< Deuteronomy 10 >

1 Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Gbé wàláà òkúta méjì bí i ti àkọ́kọ́ kí o sì gòkè tọ̀ mí wá. Kí o sì tún fi igi kan àpótí kan.
"Silloin Herra sanoi minulle: 'Veistä itsellesi kaksi kivitaulua, entisten kaltaista, ja nouse vuorelle minun tyköni; tee myös itsellesi puusta arkki.
2 Èmi yóò sì kọ ọ̀rọ̀ tí ó wà lára wàláà àkọ́kọ́ tí ìwọ fọ́, sára wàláà wọ̀nyí. Ìwọ yóò sì fi wọ́n sínú àpótí náà.”
Minä kirjoitan niihin tauluihin ne sanat, jotka olivat entisissä tauluissa, niissä, jotka sinä murskasit; pane ne arkkiin.'
3 Mo sì kan àpótí náà pẹ̀lú igi kasia, mo sì gbẹ́ wàláà òkúta méjì náà jáde bí i ti ìṣáájú. Mo sì gòkè lọ pẹ̀lú wàláà méjèèjì lọ́wọ́ mí.
Niin minä tein arkin akasiapuusta ja veistin kaksi kivitaulua, entisten kaltaista. Ja minä nousin vuorelle, kädessäni ne kaksi taulua.
4 Olúwa tún ohun tí ó ti kọ tẹ́lẹ̀ kọ sórí wàláà wọ̀nyí. Àwọn òfin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí ó ti sọ fún un yín lórí òkè, láàrín iná, ní ọjọ́ ìpéjọpọ̀. Olúwa sì fi wọ́n fún mi.
Ja hän kirjoitti tauluihin saman, minkä edellisellä kerralla, ne kymmenen sanaa, jotka Herra oli puhunut teille vuorelta, tulen keskeltä, seurakunnan kokouspäivänä. Ja Herra antoi ne minulle.
5 Mo sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà, mo sì ki àwọn wàláà òkúta náà sínú àpótí tí mo ti kàn, bí Olúwa ti pàṣẹ fún mi, wọ́n sì wà níbẹ̀ di ìsinsin yìí.
Sitten minä käännyin ja astuin alas vuorelta ja panin taulut tekemääni arkkiin, niinkuin Herra oli minua käskenyt, ja siinä ne ovat.
6 (Àwọn ará Israẹli sì gbéra láti kànga àwọn ará Jaakani dé Mosera. Níbí ni Aaroni kú sí, tí a sì sin ín, Eleasari ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ bí i àlùfáà.
Ja israelilaiset lähtivät liikkeelle Bene-Jaakanin kaivoilta ja vaelsivat Mooseraan. Siellä kuoli Aaron, ja hänet haudattiin sinne; ja hänen poikansa Eleasar tuli papiksi hänen sijaansa.
7 Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti rìn lọ sí Gudgoda, títí dé Jotbata, ilẹ̀ tí o kún fún odò tí ó ń sàn.
Sieltä he lähtivät liikkeelle Gudgodaan, ja Gudgodasta Jotbataan, seutuun, jossa on vesipuroja.
8 Ní ìgbà yìí ni Olúwa yan àwọn ẹ̀yà Lefi láti máa ru àpótí ẹ̀rí Olúwa, láti máa dúró níwájú Olúwa láti ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́, àti láti fi orúkọ Olúwa súre bí wọ́n ti ń ṣe títí di òní yìí.
Siihen aikaan Herra erotti Leevin sukukunnan kantamaan Herran liitonarkkia, seisomaan Herran edessä, palvelemaan häntä ja siunaamaan hänen nimeensä, niinkuin tähän päivään saakka on tapahtunut.
9 Ìdí nìyí tí àwọn ẹ̀yà Lefi kò fi ní ìpín tàbí ogún kan láàrín àwọn arákùnrin wọn. Olúwa ni ogún wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run ti sọ fún un yín.)
Sentähden Leevi ei saanut osuutta eikä perintöosaa veljiensä rinnalla, sillä Herra on hänen perintöosansa, niinkuin Herra, sinun Jumalasi, on hänelle puhunut.
10 Mo tún dúró ní orí òkè náà fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, bí mo ti ṣe ní ìgbà àkọ́kọ́, Olúwa sì gbọ́ tèmi ní àkókò yìí bákan náà. Kì í ṣe ìfẹ́ rẹ̀ láti run yín.
Ja minä viivyin vuorella, niinkuin edelliselläkin kerralla, neljäkymmentä päivää ja neljäkymmentä yötä; ja Herra kuuli minua vielä silläkin kertaa, sillä Herra ei tahtonut tuhota sinua.
11 Olúwa sọ fún mi pé, “Lọ darí àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọ̀nà wọn, kí wọn bá à lè wọ ilẹ̀ náà, kí wọn sì gba ilẹ̀ tí mo ti búra fún àwọn baba wọn láti fún wọn.”
Ja Herra sanoi minulle: 'Nouse ja lähde, kulje kansan edellä, että he menevät ja ottavat omakseen maan, jonka minä heidän isillensä vannotulla valalla olen luvannut antaa heille'.
12 Nísinsin yìí ìwọ Israẹli, kín ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ béèrè lọ́wọ́ rẹ? Bí kò ṣe kí ìwọ bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ àti láti máa rìn ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti fẹ́ràn rẹ̀, láti fi gbogbo ọkàn rẹ sin Olúwa Ọlọ́run rẹ ọkàn àti àyà rẹ,
Ja nyt, Israel, mitä Herra, sinun Jumalasi, sinulta muuta vaatii, kuin että pelkäät Herraa, sinun Jumalaasi, että aina vaellat hänen teitänsä ja rakastat häntä, ja että palvelet Herraa, sinun Jumalaasi, kaikesta sydämestäsi ja kaikesta sielustasi,
13 àti láti máa kíyèsi àṣẹ àti ìlànà Olúwa tí mo ń fún ọ lónìí, fún ìre ara à rẹ.
noudattaen Herran käskyjä ja säädöksiä, jotka minä sinulle tänä päivänä annan, että menestyisit.
14 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni ó ni ọ̀run àní àwọn ọ̀run tó ga ju ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.
Katso, taivaat ja taivasten taivaat, maa ja kaikki, mitä siinä on, ovat Herran, sinun Jumalasi.
15 Síbẹ̀ Olúwa sì tún fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn fún àwọn baba ńlá a yín, Ó sì fẹ́ wọn Ó sì yan ẹ̀yin ọmọ wọn láti borí gbogbo orílẹ̀-èdè títí di òní.
Mutta ainoastaan sinun isiisi Herra mielistyi ja rakasti heitä; ja hän valitsi omikseen heidän jälkeläisensä, hän valitsi teidät kaikista kansoista, niinkuin yhä vielä on.
16 Ẹ kọ ọkàn yín ní ilà, kí ẹ má sì ṣe jẹ́ olórí kunkun mọ́ láti òní lọ.
Ympärileikatkaa sentähden sydämenne älkääkä olko enää niskureita.
17 Torí pé Olúwa Ọlọ́run yín, ni Ọlọ́run àwọn ọlọ́run àti Olúwa àwọn olúwa. Ọlọ́run alágbára, tí ó tóbi tí ó sì lẹ́rù, tí kì í ṣe ojúsàájú kì í sì í gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
Sillä Herra, teidän Jumalanne, on jumalain Jumala ja herrain Herra, suuri, voimallinen ja peljättävä Jumala, joka ei katso henkilöön eikä ota lahjusta,
18 Ó máa ń gbẹjọ́ aláìní baba àti opó rò, Ó fẹ́ràn àjèjì, Òun fi aṣọ àti oúnjẹ fún wọn.
joka hankkii orvolle ja leskelle oikeuden ja joka rakastaa muukalaista ja antaa hänelle ruuan ja vaatteen.
19 Ẹ gbọdọ̀ fẹ́ràn àwọn àjèjì, torí pé ẹ̀yin pẹ̀lú ti jẹ́ àjèjì rí ní Ejibiti.
Sentähden rakastakaa muukalaista, sillä te olette itse olleet muukalaisina Egyptin maassa.
20 Ẹ bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín, ẹ sì máa sìn ín. Ẹ dìímú ṣinṣin, kí ẹ sì búra ní orúkọ rẹ̀.
Herraa, sinun Jumalaasi, pelkää, häntä palvele, hänessä riipu kiinni ja vanno hänen nimeensä.
21 Òun ni ìyìn in yín, Òun sì ni Ọlọ́run yín, tí ó ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu ńlá àti ohun ẹ̀rù, tí ẹ fojú ara yín rí.
Hän on sinun ylistyksesi, ja hän on sinun Jumalasi, joka on tehnyt sinulle ne suuret ja peljättävät teot, jotka sinun silmäsi ovat nähneet.
22 Àádọ́rin péré ni àwọn baba ńlá a yín tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run yín ti mú un yín pọ̀ sí i ní iye bí àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run.
Seitsemänkymmentä henkeä oli sinun isiesi joukkoa, kun he menivät Egyptiin, mutta nyt Herra, sinun Jumalasi, on tehnyt sinun lukusi paljoksi niinkuin taivaan tähdet."

< Deuteronomy 10 >