< Daniel 8 >

1 Nígbà tí ó di ọdún kẹta ìjọba Belṣassari ọba, èmi Daniẹli rí ìran kan èyí tí mo ti rí tẹ́lẹ̀.
Na rĩrĩ, mwaka-inĩ wa gatatũ wa wathani wa Mũthamaki Belishazaru-rĩ, niĩ Danieli nĩndonire kĩoneki kĩngĩ, thuutha wa kĩrĩa ndoonete mbere.
2 Nínú ìran náà, mo rí ara mi nínú ilé ìṣọ́ ní Susa ní agbègbè ìjọba Elamu: nínú ìran náà mo wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ odò Ulai.
Kĩoneki-inĩ kĩu gĩakwa ndeyonire ndĩ itũũra-inĩ igitĩre rĩa Shushani bũrũri-inĩ wa Elamu; kĩoneki-inĩ kĩu ndeyonire ndĩ hũgũrũrũ-inĩ cia Rũũĩ rwa Ulai.
3 Mo wo òkè mo sì rí àgbò kan tí ó ní ìwo méjì níwájú mi, ó dúró sí ẹ̀gbẹ́ odò Ulai, àwọn ìwo náà sì gùn. Ṣùgbọ́n ọ̀kan gùn ju èkejì lọ, èyí tí ó gùn jù ni ó yọ jáde kẹ́yìn.
Na rĩrĩ, ngĩcũthĩrĩria, na hau mbere yakwa ngĩona ndũrũme ĩrũngiĩ hũgũrũrũ-inĩ cia rũũĩ, na yarĩ na hĩa igĩrĩ, nacio ciarĩ ndaaya. Rũhĩa rũmwe rwarĩ rũraihu gũkĩra rũrĩa rũngĩ, o na gũtuĩka nĩruo rwamerete thuutha.
4 Mo rí àgbò náà ó ń kàn sí ìhà ìwọ̀-oòrùn, sí àríwá, àti sí gúúsù, kò sí ẹranko kankan tí ó le è dojúkọ ọ́, kò sí ẹnìkan tí ó le è yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ agbára rẹ̀, ó ń ṣe bí ó ti wù ú, ó sì di alágbára.
Ngĩcooka ngĩona ndũrũme ĩyo yaguthũka ĩrorete mwena wa ithũĩro na wa gathigathini na wa gũthini, no gũtirĩ nyamũ o na ĩmwe ĩngĩahotire kũmĩĩtiiria, na gũtirĩ ĩngĩahotire kwĩhonokia kuuma harĩ hinya wayo. Yekaga o ta ũrĩa ĩngĩendire gwĩka, nayo ĩkĩgĩa na hinya mũno.
5 Bí mo ṣe ń ronú nípa èyí, lójijì ni òbúkọ kan tí ó ní ìwo láàrín ojú u rẹ̀ méjèèjì jáde láti ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó la gbogbo ayé kọjá láìfi ara kan ilẹ̀.
Na rĩrĩa ndacũũranagia ũhoro ũcio, o rĩmwe hagĩũka thenge yumĩte mwena wa ithũĩro, ĩtuĩkanĩirie thĩ yothe ĩtekũhutia thĩ, nayo thenge ĩyo yarĩ na rũhĩa rũmwe rũnene thiithi-inĩ.
6 Ó tọ àgbò tí ó ni ìwo méjì náà wá, èyí tí mo rí tó dúró sí ẹ̀gbẹ́ odò Ulai, ó sì dojúkọ ọ́ pẹ̀lú ìrunú tí ó lágbára.
Ĩgĩũka yerekeire harĩ ndũrũme ĩrĩa yarĩ na hĩa igĩrĩ, ĩyo ndoonete ĩrũngiĩ hũgũrũrũ-inĩ cia rũũĩ, ĩkĩmĩguthũkĩra ĩrĩ na mangʼũrĩ manene.
7 Mo rí i tí ó fi ìtara kọlu àgbò náà, ó lu àgbò náà bolẹ̀, ó sì ṣẹ́ ìwo rẹ̀ méjèèjì. Àgbò náà kò sì ní agbára láti dojúkọ ọ́, Òbúkọ náà kàn án mọ́lẹ̀, ó sì fi ẹsẹ̀ tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀, kò sì ṣí ẹni tí ó lè gba àgbò náà là kúrò lọ́wọ́ agbára rẹ̀.
Ngĩona yatharĩkĩra ndũrũme ĩyo ĩrakarĩte mũno, ĩkĩringa ndũrũme ĩyo na ĩkiunanga hĩa ciayo cierĩ. Nayo ndũrũme ĩyo ndĩarĩ na hinya wa kũmĩĩtiiria, nĩ ũndũ ũcio thenge ĩyo ĩkĩmĩgũtha, ĩkĩmĩgũithia thĩ na ĩkĩmĩrangĩrĩria, na gũtirĩ mũndũ ũngĩahotire kũhonokia ndũrũme ĩyo kuuma harĩ hinya wa thenge ĩyo.
8 Òbúkọ náà sì di alágbára púpọ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí ó dé góńgó, agbára rẹ̀ ru sókè, ìwo ńlá a rẹ̀ sì ṣẹ́ dànù, ní ipò o rẹ̀, ìwo mẹ́rin mìíràn hù, ó sì yọrí sí ìhà igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ọ̀run.
Thenge ĩyo ĩkĩgĩa na hinya mũno, no rĩrĩa hinya wayo waingĩhire mũno-rĩ, rũhĩa rũu rwayo rũnene rũkiunĩka, na ithenya rĩaruo hakĩmera hĩa ingĩ inya nene, irorete mĩena ĩna ĩrĩa huho iria cia igũrũ ihurutanaga.
9 Lára ọ̀kan nínú wọn, ìwo mìíràn yọ jáde, ó kékeré, ṣùgbọ́n ó dàgbà nínú agbára sí ìhà gúúsù, àti sí ìhà ìlà-oòrùn àti sí ilẹ̀ dídára.
Na rĩrĩ, rũmwe rwacio rũkĩmerererwo nĩ rũhĩa rũngĩ, rũrĩa rwambĩrĩirie rũrĩ rũnini, no rũgĩkũra rũkĩgĩa na hinya rwerekeire mwena wa gũthini, na wa irathĩro, na wa Bũrũri ũrĩa Mũthaka.
10 Ó sì dàgbà títí ó fi kan ẹgbẹ́ ogun ọ̀run, ó sì jù lára àwọn ẹgbẹ́ ogun ọ̀run sí ayé ó sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀,
Rũkĩraiha nginya rũgĩkinyĩra mbũtũ cia igũrũ, na rũkĩrutũrũra mbũtũ imwe rũgĩcigũithia thĩ na rũgĩcirangĩrĩria.
11 ó sì gbé ara rẹ̀ ga gẹ́gẹ́ bí ọmọ-aládé ẹgbẹ́ ogun ọ̀run; ó sì mú ẹbọ ojoojúmọ́ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì gba ààyè ibi mímọ́ rẹ̀.
Rũgĩĩtũũgĩria rũnenehe rũiganane na Mũtongoria wa mbũtũ icio cia igũrũ; rũkĩeheria magongona marĩa maacinagwo o mũthenya kuuma harĩ we, nakĩo gĩikaro gĩake kĩrĩa kĩamũre gĩkĩngʼaũranio.
12 A fún un ní ẹgbẹ́ ogun ọ̀run àti ẹbọ ojoojúmọ́ nítorí ìwà ọlọ̀tẹ̀ ẹ rẹ̀, ó sọ òtítọ́ nù nínú gbogbo ohun tó ṣe.
Nĩ ũndũ wa ũremi, mbũtũ cia andũ arĩa atheru na magongona ma o mũthenya makĩneanwo harĩ ruo. Rũkĩgaacĩra maũndũ-inĩ mothe marĩa rwekire, naguo ũhoro wa ma ũgĩteanĩrio.
13 Nígbà náà, ni mo gbọ́ tí ẹni mímọ́ ń sọ̀rọ̀, àti ẹni mímọ́ mìíràn sọ̀rọ̀ fún un pé, “Yóò ti pẹ́ tó tí ìran yìí yóò fi wá sí ìmúṣẹ—ìran nípa ẹbọ ojoojúmọ́, ìṣọ̀tẹ̀ tí ó mú ìsọdahoro wa, àní láti fi ibi mímọ́ àti ogun ọ̀run fún ni ní ìtẹ̀mọ́lẹ̀?”
Ningĩ ngĩcooka ngĩigua ũmwe wa andũ arĩa atheru akĩaria, nake ũngĩ mũtheru akĩmũũria atĩrĩ, “Kĩoneki gĩkĩ-rĩ, gĩgũikara ihinda rĩigana atĩa gĩgĩkahingio: kĩoneki kĩu gĩkoniĩ magongona ma o mũthenya, na ũremi ũcio wa kũrehe ihooru, na kũneanwo gwa gĩikaro kĩrĩa gĩtheru, na kũrangĩrĩrio thĩ kwa mbũtũ?”
14 Ó sọ fún mi pé, “Yóò gbà tó ẹgbọ̀kànlá lé lọ́gọ́rùn-ún alẹ́ àti òwúrọ̀; lẹ́yìn náà ni a ó tún ibi mímọ́ yà sí mímọ́.”
Nake akĩnjookeria atĩrĩ: “Ũhoro ũcio ũgũikara matukũ 2,300; na thuutha ũcio gĩikaro kĩu gĩtheru nĩgĩkaamũrwo rĩngĩ.”
15 Nígbà tí èmi Daniẹli, ń wo ìran náà, mo sì ń fẹ́ kí ó yé mi, ẹnìkan tí ó sì dúró níwájú mi.
Rĩrĩa niĩ Danieli nderoragĩra kĩoneki kĩu o ngĩgeragia kũmenya gĩtũmi gĩakĩo-rĩ, hau mbere yakwa hakĩrũgama ũmwe wahaanaga ta mũndũ.
16 Mo gbọ́ ohùn ènìyàn ní ẹ̀gbẹ́ Ulai, tí ó ń ké pé “Gabrieli, sọ ìtumọ̀ ìran náà fún ọkùnrin yìí.”
Na ngĩigua mũgambo wa mũndũ ũgĩĩtana kuuma Rũũĩ rwa Ulai, ũkiuga atĩrĩ, “Wee Gaburieli, ta taũrĩra mũndũ ũyũ gĩtũmi gĩa kĩoneki kĩu onete.”
17 Bí ó ṣe súnmọ́ ibi tí mo dúró sí, ẹ̀rù bà mí, mo sì dọ̀bálẹ̀. Ó ń sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ́ kí ó yé ọ pé ìran náà ń sọ nípa ìgbà ìkẹyìn ni.”
Na rĩrĩa aakuhĩrĩirie harĩa ndarũgamĩte, ngĩtuĩka nda, ngĩgwa ngĩturumithia ũthiũ thĩ. Nake akĩnjĩĩra atĩrĩ: “Mũrũ wa mũndũ, nĩ wega ũmenye atĩ kĩoneki kĩu gĩkoniĩ mahinda ma ithirĩro.”
18 Bí ó ṣe ń bá mi sọ̀rọ̀, mo ti sùn lọ fọnfọn, bí mo ṣe da ojú bolẹ̀. Nígbà náà ni ó fi ọwọ́ kàn mí, ó sì gbé mi dúró lórí ẹsẹ̀ mi.
Hĩndĩ ĩyo aanjaragĩria-rĩ, ndaarĩ toro mũnene, ngakoma ndurumithĩtie ũthiũ thĩ. Nake akĩĩhutia na akĩnjũkĩria, akĩndũgamia na igũrũ.
19 Ó sọ wí pé, “Èmi yóò sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ìkẹyìn ní ìgbà ìbínú, nítorí ìran náà jẹ mọ́ àkókò ohun tí a yàn nígbà ìkẹyìn.
Akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Nĩngũkwĩra ũrĩa gũkaahaana thuutha-inĩ hĩndĩ ya mangʼũrĩ, tondũ rĩrĩ, kĩoneki gĩkĩ gĩkoniĩ mahinda marĩa maathĩrĩirio ma ithirĩro.
20 Àgbò oníwo méjì tí o rí, òun ni ó dúró gẹ́gẹ́ bí àwọn ọba Media àti Persia.
Ndũrũme ĩyo wonire ĩrĩ na hĩa igĩrĩ, hĩa icio irũgamĩrĩire athamaki a Media na Perisia.
21 Òbúkọ onírun náà ni ọba Giriki, ìwo ńlá ti ó wà láàrín ojú u rẹ̀ ni ọba àkọ́kọ́.
Nayo thenge ĩyo ĩrĩ na maguoya maingĩ mwĩrĩ nĩo mũthamaki wa Ũyunani, na rũhĩa rũu rũnene rũrĩ thiithi nĩruo mũthamaki wakuo wa mbere.
22 Ìwo mẹ́rin mìíràn sì dìde dúró dípò ọ̀kan tí ó ṣẹ́, èyí dúró gẹ́gẹ́ bí ìjọba mẹ́rin tí yóò dìde nínú orílẹ̀-èdè náà, ṣùgbọ́n wọn kì yóò ní ní irú agbára kan náà.
Hĩa icio inya ciamerire ithenya rĩa rũhĩa rũu ruoinĩkire irũgamĩrĩire mothamaki mana marĩa makoima thĩinĩ wa bũrũri wake, no matigaakorwo marĩ na ũhoti ta wake.
23 “Ní ìgbà ìkẹyìn ìjọba wọn, nígbà tí àwọn oníwà búburú bá dé ní kíkún, ni ọba kan yóò dìde, tí ojú rẹ̀ le koko, tí ó sì mòye ọ̀rọ̀ àrékérekè.
“Ningĩ mahinda ma kũrigĩrĩria ma ũthamaki wao, rĩrĩa andũ aremi magaakorwo maaganĩte biũ, nĩgũkarahũka mũthamaki ũngĩ ũtarĩ tha, mũndũ mwara na mũũgĩ na maũndũ ma ungumania.
24 Yóò di alágbára, ṣùgbọ́n tí kì í ṣe nípa agbára rẹ̀. Yóò sì máa ṣe ìparun tí yóò ya ni lẹ́nu, yóò sì máa ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tó ń ṣe. Yóò sì run àwọn alágbára àti àwọn ènìyàn mímọ́.
Nĩakagĩa na hinya mũno, no ti ũndũ wa ũhoti wake mwene. Nĩakarehithia mwanangĩko wa kũmakania, ningĩ nĩakagaacĩra ũndũ-inĩ wothe ageeka. Nĩakaniina andũ arĩa marĩ hinya na andũ arĩa a Ngai.
25 Nípa àrékérekè rẹ̀, yóò mú kí ẹ̀tàn gbèrú, yóò gbé ara rẹ̀ ga nínú ọkàn rẹ̀, nígbà tí wọ́n rò wí pé àlàáfíà dé, yóò sì pa àwọn ènìyàn run, nígbà tí wọn kò rò tẹ́lẹ̀, yóò sì lòdì sí olórí àwọn ọmọ-aládé, síbẹ̀, a ó pa á run ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa agbára ènìyàn.
Nĩagatũma maũndũ ma maheeni magaacĩre, na nĩakeyona arĩ mũnene gũkĩra andũ arĩa angĩ. Rĩrĩa makaigua ta kũrĩ thayũ nĩguo nake akooragithia andũ aingĩ, o na okĩrĩre Mũnene wa anene. No rĩrĩ, nĩakanangwo, no ti hinya wa mũndũ ũkaamwananga.
26 “Ìran alẹ́ àti ti òwúrọ̀, tí a fihàn ọ́ jẹ́ òtítọ́, ṣùgbọ́n pa ìran náà mọ́, nítorí pé, ó jẹ mọ́ ti ọjọ́ iwájú.”
“Kĩoneki kĩu wonirio kĩa mahwaĩ-inĩ na ma rũciinĩ-rĩ, nĩ kĩa ma, no rĩrĩ, hingĩrĩria ũhoro wa kĩoneki kĩu tondũ gĩkoniĩ mahinda marĩ kũraya gĩgĩkahingio.”
27 Èmi Daniẹli sì ṣe àárẹ̀ fún ọjọ́ mélòó kan. Nígbà náà, mo dìde, mo sì ń bá iṣẹ́ ọba lọ. Ìran náà sì bà mí lẹ́rù, kò sì yé mi.
Nĩ ũndũ ũcio, niĩ Danieli ngĩthirwo nĩ hinya, na ngĩikara ndĩ mũrũaru mĩthenya mĩingĩ. Ngĩcooka ngĩũkĩra, na ngĩthiĩ na mbere kũruta wĩra wa mũthamaki. Nĩndainainirio nĩ kĩoneki kĩu, tondũ ndiahotire gũtaũkĩrwo nĩ ũhoro wakĩo.

< Daniel 8 >