< Daniel 8 >

1 Nígbà tí ó di ọdún kẹta ìjọba Belṣassari ọba, èmi Daniẹli rí ìran kan èyí tí mo ti rí tẹ́lẹ̀.
Léta třetího kralování Balsazara krále ukázalo mi se vidění, mně Danielovi po onom, kteréž se mi ukázalo na počátku.
2 Nínú ìran náà, mo rí ara mi nínú ilé ìṣọ́ ní Susa ní agbègbè ìjọba Elamu: nínú ìran náà mo wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ odò Ulai.
I viděl jsem u vidění, (tehdáž pak, když jsem viděl, byl jsem v Susan, na hradě, kterýž jest v krajině Elam), viděl jsem, pravím, byv u potoka Ulai.
3 Mo wo òkè mo sì rí àgbò kan tí ó ní ìwo méjì níwájú mi, ó dúró sí ẹ̀gbẹ́ odò Ulai, àwọn ìwo náà sì gùn. Ṣùgbọ́n ọ̀kan gùn ju èkejì lọ, èyí tí ó gùn jù ni ó yọ jáde kẹ́yìn.
A pozdvih očí svých, viděl jsem, a aj, u toho potoka stál skopec jeden, kterýž měl dva rohy. A ti dva rohové byli vysocí, a však jeden vyšší než druhý, ale ten vyšší zrostl posléze.
4 Mo rí àgbò náà ó ń kàn sí ìhà ìwọ̀-oòrùn, sí àríwá, àti sí gúúsù, kò sí ẹranko kankan tí ó le è dojúkọ ọ́, kò sí ẹnìkan tí ó le è yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ agbára rẹ̀, ó ń ṣe bí ó ti wù ú, ó sì di alágbára.
Viděl jsem skopce toho, an trkal k západu, půlnoci a poledni, jemuž žádná šelma odolati nemohla, aniž kdo co mohl vytrhnouti z moci jeho; pročež činil podlé vůle své, a to věci veliké.
5 Bí mo ṣe ń ronú nípa èyí, lójijì ni òbúkọ kan tí ó ní ìwo láàrín ojú u rẹ̀ méjèèjì jáde láti ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó la gbogbo ayé kọjá láìfi ara kan ilẹ̀.
A když jsem to rozvažoval, aj, kozel přicházel od západu na svrchek vší země, a žádný se ho nedotýkal na zemi, a ten kozel měl roh znamenitý mezi očima svýma.
6 Ó tọ àgbò tí ó ni ìwo méjì náà wá, èyí tí mo rí tó dúró sí ẹ̀gbẹ́ odò Ulai, ó sì dojúkọ ọ́ pẹ̀lú ìrunú tí ó lágbára.
A přišel až k tomu skopci majícímu dva rohy, kteréhož jsem byl viděl stojícího u potoka, a přiběhl k němu v prchlivosti síly své.
7 Mo rí i tí ó fi ìtara kọlu àgbò náà, ó lu àgbò náà bolẹ̀, ó sì ṣẹ́ ìwo rẹ̀ méjèèjì. Àgbò náà kò sì ní agbára láti dojúkọ ọ́, Òbúkọ náà kàn án mọ́lẹ̀, ó sì fi ẹsẹ̀ tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀, kò sì ṣí ẹni tí ó lè gba àgbò náà là kúrò lọ́wọ́ agbára rẹ̀.
Viděl jsem také, an dotřel na toho skopce, a rozlítiv se proti němu, udeřil jej, tak že zlámal oba rohy jeho, a nebylo síly v skopci k odpírání jemu. A poraziv ho na zemi, pošlapal jej, aniž byl, kdo by vytrhl skopce z moci jeho.
8 Òbúkọ náà sì di alágbára púpọ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí ó dé góńgó, agbára rẹ̀ ru sókè, ìwo ńlá a rẹ̀ sì ṣẹ́ dànù, ní ipò o rẹ̀, ìwo mẹ́rin mìíràn hù, ó sì yọrí sí ìhà igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ọ̀run.
Kozel pak velikým učiněn jest velmi. A když se ssilil, zlámal se roh ten veliký, i zrostli znamenití čtyři místo něho, na čtyři strany světa.
9 Lára ọ̀kan nínú wọn, ìwo mìíràn yọ jáde, ó kékeré, ṣùgbọ́n ó dàgbà nínú agbára sí ìhà gúúsù, àti sí ìhà ìlà-oòrùn àti sí ilẹ̀ dídára.
Z těch pak jednoho vyšel roh jeden maličký, a zrostl velmi ku poledni a východu, a k zemi Judské.
10 Ó sì dàgbà títí ó fi kan ẹgbẹ́ ogun ọ̀run, ó sì jù lára àwọn ẹgbẹ́ ogun ọ̀run sí ayé ó sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀,
A zpjal se až k vojsku nebeskému, a svrhl na zemi některé z vojska toho i z hvězd, a pošlapal je.
11 ó sì gbé ara rẹ̀ ga gẹ́gẹ́ bí ọmọ-aládé ẹgbẹ́ ogun ọ̀run; ó sì mú ẹbọ ojoojúmọ́ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì gba ààyè ibi mímọ́ rẹ̀.
Anobrž až k vojska toho knížeti zpjal se, nebo od něho zastavena byla ustavičná obět, a zavržen příbytek svatyně Boží,
12 A fún un ní ẹgbẹ́ ogun ọ̀run àti ẹbọ ojoojúmọ́ nítorí ìwà ọlọ̀tẹ̀ ẹ rẹ̀, ó sọ òtítọ́ nù nínú gbogbo ohun tó ṣe.
Tak že vojsko to vydáno v převrácenost proti ustavičné oběti, a povrhlo pravdu na zemi, a což činilo, šťastně mu se dařilo.
13 Nígbà náà, ni mo gbọ́ tí ẹni mímọ́ ń sọ̀rọ̀, àti ẹni mímọ́ mìíràn sọ̀rọ̀ fún un pé, “Yóò ti pẹ́ tó tí ìran yìí yóò fi wá sí ìmúṣẹ—ìran nípa ẹbọ ojoojúmọ́, ìṣọ̀tẹ̀ tí ó mú ìsọdahoro wa, àní láti fi ibi mímọ́ àti ogun ọ̀run fún ni ní ìtẹ̀mọ́lẹ̀?”
Tedy slyšel jsem jednoho svatého mluvícího, a řekl ten svatý tomu, kterýž tajné věci v počtu maje, mluví: Dokudž toto vidění o oběti ustavičné, a převrácenost na zpuštění přivodící trvati bude, a svaté služby vydávány budou i vojsko v pošlapání?
14 Ó sọ fún mi pé, “Yóò gbà tó ẹgbọ̀kànlá lé lọ́gọ́rùn-ún alẹ́ àti òwúrọ̀; lẹ́yìn náà ni a ó tún ibi mímọ́ yà sí mímọ́.”
A řekli mi: Až do dvou tisíc a tří set večerů a jiter, a přijdou k obnovení svému svaté služby.
15 Nígbà tí èmi Daniẹli, ń wo ìran náà, mo sì ń fẹ́ kí ó yé mi, ẹnìkan tí ó sì dúró níwájú mi.
Stalo se pak, že když jsem já Daniel hleděl na to vidění, a ptal jsem se na rozum jeho, aj, postavil se podlé mne na pohledění jako muž.
16 Mo gbọ́ ohùn ènìyàn ní ẹ̀gbẹ́ Ulai, tí ó ń ké pé “Gabrieli, sọ ìtumọ̀ ìran náà fún ọkùnrin yìí.”
Slyšel jsem také hlas lidský mezi Ulaiem, kterýžto zavolav, řekl: Gabrieli, vylož tomuto vidění to.
17 Bí ó ṣe súnmọ́ ibi tí mo dúró sí, ẹ̀rù bà mí, mo sì dọ̀bálẹ̀. Ó ń sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ́ kí ó yé ọ pé ìran náà ń sọ nípa ìgbà ìkẹyìn ni.”
I přišel ke mně, kdež jsem stál, a když přišel, zhrozil jsem se, a padl jsem na tvář svou. I řekl ke mně: Pozoruj, synu člověčí; nebo v času uloženém vidění toto se naplní.
18 Bí ó ṣe ń bá mi sọ̀rọ̀, mo ti sùn lọ fọnfọn, bí mo ṣe da ojú bolẹ̀. Nígbà náà ni ó fi ọwọ́ kàn mí, ó sì gbé mi dúró lórí ẹsẹ̀ mi.
Když pak on mluvil se mnou, usnul jsem tvrdě, leže tváří svou na zemi. I dotekl se mne, a postavil mne tu, kdež jsem byl stál,
19 Ó sọ wí pé, “Èmi yóò sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ìkẹyìn ní ìgbà ìbínú, nítorí ìran náà jẹ mọ́ àkókò ohun tí a yàn nígbà ìkẹyìn.
A řekl: Aj, já oznámím tobě to, což se díti bude až do vykonání hněvu toho; nebo v uloženém času konec bude.
20 Àgbò oníwo méjì tí o rí, òun ni ó dúró gẹ́gẹ́ bí àwọn ọba Media àti Persia.
Skopec ten, kteréhož jsi viděl, an měl dva rohy, jsou králové Médský a Perský.
21 Òbúkọ onírun náà ni ọba Giriki, ìwo ńlá ti ó wà láàrín ojú u rẹ̀ ni ọba àkọ́kọ́.
Kozel pak ten chlupatý jest král Řecký, a roh ten veliký, kterýž jest mezi očima jeho, jest král první.
22 Ìwo mẹ́rin mìíràn sì dìde dúró dípò ọ̀kan tí ó ṣẹ́, èyí dúró gẹ́gẹ́ bí ìjọba mẹ́rin tí yóò dìde nínú orílẹ̀-èdè náà, ṣùgbọ́n wọn kì yóò ní ní irú agbára kan náà.
Že pak zlámán jest, a povstali čtyři místo něho, čtvero království z svého národu povstane, ale ne s takovou silou.
23 “Ní ìgbà ìkẹyìn ìjọba wọn, nígbà tí àwọn oníwà búburú bá dé ní kíkún, ni ọba kan yóò dìde, tí ojú rẹ̀ le koko, tí ó sì mòye ọ̀rọ̀ àrékérekè.
Při dokonání pak království jejich, když na vrch vzejdou nešlechetníci, povstane král nestydatý a chytrý.
24 Yóò di alágbára, ṣùgbọ́n tí kì í ṣe nípa agbára rẹ̀. Yóò sì máa ṣe ìparun tí yóò ya ni lẹ́nu, yóò sì máa ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tó ń ṣe. Yóò sì run àwọn alágbára àti àwọn ènìyàn mímọ́.
Jehož síla zmocní se, ačkoli ne jeho silou, tak že ku podivení hubiti bude, a šťastně se mu povede, až i vše vykoná; nebo hubiti bude silné i lid svatý.
25 Nípa àrékérekè rẹ̀, yóò mú kí ẹ̀tàn gbèrú, yóò gbé ara rẹ̀ ga nínú ọkàn rẹ̀, nígbà tí wọ́n rò wí pé àlàáfíà dé, yóò sì pa àwọn ènìyàn run, nígbà tí wọn kò rò tẹ́lẹ̀, yóò sì lòdì sí olórí àwọn ọmọ-aládé, síbẹ̀, a ó pa á run ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa agbára ènìyàn.
A obmyslností svou šťastně svede lest v předsevzetí svém, a v srdci svém zvelebí sebe, a v čas pokoje zhubí mnohé; nadto i proti knížeti knížat se postaví, a však bez rukou potřín bude.
26 “Ìran alẹ́ àti ti òwúrọ̀, tí a fihàn ọ́ jẹ́ òtítọ́, ṣùgbọ́n pa ìran náà mọ́, nítorí pé, ó jẹ mọ́ ti ọjọ́ iwájú.”
Vidění pak to večerní a jitřní, o němž povědíno, jest jistá pravda; pročež ty zavři to vidění, nebo jest mnohých dnů.
27 Èmi Daniẹli sì ṣe àárẹ̀ fún ọjọ́ mélòó kan. Nígbà náà, mo dìde, mo sì ń bá iṣẹ́ ọba lọ. Ìran náà sì bà mí lẹ́rù, kò sì yé mi.
Tedy já Daniel zchuravěl jsem, a nemocen jsem byl několik dnů. Potom povstav, konal jsem povinnost od krále poručenou, byv předěšen nad tím viděním, čehož však žádný na mně neseznal.

< Daniel 8 >