< Deuteronomy 10 >

1 Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Gbé wàláà òkúta méjì bí i ti àkọ́kọ́ kí o sì gòkè tọ̀ mí wá. Kí o sì tún fi igi kan àpótí kan.
In that tyme the Lord seide to me, Hewe thou twei tablis of stoon to thee, as the formere weren; and stie thou to me `in to the hil. And thou schalt make an arke,
2 Èmi yóò sì kọ ọ̀rọ̀ tí ó wà lára wàláà àkọ́kọ́ tí ìwọ fọ́, sára wàláà wọ̀nyí. Ìwọ yóò sì fi wọ́n sínú àpótí náà.”
`ether a cofere, of tree, and Y schal write in the tablis, the wordis that weren in these tablis whiche thou brakist bifore; and thou schalt putte tho tablis in to the arke.
3 Mo sì kan àpótí náà pẹ̀lú igi kasia, mo sì gbẹ́ wàláà òkúta méjì náà jáde bí i ti ìṣáájú. Mo sì gòkè lọ pẹ̀lú wàláà méjèèjì lọ́wọ́ mí.
Therfor Y made an ark of the trees of Sechim, and whanne Y hadde hewe twei tablis of stoon, at the licnesse of the formere tablis, Y stiede in to the hil, and hadde the tablis in the hondis.
4 Olúwa tún ohun tí ó ti kọ tẹ́lẹ̀ kọ sórí wàláà wọ̀nyí. Àwọn òfin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí ó ti sọ fún un yín lórí òkè, láàrín iná, ní ọjọ́ ìpéjọpọ̀. Olúwa sì fi wọ́n fún mi.
And he wroot in the tablis, bi that that he `hadde writun bifore, ten wordis, whiche the Lord spak to you in the hil, fro the myddis of the fyer, whanne the puple was gaderid, and he yaf the tablis to me.
5 Mo sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà, mo sì ki àwọn wàláà òkúta náà sínú àpótí tí mo ti kàn, bí Olúwa ti pàṣẹ fún mi, wọ́n sì wà níbẹ̀ di ìsinsin yìí.
And Y turnide ayen fro the hil, and cam doun, and puttide the tablis in to the arke which Y hadde maad, `whiche tablis ben there hidur to, as the Lord comaundide to me.
6 (Àwọn ará Israẹli sì gbéra láti kànga àwọn ará Jaakani dé Mosera. Níbí ni Aaroni kú sí, tí a sì sin ín, Eleasari ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ bí i àlùfáà.
Forsothe the sones of Israel moueden tentis fro Beroth of the sones of Jachan in to Mosera, where Aaron was deed, and biried, for whom his sone Eleazar was set in preesthod.
7 Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti rìn lọ sí Gudgoda, títí dé Jotbata, ilẹ̀ tí o kún fún odò tí ó ń sàn.
Fro thennus thei camen in to Galgad; fro which place thei yeden forth, and settiden tentis in Jehabatha, in the lond of watris and of strondis.
8 Ní ìgbà yìí ni Olúwa yan àwọn ẹ̀yà Lefi láti máa ru àpótí ẹ̀rí Olúwa, láti máa dúró níwájú Olúwa láti ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́, àti láti fi orúkọ Olúwa súre bí wọ́n ti ń ṣe títí di òní yìí.
In that tyme Y departide the lynage of Leuy, that it schulde bere the arke of boond of pees of the Lord, and schulde stonde bifor hym in seruyce, and schulde blesse in his name til in to present dai.
9 Ìdí nìyí tí àwọn ẹ̀yà Lefi kò fi ní ìpín tàbí ogún kan láàrín àwọn arákùnrin wọn. Olúwa ni ogún wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run ti sọ fún un yín.)
For which thing Leuy hadde not part, nether possession with hise brithren, for the Lord hym silf is his possessioun, as thi Lord God bihiyte to hym.
10 Mo tún dúró ní orí òkè náà fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, bí mo ti ṣe ní ìgbà àkọ́kọ́, Olúwa sì gbọ́ tèmi ní àkókò yìí bákan náà. Kì í ṣe ìfẹ́ rẹ̀ láti run yín.
Forsothe Y stood in the hil as bifore, fourti daies and fourti niytis, and the Lord herde me also in this tyme, and nolde leese thee.
11 Olúwa sọ fún mi pé, “Lọ darí àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọ̀nà wọn, kí wọn bá à lè wọ ilẹ̀ náà, kí wọn sì gba ilẹ̀ tí mo ti búra fún àwọn baba wọn láti fún wọn.”
And he seide to me, Go thou, and go bifor this puple, that it entre, and welde the lond which Y swoor to her fadris, that Y schulde yeue to hem.
12 Nísinsin yìí ìwọ Israẹli, kín ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ béèrè lọ́wọ́ rẹ? Bí kò ṣe kí ìwọ bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ àti láti máa rìn ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti fẹ́ràn rẹ̀, láti fi gbogbo ọkàn rẹ sin Olúwa Ọlọ́run rẹ ọkàn àti àyà rẹ,
And now, Israel, what axith thi Lord God of thee, no but that thou drede thi Lord, and go in hise weies, and that thou loue hym, and serue thi Lord God in al thin herte, and in al thi soule;
13 àti láti máa kíyèsi àṣẹ àti ìlànà Olúwa tí mo ń fún ọ lónìí, fún ìre ara à rẹ.
and that thou kepe the comaundementis of thi Lord God, and the cerymonyes of hym, whiche Y comaunde to thee to dai, that it be wel to thee.
14 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni ó ni ọ̀run àní àwọn ọ̀run tó ga ju ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.
Lo! heuene is of thi Lord God, and heuene of heuene; the erthe and alle thingis that ben ther ynne ben hise;
15 Síbẹ̀ Olúwa sì tún fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn fún àwọn baba ńlá a yín, Ó sì fẹ́ wọn Ó sì yan ẹ̀yin ọmọ wọn láti borí gbogbo orílẹ̀-èdè títí di òní.
and netheles the Lord was glued to thi fadris, and louede hem, and he chees her seed after hem, and you of alle folkis, as it is preued to dai.
16 Ẹ kọ ọkàn yín ní ilà, kí ẹ má sì ṣe jẹ́ olórí kunkun mọ́ láti òní lọ.
Therfor circumcide ye the prepucie, `ethir vnclennesse, of youre herte, and no more make ye harde youre nol.
17 Torí pé Olúwa Ọlọ́run yín, ni Ọlọ́run àwọn ọlọ́run àti Olúwa àwọn olúwa. Ọlọ́run alágbára, tí ó tóbi tí ó sì lẹ́rù, tí kì í ṣe ojúsàájú kì í sì í gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
For youre Lord God hym silf is God of goddis, and Lord of lordis, `God greet, and miyti, and feerdful, which takith not persoone, nether yiftis.
18 Ó máa ń gbẹjọ́ aláìní baba àti opó rò, Ó fẹ́ràn àjèjì, Òun fi aṣọ àti oúnjẹ fún wọn.
He makith doom to the fadirles, and modirles, and to the widewe; he loueth a pilgrym, and yyueth to hym lyiflode and clothing.
19 Ẹ gbọdọ̀ fẹ́ràn àwọn àjèjì, torí pé ẹ̀yin pẹ̀lú ti jẹ́ àjèjì rí ní Ejibiti.
And therfor `loue ye pilgryms, for also ye weren comelyngis in the lond of Egipt.
20 Ẹ bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín, ẹ sì máa sìn ín. Ẹ dìímú ṣinṣin, kí ẹ sì búra ní orúkọ rẹ̀.
Thou schalt drede thi Lord God, and thou schalt serue hym aloone, and thou schalt cleue to hym, and thou schalt swere in his name.
21 Òun ni ìyìn in yín, Òun sì ni Ọlọ́run yín, tí ó ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu ńlá àti ohun ẹ̀rù, tí ẹ fojú ara yín rí.
He is thi preisyng, and thi God, that made to thee these grete dedis, and ferdful, whiche thin iyen siyen.
22 Àádọ́rin péré ni àwọn baba ńlá a yín tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run yín ti mú un yín pọ̀ sí i ní iye bí àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run.
In seuenti men thi fadris yeden doun in to Egipt, and lo! now thi Lord God hath multiplied thee as the sterris of heuene.

< Deuteronomy 10 >