< Deuteronomy 1 >
1 Wọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Mose sọ fún gbogbo Israẹli ní aginjù, aginjù ìlà-oòrùn Jordani, ni Arabah, ní òdìkejì Ṣufi, ní àárín Parani àti Tofeli, Labani, Haserotu àti Disahabu.
In this book is written what Moses/I said to the Israeli people. He/I told them these things when they/we were in the desert, on the east side of the Jordan [River]. They/We had set up our tents near [a place named] Suph, between Paran [town on the one side of the river] and Tophel, Laban, Hazeroth, and Dizahab [towns on the other side of the river].
2 (Ọjọ́ mọ́kànlá ni ó gbà láti rin ìrìnàjò láti Horebu dé Kadeṣi-Barnea, bí a bá gba ọ̀nà òkè Seiri.)
To walk from Sinai [Mountain] to the Kadesh-Barnea [oasis], people usually travel for only eleven days, going by way of the hilly area named Edom.
3 Ní ìgbà tí ó pé ogójì ọdún, ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kọ́kànlá, Mose sọ ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ nípa àwọn ọmọ Israẹli fún wọn.
Forty years after (the Israelis/we) left Egypt, in the middle of January, Moses/I told the Israeli people everything that Yahweh had commanded him/me to tell them.
4 Èyí ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣẹ́gun Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani ni ó ṣẹ́gun ní Edrei, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu.
This was after they/we had defeated Sihon, the king of the Amor people-group, who lived in Heshbon [city], and Og, the king of the Bashan [region] who lived in Ashtaroth and Edrei [towns].
5 Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani tí ó wà nínú ilẹ̀ Moabu ni Mose bẹ̀rẹ̀ sísọ àsọyé òfin wọ̀nyí wí pé:
Moses/I told them these things while the people were in the Moab region, on the east side of the Jordan [River]. He/I (explained to them/enabled them to understand) God’s laws. This is what he/I said to them:
6 Olúwa Ọlọ́run wa bá wa sọ̀rọ̀ ní Horebu pé, “Ẹ ti dúró ní orí òkè yìí pẹ́ tó.
“Yahweh our God said to us when we were at Sinai [Mountain], ‘You have stayed for a very long time at [the bottom of] this mountain.
7 Ẹ yípadà kí ẹ sì tẹ̀síwájú ní ìrìnàjò yín lọ sí ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, ẹ tọ gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń gbé Arabah lọ ní aginjù, ní àwọn orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀, ní gúúsù àti ní etí Òkun, lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani àti lọ sí Lebanoni, títí fi dé odò ńlá Eufurate.
So now continue traveling. Go to the hilly area where the Amor people-group lives and to the nearby areas—to the Jordan [River] Valley, to the hilly region, to the western (foothills/hills at the bottom of the mountains), to the desert area to the south, to the [Mediterranean] Seacoast, to all of Canaan land, to the Lebanon [Mountains], and [northeast] to the great Euphrates River.
8 Wò ó, èmi tí fi ilẹ̀ yí fún un yín, ẹ wọ inú rẹ̀ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí Olúwa ti búra wí pé òun yóò fún àwọn baba yín: fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu, àti fún àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn.”
Note that I will give that land to you. I, Yahweh, promised to your ancestors Abraham and Isaac and Jacob that I would give it to them and to their descendants. So now go and occupy it.’”
9 Mo wí fún un yín nígbà náà pé, “Èmi nìkan kò lè dá ẹrù u yín gbé.
Moses/I also said to the people, “When [we were still at Sinai Mountain], I told your ancestors ‘It is a very big burden/responsibility for me to govern all of you. So I cannot do it by myself.
10 Olúwa Ọlọ́run yín ti sọ yín di púpọ̀ lónìí, ẹ̀yin sì ti pọ̀ bí ìràwọ̀ ní ojú ọ̀run.
Yahweh our God has caused us Israelis to now become as numerous as the stars in the sky.
11 Kí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín sọ yín di púpọ̀ ní ọ̀nà ẹgbẹ̀rún sí i, kí ó sì bùkún un yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
And I hope/desire that Yahweh, the God whom our ancestors [worshiped], will cause us to become 1,000 times as numerous as we are now and that he will bless us just like he promised to do.
12 Báwo ni èmi nìkan ṣe lè máa ru àjàgà àti ìṣòro yín àti èdè-àìyedè yín?
But I certainly cannot [RHQ] (solve/deal with) all of your complaints/problems.
13 Ẹ yan àwọn ọlọ́gbọ́n, olóye àti àwọn ẹni àpọ́nlé, láti inú ẹ̀yà yín kọ̀ọ̀kan, èmi yóò sì fi wọ́n ṣe olórí yín.”
So choose some men from your tribes who are wise and who have good sense and who are respected. Then I will appoint them to be your leaders.’
14 Ẹ̀yin sì dá mi lóhùn wí pé, “Ohun tí ìwọ ti gbèrò láti ṣe nì dára.”
Your ancestors replied, ‘What you have suggested is good for us to do.’
15 Bẹ́ẹ̀ ni mo yan olórí àwọn ẹ̀yà yín, àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin, ẹni àpọ́nlé, mo sì fi jẹ olórí yín, olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà yín.
So I took the wise and respected men [that your ancestors chose] from your tribes, and I appointed them to be your leaders. I appointed some to (rule/have authority) over 1,000 people, some to have authority over 100 people, some to have authority over 50 people, and some to have authority over ten people. I also appointed other officers from throughout your tribes.
16 Mo sì kìlọ̀ fún àwọn onídàájọ́ yín nígbà náà pé, ẹ gbọ́ èdè-àìyedè tí ó wà láàrín àwọn ènìyàn an yín kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ òdodo, bóyá ẹjọ́ tí ó ṣẹlẹ̀ láàrín Israẹli sí Israẹli ni tàbí láàrín Israẹli kan sí àlejò.
I instructed/told your leaders, ‘Listen to the disputes that occur among your people. Judge each dispute, including disputes between close relatives and quarrels between your people and people from other countries who live among you.
17 Ẹ má sì ṣe ojúsàájú ní ìdájọ́. Ẹ ṣe ìdájọ́ ẹni ńlá àti kékeré bákan náà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹnikẹ́ni torí pé ti Ọlọ́run ni ìdájọ́. Ẹjọ́ tí ó bá le jù fún un yín ni kí ẹ mú wá fún mi. Èmi yóò sì gbọ́ ọ.
You must (be impartial/not favor one person more than another); you must treat poor people and important people equally. You must not worry about what anyone will think [about how you decide matters], because you will decide matters as God [wants you to]. If any quarrel/dispute is very difficult and you are unable to decide it, bring it to me, and I will decide.’
18 Nígbà náà ni èmi yóò sọ ohun tí ẹ ó ṣe fún un yín.
At that time I also told you other things that you should do.”
19 Nígbà náà ní a gbéra láti Horebu, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wá, a sì la àwọn ilẹ̀ lókè Amori kọjá lọ dé gbogbo aginjù ńlá tí ó ba ni lẹ́rù nì tí ẹ̀yin ti rí, bẹ́ẹ̀ ni a sì dé Kadeṣi-Barnea.
“Then, just like Yahweh our God commanded us, we left Sinai [Mountain] and went through that huge desert that was very (dangerous/difficult to travel through), on the road to the hilly area where the Amor people-group live. We arrived at Kadesh-Barnea.
20 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ ti dé ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, èyí tí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.
I said to your ancestors, ‘We have now come to the hilly area where the Amor people-group live. This is part of the area that Yahweh our God, the one whom our ancestors [worshiped], is giving to us.
21 Ẹ kíyèsi i, Olúwa Ọlọ́run yín ló ni ilẹ̀ náà. Ẹ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín tí sọ fún un yín. Ẹ má bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà.”
Note that Yahweh our God is giving this land to us. So go and occupy it as he commanded. Do not be (at all/even a little bit) afraid.’
22 Nígbà náà ni gbogbo yín tọ̀ mí wá wí pé, “Jẹ́ kí a yan àwọn ayọ́lẹ̀wò láti yọ́ ilẹ̀ náà wò fún wa, kí wọn sì fún wa ní ìròyìn àwọn ọ̀nà tí a ó gbà àti àwọn ìlú tí a ó bá pàdé.”
But all of your ancestors came to me and said, ‘Before we go, we should [first] send some men there to explore the land, in order that they can return and tell us which will be the best road to go there and what kind of towns are there.’
23 Èrò náà sì dára lójú mi, torí èyí ni mo ṣe yan àwọn ènìyàn méjìlá nínú yín, ẹnìkan láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
I thought that it would be good to do that, so I chose twelve men, one man from each tribe.
24 Wọ́n sì gòkè lọ sí ilẹ̀ òkè náà, wọ́n sì wá sí àfonífojì Eṣkolu, wọ́n sì yẹ̀ ẹ́ wò.
They went up into the hilly area as far as Eshcol Valley, and they explored all that area.
25 Wọ́n sì mú lára èso ilẹ̀ náà wá fún wa pé, “Ilẹ̀ tí ó dára ni Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
They picked some of the fruit that they found there and brought it to us. They reported that the land that Yahweh our God was giving to us is very good/fertile.”
26 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́ gòkè lọ; ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín.
“But your ancestors refused to go [and conquer that land]. They rebelled against what Yahweh our God had commanded them to do, and they would not go into that land.
27 Ẹ kùn nínú àgọ́ ọ yín, ẹ sì wí pé, “Olúwa kórìíra wa, torí èyí ló fi mú wa jáde láti Ejibiti láti fi wá lé àwọn ará Amori lọ́wọ́ láti pa wá run.
Your ancestors [stayed] in their tents and complained saying ‘Yahweh hates us. So he has brought us here from Egypt just to allow the Amor people-group to destroy us.
28 Níbo la ó lọ? Àwọn arákùnrin wa ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wa nípa sísọ pé, ‘Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga jù wá lọ; àwọn ìlú náà tóbi jọjọ bẹ́ẹ̀ ni odi wọn ga kan ọ̀run. A tilẹ̀ rí àwọn òmíràn (ìran Anaki) níbẹ̀.’”
(Why should we go there?/We do not want to go there.) [RHQ] The men whom we sent there have caused us to become very discouraged/afraid. They have told us that the people there are much stronger and taller than we are and that there are extremely high [HYP] walls around their towns. Also they reported that they saw [giants there that are] descendants of Anak.’
29 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ má ṣojo, ẹ kò sì gbọdọ̀ bẹ̀rù wọn.
Then I said to your ancestors, ‘Do not be afraid (at all/even a little bit) [DOU] of those people!
30 Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń ṣáájú yín yóò jà fún un yín; bí ó ti ṣe fún un yín ní Ejibiti lójú ẹ̀yin tìkára yín
Yahweh our God will go ahead of you, and he will fight for you, just like you saw him do for you in Egypt
31 àti ní aginjù. Níbẹ̀ ni ẹ ti rí i bí Olúwa Ọlọ́run yín ti gbé yín, bí baba ti í gbé ọmọ rẹ̀, ní gbogbo ọ̀nà tí ẹ lọ títí ẹ fi padà dé ibí yìí.”
and in the desert. You saw how he brought you safely here, like a man would carry his son. [SIM]’
32 Pẹ̀lú gbogbo èyí tí mo wí, ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín,
[I reminded them that] he always went ahead of them while they traveled [in the desert]. He directed them by [a pillar of] fire during the night and a [pillar of] cloud during the day. He showed them places to set up their tents. But in spite of what I said, your ancestors would not trust Yahweh our God.
33 tí ń ṣáájú u yín lọ ní gbogbo ọ̀nà yín, nípa fífi iná ṣe amọ̀nà yín ní òru àti ìkùùkuu ní ọ̀sán, láti fi àwọn ibi tí ẹ lè tẹ̀dó sí hàn yín àti àwọn ọ̀nà tí ẹ ó rìn.
34 Nígbà tí Olúwa gbọ́ ohun tí ẹ sọ, inú bí i, ó sì búra wí pé,
Yahweh heard what they said, and he became angry. He solemnly declared,
35 “Kò sí ọ̀kan nínú ìran búburú yìí tí yóò dé ilẹ̀ rere tí mo ti búra láti fún àwọn baba ńlá a yín.
‘Caleb, the son of Jephunneh, will enter the land. He has obeyed me completely. So I will give to him and to his descendants [some of] the land that he explored. He is the only one of all you people who will enter that land. None of these evil people will ever see that good land which I solemnly promised to give to your ancestors.’
36 Bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne. Òun ni yóò wọ̀ ọ́. Èmi yóò sì fún òun àti àwọn ìran rẹ̀ ní ilẹ̀ náà tí ó ti fi ẹsẹ̀ rẹ̀ tẹ̀; torí pé ó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ tẹ̀lé Olúwa.”
37 Torí i tiyín ni Olúwa fi bínú sí mi wí pé, “Ìwọ náà kì yóò wọ ibẹ̀ bákan náà,
But because of [what] your ancestors [did], Yahweh was also angry with me. He said to me, ‘You also will not enter that land.
38 ṣùgbọ́n Joṣua ọmọ Nuni tí ń ṣe olùrànlọ́wọ́ rẹ ni yóò wọ ibẹ̀. Mú un, ní ọkàn le torí pé, òun yóò ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli láti gba ilẹ̀ náà.
Joshua, the son of Nun, who is your helper, will enter it. Encourage him, because he is the one who will enable you Israeli people to occupy that land.’
39 Àwọn èwe yín tí ẹ sọ pé wọn yóò kó lẹ́rú. Àwọn ọmọ yín tí ko tí ì mọ rere yàtọ̀ sí búburú ni yóò wọ ilẹ̀ náà.
Then Yahweh said to all of us, ‘You said that your children would be captured by your enemies. Because they are very young, they do not yet know what is good and what is evil. But they are the ones to whom I will give that land, and they will enter it and occupy it.
40 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, ẹ yí padà sí aginjù tí ó wà ní ọ̀nà tí ó lọ sí Òkun Pupa.”
But as for you, turn around and go back into the desert, toward the (Red Sea/Gulf of Aqaba).’
41 Nígbà náà ni ẹ fèsì wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa. A ó sì gòkè lọ láti jà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wa.” Torí náà gbogbo yín ẹ mú ohun ìjà a yín, ẹ rò pé ó rọrùn láti gòkè lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè náà.
Then your ancestors replied, ‘We have sinned; we have disobeyed Yahweh. So we will go and attack [the people who live in] that land, just like Yahweh our God commanded us to do.’ And each of their men put on his weapons, and they thought that it would be easy to invade the hilly region.
42 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ fún wọn, ‘Ẹ má ṣe gòkè lọ láti jà torí pé èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín. Àwọn ọ̀tá a yín yóò sì ṣẹ́gun yín.’”
But Yahweh said to me, ‘Tell them, “Do not go up there and attack those people, because I will not go with you. If you go, your enemies will defeat you.”’
43 Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbọ́, ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa, pẹ̀lú ìgbéraga yín, ẹ gòkè lọ sí ìlú olókè náà.
So I told that to your ancestors, but they would not heed what I said. They [again] rebelled against what Yahweh commanded them to do. Their soldiers proudly/arrogantly marched up into that hilly region.
44 Àwọn ará Amori tí ń gbé ní àwọn òkè náà, dojúkọ yín bí àgbájọpọ̀ oyin. Wọ́n sì lù yín bolẹ̀ láti Seiri títí dé Horma.
Then the men of the Amor people-group who lived in that region came out [of their towns] and attacked those soldiers. They pursued your ancestors’ soldiers like [a swarm of] bees pursues people, and they pursued them [south] from the Edom area and defeated them at Hormah [city].
45 Ẹ padà, ẹ sì sọkún níwájú Olúwa, òun kò sì fetí sí igbe ẹkún yín, Ó sì kọ etí dídi sí i yín.
So your ancestors went back [to Kadesh-Barnea] and cried out to request Yahweh [to help them], but he did not heed them. He did not pay any attention to them [DOU].
46 Báyìí ni ẹ sì dúró ní Kadeṣi fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ṣe.
So we stayed there at Kadesh-Barnea for a long time.”