< Daniel 1 >

1 Ní ọdún kẹta tí Jehoiakimu jẹ ọba Juda, Nebukadnessari ọba Babeli wá sí Jerusalẹmu, ó sì kọlù ú pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
Harmadik évében Jehójákím Jehúda királya királyságának, Jeruzsálem ellen jött Nebúkadnecczár, Bábel királya s ostromolta azt.
2 Olúwa sì fa Jehoiakimu ọba Juda lé e lọ́wọ́, pẹ̀lú àwọn ohun èlò ilé Ọlọ́run. Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó kó lọ sí ilé òrìṣà ní Babeli, sí inú ilé ìṣúra òrìṣà rẹ̀.
S kezébe adta az Úr Jehójákimot, Jehúda királyát, meg egy részét az Isten háza edényeinek s elvitte őket Síneár országába az ő istenének házába, az edényeket pedig bevitte istenének kincses házába.
3 Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Aṣipenasi, olórí àwọn ìwẹ̀fà ààfin rẹ̀ pé, kí ó mú nínú àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n wá láti ìdílé ọba àti lára àwọn tí ó wá láti ilé ọlá.
És mondta a király Aspenáznak, udvari tisztjei fejének, hogy hozzon Izraél fiai közül és pedig a királyi nemzetségből és a főnemesek közül
4 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí kò ní àbùkù ara, tí wọ́n rẹwà, tí wọ́n sì fi ìfẹ́ sí ẹ̀kọ́ hàn, tí wọ́n sì ní ìmọ̀, tí òye tètè ń yé àti àwọn tí ó kún ojú òsùwọ̀n láti ṣiṣẹ́ ní ààfin ọba kí ó kọ́ wọ́n ní èdè àti onírúurú ẹ̀kọ́ ìwé ti àwọn Babeli.
fiúkat, a kikben nincs semmi hiba s a kik szép ábrázatuak és eszesek minden bölcseségben, ismernek tudást és értenek tudományt, kikben van erő, hogy álljanak a király palotájában és hogy tanítsák őket könyvre és a kaldeusok nyelvére.
5 Ọba pèsè oúnjẹ ojoojúmọ́ àti wáìnì láti orí tábìlì i rẹ̀ fún wọn, ó sì kọ́ wọn fún ọdún mẹ́ta. Lẹ́yìn náà ni wọn yóò bẹ̀rẹ̀ sí í ṣiṣẹ́ fún ọba.
És kirendelte számukra a király a minden napra valót annak napján a király ételéből s az ő ivó borából, s hogy neveljék őket három évig; azoknak végén pedig álljanak a király előtt.
6 Lára àwọn wọ̀nyí ni àwọn tó wá láti Juda: Daniẹli, Hananiah, Miṣaeli àti Asariah.
És voltak köztük Jehúda fiaiból: Dániél, Chananja, Mísáél és Azarja.
7 Olórí àwọn ìwẹ̀fà fún wọn ní orúkọ tuntun: Ó fún Daniẹli ní Belteṣassari, ó fún Hananiah ní Ṣadraki, ó fún Miṣaeli ní Meṣaki àti Asariah ní Abednego.
S adott nekik neveket az udvari tisztek nagyja; Dániélnek ezt a nevet adta: Béltsacczár, Chananjának Sadrák, Misáélnek Mésák és Azarjának Abéd-Negó.
8 Ṣùgbọ́n Daniẹli pinnu ní ọkàn ara rẹ̀ pé òun kò ní ba ara òun jẹ́ pẹ̀lú oúnjẹ àti wáìnì ọba, nígbà náà ni ó gba ààyè lọ́wọ́ olórí àwọn ìwẹ̀fà wí pé òun kò fẹ́ ba ara òun jẹ́ ní ọ̀nà yìí.
És föltette Dániél a szivében, hogy nem fertőzteti meg magát a király ételével és ivó borával; kérte tehát az udvari tisztek nagyjától, hogy ne kelljen magát megfertőztetnie.
9 Ọlọ́run mú kí Daniẹli rí ojúrere àti àánú gbà láti ọwọ́ olórí àwọn ìwẹ̀fà,
És adta az Isten Dániélt kegyre és irgalomra az udvari tisztek nagyja előtt.
10 ṣùgbọ́n olórí àwọn ìwẹ̀fà sọ fún Daniẹli pé, “Mo bẹ̀rù olúwa mi, ẹni tí o ti pèsè oúnjẹ àti ohun mímu rẹ. Báwo ni ìrísí rẹ yóò ṣe burú jù ti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ẹlẹgbẹ́ ẹ̀ rẹ lọ? Nígbà náà ni èmi yóò fi orí mi wéwu lọ́dọ̀ ọba.”
És mondta az udvari tisztek nagyja Daniélnek: Félek én uramtól a királytól, aki kirendelte evésteket és ivástokat, hogy miért lássa arczotokat kedvetlenebbnek a veletek egyivásu fiúkénál s főbenjáró bűnbe vinnétek a királynál?
11 Nígbà náà ni Daniẹli sọ fún olùṣọ́ tí olórí àwọn ìwẹ̀fà yàn lórí i Daniẹli, Hananiah, Miṣaeli àti Asariah pé,
Erre szólt Dániél a kamarásnak, a kit az udvari tisztek nagyja kirendelt Dániél, Chananja, Mísáél és Azarja fölé:
12 “Jọ̀wọ́ dán àwa ìránṣẹ́ rẹ wò fún ọjọ́ mẹ́wàá. Má ṣe fún wa ní ohun kankan, àfi ewébẹ̀ láti jẹ àti omi láti mu.
Kiséreld csak meg szolgáidat tíz napig, hadd adjanak nekünk a veteményekből, hogy együnk és vizet, hogy igyunk;
13 Nígbà náà ni kí o fi ìrísí i wa wé ti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí wọ́n ń jẹ oúnjẹ ọba, kí o sì ṣe àwa ìránṣẹ́ rẹ ní ìbámu pẹ̀lú u bí o bá ṣe rí i sí.”
s majd meglátszik előtted a mi ábrázatunk és azon fiúk ábrázata, a kik a király ételét eszik és a szerint, a mit látni fogsz, cselekedjél szolgáiddal.
14 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì gbà láti dán wọn wò fún ọjọ́ mẹ́wàá.
És hallgatott rájuk e dologban s megkisérlette őket tíz napig.
15 Lẹ́yìn ọjọ́ kẹwàá ara wọn le, wọ́n sì sanra ju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí wọ́n ń jẹ oúnjẹ ọba lọ.
Tíz nap végén pedig ábrázatuk jobbnak látszott és husban kövérebbek voltak, mint mindazon fiúk, kik a király ételét ették.
16 Bẹ́ẹ̀ ni olùṣọ́ mú oúnjẹ àdídùn àti wáìnì tí ó yẹ kí wọ́n mu kúrò, ó sì fún wọn ní ewébẹ̀ dípò rẹ̀.
És a kamarás el szokta hordani ételüket és ivó borukat s adott nekik veteményeket.
17 Ọlọ́run fún àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọ̀nyí ní ìmọ̀ àti òye nínú gbogbo onírúurú ìwé àti ẹ̀kọ́ ọ wọn: Daniẹli sì ní òye ìran àti àlá ní oríṣìíríṣìí.
E fiúknak pedig mindnégyüknek adott az Isten tudást és belátást minden könyvben és bölcseségben; Dániél pedig értett minden látomáshoz és álomhoz.
18 Ní òpin ìgbà tí ọba dá, pé kí a mú wọn wá sínú ààfin, olórí àwọn ìwẹ̀fà mú wọn wá síwájú ọba Nebukadnessari.
És azon napok végén, a mikorra mondta a király, hogy elhozzák őket, bevitte őket az udvari tisztek nagyja Nebúkadnecczár szine elé.
19 Ọba sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì rí i pé kò sí ẹni tí ó dàbí i Daniẹli, Hananiah, Miṣaeli àti Asariah; nítorí náà wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣe iṣẹ́ ọba.
És beszélt velök a király, és nem találtatott valamennyiök közül olyan, mint Dániél, Chananja, Mísáél és Azarja; és álltak a király előtt.
20 Nínú gbogbo ọ̀ràn ọgbọ́n àti òye tí ọba ń béèrè lọ́wọ́ wọn, ó rí i pé wọ́n sàn ní ìlọ́po mẹ́wàá ju gbogbo àwọn amòye àti ọlọ́gbọ́n tí ó wà ní gbogbo ìjọba rẹ̀.
És a bölcseség és értelem minden dolgában, a mit kivánt tőlük a király, tízszerte kiválóbbaknak találta őket mindaz irástudóknál, a jósokná1, kik egész királyságában voltak.
21 Daniẹli sì wà níbẹ̀ títí di ọdún kìn-ín-ní ọba Kirusi.
És ott volt Dániél Kóres király első évéig.

< Daniel 1 >