< Deuteronomy 1 >

1 Wọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Mose sọ fún gbogbo Israẹli ní aginjù, aginjù ìlà-oòrùn Jordani, ni Arabah, ní òdìkejì Ṣufi, ní àárín Parani àti Tofeli, Labani, Haserotu àti Disahabu.
Estas são as palavras que Moisés falou a todo Israel além do Jordão no deserto, no Arabah em frente ao Suf, entre Paran, Tophel, Laban, Hazeroth, e Dizahab.
2 (Ọjọ́ mọ́kànlá ni ó gbà láti rin ìrìnàjò láti Horebu dé Kadeṣi-Barnea, bí a bá gba ọ̀nà òkè Seiri.)
São onze dias de viagem de Horeb, pelo caminho do Monte Seir até Kadesh Barnea.
3 Ní ìgbà tí ó pé ogójì ọdún, ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kọ́kànlá, Mose sọ ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ nípa àwọn ọmọ Israẹli fún wọn.
No quadragésimo ano, no décimo primeiro mês, no primeiro dia do mês, Moisés falou aos filhos de Israel de acordo com tudo o que Iavé lhes havia ordenado,
4 Èyí ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣẹ́gun Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani ni ó ṣẹ́gun ní Edrei, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu.
depois de ter atingido Sihon, o rei dos amorreus que vivia em Heshbon, e Og, o rei de Basã que vivia em Ashtaroth, em Edrei.
5 Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani tí ó wà nínú ilẹ̀ Moabu ni Mose bẹ̀rẹ̀ sísọ àsọyé òfin wọ̀nyí wí pé:
Além do Jordão, na terra dos moabitas, Moisés começou a declarar esta lei, dizendo:
6 Olúwa Ọlọ́run wa bá wa sọ̀rọ̀ ní Horebu pé, “Ẹ ti dúró ní orí òkè yìí pẹ́ tó.
“Yahweh nosso Deus nos falou em Horeb, dizendo: 'Vós já vivestes tempo suficiente nesta montanha'.
7 Ẹ yípadà kí ẹ sì tẹ̀síwájú ní ìrìnàjò yín lọ sí ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, ẹ tọ gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń gbé Arabah lọ ní aginjù, ní àwọn orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀, ní gúúsù àti ní etí Òkun, lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani àti lọ sí Lebanoni, títí fi dé odò ńlá Eufurate.
Vire, e faça sua viagem, e vá para a região montanhosa dos amorreus e para todos os lugares próximos: no Arabah, na região montanhosa, na planície, no Sul, à beira-mar, na terra dos cananeus, e no Líbano até o grande rio, o rio Eufrates.
8 Wò ó, èmi tí fi ilẹ̀ yí fún un yín, ẹ wọ inú rẹ̀ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí Olúwa ti búra wí pé òun yóò fún àwọn baba yín: fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu, àti fún àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn.”
Eis que eu pus a terra diante de vocês. Ide e possuí a terra que Javé jurou a vossos pais - a Abraão, a Isaac e a Jacó - dar a eles e a seus descendentes depois deles”.
9 Mo wí fún un yín nígbà náà pé, “Èmi nìkan kò lè dá ẹrù u yín gbé.
Falei com você naquela época, dizendo: “Eu mesmo não sou capaz de suportá-lo sozinho”.
10 Olúwa Ọlọ́run yín ti sọ yín di púpọ̀ lónìí, ẹ̀yin sì ti pọ̀ bí ìràwọ̀ ní ojú ọ̀run.
Yahweh seu Deus multiplicou você, e eis que hoje você é como as estrelas do céu para a multidão.
11 Kí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín sọ yín di púpọ̀ ní ọ̀nà ẹgbẹ̀rún sí i, kí ó sì bùkún un yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
Que Yahweh, o Deus de seus pais, faça de vocês mil vezes mais numerosos e os abençoe, como Ele lhes prometeu!
12 Báwo ni èmi nìkan ṣe lè máa ru àjàgà àti ìṣòro yín àti èdè-àìyedè yín?
Como eu mesmo posso suportar sozinho seus problemas, seus fardos e suas lutas?
13 Ẹ yan àwọn ọlọ́gbọ́n, olóye àti àwọn ẹni àpọ́nlé, láti inú ẹ̀yà yín kọ̀ọ̀kan, èmi yóò sì fi wọ́n ṣe olórí yín.”
Tomai homens sábios de entendimento que são respeitados entre vossas tribos, e eu os farei passar por cima de vós”.
14 Ẹ̀yin sì dá mi lóhùn wí pé, “Ohun tí ìwọ ti gbèrò láti ṣe nì dára.”
Você me respondeu e disse: “O que você falou é bom de se fazer”.
15 Bẹ́ẹ̀ ni mo yan olórí àwọn ẹ̀yà yín, àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin, ẹni àpọ́nlé, mo sì fi jẹ olórí yín, olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà yín.
Então eu tomei os chefes de suas tribos, homens sábios e respeitados, e os fiz cabeças sobre você, capitães de milhares, capitães de centenas, capitães de cinqüenta, capitães de dezenas, e oficiais, de acordo com suas tribos.
16 Mo sì kìlọ̀ fún àwọn onídàájọ́ yín nígbà náà pé, ẹ gbọ́ èdè-àìyedè tí ó wà láàrín àwọn ènìyàn an yín kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ òdodo, bóyá ẹjọ́ tí ó ṣẹlẹ̀ láàrín Israẹli sí Israẹli ni tàbí láàrín Israẹli kan sí àlejò.
Ordenei a seus juízes naquela época, dizendo: “Ouçam os casos entre seus irmãos e julguem com justiça entre um homem e seu irmão, e o estrangeiro que vive com ele”.
17 Ẹ má sì ṣe ojúsàájú ní ìdájọ́. Ẹ ṣe ìdájọ́ ẹni ńlá àti kékeré bákan náà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹnikẹ́ni torí pé ti Ọlọ́run ni ìdájọ́. Ẹjọ́ tí ó bá le jù fún un yín ni kí ẹ mú wá fún mi. Èmi yóò sì gbọ́ ọ.
Não demonstrará parcialidade no julgamento; ouvirá os pequenos e os grandes. Não terás medo da face do homem, pois o julgamento é de Deus. O caso que for muito difícil para você, você me trará, e eu o ouvirei”.
18 Nígbà náà ni èmi yóò sọ ohun tí ẹ ó ṣe fún un yín.
Eu lhe ordenei naquela época todas as coisas que você deve fazer”.
19 Nígbà náà ní a gbéra láti Horebu, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wá, a sì la àwọn ilẹ̀ lókè Amori kọjá lọ dé gbogbo aginjù ńlá tí ó ba ni lẹ́rù nì tí ẹ̀yin ti rí, bẹ́ẹ̀ ni a sì dé Kadeṣi-Barnea.
Viajamos de Horeb e passamos por todo aquele grande e terrível deserto que você viu, pelo caminho para o país montanhoso dos Amoritas, como Javé nosso Deus nos ordenou; e viemos para Kadesh Barnea.
20 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ ti dé ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, èyí tí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.
Eu lhes disse: “Vocês vieram à região montanhosa dos amorreus, que Javé, nosso Deus, nos dá.
21 Ẹ kíyèsi i, Olúwa Ọlọ́run yín ló ni ilẹ̀ náà. Ẹ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín tí sọ fún un yín. Ẹ má bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà.”
Eis que Yahweh, nosso Deus, colocou a terra diante de vocês. Suba, tome posse, como Javé, o Deus de seus pais, falou com você. Não tenha medo, nem se desespere”.
22 Nígbà náà ni gbogbo yín tọ̀ mí wá wí pé, “Jẹ́ kí a yan àwọn ayọ́lẹ̀wò láti yọ́ ilẹ̀ náà wò fún wa, kí wọn sì fún wa ní ìròyìn àwọn ọ̀nà tí a ó gbà àti àwọn ìlú tí a ó bá pàdé.”
Vocês se aproximaram de mim, todos vocês, e disseram: “Vamos enviar homens diante de nós, para que eles possam procurar por nós na terra e trazer-nos notícias sobre o caminho pelo qual devemos subir, e as cidades para onde devemos ir”.
23 Èrò náà sì dára lójú mi, torí èyí ni mo ṣe yan àwọn ènìyàn méjìlá nínú yín, ẹnìkan láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
A coisa me agradou bem. Levei doze de seus homens, um homem para cada tribo.
24 Wọ́n sì gòkè lọ sí ilẹ̀ òkè náà, wọ́n sì wá sí àfonífojì Eṣkolu, wọ́n sì yẹ̀ ẹ́ wò.
Eles se viraram e subiram para a região montanhosa, chegaram ao vale de Eshcol e o espiaram.
25 Wọ́n sì mú lára èso ilẹ̀ náà wá fún wa pé, “Ilẹ̀ tí ó dára ni Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
Eles pegaram alguns dos frutos da terra em suas mãos e trouxeram-nos para baixo, trouxeram-nos notícias novamente, e disseram: “É uma boa terra que Yahweh nosso Deus nos dá”.
26 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́ gòkè lọ; ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín.
No entanto, você não subiria, mas se rebelou contra o mandamento de Yahweh, seu Deus.
27 Ẹ kùn nínú àgọ́ ọ yín, ẹ sì wí pé, “Olúwa kórìíra wa, torí èyí ló fi mú wa jáde láti Ejibiti láti fi wá lé àwọn ará Amori lọ́wọ́ láti pa wá run.
Você murmurou em suas tendas, e disse: “Porque Javé nos odiava, ele nos tirou da terra do Egito, para nos entregar nas mãos dos amorreus para nos destruir”.
28 Níbo la ó lọ? Àwọn arákùnrin wa ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wa nípa sísọ pé, ‘Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga jù wá lọ; àwọn ìlú náà tóbi jọjọ bẹ́ẹ̀ ni odi wọn ga kan ọ̀run. A tilẹ̀ rí àwọn òmíràn (ìran Anaki) níbẹ̀.’”
Aonde vamos subir? Nossos irmãos fizeram nosso coração derreter, dizendo: “O povo é maior e mais alto do que nós”. As cidades são grandes e fortificadas até o céu”. Além disso, vimos lá os filhos dos Anakim””.
29 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ má ṣojo, ẹ kò sì gbọdọ̀ bẹ̀rù wọn.
Então eu lhe disse: “Não fique aterrorizado. Não tenha medo deles”.
30 Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń ṣáájú yín yóò jà fún un yín; bí ó ti ṣe fún un yín ní Ejibiti lójú ẹ̀yin tìkára yín
Yahweh seu Deus, que vai antes de você, ele lutará por você, de acordo com tudo o que ele fez por você no Egito diante de seus olhos,
31 àti ní aginjù. Níbẹ̀ ni ẹ ti rí i bí Olúwa Ọlọ́run yín ti gbé yín, bí baba ti í gbé ọmọ rẹ̀, ní gbogbo ọ̀nà tí ẹ lọ títí ẹ fi padà dé ibí yìí.”
e no deserto onde você viu como aquele Yahweh seu Deus o carregou, como um homem carrega seu filho, em todo o caminho que você percorreu, até chegar a este lugar”.
32 Pẹ̀lú gbogbo èyí tí mo wí, ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín,
No entanto, nesta coisa você não acreditava em Yahweh seu Deus,
33 tí ń ṣáájú u yín lọ ní gbogbo ọ̀nà yín, nípa fífi iná ṣe amọ̀nà yín ní òru àti ìkùùkuu ní ọ̀sán, láti fi àwọn ibi tí ẹ lè tẹ̀dó sí hàn yín àti àwọn ọ̀nà tí ẹ ó rìn.
que foi antes de você no caminho, para procurar um lugar para você armar suas tendas: no fogo à noite, para mostrar-lhe por que caminho você deve ir, e na nuvem de dia.
34 Nígbà tí Olúwa gbọ́ ohun tí ẹ sọ, inú bí i, ó sì búra wí pé,
Javé ouviu a voz de suas palavras e se indignou, e jurou, dizendo:
35 “Kò sí ọ̀kan nínú ìran búburú yìí tí yóò dé ilẹ̀ rere tí mo ti búra láti fún àwọn baba ńlá a yín.
“Certamente nenhum destes homens desta geração má verá a terra boa que jurei dar a seus pais,
36 Bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne. Òun ni yóò wọ̀ ọ́. Èmi yóò sì fún òun àti àwọn ìran rẹ̀ ní ilẹ̀ náà tí ó ti fi ẹsẹ̀ rẹ̀ tẹ̀; torí pé ó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ tẹ̀lé Olúwa.”
exceto Caleb, o filho de Jefoné. Ele a verá. Eu darei a ele e a seus filhos a terra que ele pisou, porque ele seguiu totalmente Yahweh”.
37 Torí i tiyín ni Olúwa fi bínú sí mi wí pé, “Ìwọ náà kì yóò wọ ibẹ̀ bákan náà,
Também Yahweh ficou zangado comigo por sua causa, dizendo: “Você também não deve entrar ali”.
38 ṣùgbọ́n Joṣua ọmọ Nuni tí ń ṣe olùrànlọ́wọ́ rẹ ni yóò wọ ibẹ̀. Mú un, ní ọkàn le torí pé, òun yóò ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli láti gba ilẹ̀ náà.
Josué, o filho de Freira, que está diante de você, deve entrar ali. Encoraje-o, pois ele fará Israel herdá-la.
39 Àwọn èwe yín tí ẹ sọ pé wọn yóò kó lẹ́rú. Àwọn ọmọ yín tí ko tí ì mọ rere yàtọ̀ sí búburú ni yóò wọ ilẹ̀ náà.
Além disso, seus filhinhos, que você disse que seriam capturados ou mortos, seus filhos, que hoje não têm conhecimento do bem ou do mal, entrarão ali. Eu lhes darei, e eles o possuirão.
40 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, ẹ yí padà sí aginjù tí ó wà ní ọ̀nà tí ó lọ sí Òkun Pupa.”
Mas quanto a você, vire-se, e faça sua viagem ao deserto pelo caminho do Mar Vermelho”.
41 Nígbà náà ni ẹ fèsì wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa. A ó sì gòkè lọ láti jà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wa.” Torí náà gbogbo yín ẹ mú ohun ìjà a yín, ẹ rò pé ó rọrùn láti gòkè lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè náà.
Então você respondeu e me disse: “Pecamos contra Yahweh”. Vamos subir e lutar, de acordo com tudo o que Javé, nosso Deus, nos ordenou”. Cada um de vocês colocou suas armas de guerra, e presumiu ir para o país das colinas.
42 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ fún wọn, ‘Ẹ má ṣe gòkè lọ láti jà torí pé èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín. Àwọn ọ̀tá a yín yóò sì ṣẹ́gun yín.’”
Yahweh disse-me: “Diga-lhes: 'Não subam e não lutem; pois não estou entre vocês, para que não sejam atingidos diante de seus inimigos'”.
43 Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbọ́, ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa, pẹ̀lú ìgbéraga yín, ẹ gòkè lọ sí ìlú olókè náà.
Então eu falei com você, e você não me ouviu; mas você se rebelou contra o mandamento de Javé, e foi presunçoso, e subiu para o país das colinas.
44 Àwọn ará Amori tí ń gbé ní àwọn òkè náà, dojúkọ yín bí àgbájọpọ̀ oyin. Wọ́n sì lù yín bolẹ̀ láti Seiri títí dé Horma.
Os amoritas, que viviam naquela região montanhosa, saíram contra vocês e os perseguiram como abelhas, e os espancaram em Seir, até mesmo a Hormah.
45 Ẹ padà, ẹ sì sọkún níwájú Olúwa, òun kò sì fetí sí igbe ẹkún yín, Ó sì kọ etí dídi sí i yín.
Você voltou e chorou antes de Javé, mas Javé não ouviu sua voz, nem virou seu ouvido para você.
46 Báyìí ni ẹ sì dúró ní Kadeṣi fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ṣe.
Então você ficou muitos dias em Kadesh, de acordo com os dias que você permaneceu.

< Deuteronomy 1 >