< Daniel 9 >

1 Ní ọdún kìn-ín-ní Dariusi ọmọ Ahaswerusi, ẹni tí a bí ní Media, òun ló jẹ ọba lórí ìjọba Babeli.
Léta prvního Daria syna Asverova z semene Médského, kteréhož učiněn jest králem v království Kaldejském,
2 Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba rẹ̀, èmi Daniẹli fi iyè sí i láti inú ìwé, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí wòlíì Jeremiah, wá pé, àádọ́rin ọdún ni Jerusalẹmu yóò fi wà ní ahoro.
Léta prvního kralování jeho já Daniel porozuměl jsem z knih počtu let, o nichž se stalo slovo Hospodinovo k Jeremiášovi proroku, že se vyplní zpuštění Jeruzaléma sedmdesátého léta.
3 Nígbà náà, ni mo yípadà sí Olúwa Ọlọ́run, mo bẹ̀ ẹ́ pẹ̀lú àdúrà àti ẹ̀bẹ̀, pẹ̀lú àwẹ̀, aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú.
A obrátil jsem tvář svou ku Pánu Bohu, hledaje ho modlitbou a pokornými prosbami, v postu, v žíni a popele.
4 Mo gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run mi, mo sì jẹ́wọ́ wí pé: “Ìwọ Olúwa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó ní ìfẹ́ rẹ̀ àti àwọn tí ó ń pa àwọn òfin rẹ̀ mọ́.
I modlil jsem se Hospodinu Bohu svému, a vyznávaje se, řekl jsem: Prosím, Pane Bože silný, veliký a všeliké cti hodný, ostříhající smlouvy a dobrotivosti k těm, kteříž tě milují, a ostříhají přikázaní tvých.
5 Àwa ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú. Àwa ti hu ìwà búburú, a sì ti ṣe ọ̀tẹ̀, a ti yí padà kúrò nínú àwọn àṣẹ àti àwọn ìlànà rẹ̀.
Zhřešiliť jsme a převráceně jsme činili, bezbožnost jsme páchali, a protivili jsme se, a odvrátili od přikázaní tvých a soudů tvých.
6 Àwa kò fetí sí àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ, ẹni tí ó sọ̀rọ̀ ní orúkọ rẹ sí àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé àti àwọn baba wa, àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà.
Aniž jsme poslouchali služebníků tvých proroků, kteříž mluvívali ve jménu tvém králům našim, knížatům našim a otcům našim, i všemu lidu země.
7 “Olúwa ìwọ ni olódodo, ṣùgbọ́n báyìí ìtìjú dé bá àwọn ènìyàn Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu àti gbogbo Israẹli ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti fọ́n wa ká sí nítorí àìṣòótọ́ ọ wa sí ọ.
Toběť, ó Pane, přísluší spravedlnost, nám pak zahanbení tváři, jakž se to děje nyní mužům Judským a obyvatelům Jeruzalémským, a všechněm Izraelským, blízkým i dalekým, ve všech zemích, kamž jsi je zahnal pro přestoupení jejich, jímž přestupovali proti tobě.
8 Háà! Olúwa, àwa àti àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé, àti àwọn baba wa, ìtìjú dé bá wa nítorí àwa ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ.
Námť, ó Hospodine, sluší zahanbení tváři, králům našim, knížatům našim a otcům našim, neboť jsme zhřešili proti tobě,
9 Olúwa Ọlọ́run wa ní àánú, ó sì ń dáríjì, bí àwa tilẹ̀ ti ṣe ọ̀tẹ̀ sí i;
Pánu Bohu pak našemu milosrdenství a slitování, poněvadž jsme se protivili jemu,
10 àwa kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, a kò sì pa àwọn òfin rẹ mọ́, èyí tí ó fún wa nípasẹ̀ àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
A neposlouchali jsme hlasu Hospodina Boha našeho, abychom chodili v naučeních jeho, kteréž předkládal před oči naše skrze služebníky své proroky.
11 Gbogbo Israẹli ti ṣẹ̀ sí òfin rẹ, wọ́n ti yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, wọ́n kọ̀ láti ṣe ìgbọ́ràn sí ọ. “Nígbà náà ni ègún àti ìdájọ́ tí a kọ sílẹ̀ pẹ̀lú ìbúra nínú òfin Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run dà sórí i wa, nítorí tí àwa ti sẹ̀ sí ọ.
Nýbrž všickni Izraelští přestoupili zákon tvůj a odvrátili se, aby neposlouchali hlasu tvého; protož vylito jest na nás to prokletí a klatba, kteráž jest zapsána v zákoně Mojžíše služebníka Božího, nebo jsme zhřešili proti němu.
12 Ìwọ ti mú ọ̀rọ̀ tí o sọ sí wa sẹ àti lórí àwọn alákòóso wa, nípa mímú kí ibi ńlá bá wa, irú èyí tí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí lábẹ́ ọ̀run, bí ó ti ṣẹlẹ̀ sí Jerusalẹmu yìí.
Pročež splnil slovo své, kteréž mluvil proti nám a proti soudcům našim, kteříž nás soudili, a uvedl na nás toto zlé veliké, jehož se nestalo pode vším nebem, jakéž se stalo v Jeruzalémě.
13 Bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Mose bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ibi yìí ti dé bá wa, síbẹ̀ a kò bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere Olúwa Ọlọ́run wa, nípa yíyí padà kí a kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wa kí a sì mọ òtítọ́ rẹ.
Tak jakž zapsáno jest v zákoně Mojžíšově, všecko to zlé přišlo na nás, a však ani tak jsme se nekořili před tváří hněvivou Hospodina Boha našeho, abychom se odvrátili od nepravostí svých, a šetřili pravdy jeho.
14 Olúwa kò jáfara láti mú ibi náà wá sórí wa, nítorí olódodo ni Olúwa Ọlọ́run wa nínú u gbogbo ohun tí ó ń ṣe; síbẹ̀ àwa kò ṣe ìgbọ́ràn sí i.
Protož neobmeškal Hospodin s tím zlým, ale uvedl je na nás; nebo spravedlivý jest Hospodin Bůh náš ve všech skutcích svých, kteréž činí, jehož hlasu poslušni jsme nebyli.
15 “Ní ìsinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, pẹ̀lú ọwọ́ agbára, tí ó fún ara rẹ̀ ní orúkọ tí ó wà títí di òní, a ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú.
Nyní však, ó Pane Bože náš, kterýž jsi vyvedl lid svůj z země Egyptské rukou silnou, a způsobils sobě jméno, jakéž jest dnešního dne, zhřešili jsme, bezbožně jsme činili.
16 Olúwa, ní ìbámu pẹ̀lú ìwà òdodo rẹ, yí ìbínú àti ìrunú rẹ padà kúrò ní Jerusalẹmu ìlú u rẹ, òkè mímọ́ rẹ. Ẹ̀ṣẹ̀ wa àti àìṣedéédéé àwọn baba wa ti mú Jerusalẹmu àti ènìyàn rẹ di ẹ̀gàn fún gbogbo àwọn tí ó yí wọn ká.
Ó Pane, podlé vší tvé dobrotivosti nechť se, prosím, odvrátí hněv tvůj a prchlivost tvá od města tvého Jeruzaléma, hory svatosti tvé; nebo pro hříchy naše a pro nepravosti otců našich Jeruzalém a lid tvůj v pohanění jest u všech, kteříž jsou vůkol nás.
17 “Nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, nítorí i tìrẹ Olúwa, fi ojú àánú wo ibi mímọ́ rẹ tí ó ti dahoro.
Nyní tedy, ó Bože náš, vyslyš modlitbu služebníka svého, a pokorné prosby jeho, a zasvěť tvář svou nad svatyní svou spuštěnou, pro Pána.
18 Tẹ́ etí rẹ sílẹ̀, Ọlọ́run, kí o gbọ́; ya ojú rẹ sílẹ̀, kí o sì wo ìdahoro ìlú tí a ń fi orúkọ rẹ pè. Àwa kò gbé ẹ̀bẹ̀ wa kalẹ̀ níwájú u rẹ nítorí pé a jẹ́ olódodo, bí kò ṣe nítorí àánú ńlá rẹ.
Nakloň, Bože můj, ucha svého a slyš, otevři oči své a viz zpuštění naše i města, kteréž jest nazváno od jména tvého; nebo ne pro nějaké naše spravedlnosti padajíce, pokorně prosíme tebe, ale pro milosrdenství tvá mnohá.
19 Olúwa, fetísílẹ̀! Olúwa, dáríjì! Olúwa, gbọ́ kí o sì ṣe é! Nítorí i tìrẹ, Ọlọ́run mi, má ṣe pẹ́ títí, nítorí ìlú rẹ àti àwọn ènìyàn rẹ ń jẹ́ orúkọ mọ́ ọ lára.”
Vyslyšiž, ó Pane, Pane, odpusť, Pane, pozoruj a učiň; neprodlévejž pro sebe samého, můj Bože, nebo od jména tvého nazváno jest město toto i lid tvůj.
20 Bí mo ṣe ń sọ̀rọ̀, tí mo sì ń gba àdúrà, tí mo ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi àti ẹ̀ṣẹ̀ àwọn Israẹli ènìyàn mi, tí mo sì ń mú ẹ̀bẹ̀ mi tọ Olúwa Ọlọ́run mi nítorí òkè mímọ́ rẹ.
Ještě jsem mluvil a modlil se, a vyznával hřích svůj i hřích lidu svého Izraelského, a padna, pokorně jsem se modlil před tváří Hospodina Boha svého, za horu svatosti Boha svého,
21 Bí mo ṣe ń gba àdúrà náà lọ́wọ́, Gabrieli ọkùnrin tí mo rí nínú ìran ìṣáájú, yára kánkán wá sí ọ̀dọ̀ mi ní àkókò ẹbọ àṣálẹ́.
Ještě, pravím, mluvil jsem při modlitbě, a muž ten Gabriel, kteréhož jsem viděl v tom vidění na počátku, rychle přiletěv, dotekl se mne v čas oběti večerní.
22 Ó jẹ́ kí ó yé mi, ó sì wí fún mi pé, “Daniẹli, mo wá láti jẹ́ kí o mọ̀ kí o sì ní òye.
A slouže mi k srozumění, mluvil se mnou a řekl: Danieli, nyní jsem vyšel, abych tě naučil vyrozumívati tajemstvím.
23 Bí o ṣe bẹ̀rẹ̀ sí nígbà àdúrà, a fún ọ ní ìdáhùn kan, èyí tí mo wá láti sọ fún ọ, nítorí ìwọ jẹ́ àyànfẹ́ gidigidi. Nítorí náà, gba ọ̀rọ̀ náà yẹ̀ wò kí ìran náà sì yé ọ:
Při počátku pokorných proseb tvých vyšlo slovo, a já jsem přišel, aťbych je oznámil, nebo jsi velmi milý; pročež pozoruj slova toho, a rozuměj vidění tomu.
24 “Àádọ́rin ọ̀sẹ̀ ni a pàṣẹ fún àwọn ènìyàn rẹ àti fún àwọn ìlú mímọ́ rẹ láti parí ìrékọjá, láti fi òpin sí ẹ̀ṣẹ̀, láti ṣe ètùtù sí ìwà búburú, láti mú òdodo títí ayé wá, láti ṣe èdìdì ìran àti wòlíì àti láti fi òróró yan Ibi Mímọ́ Jùlọ.
Sedmdesáte téhodnů odečteno jest lidu tvému a městu svatému tvému k zabránění převrácenosti a k zapečetění hříchů, i vyčištění nepravosti a k přivedení spravedlnosti věčné, a k zapečetění vidění i proroctví, a ku pomazání Svatého svatých.
25 “Nítorí náà, mọ èyí pé, láti ìgbà tí a ti gbé ọ̀rọ̀ náà jáde wí pé kí a tún Jerusalẹmu ṣe, kí a sì tún kọ́, títí dé ìgbà ọmọ-aládé, ẹni òróró náà, alákòóso wa yóò fi dé, ó jẹ́ ọ̀sẹ̀ méje àti ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó sì tún ìgboro àti yàrá rẹ̀ mọ, ṣùgbọ́n ní àkókò wàhálà ni.
Věziž tedy a rozuměj, že od vyjití výpovědi o navrácení a o vystavení Jeruzaléma až do Mesiáše vývody bude téhodnů sedm, potom téhodnů šedesáte dva, když již zase vzdělána bude ulice a příkopa, a ti časové budou přenesnadní.
26 Lẹ́yìn ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó ké Ẹni òróró náà kúrò, kò sì ní ní ohun kan. Àwọn ènìyàn ọmọ-aládé náà tí yóò wá ni yóò pa ìlú náà àti ibi mímọ́ run. Òpin yóò dé bí ìkún omi, ogun yóò máa jà títí dé òpin, a sì ti pàṣẹ ìdahoro.
Po téhodnech pak těch šedesáti a dvou zabit bude Mesiáš, však jemu to nic neuškodí; nýbrž to město i tu svatyni zkazí, i lid ten svůj budoucí, tak že skončení jeho bude hrozné, ano i do vykonání boje bude boj stálý všelijak do vyplénění.
27 Yóò sì fi ìdí i májẹ̀mú kan múlẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún ọ̀sẹ̀ kan. Ní àárín ọ̀sẹ̀ ni yóò mú òpin bá ẹbọ àti ọrẹ ẹbọ. Àti lórí apá kan ni yóò dà ìríra tí ó mú ìdahoro wá, títí tí òpin tí a ti pàṣẹ lórí asọnidahoro yóò fi padà fi dé bá a.”
Utvrdí však smlouvu mnohým v téhodni posledním, u prostřed pak toho téhodne učiní konec oběti zápalné i oběti suché; a skrze vojsko ohavné, až do posledního a uloženého poplénění hubící, na popléněné vylito bude zpuštění.

< Daniel 9 >