< Daniel 8 >

1 Nígbà tí ó di ọdún kẹta ìjọba Belṣassari ọba, èmi Daniẹli rí ìran kan èyí tí mo ti rí tẹ́lẹ̀.
En la troisième année du règne de Baltasar, une vision m'apparut à moi, Daniel, après celle qui m'était d'abord apparue.
2 Nínú ìran náà, mo rí ara mi nínú ilé ìṣọ́ ní Susa ní agbègbè ìjọba Elamu: nínú ìran náà mo wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ odò Ulai.
J'étais dans le palais à Suse, qui est au pays d'Élam, et j'étais sur la rive du fleuve Ubal.
3 Mo wo òkè mo sì rí àgbò kan tí ó ní ìwo méjì níwájú mi, ó dúró sí ẹ̀gbẹ́ odò Ulai, àwọn ìwo náà sì gùn. Ṣùgbọ́n ọ̀kan gùn ju èkejì lọ, èyí tí ó gùn jù ni ó yọ jáde kẹ́yìn.
Et je levai les yeux, et je regardai; et voilà qu'un bélier se tenait devant l'Ubal. Et il avait de grandes cornes, et l'une était plus grande que l'autre, et allait toujours croissant.
4 Mo rí àgbò náà ó ń kàn sí ìhà ìwọ̀-oòrùn, sí àríwá, àti sí gúúsù, kò sí ẹranko kankan tí ó le è dojúkọ ọ́, kò sí ẹnìkan tí ó le è yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ agbára rẹ̀, ó ń ṣe bí ó ti wù ú, ó sì di alágbára.
Et je vis le bélier frappant de ses cornes du côté de la mer, de l'aquilon et du midi; et devant lui nulle bête ne pouvait tenir, et nul ne pouvait échapper à ses coups, et il fit ce qu'il voulut, et il devint grand.
5 Bí mo ṣe ń ronú nípa èyí, lójijì ni òbúkọ kan tí ó ní ìwo láàrín ojú u rẹ̀ méjèèjì jáde láti ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó la gbogbo ayé kọjá láìfi ara kan ilẹ̀.
Et j'étais là, le regardant; et voilà qu'un jeune bouc vint du sud-ouest, sur la face de toute la terre, et il ne touchait pas à terre; et ce bouc avait une corne entre les yeux.
6 Ó tọ àgbò tí ó ni ìwo méjì náà wá, èyí tí mo rí tó dúró sí ẹ̀gbẹ́ odò Ulai, ó sì dojúkọ ọ́ pẹ̀lú ìrunú tí ó lágbára.
Et il arriva jusqu'au bélier qui avait des cornes, celui que j'avais vu en face de l'Ubal; et il s'élança contre lui dans toute la force de sa fureur.
7 Mo rí i tí ó fi ìtara kọlu àgbò náà, ó lu àgbò náà bolẹ̀, ó sì ṣẹ́ ìwo rẹ̀ méjèèjì. Àgbò náà kò sì ní agbára láti dojúkọ ọ́, Òbúkọ náà kàn án mọ́lẹ̀, ó sì fi ẹsẹ̀ tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀, kò sì ṣí ẹni tí ó lè gba àgbò náà là kúrò lọ́wọ́ agbára rẹ̀.
Et je le vis atteindre le bélier, et il se rua sur lui, et il le frappa, et lui brisa les deux cornes: et le bélier fut sans force pour lui résister en face. Puis il le jeta contre terre, et il le foula aux pieds, et nul n'était là pour délivrer le bélier de ses coups.
8 Òbúkọ náà sì di alágbára púpọ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí ó dé góńgó, agbára rẹ̀ ru sókè, ìwo ńlá a rẹ̀ sì ṣẹ́ dànù, ní ipò o rẹ̀, ìwo mẹ́rin mìíràn hù, ó sì yọrí sí ìhà igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ọ̀run.
Or le bouc grandit à l'excès; et pendant qu'il croissait en force, sa grande corne se brisa, et quatre autres cornes lui poussèrent au-dessous de celle-ci, des quatre côtés du ciel, d'où viennent les vents.
9 Lára ọ̀kan nínú wọn, ìwo mìíràn yọ jáde, ó kékeré, ṣùgbọ́n ó dàgbà nínú agbára sí ìhà gúúsù, àti sí ìhà ìlà-oòrùn àti sí ilẹ̀ dídára.
Et de l'une de ces cornes sortit une autre corne puissante, qui s'éleva prodigieusement contre le midi et contre un peuple fort;
10 Ó sì dàgbà títí ó fi kan ẹgbẹ́ ogun ọ̀run, ó sì jù lára àwọn ẹgbẹ́ ogun ọ̀run sí ayé ó sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀,
Et même elle s'éleva jusqu'à l'armée du ciel; et elle fit tomber du ciel une partie de l'armée et une partie des étoiles, et elles furent foulées aux pieds.
11 ó sì gbé ara rẹ̀ ga gẹ́gẹ́ bí ọmọ-aládé ẹgbẹ́ ogun ọ̀run; ó sì mú ẹbọ ojoojúmọ́ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì gba ààyè ibi mímọ́ rẹ̀.
Et il en fut ainsi, jusqu'à ce que le chef de l'armée eût délivré ses captifs; et à cause de ce bouc les sacrifices furent interrompus, et il prospèrera, et le sanctuaire sera désolé.
12 A fún un ní ẹgbẹ́ ogun ọ̀run àti ẹbọ ojoojúmọ́ nítorí ìwà ọlọ̀tẹ̀ ẹ rẹ̀, ó sọ òtítọ́ nù nínú gbogbo ohun tó ṣe.
Et au lieu de victimes les offrandes furent le péché, et la justice fut renversée à terre. Pour lui, il fera son œuvre, et il prospèrera.
13 Nígbà náà, ni mo gbọ́ tí ẹni mímọ́ ń sọ̀rọ̀, àti ẹni mímọ́ mìíràn sọ̀rọ̀ fún un pé, “Yóò ti pẹ́ tó tí ìran yìí yóò fi wá sí ìmúṣẹ—ìran nípa ẹbọ ojoojúmọ́, ìṣọ̀tẹ̀ tí ó mú ìsọdahoro wa, àní láti fi ibi mímọ́ àti ogun ọ̀run fún ni ní ìtẹ̀mọ́lẹ̀?”
Et j'entendis l'un des saints qui parlait, et l'un des saints dit à un autre qui m'était inconnu: Jusques à quand durera cette vision des sacrifices abolis, du péché, cause de cette désolation, du sanctuaire et de l'armée céleste foulés aux pieds.
14 Ó sọ fún mi pé, “Yóò gbà tó ẹgbọ̀kànlá lé lọ́gọ́rùn-ún alẹ́ àti òwúrọ̀; lẹ́yìn náà ni a ó tún ibi mímọ́ yà sí mímọ́.”
Et le premier répondit: Du soir au matin, durant deux mille quatre cents jours, puis le sanctuaire sera purifié.
15 Nígbà tí èmi Daniẹli, ń wo ìran náà, mo sì ń fẹ́ kí ó yé mi, ẹnìkan tí ó sì dúró níwájú mi.
Et ceci advint: tandis que moi, Daniel, j'avais cette vision et que je cherchais à la comprendre, voilà que la vision d'un homme se dressa devant moi.
16 Mo gbọ́ ohùn ènìyàn ní ẹ̀gbẹ́ Ulai, tí ó ń ké pé “Gabrieli, sọ ìtumọ̀ ìran náà fún ọkùnrin yìí.”
Et j'entendis une voix d'homme, entre l'Ubal et moi, et elle appela et dit: Gabriel, explique à celui-ci sa vision.
17 Bí ó ṣe súnmọ́ ibi tí mo dúró sí, ẹ̀rù bà mí, mo sì dọ̀bálẹ̀. Ó ń sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ́ kí ó yé ọ pé ìran náà ń sọ nípa ìgbà ìkẹyìn ni.”
Et Gabriel s'approcha, et il se tint auprès de moi, et pendant qu'il venait j'étais frappé de crainte; et je tombai la face contre terre, et il me dit: Comprends, fils de l'homme; car cette vision s'accomplira au temps marqué.
18 Bí ó ṣe ń bá mi sọ̀rọ̀, mo ti sùn lọ fọnfọn, bí mo ṣe da ojú bolẹ̀. Nígbà náà ni ó fi ọwọ́ kàn mí, ó sì gbé mi dúró lórí ẹsẹ̀ mi.
Et pendant qu'il me dit ces paroles, je retombai encore la face contre terre, et il me toucha, et il me remit debout sur mes pieds.
19 Ó sọ wí pé, “Èmi yóò sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ìkẹyìn ní ìgbà ìbínú, nítorí ìran náà jẹ mọ́ àkókò ohun tí a yàn nígbà ìkẹyìn.
Et il me dit: Je vais te faire savoir ce qui adviendra aux derniers jours de la colère; car c'est aussi le temps marqué pour l'accomplissement de ta vision.
20 Àgbò oníwo méjì tí o rí, òun ni ó dúró gẹ́gẹ́ bí àwọn ọba Media àti Persia.
Le bélier que tu as vu ayant des cornes est le roi des Mèdes et des Perses.
21 Òbúkọ onírun náà ni ọba Giriki, ìwo ńlá ti ó wà láàrín ojú u rẹ̀ ni ọba àkọ́kọ́.
Le bouc est le roi des Hellènes; et la grande corne qu'il avait entre les deux yeux est leur premier roi.
22 Ìwo mẹ́rin mìíràn sì dìde dúró dípò ọ̀kan tí ó ṣẹ́, èyí dúró gẹ́gẹ́ bí ìjọba mẹ́rin tí yóò dìde nínú orílẹ̀-èdè náà, ṣùgbọ́n wọn kì yóò ní ní irú agbára kan náà.
Et quand elle a été brisée, les quatre cornes qui se sont élevées au- dessous sont quatre rois qui s'élèveront parmi les nations, mais non par leur propre force.
23 “Ní ìgbà ìkẹyìn ìjọba wọn, nígbà tí àwọn oníwà búburú bá dé ní kíkún, ni ọba kan yóò dìde, tí ojú rẹ̀ le koko, tí ó sì mòye ọ̀rọ̀ àrékérekè.
Et à la fin de leurs règnes, quand la mesure de leurs péchés sera remplie, un roi s'élèvera, au front impudent, comprenant les énigmes.
24 Yóò di alágbára, ṣùgbọ́n tí kì í ṣe nípa agbára rẹ̀. Yóò sì máa ṣe ìparun tí yóò ya ni lẹ́nu, yóò sì máa ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tó ń ṣe. Yóò sì run àwọn alágbára àti àwọn ènìyàn mímọ́.
Et sa force sera grande, et il détruira des choses admirables, et il prospèrera, et il entreprendra, et il détruira les forts et le peuple saint.
25 Nípa àrékérekè rẹ̀, yóò mú kí ẹ̀tàn gbèrú, yóò gbé ara rẹ̀ ga nínú ọkàn rẹ̀, nígbà tí wọ́n rò wí pé àlàáfíà dé, yóò sì pa àwọn ènìyàn run, nígbà tí wọn kò rò tẹ́lẹ̀, yóò sì lòdì sí olórí àwọn ọmọ-aládé, síbẹ̀, a ó pa á run ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa agbára ènìyàn.
Et le joug de sa chaîne sera bien dirigé; la fraude à la main, il se glorifiera en son cœur; il fera périr par ses ruses une multitude d'hommes, et il s'affermira par la ruine de plusieurs; et il les écrasera comme un œuf dans la main.
26 “Ìran alẹ́ àti ti òwúrọ̀, tí a fihàn ọ́ jẹ́ òtítọ́, ṣùgbọ́n pa ìran náà mọ́, nítorí pé, ó jẹ mọ́ ti ọjọ́ iwájú.”
Cette vision que tu as eue du soir au matin est véritable; mets-y le sceau, parce qu'elle ne s'accomplira qu'après bien des jours.
27 Èmi Daniẹli sì ṣe àárẹ̀ fún ọjọ́ mélòó kan. Nígbà náà, mo dìde, mo sì ń bá iṣẹ́ ọba lọ. Ìran náà sì bà mí lẹ́rù, kò sì yé mi.
Après cela, moi, Daniel, je fus alité et je tombai dans la langueur; puis je me levai, et je m'appliquai aux affaires du roi, et je fus émerveillé de ma vision; mais il n'y eut personne pour la comprendre.

< Daniel 8 >