< Daniel 9 >

1 Ní ọdún kìn-ín-ní Dariusi ọmọ Ahaswerusi, ẹni tí a bí ní Media, òun ló jẹ ọba lórí ìjọba Babeli.
La première année de Darius, fils d'Assuérus, de la descendance des Mèdes, qui fut établi roi sur le royaume des Chaldéens -
2 Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba rẹ̀, èmi Daniẹli fi iyè sí i láti inú ìwé, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí wòlíì Jeremiah, wá pé, àádọ́rin ọdún ni Jerusalẹmu yóò fi wà ní ahoro.
la première année de son règne, moi, Daniel, je compris par les livres le nombre des années au sujet desquelles la parole de Yahvé fut adressée à Jérémie, le prophète, pour l'accomplissement des désolations de Jérusalem, soit soixante-dix ans.
3 Nígbà náà, ni mo yípadà sí Olúwa Ọlọ́run, mo bẹ̀ ẹ́ pẹ̀lú àdúrà àti ẹ̀bẹ̀, pẹ̀lú àwẹ̀, aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú.
Je me suis tourné vers le Seigneur Dieu, pour le consulter par des prières et des supplications, avec des jeûnes, des sacs et des cendres.
4 Mo gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run mi, mo sì jẹ́wọ́ wí pé: “Ìwọ Olúwa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó ní ìfẹ́ rẹ̀ àti àwọn tí ó ń pa àwọn òfin rẹ̀ mọ́.
J'ai prié Yahvé, mon Dieu, et je me suis confessé, en disant, « Seigneur, Dieu grand et redoutable, qui garde l'alliance et la bonté envers ceux qui l'aiment et gardent ses commandements,
5 Àwa ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú. Àwa ti hu ìwà búburú, a sì ti ṣe ọ̀tẹ̀, a ti yí padà kúrò nínú àwọn àṣẹ àti àwọn ìlànà rẹ̀.
nous avons péché, nous avons agi avec perversité, nous avons fait le mal, nous nous sommes rebellés, nous nous sommes détournés de tes préceptes et de tes ordonnances.
6 Àwa kò fetí sí àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ, ẹni tí ó sọ̀rọ̀ ní orúkọ rẹ sí àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé àti àwọn baba wa, àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà.
Nous n'avons pas écouté tes serviteurs les prophètes, qui ont parlé en ton nom à nos rois, à nos princes, à nos pères et à tout le peuple du pays.
7 “Olúwa ìwọ ni olódodo, ṣùgbọ́n báyìí ìtìjú dé bá àwọn ènìyàn Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu àti gbogbo Israẹli ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti fọ́n wa ká sí nítorí àìṣòótọ́ ọ wa sí ọ.
« Seigneur, la justice t'appartient, mais à nous la confusion de visage, comme aujourd'hui, aux hommes de Juda, aux habitants de Jérusalem, et à tout Israël, proches et lointains, dans tous les pays où tu les as chassés, à cause de la faute qu'ils ont commise contre toi.
8 Háà! Olúwa, àwa àti àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé, àti àwọn baba wa, ìtìjú dé bá wa nítorí àwa ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ.
Seigneur, à nous la confusion du visage, à nos rois, à nos princes et à nos pères, parce que nous avons péché contre toi.
9 Olúwa Ọlọ́run wa ní àánú, ó sì ń dáríjì, bí àwa tilẹ̀ ti ṣe ọ̀tẹ̀ sí i;
Au Seigneur notre Dieu appartiennent la miséricorde et le pardon, car nous nous sommes révoltés contre lui.
10 àwa kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, a kò sì pa àwọn òfin rẹ mọ́, èyí tí ó fún wa nípasẹ̀ àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
Nous n'avons pas obéi à la voix de l'Éternel, notre Dieu, pour marcher dans ses lois, qu'il nous avait prescrites par ses serviteurs les prophètes.
11 Gbogbo Israẹli ti ṣẹ̀ sí òfin rẹ, wọ́n ti yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, wọ́n kọ̀ láti ṣe ìgbọ́ràn sí ọ. “Nígbà náà ni ègún àti ìdájọ́ tí a kọ sílẹ̀ pẹ̀lú ìbúra nínú òfin Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run dà sórí i wa, nítorí tí àwa ti sẹ̀ sí ọ.
Oui, tout Israël a transgressé ta loi, en se détournant, pour ne pas obéir à ta voix. « C'est pourquoi la malédiction et le serment écrits dans la loi de Moïse, serviteur de Dieu, ont été répandus sur nous, car nous avons péché contre lui.
12 Ìwọ ti mú ọ̀rọ̀ tí o sọ sí wa sẹ àti lórí àwọn alákòóso wa, nípa mímú kí ibi ńlá bá wa, irú èyí tí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí lábẹ́ ọ̀run, bí ó ti ṣẹlẹ̀ sí Jerusalẹmu yìí.
Il a confirmé les paroles qu'il a prononcées contre nous et contre les juges qui nous ont jugés, en faisant venir sur nous un grand malheur; car, sous tout le ciel, il n'a pas été fait à Jérusalem ce qui lui a été fait.
13 Bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Mose bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ibi yìí ti dé bá wa, síbẹ̀ a kò bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere Olúwa Ọlọ́run wa, nípa yíyí padà kí a kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wa kí a sì mọ òtítọ́ rẹ.
Comme il est écrit dans la loi de Moïse, tout ce malheur est venu sur nous. Et nous n'avons pas imploré la faveur de l'Éternel, notre Dieu, pour que nous nous détournions de nos iniquités et que nous soyons éclairés par ta vérité.
14 Olúwa kò jáfara láti mú ibi náà wá sórí wa, nítorí olódodo ni Olúwa Ọlọ́run wa nínú u gbogbo ohun tí ó ń ṣe; síbẹ̀ àwa kò ṣe ìgbọ́ràn sí i.
C'est pourquoi l'Éternel a veillé sur le malheur et l'a fait venir sur nous; car l'Éternel, notre Dieu, est juste dans toutes les œuvres qu'il fait, et nous n'avons pas obéi à sa voix.
15 “Ní ìsinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, pẹ̀lú ọwọ́ agbára, tí ó fún ara rẹ̀ ní orúkọ tí ó wà títí di òní, a ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú.
« Maintenant, Seigneur notre Dieu, toi qui as fait sortir ton peuple du pays d'Égypte d'une main puissante, et qui t'es acquis une renommée, comme c'est le cas aujourd'hui, nous avons péché. Nous avons fait le mal.
16 Olúwa, ní ìbámu pẹ̀lú ìwà òdodo rẹ, yí ìbínú àti ìrunú rẹ padà kúrò ní Jerusalẹmu ìlú u rẹ, òkè mímọ́ rẹ. Ẹ̀ṣẹ̀ wa àti àìṣedéédéé àwọn baba wa ti mú Jerusalẹmu àti ènìyàn rẹ di ẹ̀gàn fún gbogbo àwọn tí ó yí wọn ká.
Seigneur, selon toute ta justice, fais que ta colère et ton courroux se détournent de ta ville Jérusalem, ta montagne sainte, car à cause de nos péchés et des iniquités de nos pères, Jérusalem et ton peuple sont devenus un opprobre pour tous ceux qui nous entourent.
17 “Nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, nítorí i tìrẹ Olúwa, fi ojú àánú wo ibi mímọ́ rẹ tí ó ti dahoro.
« Maintenant, notre Dieu, écoute la prière de ton serviteur et ses supplications, et fais briller ta face sur ton sanctuaire dévasté, à cause du Seigneur.
18 Tẹ́ etí rẹ sílẹ̀, Ọlọ́run, kí o gbọ́; ya ojú rẹ sílẹ̀, kí o sì wo ìdahoro ìlú tí a ń fi orúkọ rẹ pè. Àwa kò gbé ẹ̀bẹ̀ wa kalẹ̀ níwájú u rẹ nítorí pé a jẹ́ olódodo, bí kò ṣe nítorí àánú ńlá rẹ.
Mon Dieu, tends l'oreille et écoute. Ouvre tes yeux et vois nos désolations, et la ville qui est appelée de ton nom; car nous ne présentons pas nos requêtes devant toi à cause de notre justice, mais à cause de tes grandes compassions.
19 Olúwa, fetísílẹ̀! Olúwa, dáríjì! Olúwa, gbọ́ kí o sì ṣe é! Nítorí i tìrẹ, Ọlọ́run mi, má ṣe pẹ́ títí, nítorí ìlú rẹ àti àwọn ènìyàn rẹ ń jẹ́ orúkọ mọ́ ọ lára.”
Seigneur, écoute. Seigneur, pardonne. Seigneur, écoute et fais. Ne diffère pas, pour ton bien, mon Dieu, parce que ta ville et ton peuple sont appelés par ton nom. »
20 Bí mo ṣe ń sọ̀rọ̀, tí mo sì ń gba àdúrà, tí mo ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi àti ẹ̀ṣẹ̀ àwọn Israẹli ènìyàn mi, tí mo sì ń mú ẹ̀bẹ̀ mi tọ Olúwa Ọlọ́run mi nítorí òkè mímọ́ rẹ.
Pendant que je parlais, que je priais, que je confessais mon péché et le péché de mon peuple d'Israël, et que je présentais mes supplications à Yahvé mon Dieu pour la montagne sainte de mon Dieu -
21 Bí mo ṣe ń gba àdúrà náà lọ́wọ́, Gabrieli ọkùnrin tí mo rí nínú ìran ìṣáájú, yára kánkán wá sí ọ̀dọ̀ mi ní àkókò ẹbọ àṣálẹ́.
oui, pendant que je parlais en priant - l'homme Gabriel, que j'avais vu dans la vision du début, se mit à voler rapidement et me toucha au moment de l'offrande du soir.
22 Ó jẹ́ kí ó yé mi, ó sì wí fún mi pé, “Daniẹli, mo wá láti jẹ́ kí o mọ̀ kí o sì ní òye.
Il m'instruisit et s'entretint avec moi, et dit: « Daniel, je suis venu maintenant pour te donner la sagesse et l'intelligence.
23 Bí o ṣe bẹ̀rẹ̀ sí nígbà àdúrà, a fún ọ ní ìdáhùn kan, èyí tí mo wá láti sọ fún ọ, nítorí ìwọ jẹ́ àyànfẹ́ gidigidi. Nítorí náà, gba ọ̀rọ̀ náà yẹ̀ wò kí ìran náà sì yé ọ:
Au début de tes requêtes, le commandement est sorti, et je suis venu te le dire, car tu es très aimé. Considère donc la question et comprends la vision.
24 “Àádọ́rin ọ̀sẹ̀ ni a pàṣẹ fún àwọn ènìyàn rẹ àti fún àwọn ìlú mímọ́ rẹ láti parí ìrékọjá, láti fi òpin sí ẹ̀ṣẹ̀, láti ṣe ètùtù sí ìwà búburú, láti mú òdodo títí ayé wá, láti ṣe èdìdì ìran àti wòlíì àti láti fi òróró yan Ibi Mímọ́ Jùlọ.
« Soixante-dix semaines ont été décrétées pour ton peuple et pour ta ville sainte, afin d'achever la désobéissance, de faire cesser les péchés, de réparer l'iniquité, d'instaurer la justice éternelle, de sceller les visions et les prophéties, et d'oindre le Très Saint.
25 “Nítorí náà, mọ èyí pé, láti ìgbà tí a ti gbé ọ̀rọ̀ náà jáde wí pé kí a tún Jerusalẹmu ṣe, kí a sì tún kọ́, títí dé ìgbà ọmọ-aládé, ẹni òróró náà, alákòóso wa yóò fi dé, ó jẹ́ ọ̀sẹ̀ méje àti ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó sì tún ìgboro àti yàrá rẹ̀ mọ, ṣùgbọ́n ní àkókò wàhálà ni.
« Sachez donc et discernez que, depuis l'envoi du commandement de rétablir et de reconstruire Jérusalem jusqu'à l'Oint, le prince, il y aura sept semaines et soixante-deux semaines. Elle sera rebâtie, avec des rues et des douves, même en des temps troublés.
26 Lẹ́yìn ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó ké Ẹni òróró náà kúrò, kò sì ní ní ohun kan. Àwọn ènìyàn ọmọ-aládé náà tí yóò wá ni yóò pa ìlú náà àti ibi mímọ́ run. Òpin yóò dé bí ìkún omi, ogun yóò máa jà títí dé òpin, a sì ti pàṣẹ ìdahoro.
Après les soixante-deux semaines, l'Oint sera retranché et n'aura plus rien. Le peuple du prince qui vient détruira la ville et le sanctuaire. Sa fin sera un déluge, et la guerre durera jusqu'à la fin. Les désolations sont déterminées.
27 Yóò sì fi ìdí i májẹ̀mú kan múlẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún ọ̀sẹ̀ kan. Ní àárín ọ̀sẹ̀ ni yóò mú òpin bá ẹbọ àti ọrẹ ẹbọ. Àti lórí apá kan ni yóò dà ìríra tí ó mú ìdahoro wá, títí tí òpin tí a ti pàṣẹ lórí asọnidahoro yóò fi padà fi dé bá a.”
Il conclura avec beaucoup de gens une alliance ferme pour une semaine. Au milieu de la semaine, il fera cesser le sacrifice et l'offrande. Sur l'aile des abominations viendra celui qui fait la désolation; et jusqu'au terme fixé, la colère se répandra sur les désolés. »

< Daniel 9 >