< Daniel 8 >

1 Nígbà tí ó di ọdún kẹta ìjọba Belṣassari ọba, èmi Daniẹli rí ìran kan èyí tí mo ti rí tẹ́lẹ̀.
During the third year that Belshazzar was the King [of Babylonia], I had another vision.
2 Nínú ìran náà, mo rí ara mi nínú ilé ìṣọ́ ní Susa ní agbègbè ìjọba Elamu: nínú ìran náà mo wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ odò Ulai.
In that vision I was in Susa, the capital city of Elam Province. I was [standing] alongside the Ulai Canal.
3 Mo wo òkè mo sì rí àgbò kan tí ó ní ìwo méjì níwájú mi, ó dúró sí ẹ̀gbẹ́ odò Ulai, àwọn ìwo náà sì gùn. Ṣùgbọ́n ọ̀kan gùn ju èkejì lọ, èyí tí ó gùn jù ni ó yọ jáde kẹ́yìn.
I looked up and saw a ram that was standing alongside the canal. It had two [long] horns, but the newest one was longer than the other one.
4 Mo rí àgbò náà ó ń kàn sí ìhà ìwọ̀-oòrùn, sí àríwá, àti sí gúúsù, kò sí ẹranko kankan tí ó le è dojúkọ ọ́, kò sí ẹnìkan tí ó le è yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ agbára rẹ̀, ó ń ṣe bí ó ti wù ú, ó sì di alágbára.
The ram butted/knocked away [with its horns] everything that was west and everything that was north and everything that was south of it. There were no [other] animals that were able to oppose it, and none that could rescue/save [other animals] from its power. The ram did whatever it wanted to do and became very powerful.
5 Bí mo ṣe ń ronú nípa èyí, lójijì ni òbúkọ kan tí ó ní ìwo láàrín ojú u rẹ̀ méjèèjì jáde láti ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó la gbogbo ayé kọjá láìfi ara kan ilẹ̀.
While I was thinking [about what I had seen, in the vision] I saw a goat come from the west. It ran across the land so quickly, that [it seemed like] its feet did not touch the ground. This goat had one very large horn between its eyes.
6 Ó tọ àgbò tí ó ni ìwo méjì náà wá, èyí tí mo rí tó dúró sí ẹ̀gbẹ́ odò Ulai, ó sì dojúkọ ọ́ pẹ̀lú ìrunú tí ó lágbára.
It was very angry, and it ran [straight] toward the ram that I had seen [previously, the ram] that was standing alongside the canal.
7 Mo rí i tí ó fi ìtara kọlu àgbò náà, ó lu àgbò náà bolẹ̀, ó sì ṣẹ́ ìwo rẹ̀ méjèèjì. Àgbò náà kò sì ní agbára láti dojúkọ ọ́, Òbúkọ náà kàn án mọ́lẹ̀, ó sì fi ẹsẹ̀ tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀, kò sì ṣí ẹni tí ó lè gba àgbò náà là kúrò lọ́wọ́ agbára rẹ̀.
The goat struck the ram furiously and broke off its two horns, with the result that the ram was unable [to defend itself]. [So] the goat knocked the ram down and trampled on it. No one could rescue the ram from the goat’s power.
8 Òbúkọ náà sì di alágbára púpọ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí ó dé góńgó, agbára rẹ̀ ru sókè, ìwo ńlá a rẹ̀ sì ṣẹ́ dànù, ní ipò o rẹ̀, ìwo mẹ́rin mìíràn hù, ó sì yọrí sí ìhà igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ọ̀run.
The goat became very powerful. But when its power was very great, its horn was broken off. But four [other] large horns took its place. They each pointed in a different direction.
9 Lára ọ̀kan nínú wọn, ìwo mìíràn yọ jáde, ó kékeré, ṣùgbọ́n ó dàgbà nínú agbára sí ìhà gúúsù, àti sí ìhà ìlà-oòrùn àti sí ilẹ̀ dídára.
[Then] from one of those [large horns] appeared a little horn, which became very big, [and pointed] toward the south and [then] toward the east and [then] toward the beautiful land [of Israel].
10 Ó sì dàgbà títí ó fi kan ẹgbẹ́ ogun ọ̀run, ó sì jù lára àwọn ẹgbẹ́ ogun ọ̀run sí ayé ó sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀,
[The man who was represented by] that horn became very strong, with the result that he attacked some of the [soldiers of the] army of heaven, and (OR, meaning) the stars in the sky [which represented God’s people]. He threw some of them to the ground and trampled on them.
11 ó sì gbé ara rẹ̀ ga gẹ́gẹ́ bí ọmọ-aládé ẹgbẹ́ ogun ọ̀run; ó sì mú ẹbọ ojoojúmọ́ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì gba ààyè ibi mímọ́ rẹ̀.
He (defied/considered himself to be greater than) the leader of the army [of heaven], and prevented [priests from] offering sacrifices to him. He also (defiled the temple/caused the temple to become unholy).
12 A fún un ní ẹgbẹ́ ogun ọ̀run àti ẹbọ ojoojúmọ́ nítorí ìwà ọlọ̀tẹ̀ ẹ rẹ̀, ó sọ òtítọ́ nù nínú gbogbo ohun tó ṣe.
Then God’s people allowed the [man who was represented by] that horn to control/rule them, with the result that they sinned by offering sacrifices to him. And he threw to the ground the [laws that contained the] true religion. Everything that he did was successful.
13 Nígbà náà, ni mo gbọ́ tí ẹni mímọ́ ń sọ̀rọ̀, àti ẹni mímọ́ mìíràn sọ̀rọ̀ fún un pé, “Yóò ti pẹ́ tó tí ìran yìí yóò fi wá sí ìmúṣẹ—ìran nípa ẹbọ ojoojúmọ́, ìṣọ̀tẹ̀ tí ó mú ìsọdahoro wa, àní láti fi ibi mímọ́ àti ogun ọ̀run fún ni ní ìtẹ̀mọ́lẹ̀?”
Then I heard two angels who were talking to each other. One of them asked, “How long will the things/events that were in this vision continue? How long will the man who rebels against God and causes [the temple] to be defiled be able to prevent [priests from] offering sacrifices? How long will he trample on the temple and on the armies of heaven?”
14 Ó sọ fún mi pé, “Yóò gbà tó ẹgbọ̀kànlá lé lọ́gọ́rùn-ún alẹ́ àti òwúrọ̀; lẹ́yìn náà ni a ó tún ibi mímọ́ yà sí mímọ́.”
The other angel replied, “[It will continue] for 1,150 days. During all of that time, [people will not be permitted to offer sacrifices] in the morning or in the evening. After that, the temple will be purified.”
15 Nígbà tí èmi Daniẹli, ń wo ìran náà, mo sì ń fẹ́ kí ó yé mi, ẹnìkan tí ó sì dúró níwájú mi.
While I, Daniel, was trying to understand what the vision meant, suddenly [an angel] who resembled a man stood/appeared in front of me.
16 Mo gbọ́ ohùn ènìyàn ní ẹ̀gbẹ́ Ulai, tí ó ń ké pé “Gabrieli, sọ ìtumọ̀ ìran náà fún ọkùnrin yìí.”
And I heard a man call out from [the other side of] the Ulai Canal, saying, “Gabriel, explain to him the meaning of the vision [that he saw]!”
17 Bí ó ṣe súnmọ́ ibi tí mo dúró sí, ẹ̀rù bà mí, mo sì dọ̀bálẹ̀. Ó ń sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ́ kí ó yé ọ pé ìran náà ń sọ nípa ìgbà ìkẹyìn ni.”
So Gabriel came and stood beside me. I was very terrified, with the result that I fell onto the ground. But he said to me, “You human, it is necessary for you to understand that [the events that you saw in] the vision will occur [near] the time that [the world] will end.”
18 Bí ó ṣe ń bá mi sọ̀rọ̀, mo ti sùn lọ fọnfọn, bí mo ṣe da ojú bolẹ̀. Nígbà náà ni ó fi ọwọ́ kàn mí, ó sì gbé mi dúró lórí ẹsẹ̀ mi.
While he was speaking, I fainted. I lay there, unconscious, with my face still on the ground. But Gabriel put his hand on me and lifted me up in order that I could stand again.
19 Ó sọ wí pé, “Èmi yóò sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ìkẹyìn ní ìgbà ìbínú, nítorí ìran náà jẹ mọ́ àkókò ohun tí a yàn nígbà ìkẹyìn.
Then he said, “I [have come here to] tell you what will happen because of [God] being angry. These things will happen near the time when [the world] will end.
20 Àgbò oníwo méjì tí o rí, òun ni ó dúró gẹ́gẹ́ bí àwọn ọba Media àti Persia.
As for the ram with two horns that you saw, those horns [represent] the kingdoms of Media and Persia.
21 Òbúkọ onírun náà ni ọba Giriki, ìwo ńlá ti ó wà láàrín ojú u rẹ̀ ni ọba àkọ́kọ́.
The goat [that you saw represents] the kingdom of Greece, and the horn that appeared between its eyes [represents] its first king.
22 Ìwo mẹ́rin mìíràn sì dìde dúró dípò ọ̀kan tí ó ṣẹ́, èyí dúró gẹ́gẹ́ bí ìjọba mẹ́rin tí yóò dìde nínú orílẹ̀-èdè náà, ṣùgbọ́n wọn kì yóò ní ní irú agbára kan náà.
As for the four horns that grew after the first horn was broken off, they [represent] four kingdoms into which that first kingdom will be divided [after the first king dies]. Those four kingdoms will not be as strong/powerful as the first kingdom was.
23 “Ní ìgbà ìkẹyìn ìjọba wọn, nígbà tí àwọn oníwà búburú bá dé ní kíkún, ni ọba kan yóò dìde, tí ojú rẹ̀ le koko, tí ó sì mòye ọ̀rọ̀ àrékérekè.
The people [in those kingdoms] will become very wicked, with the result that it will be necessary for them to be punished. But near the time when those kingdoms will end, one of those kingdoms will have a king who will be very proud/defiant [IDM]. He will [also] be very fierce and very deceitful.
24 Yóò di alágbára, ṣùgbọ́n tí kì í ṣe nípa agbára rẹ̀. Yóò sì máa ṣe ìparun tí yóò ya ni lẹ́nu, yóò sì máa ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tó ń ṣe. Yóò sì run àwọn alágbára àti àwọn ènìyàn mímọ́.
He will become very powerful, but it will not be because of what he himself does. He will terribly destroy things in many places, and he will succeed in doing everything that he wants to. He will get rid of [many] powerful men, and [also] some of God’s people.
25 Nípa àrékérekè rẹ̀, yóò mú kí ẹ̀tàn gbèrú, yóò gbé ara rẹ̀ ga nínú ọkàn rẹ̀, nígbà tí wọ́n rò wí pé àlàáfíà dé, yóò sì pa àwọn ènìyàn run, nígbà tí wọn kò rò tẹ́lẹ̀, yóò sì lòdì sí olórí àwọn ọmọ-aládé, síbẹ̀, a ó pa á run ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa agbára ènìyàn.
Because he is very cunning/clever, he will succeed by doing things that deceive many people. He will be proud of himself. He will destroy many people when they think that they are safe. He will also rebel against [God] [EUP], who is the greatest king. But [God] will destroy him, without the help [MTY] of any human being.
26 “Ìran alẹ́ àti ti òwúrọ̀, tí a fihàn ọ́ jẹ́ òtítọ́, ṣùgbọ́n pa ìran náà mọ́, nítorí pé, ó jẹ mọ́ ti ọjọ́ iwájú.”
What you saw in the vision about [priests being prevented from making] sacrifices in the morning and in the evening, which [I] explained [to you], will surely happen. But [for the present time], do not reveal the vision [to others], because it will be many years before those things happen.”
27 Èmi Daniẹli sì ṣe àárẹ̀ fún ọjọ́ mélòó kan. Nígbà náà, mo dìde, mo sì ń bá iṣẹ́ ọba lọ. Ìran náà sì bà mí lẹ́rù, kò sì yé mi.
Then I, Daniel, became weak, and I was sick for several days. Then I arose and [returned to] doing the work that the king [had given to me], but I was perplexed/confused about the vision, and I could not understand it.

< Daniel 8 >