< Deuteronomy 10 >

1 Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Gbé wàláà òkúta méjì bí i ti àkọ́kọ́ kí o sì gòkè tọ̀ mí wá. Kí o sì tún fi igi kan àpótí kan.
Ob tistem času mi je Gospod rekel: ›Izsekaj si dve kamniti plošči, podobni prvima in pridi gor k meni na goro in si naredi skrinjo iz lesa.
2 Èmi yóò sì kọ ọ̀rọ̀ tí ó wà lára wàláà àkọ́kọ́ tí ìwọ fọ́, sára wàláà wọ̀nyí. Ìwọ yóò sì fi wọ́n sínú àpótí náà.”
Na tabli bom zapisal besede, ki so bile na prvih tablah, ki si ju razbil in položil ju boš v skrinjo.‹
3 Mo sì kan àpótí náà pẹ̀lú igi kasia, mo sì gbẹ́ wàláà òkúta méjì náà jáde bí i ti ìṣáájú. Mo sì gòkè lọ pẹ̀lú wàláà méjèèjì lọ́wọ́ mí.
In naredil sem skrinjo iz akacijevega lesa in izsekal dve kamniti plošči, podobni prvima in odšel gor na goro in v svoji roki sem imel dve tabli.
4 Olúwa tún ohun tí ó ti kọ tẹ́lẹ̀ kọ sórí wàláà wọ̀nyí. Àwọn òfin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí ó ti sọ fún un yín lórí òkè, láàrín iná, ní ọjọ́ ìpéjọpọ̀. Olúwa sì fi wọ́n fún mi.
Na tabli je zapisal deset zapovedi, glede na prvo pisanje, ki vam jih je Gospod govoril na gori iz srede ognja na dan zbora. In Gospod mi ju je dal.
5 Mo sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà, mo sì ki àwọn wàláà òkúta náà sínú àpótí tí mo ti kàn, bí Olúwa ti pàṣẹ fún mi, wọ́n sì wà níbẹ̀ di ìsinsin yìí.
Obrnil sem se in prišel dol z gore in tabli položil v skrinjo, ki sem jo naredil, in tam sta, kakor mi je Gospod zapovedal.
6 (Àwọn ará Israẹli sì gbéra láti kànga àwọn ará Jaakani dé Mosera. Níbí ni Aaroni kú sí, tí a sì sin ín, Eleasari ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ bí i àlùfáà.
Izraelovi otroci so odšli na svoje potovanje od Beeróta Jaakánovih otrok v Mosêro. Tam je Aron umrl in tam je bil pokopan in namesto njega je v duhovniški službi služil njegov sin Eleazar.
7 Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti rìn lọ sí Gudgoda, títí dé Jotbata, ilẹ̀ tí o kún fún odò tí ó ń sàn.
Od tam so odpotovali v Gidgád in iz Gidgáda v Jotbáto, deželo rek vodá.
8 Ní ìgbà yìí ni Olúwa yan àwọn ẹ̀yà Lefi láti máa ru àpótí ẹ̀rí Olúwa, láti máa dúró níwájú Olúwa láti ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́, àti láti fi orúkọ Olúwa súre bí wọ́n ti ń ṣe títí di òní yìí.
Ob tistem času je Gospod ločil Lévijev rod, da nosi skrinjo Gospodove zaveze, da stojijo pred Gospodom, da mu služijo in da blagoslavljajo v njegovem imenu, do današnjega dne.
9 Ìdí nìyí tí àwọn ẹ̀yà Lefi kò fi ní ìpín tàbí ogún kan láàrín àwọn arákùnrin wọn. Olúwa ni ogún wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run ti sọ fún un yín.)
Zato Levi nima deleža niti dediščine s svojimi brati; Gospod je njegova dediščina, kakor mu je obljubil Gospod, tvoj Bog.
10 Mo tún dúró ní orí òkè náà fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, bí mo ti ṣe ní ìgbà àkọ́kọ́, Olúwa sì gbọ́ tèmi ní àkókò yìí bákan náà. Kì í ṣe ìfẹ́ rẹ̀ láti run yín.
In ostal sem na gori, kakor prvič, štirideset dni in štirideset noči in Gospod mi je prisluhnil tudi ob tistem času in Gospod te ni hotel uničiti.
11 Olúwa sọ fún mi pé, “Lọ darí àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọ̀nà wọn, kí wọn bá à lè wọ ilẹ̀ náà, kí wọn sì gba ilẹ̀ tí mo ti búra fún àwọn baba wọn láti fún wọn.”
Gospod mi je rekel: ›Vstani, odpravi se na svoje potovanje pred ljudstvom, da lahko vstopijo in vzamejo v last deželo, ki sem jo prisegel njihovim očetom, da jim jo dam.‹
12 Nísinsin yìí ìwọ Israẹli, kín ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ béèrè lọ́wọ́ rẹ? Bí kò ṣe kí ìwọ bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ àti láti máa rìn ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti fẹ́ràn rẹ̀, láti fi gbogbo ọkàn rẹ sin Olúwa Ọlọ́run rẹ ọkàn àti àyà rẹ,
In sedaj, Izrael, kaj Gospod, tvoj Bog, zahteva od tebe, razen, da se bojiš Gospoda, svojega Boga, da hodiš po vseh njegovih poteh, da ga ljubiš, da služiš Gospodu, svojemu Bogu, z vsem svojim srcem in z vso svojo dušo.
13 àti láti máa kíyèsi àṣẹ àti ìlànà Olúwa tí mo ń fún ọ lónìí, fún ìre ara à rẹ.
Da varuješ Gospodove zapovedi in njegove zakone, ki ti jih ta dan zapovedujem v tvoje dobro?
14 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni ó ni ọ̀run àní àwọn ọ̀run tó ga ju ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.
Glej, nebo in nebesa nebes so od Gospoda, tvojega Boga, tudi zemlja z vsem, kar je na njej.
15 Síbẹ̀ Olúwa sì tún fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn fún àwọn baba ńlá a yín, Ó sì fẹ́ wọn Ó sì yan ẹ̀yin ọmọ wọn láti borí gbogbo orílẹ̀-èdè títí di òní.
Samo Gospod je imel zadovoljstvo v tvojih očetih, da jih vzljubi in izbral je njihovo seme za njimi, torej vas, izmed vseh ljudstev, kakor je to ta dan.
16 Ẹ kọ ọkàn yín ní ilà, kí ẹ má sì ṣe jẹ́ olórí kunkun mọ́ láti òní lọ.
Obrežite torej prednjo kožico svojega srca in ne bodite več trdovratni.
17 Torí pé Olúwa Ọlọ́run yín, ni Ọlọ́run àwọn ọlọ́run àti Olúwa àwọn olúwa. Ọlọ́run alágbára, tí ó tóbi tí ó sì lẹ́rù, tí kì í ṣe ojúsàájú kì í sì í gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
Kajti Gospod, vaš Bog, je Bog bogov in Gospod gospodov in véliki Bog, mogočen in strašen, ki se ne ozira na osebe niti ne sprejema nagrade.
18 Ó máa ń gbẹjọ́ aláìní baba àti opó rò, Ó fẹ́ràn àjèjì, Òun fi aṣọ àti oúnjẹ fún wọn.
Izvaja sodbo sirote in vdove in ljubi tujca v tem, da mu daje hrano in oblačilo.
19 Ẹ gbọdọ̀ fẹ́ràn àwọn àjèjì, torí pé ẹ̀yin pẹ̀lú ti jẹ́ àjèjì rí ní Ejibiti.
Ljubite torej tujca, kajti tujci ste bili v egiptovski deželi.
20 Ẹ bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín, ẹ sì máa sìn ín. Ẹ dìímú ṣinṣin, kí ẹ sì búra ní orúkọ rẹ̀.
Bal se boš Gospoda, svojega Boga. Njemu boš služil in k njemu se boš trdno pridružil in prisegal pri njegovem imenu.
21 Òun ni ìyìn in yín, Òun sì ni Ọlọ́run yín, tí ó ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu ńlá àti ohun ẹ̀rù, tí ẹ fojú ara yín rí.
On je tvoja hvala in on je tvoj Bog, ki je zate storil te velike in strašne stvari, ki so jih videle tvoje oči.
22 Àádọ́rin péré ni àwọn baba ńlá a yín tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run yín ti mú un yín pọ̀ sí i ní iye bí àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run.
Tvoji očetje so odšli dol v Egipt s sedemdesetimi osebami in sedaj te je Gospod, tvoj Bog, naredil kakor zvezd neba zaradi množice.

< Deuteronomy 10 >