin te olette.
24 Gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹsẹ̀ ẹ yín tẹ̀ ni yóò jẹ́ tiyín, ilẹ̀ ẹ yín yóò gbilẹ̀ láti aginjù dé Lebanoni, àti láti odò Eufurate dé Òkun Ńlá.
Kaikki paikat, mihin teidän jalkanne astuu, pitää teidän oleman: korvesta ja Libanonista ja Phrathin virrasta, ärimäiseen mereen asti, pitää teidän rajanne oleman.
25 Kò sí ẹni náà tí yóò lè kò yín lójú ìjà, Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi ẹ̀rù àti ìwárìrì i yín sórí gbogbo ilẹ̀ náà bí ó ti ṣèlérí fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá lọ.
Ei yksikään voi olla teitä vastaan: teidän pelkonne ja vavistuksenne antaa Herra tulla kaikkein niiden maiden päälle, kussa te vaellatte; niinkuin hän teille on sanonut.
26 Ẹ kíyèsi i, mo fi ìbùkún àti ègún lélẹ̀ níwájú u yín lónìí:
Katso, minä asetan tänäpänä teidän eteenne, sekä siunauksen että kirouksen.
27 ìbùkún ni, bí ẹ bá pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín, tí mo ń fún un yín lónìí mọ́.
Siunauksen, jos te kuuliaiset olette Herran teidän Jumalanne käskylle, jonka minä tänäpänä teille käsken.
28 Ègún ni, bí ẹ bá ṣàìgbọ́ràn, sí òfin Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì yapa kúrò ní ọ̀nà tí mo ti là sílẹ̀ fún yín lónìí, nípa títẹ̀lé ọlọ́run mìíràn, tí ẹ kò tí ì mọ̀.
Kirouksen, jos ette tottele Herran teidän Jumalanne käskyjä, ja poikkeette siitä tiestä, jonka minä teille tänäpänä käsken; niin että te vaellatte muiden jumalain jälkeen, joita ette tunne.
29 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti mú un yín dé ilẹ̀ náà tí ẹ ń wọ̀ láti gbà, kí ẹ kéde àwọn ìbùkún náà ní orí òkè Gerisimu, kí ẹ sì kéde àwọn ègún ní orí òkè Ebali.
Koska Herra sinun Jumalas johdattaa sinun siihen maahan, johonkas tulet omistamaan sitä; niin anna siunaus sanottaa Grisimin vuorella, ja kirous Ebalin vuorella.
30 Bí ẹ ti mọ̀ pé àwọn òkè wọ̀nyí wà ní ìkọjá a Jordani ní apá ìwọ̀-oòrùn lójú ọ̀nà lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, ní ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó More, ní ilẹ̀ àwọn ará a Kenaani, tí wọ́n ń gbé ní aginjù, ni agbègbè Gilgali.
Eikö he ole tuolla puolella Jordania tien perällä, auringon laskemiseen päin Kanaanealaisten maalla, jotka asuvat lakeudella, Gilgalin kohdalla, Moren tammiston tykönä?
31 Ẹ ti ṣetán láti la Jordani kọjá láti lè gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín ń fún un yín. Nígbà tí ẹ bá gbà á, tí ẹ bá sì ń gbé ibẹ̀,
Sillä teidän pitää menemän Jordanin yli, tuleman ja omistaman maan, jonka Herra teidän Jumalanne teille antaa, sen omistaaksenne, ja asuaksenne siinä.
32 ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń gbọ́rọ̀ sí gbogbo ìlànà àti òfin tí mo ń gbé kalẹ̀ fún un yín lónìí.
Niin pitäkäät ja tehkäät kaikki ne säädyt ja oikeudet, jotka minä tänäpänä panen teidän eteenne.

< Deuteronomy 11 >