< Daniel 7 >

1 Ní ọdún àkọ́kọ́ Belṣassari ọba Babeli, Daniẹli lá àlá kan, ìran náà sì wá sí ọkàn an rẹ̀ bí ó ṣe sùn sórí ibùsùn un rẹ̀, ó sì kọ àlá náà sílẹ̀.
Babylon manghai Belshazzar kah a kum khat dongah Daniel loh amah kah thingkong dongah mang neh a lu dongkah mangthui te a hmuh. Te dongah a mang kah olka a thui te a cuinah ah a daek.
2 Daniẹli sọ pé, “Nínú ìran mi lóru mo wò ó, mo sì rí afẹ́fẹ́ ọ̀run mẹ́rin tí ó ń ru omi Òkun ńlá sókè.
Daniel loh a thui vaengah, “Khoyin kah ka mangthui neh ka om vaengah ka hmuh. Te vaengah vaan kah khohli pali tah tuitun puei duela kilkul.
3 Ẹranko ńlá mẹ́rin tí ó yàtọ̀ sí ara wọn, jáde láti inú Òkun náà.
Te phoeiah rhamsa len pali te tuitunli lamloh ha thoeng tih khat neh khat hlihloeh uh.
4 “Ẹranko kìn-ín-ní dàbí i kìnnìún, ó sì ní ìyẹ́ apá a idì, mo sì wò títí a fi fa ìyẹ́ apá rẹ̀ náà tu, a sì gbé e sókè kúrò ní ilẹ̀, a mú kí ó fi ẹsẹ̀ dúró bí ènìyàn, a sì fi àyà ènìyàn fún un.
A cuek te sathueng bangla om dae a phae tah atha kah bangla ka hmuh. A phae te a poelh uh tih diklai lamloh a huel uh duela ka om. Te phoeiah hlang bangla a khobom dongah pai tih anih te hlang kah thinko a paek.
5 “Mo sì tún rí ẹranko kejì, ó rí bí irú ẹranko ńlá beari kan tí ó ń gbé ilẹ̀ òtútù; o gbé ara sókè ní apá kan, ó sì ní egungun ìhà mẹ́ta láàrín ẹ̀yìn in rẹ̀, wọ́n sì sọ fún un pé, ‘Dìde kí o sì jẹ ẹran tó pọ̀!’
A pabae kah rhamsa pakhat bal tah vom neh lo u tih khat ben ah pai ne. A ka khui kah a no neh a no laklo ah vaerhuh cungthum a koeng tih anih te, “Thoo lamtah a saa he muep ca,” a ti nah.
6 “Lẹ́yìn ìgbà náà, mo tún rí ẹranko kẹta ó rí bí àmọ̀tẹ́kùn. Ẹranko náà ní ìyẹ́ bí i ti ẹyẹ ní ẹ̀yìn, ó sì ní orí mẹ́rin, a sì fún un ní agbára láti ṣe ìjọba.
Te phoeikah te ka sawt vaengah pakhat tah kaihlaeng bangla tarha om. Te te a nam, a nam ah vaa pali kah a phae om. Rhamsa te lu pali lo tih anih te saithainah a paek.
7 “Lẹ́yìn èyí, nínú ìran mi ní òru mo tún rí ẹranko kẹrin, ó dẹ́rùbà ni, ó dáyà fo ni, ó sì lágbára gidigidi. Ó ní eyín irin ńlá; ó ń jẹ, ó sì ń fọ́ túútúú, ó sì fi ẹsẹ̀ tẹ èyí tókù mọ́lẹ̀. Ó yàtọ̀ sí gbogbo àwọn ẹranko ti ìṣáájú, ó sì ní ìwo mẹ́wàá.
Te phoeiah khaw khoyin kah mangthui neh ka hmuh tih ka om. A pali nah rhamsa tah rhimom neh rhihom tih bahoeng tlung. Amah kah thi no a len khaw a ai tih a tip phoeiah a coih te a khobom neh a til. Te tah a taengkah rhamsa boeih lakah tloethoeh tih a ki parha lo.
8 “Bí mo ṣe ń ronú nípa ìwo náà, nígbà náà ni mo rí ìwo mìíràn, tí ó kéré tí ó jáde wá ní àárín wọn; mẹ́ta lára àwọn ìwo ti àkọ́kọ́ sì fàtu níwájú u rẹ̀. Ìwo yìí ní ojú bí i ojú ènìyàn àti ẹnu tí ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga.
A ki te ka poek tih ka om vaengah a ki ca pakhat te a laklung ah tarha cawn. A hmai, a hmai ah a ki cuek te pathum a phuk pauh. Tekah a ki dongah hlang mik bangla mik om tih a ka khaw a len la cal he.
9 “Bí mo ṣe ń wò, “a gbé ìtẹ́ ọba kan kalẹ̀, ẹni ìgbàanì jókòó sórí ìtẹ́ rẹ̀. Aṣọ rẹ̀ funfun bí ẹ̀gbọ̀n òwú; irun orí rẹ̀ funfun bí òwú, ìtẹ́ ọba rẹ̀ rí bí ọwọ́ iná. Àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ ń jó bí i iná.
Ngolkhoel a hol rhoek te ka sawt tih ka om li vaengah tampo khohnin te ngol. A pueinak tah vuel bangla bok tih a lu sam khaw tumul bangla bok. A ngolkhoel tah hmairhong hmai la om tih a kho te hmai la rhong.
10 Odò iná ń sàn, ó ń jáde ní iwájú rẹ̀ wá. Àwọn ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún ń ṣe ìránṣẹ́ fún un; ọ̀nà ẹgbẹẹgbàárùn-ún nígbà ẹgbàárùn-ún dúró níwájú rẹ̀. Àwọn onídàájọ́ jókòó, a sì ṣí ìwé wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀.
Hmai sok te anih taeng lamloh phuet tih long. A thawng a thawng loh thotat uh tih amah taengah a sang a sang la pai uh. Laitloeknah te a hol tih cabu a rha uh.
11 “Nígbà náà ni mo bẹ̀rẹ̀ sí ní wò, nítorí àwọn ọ̀rọ̀ ìgbéraga tí ìwo náà ń sọ, mo wò títí a fi pa ẹranko náà, a sì pa á run, a sì jù ú sínú iná tí ń jó.
Ka sawt tih ka om vaengah a ki loh a thui boeilen olka ol dongah rhamsa a ngawn hil ka om tih ka sawt. Te vaengah a pum te a thup pah tih hmaitak hmaisai khuila a pup.
12 A sì gba ìjọba lọ́wọ́ àwọn ẹranko yòókù, ṣùgbọ́n a fún wọn láààyè láti wà fún ìgbà díẹ̀.
Rhamsa tloe rhoek te a saithainah a khoe pah dae amih hingnah ham te khoning neh a tue a congnah la a paek.
13 “Nínú ìran mi ní òru mo wò, mo rí ẹnìkan tí ó dúró sí iwájú u mi, ó rí bí ọmọ ènìyàn, ó ń bọ̀ wá nínú àwọsánmọ̀ ọ̀run, ó ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ ẹni ìgbàanì, a sì mú u wá sí iwájú rẹ̀.
Khoyin mangthui neh ka om tih ka hmuh. Te vaengah hlang capa phek te vaan kah khomai neh tarha ha pai tih tampo khohnin te a paan. Te phoeiah anih te amah taengla a nawn.
14 A sì fi ìjọba, ògo àti agbára ilẹ̀ ọba fún un; gbogbo ènìyàn, orílẹ̀-èdè àti èdè gbogbo wọn wólẹ̀ fún un. Ìjọba rẹ̀, ìjọba ayérayé ni, èyí tí kò le è kọjá, ìjọba rẹ̀ kò sì le è díbàjẹ́ láéláé.
A taengah saithainah neh thangpomnah neh ram khaw a paek coeng. Te dongah namtu pilnam boeih neh olcom olcae loh amah te a bawk uh. A saithainah khaw kumhal kah saithainah la om tih nong mahpawh. Te dongah a ram he tim tlaih mahpawh.
15 “Ọkàn èmi Daniẹli, dàrú, ìran tí ó wá sọ́kàn mi dẹ́rùbà mí.
Kai Daniel he ka pum khui ah ka mueihla mawn tih ka lu kah mangthui loh kamah n'cahawh.
16 Mo lọ bá ọ̀kan nínú àwọn tí ó dúró níbẹ̀, mo sì bi í léèrè òtítọ́ ìtumọ̀ nǹkan wọ̀nyí. “Ó sọ fún mi, ó sì túmọ̀ àwọn nǹkan wọ̀nyí fún mi:
Aka pai khuikah pakhat te ka paan tih a cungkuem te anih taengah rhep ka dawt. Te dongah kai hamla a thui tih ol kah thuingaihnah te kai m'ming sak.
17 ‘Àwọn ẹranko ńlá mẹ́rin yìí, ni ìjọba mẹ́rin tí yóò dìde ní ayé.
Amih rhamsa len pali he tah diklai lamloh manghai pali pai ni.
18 Ṣùgbọ́n, ẹni mímọ́ ti Ọ̀gá-ògo ni yóò gba ìjọba náà, yóò sì jogún un rẹ títí láé àti títí láéláé.’
Tedae ram te sangkoek kah aka cim rhoek loh a dang uh vetih ram te dungyan duela a pang uh ni. Dungyan kah dungyan duela a pang ni.
19 “Nígbà náà, ni mo fẹ́ mọ ìtumọ̀ òtítọ́ ẹranko kẹrin, tí ó yàtọ̀ sí àwọn yòókù, èyí tí ó dẹ́rùba ni gidigidi, tí ó ní eyín irin àti èékánná idẹ, ẹranko tí ó ń run tí ó sì ń pajẹ, tí ó sì ń fi ẹsẹ̀ tẹ èyí tókù mọ́lẹ̀.
Te vaengah rhamsa pali te oltak la ka ngaih. Amih boeih te a cungkuem dongah a hlihloeh la om tih a no mah bahoeng a rhimom. A no te thi tih a kuttin te rhohum, a hnom tih a ai phoeikah a coih te a khobom neh a til.
20 Bẹ́ẹ̀ ni mo sì fẹ́ mọ̀ nípa ìwo mẹ́wàá orí rẹ̀ àti nípa ìwo yòókù tí ó jáde, nínú èyí tí mẹ́ta lára wọn ṣubú, ìwo tí ó ní ojú, tí ẹnu rẹ̀ ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga.
A lu dongkah a ki parha neh pakhat aka cawn te khaw, a taengah pathum rhoek a rhul la a rhul te khaw, ki loh a mik a khueh bal tih a ka loh a len la a cal khaw, a hui lakah a mangthui a len kawng khaw ka ngaih.
21 Bí mo ṣe ń wò, ìwo yìí ń bá àwọn ènìyàn mímọ́ jagun, ó sì borí i wọn,
Ka om tih ka sawt vaengah tekah ki loh hlang cim rhoek taengah caemtloeknah a saii tih amih te a noeng uh.
22 títí ẹni ìgbàanì fi dé, ó sì ṣe ìdájọ́ ìdáláre fún àwọn ẹni mímọ́ Ọ̀gá-ògo, àsìkò náà sì dé nígbà tí àwọn ẹni mímọ́ náà jogún ìjọba.
Tampo khohnin a pai hil laitloeknah he sangkoek kah a cim rhoek ham a paek coeng. Te dongah a tue a pha vaengah ram he aka cim rhoek loh a pang uh.
23 “Ó ṣe àlàyé yìí fún mi pé, ‘Ẹranko kẹrin ni ìjọba kẹrin tí yóò wà ní ayé. Yóò yàtọ̀ sí gbogbo àwọn ìjọba yòókù yóò sì pa gbogbo ayé run, yóò tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀, yóò sì fọ́ ọ́ sí wẹ́wẹ́.
Rhamsa a pali te, “Diklai ah ram a pali, pali la om ni. Te tah ram boeih lakah tloethoeh vetih diklai pum he a hnom ni. A taelh vetih a tip sak ni,” a ti.
24 Ìwo mẹ́wàá ni ọba mẹ́wàá tí yóò wá láti inú ìjọba yìí. Lẹ́yìn tí wọn ní ọba mìíràn yóò dìde, ti yóò yàtọ̀ sí tí àwọn ti ìṣáájú, yóò sì borí ọba mẹ́ta.
Ki parha tah ram khui lamloh manghai parha pai vetih amih lamloh a tloe phoe bal ni. Anih tah a cuek kah lakah tloethoeh vetih manghai pathum rhoek te a kunyun sak ni.
25 Yóò sọ̀rọ̀ odi sí Ọ̀gá-ògo, yóò sì pọ́n ẹni mímọ́ lójú, yóò sì gbèrò láti yí ìgbà àti òfin padà. A ó fi àwọn ẹni mímọ́ lé e lọ́wọ́ fún ìgbà díẹ̀, ní ọdún méjì àti ààbọ̀.
Sangkoek kah sangkoek soehsalnah te ol la a thui vetih sangkoek kah a cim rhoek te a hnaemtaek ni. Khoning neh oltlueh te thovael hamla cai vetih a kut ah a tue neh kum dongkah kum rhakthuem a paek ni.
26 “‘Ṣùgbọ́n àwọn onídàájọ́ yóò jókòó, nígbà náà ni a ó gba agbára rẹ̀, a ó sì pa á rùn pátápátá títí ayé.
Tedae laitloeknah a khueh vetih yoop ham neh a bawtnah hil thup hamla anih kah saithainah te a khoe pah ni.
27 Nígbà náà, ni a ó gba ìjọba, agbára àti títóbi ìjọba rẹ̀ ní abẹ́ gbogbo ọ̀run, a ó sì fi fún àwọn ẹni mímọ́, àwọn ènìyàn Ọ̀gá-ògo. Ìjọba rẹ̀ yóò jẹ́ ìjọba títí ayé, gbogbo aláṣẹ ni yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí i, wọn yóò sì máa sìn ín.’
Te vaengah ram neh saithainah khaw, vaan pum hmuiah ram kah lennah khaw sangkoek kah a cim pilnam taengah a paek ni. A ram he dungyan ram la a om dongah khohung boeih loh anih taengah tho a thueng uh vetih boe a ngai uh ni.
28 “Báyìí ni àlá náà ṣe parí, ọkàn èmi Daniẹli sì dàrú gidigidi, nítorí èrò ọkàn mi yìí, ojú mi sì yípadà ṣùgbọ́n mo pa ọ̀ràn náà mọ́ ní ọkàn mi.”
He hil he ol bawtnah la om. Kai Daniel khaw, ka poeknah yet tih kamah n'cahawh. Te dongah ka aa khaw kai soah yat dae ol he ka lungbuei ah ka khoem.

< Daniel 7 >