< Daniel 9 >

1 Ní ọdún kìn-ín-ní Dariusi ọmọ Ahaswerusi, ẹni tí a bí ní Media, òun ló jẹ ọba lórí ìjọba Babeli.
În anul întâi al lui Darius fiul lui Ahașveroș, din sămânța mezilor, care a fost făcut împărat peste domeniul caldeenilor;
2 Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba rẹ̀, èmi Daniẹli fi iyè sí i láti inú ìwé, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí wòlíì Jeremiah, wá pé, àádọ́rin ọdún ni Jerusalẹmu yóò fi wà ní ahoro.
În anul întâi al domniei lui, eu, Daniel, am înțeles din cărți că numărul anilor pentru care fusese cuvântul DOMNULUI către profetul Ieremia, pentru împlinirea pustiirilor Ierusalimului, era șaptezeci de ani.
3 Nígbà náà, ni mo yípadà sí Olúwa Ọlọ́run, mo bẹ̀ ẹ́ pẹ̀lú àdúrà àti ẹ̀bẹ̀, pẹ̀lú àwẹ̀, aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú.
Și mi-am îndreptat fața către Domnul Dumnezeu, să caut prin rugăciune și cerere, cu postire și pânză de sac și cenușă.
4 Mo gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run mi, mo sì jẹ́wọ́ wí pé: “Ìwọ Olúwa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó ní ìfẹ́ rẹ̀ àti àwọn tí ó ń pa àwọn òfin rẹ̀ mọ́.
Și m-am rugat DOMNULUI Dumnezeul meu și am mărturisit și am spus: Doamne, marele și înfricoșătorul Dumnezeu, ce ține legământul și mila pentru cei ce îl iubesc și pentru cei ce țin poruncile lui;
5 Àwa ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú. Àwa ti hu ìwà búburú, a sì ti ṣe ọ̀tẹ̀, a ti yí padà kúrò nínú àwọn àṣẹ àti àwọn ìlànà rẹ̀.
Noi am păcătuit și am făcut nelegiuire și ne-am purtat cu stricăciune și ne-am răzvrătit, prin îndepărtarea de preceptele tale și de judecățile tale;
6 Àwa kò fetí sí àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ, ẹni tí ó sọ̀rọ̀ ní orúkọ rẹ sí àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé àti àwọn baba wa, àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà.
Și nu am dat ascultare servitorilor tăi profeții, care au vorbit în numele tău împăraților noștri, prinților noștri și părinților noștri și întregului popor al țării.
7 “Olúwa ìwọ ni olódodo, ṣùgbọ́n báyìí ìtìjú dé bá àwọn ènìyàn Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu àti gbogbo Israẹli ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti fọ́n wa ká sí nítorí àìṣòótọ́ ọ wa sí ọ.
A ta, Doamne, [este] dreptatea iar a noastră [este] rușinea fețelor, ca în această zi; bărbaților din Iuda și locuitorilor Ierusalimului și întregului Israel, [care sunt] aproape și [care sunt] departe, prin toate țările unde i-ai alungat din cauza fărădelegii lor prin care au încălcat legea împotriva ta.
8 Háà! Olúwa, àwa àti àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé, àti àwọn baba wa, ìtìjú dé bá wa nítorí àwa ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ.
Doamne, a noastră [este] rușinea feței, a împăraților noștri, a prinților noștri și a părinților noștri, deoarece am încălcat [legea] împotriva ta.
9 Olúwa Ọlọ́run wa ní àánú, ó sì ń dáríjì, bí àwa tilẹ̀ ti ṣe ọ̀tẹ̀ sí i;
La Domnul Dumnezeul nostru [sunt] îndurări și iertări, cu toate că ne-am răzvrătit împotriva lui;
10 àwa kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, a kò sì pa àwọn òfin rẹ mọ́, èyí tí ó fún wa nípasẹ̀ àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
Și nu am ascultat de vocea DOMNULUI Dumnezeul nostru, să umblăm în legile lui, pe care le-a pus înaintea servitorilor lui, profeții.
11 Gbogbo Israẹli ti ṣẹ̀ sí òfin rẹ, wọ́n ti yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, wọ́n kọ̀ láti ṣe ìgbọ́ràn sí ọ. “Nígbà náà ni ègún àti ìdájọ́ tí a kọ sílẹ̀ pẹ̀lú ìbúra nínú òfin Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run dà sórí i wa, nítorí tí àwa ti sẹ̀ sí ọ.
Da, tot Israelul a încălcat legea ta, prin îndepărtare, ca să nu asculte de vocea ta; de aceea blestemul este turnat peste noi și jurământul care [este] scris în legea lui Moise servitorul lui Dumnezeu, deoarece am păcătuit împotriva lui [Dumnezeu].
12 Ìwọ ti mú ọ̀rọ̀ tí o sọ sí wa sẹ àti lórí àwọn alákòóso wa, nípa mímú kí ibi ńlá bá wa, irú èyí tí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí lábẹ́ ọ̀run, bí ó ti ṣẹlẹ̀ sí Jerusalẹmu yìí.
Și el a întărit cuvintele lui, pe care le-a vorbit împotriva noastră și împotriva judecătorilor noștri care ne-au judecat, aducând asupra noastră un mare rău, căci sub întreg cerul nu s-a făcut cum s-a făcut asupra Ierusalimului.
13 Bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Mose bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ibi yìí ti dé bá wa, síbẹ̀ a kò bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere Olúwa Ọlọ́run wa, nípa yíyí padà kí a kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wa kí a sì mọ òtítọ́ rẹ.
Precum [este] scris în legea lui Moise, tot acest rău a venit peste noi, totuși nu ne-am făcut rugăciunea înaintea DOMNULUI Dumnezeul nostru, ca să ne întoarcem de la nelegiuirile noastre și să înțelegem adevărul tău.
14 Olúwa kò jáfara láti mú ibi náà wá sórí wa, nítorí olódodo ni Olúwa Ọlọ́run wa nínú u gbogbo ohun tí ó ń ṣe; síbẹ̀ àwa kò ṣe ìgbọ́ràn sí i.
De aceea DOMNUL a vegheat asupra răului și l-a adus asupra noastră, fiindcă DOMNUL Dumnezeul nostru [este] drept în toate lucrările lui pe care le face, căci nu am ascultat de vocea lui.
15 “Ní ìsinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, pẹ̀lú ọwọ́ agbára, tí ó fún ara rẹ̀ ní orúkọ tí ó wà títí di òní, a ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú.
Și acum, Doamne Dumnezeul nostru, care ai scos poporul tău afară din țara Egiptului cu o mână puternică și ți-ai făcut renume, ca în această zi; noi am păcătuit, am lucrat cu stricăciune.
16 Olúwa, ní ìbámu pẹ̀lú ìwà òdodo rẹ, yí ìbínú àti ìrunú rẹ padà kúrò ní Jerusalẹmu ìlú u rẹ, òkè mímọ́ rẹ. Ẹ̀ṣẹ̀ wa àti àìṣedéédéé àwọn baba wa ti mú Jerusalẹmu àti ènìyàn rẹ di ẹ̀gàn fún gbogbo àwọn tí ó yí wọn ká.
Doamne, conform tuturor dreptăților tale, te implor, să fie mânia și furia ta întoarse de la cetatea ta Ierusalim, muntele tău sfânt, deoarece pentru păcatele noastre și pentru nelegiuirile părinților noștri, Ierusalimul și poporul tău [au ajuns să fie de] ocară pentru toți [cei] din jurul nostru.
17 “Nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, nítorí i tìrẹ Olúwa, fi ojú àánú wo ibi mímọ́ rẹ tí ó ti dahoro.
Acum, de aceea, Dumnezeul nostru, ascultă rugăciunea servitorului tău și cererile lui, și pentru Domnul fă să strălucească fața ta peste sanctuarul tău pustiu.
18 Tẹ́ etí rẹ sílẹ̀, Ọlọ́run, kí o gbọ́; ya ojú rẹ sílẹ̀, kí o sì wo ìdahoro ìlú tí a ń fi orúkọ rẹ pè. Àwa kò gbé ẹ̀bẹ̀ wa kalẹ̀ níwájú u rẹ nítorí pé a jẹ́ olódodo, bí kò ṣe nítorí àánú ńlá rẹ.
Dumnezeul meu, apleacă-ți urechea și ascultă; deschide-ți ochii și privește pustiirile noastre și cetatea chemată după numele tău, fiindcă noi nu prezentăm cererile noastre înaintea ta din cauza faptelor noastre drepte, ci din cauza îndurărilor tale mari.
19 Olúwa, fetísílẹ̀! Olúwa, dáríjì! Olúwa, gbọ́ kí o sì ṣe é! Nítorí i tìrẹ, Ọlọ́run mi, má ṣe pẹ́ títí, nítorí ìlú rẹ àti àwọn ènìyàn rẹ ń jẹ́ orúkọ mọ́ ọ lára.”
Doamne, ascultă; Doamne, iartă; Doamne, dă ascultare și lucrează; nu întârzia, pentru tine, Dumnezeul meu, fiindcă cetatea ta și poporul tău sunt chemați după numele tău.
20 Bí mo ṣe ń sọ̀rọ̀, tí mo sì ń gba àdúrà, tí mo ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi àti ẹ̀ṣẹ̀ àwọn Israẹli ènìyàn mi, tí mo sì ń mú ẹ̀bẹ̀ mi tọ Olúwa Ọlọ́run mi nítorí òkè mímọ́ rẹ.
Și în timp ce vorbeam și mă rugam și mărturiseam păcatul meu și păcatul poporului meu Israel și prezentam cererea mea înaintea DOMNULUI Dumnezeul meu pentru muntele sfânt al Dumnezeului meu;
21 Bí mo ṣe ń gba àdúrà náà lọ́wọ́, Gabrieli ọkùnrin tí mo rí nínú ìran ìṣáájú, yára kánkán wá sí ọ̀dọ̀ mi ní àkókò ẹbọ àṣálẹ́.
Da, în timp ce încă vorbeam în rugăciune, bărbatul Gabriel, pe care l-am văzut în viziunea de la început, fiindu-i [poruncit] să zboare iute, m-a atins pe la timpul ofrandei de seară.
22 Ó jẹ́ kí ó yé mi, ó sì wí fún mi pé, “Daniẹli, mo wá láti jẹ́ kí o mọ̀ kí o sì ní òye.
Și [mi-]a dat de înțeles și a vorbit cu mine și a spus: Daniele, am venit acum să îți dau pricepere și înțelegere.
23 Bí o ṣe bẹ̀rẹ̀ sí nígbà àdúrà, a fún ọ ní ìdáhùn kan, èyí tí mo wá láti sọ fún ọ, nítorí ìwọ jẹ́ àyànfẹ́ gidigidi. Nítorí náà, gba ọ̀rọ̀ náà yẹ̀ wò kí ìran náà sì yé ọ:
La începutul cererilor tale a ieșit porunca și am venit să [îți] arăt; fiindcă tu [ești] foarte mult iubit; de aceea înțelege acest lucru și ia aminte la viziune.
24 “Àádọ́rin ọ̀sẹ̀ ni a pàṣẹ fún àwọn ènìyàn rẹ àti fún àwọn ìlú mímọ́ rẹ láti parí ìrékọjá, láti fi òpin sí ẹ̀ṣẹ̀, láti ṣe ètùtù sí ìwà búburú, láti mú òdodo títí ayé wá, láti ṣe èdìdì ìran àti wòlíì àti láti fi òróró yan Ibi Mímọ́ Jùlọ.
Șaptezeci de săptămâni sunt hotărâte asupra poporului tău și asupra cetății tale sfinte, pentru a sfârși fărădelegea și pentru a pune capăt păcatelor și pentru a face împăcare pentru nelegiuire și pentru a aduce dreptatea veșnică și pentru a sigila viziunea și profeția și pentru a unge pe cel Preasfânt.
25 “Nítorí náà, mọ èyí pé, láti ìgbà tí a ti gbé ọ̀rọ̀ náà jáde wí pé kí a tún Jerusalẹmu ṣe, kí a sì tún kọ́, títí dé ìgbà ọmọ-aládé, ẹni òróró náà, alákòóso wa yóò fi dé, ó jẹ́ ọ̀sẹ̀ méje àti ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó sì tún ìgboro àti yàrá rẹ̀ mọ, ṣùgbọ́n ní àkókò wàhálà ni.
Să știi de aceea și să înțelegi, [că] de la ieșirea poruncii de a restaura și de a construi Ierusalimul până la Mesia Prințul [vor fi] șapte săptămâni și șaizeci și două de săptămâni; strada va fi construită din nou și zidul, chiar în timpuri de necaz.
26 Lẹ́yìn ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó ké Ẹni òróró náà kúrò, kò sì ní ní ohun kan. Àwọn ènìyàn ọmọ-aládé náà tí yóò wá ni yóò pa ìlú náà àti ibi mímọ́ run. Òpin yóò dé bí ìkún omi, ogun yóò máa jà títí dé òpin, a sì ti pàṣẹ ìdahoro.
Și după șaizeci și două de săptămâni Mesia va fi stârpit, dar nu pentru el însuși; și poporul prințului care va veni va distruge cetatea și sanctuarul; și sfârșitul lor [va fi] cu un potop și până la sfârșitul războiului, pustiiri sunt hotărâte.
27 Yóò sì fi ìdí i májẹ̀mú kan múlẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún ọ̀sẹ̀ kan. Ní àárín ọ̀sẹ̀ ni yóò mú òpin bá ẹbọ àti ọrẹ ẹbọ. Àti lórí apá kan ni yóò dà ìríra tí ó mú ìdahoro wá, títí tí òpin tí a ti pàṣẹ lórí asọnidahoro yóò fi padà fi dé bá a.”
Și el va confirma legământul cu mulți pentru o săptămână; și în mijlocul săptămânii el va face ca sacrificiul și ofranda să înceteze și din cauza împrăștierii urâciunilor [îl] va pustii, chiar până la mistuire și ce s-a hotărât se va turna peste cel pustiit.

< Daniel 9 >