< Daniel 8 >

1 Nígbà tí ó di ọdún kẹta ìjọba Belṣassari ọba, èmi Daniẹli rí ìran kan èyí tí mo ti rí tẹ́lẹ̀.
W trzecim roku panowania króla Belszazara ukazało mi się widzenie, mnie Danielowi, po tym, które ukazało mi się na początku.
2 Nínú ìran náà, mo rí ara mi nínú ilé ìṣọ́ ní Susa ní agbègbè ìjọba Elamu: nínú ìran náà mo wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ odò Ulai.
Zobaczyłem w widzeniu, że jestem w pałacu Suza, który znajdował się w prowincji Elam; zobaczyłem w widzeniu, że jestem nad rzeką Ulaj.
3 Mo wo òkè mo sì rí àgbò kan tí ó ní ìwo méjì níwájú mi, ó dúró sí ẹ̀gbẹ́ odò Ulai, àwọn ìwo náà sì gùn. Ṣùgbọ́n ọ̀kan gùn ju èkejì lọ, èyí tí ó gùn jù ni ó yọ jáde kẹ́yìn.
I podniosłem swoje oczy, i spojrzałem, a oto nad rzeką stał baran mający dwa rogi. Te dwa rogi były wysokie, lecz jeden [był] wyższy od drugiego, ale ten wyższy wyrósł później.
4 Mo rí àgbò náà ó ń kàn sí ìhà ìwọ̀-oòrùn, sí àríwá, àti sí gúúsù, kò sí ẹranko kankan tí ó le è dojúkọ ọ́, kò sí ẹnìkan tí ó le è yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ agbára rẹ̀, ó ń ṣe bí ó ti wù ú, ó sì di alágbára.
Widziałem, jak baran bódł na zachód, na północ i na południe, a żadna bestia nie mogła stać przed nim i nie było [nikogo], kto by wyrwał się z jego ręki. Czynił on według swojej woli i stał się wielki.
5 Bí mo ṣe ń ronú nípa èyí, lójijì ni òbúkọ kan tí ó ní ìwo láàrín ojú u rẹ̀ méjèèjì jáde láti ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó la gbogbo ayé kọjá láìfi ara kan ilẹ̀.
Gdy się zastanawiałem [nad tym], oto przyszedł kozioł z zachodu po powierzchni całej ziemi, nie dotykając ziemi. A [ten] kozioł miał okazały róg między swoimi oczami.
6 Ó tọ àgbò tí ó ni ìwo méjì náà wá, èyí tí mo rí tó dúró sí ẹ̀gbẹ́ odò Ulai, ó sì dojúkọ ọ́ pẹ̀lú ìrunú tí ó lágbára.
I przyszedł aż do tego barana, który miał dwa rogi, którego widziałem stojącego nad rzeką; podbiegł do niego w zapalczywości swojej siły.
7 Mo rí i tí ó fi ìtara kọlu àgbò náà, ó lu àgbò náà bolẹ̀, ó sì ṣẹ́ ìwo rẹ̀ méjèèjì. Àgbò náà kò sì ní agbára láti dojúkọ ọ́, Òbúkọ náà kàn án mọ́lẹ̀, ó sì fi ẹsẹ̀ tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀, kò sì ṣí ẹni tí ó lè gba àgbò náà là kúrò lọ́wọ́ agbára rẹ̀.
Widziałem także, że natarł na tego barana, a rozjuszywszy się na niego, uderzył barana, tak że złamał mu oba rogi. I baran nie miał siły, aby go odeprzeć; i rzucił go o ziemię, zdeptał go, a nie było [nikogo], kto by wyrwał barana z jego mocy.
8 Òbúkọ náà sì di alágbára púpọ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí ó dé góńgó, agbára rẹ̀ ru sókè, ìwo ńlá a rẹ̀ sì ṣẹ́ dànù, ní ipò o rẹ̀, ìwo mẹ́rin mìíràn hù, ó sì yọrí sí ìhà igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ọ̀run.
Wtedy kozioł stawał się bardzo wielki, ale gdy stał się potężny, złamał się wielki róg, a na jego miejsce wyrosły cztery rogi okazałe na cztery strony świata.
9 Lára ọ̀kan nínú wọn, ìwo mìíràn yọ jáde, ó kékeré, ṣùgbọ́n ó dàgbà nínú agbára sí ìhà gúúsù, àti sí ìhà ìlà-oòrùn àti sí ilẹ̀ dídára.
Z jednego z nich wyrósł mały róg, a ten bardzo wzrastał ku południu, ku wschodowi i ku wspaniałej ziemi.
10 Ó sì dàgbà títí ó fi kan ẹgbẹ́ ogun ọ̀run, ó sì jù lára àwọn ẹgbẹ́ ogun ọ̀run sí ayé ó sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀,
Wzrósł aż do wojska niebieskiego i zrzucił na ziemię [część] wojska oraz gwiazd i podeptał je.
11 ó sì gbé ara rẹ̀ ga gẹ́gẹ́ bí ọmọ-aládé ẹgbẹ́ ogun ọ̀run; ó sì mú ẹbọ ojoojúmọ́ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì gba ààyè ibi mímọ́ rẹ̀.
Wzniósł się nawet aż do księcia tego wojska i przez niego została odjęta codzienna [ofiara] i [zostało] porzucone miejsce jego świątyni.
12 A fún un ní ẹgbẹ́ ogun ọ̀run àti ẹbọ ojoojúmọ́ nítorí ìwà ọlọ̀tẹ̀ ẹ rẹ̀, ó sọ òtítọ́ nù nínú gbogbo ohun tó ṣe.
Także wojsko zostało [mu] podane przeciwko codziennej [ofierze] z powodu przestępstwa i porzucił prawdę na ziemię, a cokolwiek czynił, powodziło mu się.
13 Nígbà náà, ni mo gbọ́ tí ẹni mímọ́ ń sọ̀rọ̀, àti ẹni mímọ́ mìíràn sọ̀rọ̀ fún un pé, “Yóò ti pẹ́ tó tí ìran yìí yóò fi wá sí ìmúṣẹ—ìran nípa ẹbọ ojoojúmọ́, ìṣọ̀tẹ̀ tí ó mú ìsọdahoro wa, àní láti fi ibi mímọ́ àti ogun ọ̀run fún ni ní ìtẹ̀mọ́lẹ̀?”
Wtedy usłyszałem jednego ze świętych mówiącego, a inny święty zapytał tego, który mówił: Jak długo [będzie trwać] widzenie o codziennej [ofierze] i przestępstwie spustoszenia, a świątynia i wojsko będą podane na podeptanie?
14 Ó sọ fún mi pé, “Yóò gbà tó ẹgbọ̀kànlá lé lọ́gọ́rùn-ún alẹ́ àti òwúrọ̀; lẹ́yìn náà ni a ó tún ibi mímọ́ yà sí mímọ́.”
I powiedział do mnie: Aż do dwóch tysięcy trzystu wieczorów i poranków. Wtedy świątynia zostanie oczyszczona.
15 Nígbà tí èmi Daniẹli, ń wo ìran náà, mo sì ń fẹ́ kí ó yé mi, ẹnìkan tí ó sì dúró níwájú mi.
A gdy ja, Daniel, patrzyłem na to widzenie i pytałem się o jego znaczenie, oto stanął przede mną [ktoś] o wyglądzie mężczyzny.
16 Mo gbọ́ ohùn ènìyàn ní ẹ̀gbẹ́ Ulai, tí ó ń ké pé “Gabrieli, sọ ìtumọ̀ ìran náà fún ọkùnrin yìí.”
Usłyszałem też ludzki głos między [brzegami] Ulaj, który zawołał: Gabrielu, wyjaśnij mu to widzenie.
17 Bí ó ṣe súnmọ́ ibi tí mo dúró sí, ẹ̀rù bà mí, mo sì dọ̀bálẹ̀. Ó ń sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ́ kí ó yé ọ pé ìran náà ń sọ nípa ìgbà ìkẹyìn ni.”
I przyszedł do mnie, gdzie stałem. A gdy przyszedł, zląkłem się i padłem na twarz. I powiedział do mnie: Zrozum, synu człowieczy, bo to widzenie [spełni się] w czasie ostatecznym.
18 Bí ó ṣe ń bá mi sọ̀rọ̀, mo ti sùn lọ fọnfọn, bí mo ṣe da ojú bolẹ̀. Nígbà náà ni ó fi ọwọ́ kàn mí, ó sì gbé mi dúró lórí ẹsẹ̀ mi.
Gdy mówił do mnie, zapadłem w głęboki sen, leżąc twarzą ku ziemi. Wtedy dotknął mnie i postawił na nogi.
19 Ó sọ wí pé, “Èmi yóò sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ìkẹyìn ní ìgbà ìbínú, nítorí ìran náà jẹ mọ́ àkókò ohun tí a yàn nígbà ìkẹyìn.
I powiedział: Oto oznajmię tobie, co się będzie dziać, kiedy skończy się gniew, bo koniec nastąpi w czasie oznaczonym.
20 Àgbò oníwo méjì tí o rí, òun ni ó dúró gẹ́gẹ́ bí àwọn ọba Media àti Persia.
Ten baran, którego widziałeś, o dwóch rogach, to [są] królowie Medów i Persów.
21 Òbúkọ onírun náà ni ọba Giriki, ìwo ńlá ti ó wà láàrín ojú u rẹ̀ ni ọba àkọ́kọ́.
A ten kosmaty kozioł to król Grecji, a ten wielki róg między jego oczami to pierwszy król.
22 Ìwo mẹ́rin mìíràn sì dìde dúró dípò ọ̀kan tí ó ṣẹ́, èyí dúró gẹ́gẹ́ bí ìjọba mẹ́rin tí yóò dìde nínú orílẹ̀-èdè náà, ṣùgbọ́n wọn kì yóò ní ní irú agbára kan náà.
A to, że został złamany, a powstały cztery inne w jego miejsce, [oznacza, że] cztery królestwa powstaną z jego narodu, ale nie [będą miały] jego potęgi.
23 “Ní ìgbà ìkẹyìn ìjọba wọn, nígbà tí àwọn oníwà búburú bá dé ní kíkún, ni ọba kan yóò dìde, tí ojú rẹ̀ le koko, tí ó sì mòye ọ̀rọ̀ àrékérekè.
A pod koniec ich panowania, gdy przestępcy dopełnią [swej miary], powstanie król o srogim obliczu i podstępny;
24 Yóò di alágbára, ṣùgbọ́n tí kì í ṣe nípa agbára rẹ̀. Yóò sì máa ṣe ìparun tí yóò ya ni lẹ́nu, yóò sì máa ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tó ń ṣe. Yóò sì run àwọn alágbára àti àwọn ènìyàn mímọ́.
Jego moc będzie potężna, lecz nie dzięki własnej sile. Będzie niszczył w sposób zadziwiający i szczęśliwie mu się powiedzie w działaniu, bo zniszczy mocarzy i lud święty.
25 Nípa àrékérekè rẹ̀, yóò mú kí ẹ̀tàn gbèrú, yóò gbé ara rẹ̀ ga nínú ọkàn rẹ̀, nígbà tí wọ́n rò wí pé àlàáfíà dé, yóò sì pa àwọn ènìyàn run, nígbà tí wọn kò rò tẹ́lẹ̀, yóò sì lòdì sí olórí àwọn ọmọ-aládé, síbẹ̀, a ó pa á run ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa agbára ènìyàn.
A dzięki jego pomyślności poszczęści mu się podstęp w jego ręku, będzie się wynosił w swoim sercu i w czasie pokoju zniszczy wielu. [Ponadto] powstanie przeciw Księciu książąt, lecz bez [udziału] ręki [ludzkiej] zostanie skruszony.
26 “Ìran alẹ́ àti ti òwúrọ̀, tí a fihàn ọ́ jẹ́ òtítọ́, ṣùgbọ́n pa ìran náà mọ́, nítorí pé, ó jẹ mọ́ ti ọjọ́ iwájú.”
A to widzenie wieczorne i poranne, o którym była mowa, jest prawdą. Dlatego zapieczętuj to widzenie, bo [spełni się po] wielu dniach.
27 Èmi Daniẹli sì ṣe àárẹ̀ fún ọjọ́ mélòó kan. Nígbà náà, mo dìde, mo sì ń bá iṣẹ́ ọba lọ. Ìran náà sì bà mí lẹ́rù, kò sì yé mi.
Wtedy ja, Daniel, zemdlałem i chorowałem przez kilka dni; potem wstałem i załatwiałem sprawy króla; zdumiewałem się nad tym widzeniem, [ale] nikt go nie rozumiał.

< Daniel 8 >