< Daniel 6 >

1 Ó dára lójú Dariusi láti yan ọgọ́fà àwọn baálẹ̀ sórí ìjọba,
Dareju je ugajalo, da postavi nad kraljestvo sto dvajset princev, ki naj bi bili nad celotnim kraljestvom,
2 pẹ̀lú alákòóso mẹ́ta, Daniẹli sì jẹ́ ọ̀kan nínú wọn, kí àwọn baálẹ̀ lè wá máa jẹ́ ààbọ̀ fún wọn, kí ọba má ba à ní ìpalára.
in nad temi tri predstojnike, od katerih je bil Daniel prvi, da bi jim princi lahko dajali obračun in kralj ne bi trpel nobene škode.
3 Daniẹli ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ láàrín àwọn alákòóso àti àwọn baálẹ̀ nítorí ẹ̀mí tí ó tayọ wà lára rẹ̀ dé bi pé ọba sì ń gbèrò láti fi ṣe olórí i gbogbo ìjọba.
Potem je bil ta Daniel povišan nad predstojnike in prince, ker je bil v njem odličen duh, in kralj ga je mislil postaviti nad celotno območje.
4 Nítorí èyí, gbogbo àwọn alákòóso àti àwọn baálẹ̀ ń gbèrò láti wá ẹ̀ṣẹ̀ kà sí Daniẹli lọ́rùn nínú ètò ìṣèjọba rẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò rí ẹ̀ṣẹ̀ kankan kà sí i lọ́rùn, wọn kò rí ìwà ìbàjẹ́ kankan tí ó ṣe, nítorí ó jẹ́ olóòtítọ́ kò sì ní ìwà ìjáfara.
Potem so predstojniki in princi iskali, da najdejo povod zoper Daniela glede kraljestva, toda niso mogli najti nobenega povoda niti krivde, ker je bil zvest niti ni bilo na njem najti nobene napake ali krivde.
5 Nígbẹ̀yìn ni àwọn ọkùnrin wọ̀nyí sọ wí pé, “Àwa kò ní rí ìdí kankan láti kà ẹ̀ṣẹ̀ sí Daniẹli lọ́rùn, àfi èyí tí ó bá ní í ṣe pẹ̀lú òfin Ọlọ́run rẹ̀.”
Potem so ti možje rekli: »Nobenega razloga ne bomo našli zoper tega Daniela, razen če zoper njega najdemo to, kar se tiče postave njegovega Boga.«
6 Nígbà náà ni àwọn alákòóso àti àwọn baálẹ̀ lọ gẹ́gẹ́ bí ikọ̀ sí ọ̀dọ̀ ọba, wọ́n wí pé, “Ìwọ Dariusi ọba, kí o pẹ́!
Potem so se ti predstojniki in princi zbrali skupaj h kralju in mu rekli takole: »Kralj Darej, živi na veke.
7 Àwọn alákòóso ọba, ìjòyè, baálẹ̀, olùdámọ̀ràn, àti àwọn olórí gbìmọ̀ pọ̀ wí pé kí ọba kéde òfin kan pé ẹnikẹ́ni tí ó bá gba àdúrà sí Ọlọ́run tàbí ènìyàn kankan fún ọgbọ̀n ọjọ́, yàtọ̀ fún ìwọ ọba, a ó ju ẹni náà sí inú ihò kìnnìún.
Vsi predstojniki kraljestva, voditelji in princi, svetovalci in poveljniki, smo se skupaj posvetovali, da bi osnovali kraljevo pravilo in da bi naredili trden odlok, da kdorkoli bi prosil prošnjo od kateregakoli Boga ali človeka v tridesetih dneh, razen od tebe, oh kralj, bo vržen v levji brlog.
8 Nísinsin yìí, ìwọ ọba, gbé òfin yìí jáde, kí o sì kọ ọ́ sínú ìwé kí a má ba à yí i padà ní ìbámu pẹ̀lú òfin àwọn Media àti Persia, èyí tí kò ní le è parẹ́.”
Torej, oh kralj, uveljavi odlok in podpiši pisanje, da to ne more biti spremenjeno, glede na postavo Medijcev in Perzijcev, ki se ne predrugači.«
9 Nígbà náà, ni Dariusi ọba fi ọwọ́ sí ìwé àṣẹ náà.
Zatorej je kralj Darej podpisal pisanje in odlok.
10 Lóòótọ́, Daniẹli mọ̀ pé a ti fi ọwọ́ sí ìwé òfin náà, síbẹ̀ ó wọ ilé e rẹ̀ lọ, nínú yàrá òkè, ó ṣí fèrèsé èyí tí ó kọjú sí Jerusalẹmu sílẹ̀. Ó kúnlẹ̀ lórí orúnkún un rẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lójoojúmọ́, ó gbàdúrà, ó fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ̀ tẹ́lẹ̀.
Torej ko je Daniel izvedel, da je bilo pisanje podpisano, je odšel v svojo hišo. Pri svojih oknih v svoji sobi, odprtih proti Jeruzalemu, je trikrat na dan pokleknil na svoja kolena in molil ter se zahvaljeval pred svojim Bogom, kot je to delal poprej.
11 Nígbà náà ni, àwọn ọlọ̀tẹ̀ yìí kó ara wọn jọ, wọ́n sì rí Daniẹli tí ó ń gba àdúrà, ó sì ń bẹ̀bẹ̀ fún àánú lọ́dọ̀ Ọlọ́run.
Potem so se ti možje zbrali in našli Daniela, kako moli in dela ponižne prošnje pred svojim Bogom.
12 Wọ́n lọ sí iwájú ọba, wọ́n sì rán ọba létí nípa òfin tí ó ṣe pé, “Ìwọ kò ha fi ọwọ́ sí òfin wí pé ní ìwọ̀n ọgbọ̀n ọjọ́ ẹnikẹ́ni tí ó bá gba àdúrà sí Ọlọ́run tàbí ènìyàn, láì bá ṣe ìwọ ọba, a ó gbé e jù sínú ihò kìnnìún?” Ọba sì dáhùn pé, “Àṣẹ náà dúró síbẹ̀, ní ìbámu pẹ̀lú òfin àwọn ará Media àti Persia, èyí tí a kò le è parẹ́.”
Potem so prišli blizu in pred kraljem spregovorili glede kraljevega odloka: »Mar nisi podpisal odloka, da katerikoli človek, ki bo prosil prošnjo od kateregakoli Boga ali človeka, znotraj tridesetih dni, razen od tebe, oh kralj, bo vržen v levji brlog?« Kralj je odgovoril in rekel: »Stvar je resnična glede na postavo Medijcev in Perzijcev, ki se ne predrugači.«
13 Nígbà náà, ni wọ́n sọ fún ọba pé, “Daniẹli, ọ̀kan lára ìgbèkùn Juda, kò ka ìwọ ọba sí, tàbí àṣẹ ẹ̀ rẹ tí o fi ọwọ́ sí. Òun sì tún ń gba àdúrà ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lójúmọ́.”
Potem so odgovorili in pred kraljem rekli: »Tisti Daniel, ki je od otrok Judovega ujetništva, te ne upošteva, oh kralj niti odloka, ki si ga podpisal, temveč trikrat na dan opravlja svojo prošnjo.«
14 Nígbà tí ọba gbọ́ èyí, inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi; ó pinnu láti kó Daniẹli yọ, títí oòrùn fi rọ̀, ó sa gbogbo ipá a rẹ̀ láti gba Daniẹli sílẹ̀.
Potem je bil kralj, ko je slišal te besede, sam pri sebi boleče nejevoljen in je svoje srce naravnal na Daniela, da ga osvobodi, in do sončnega zahoda se je trudil, da ga osvobodi.
15 Nígbà náà, ni àwọn ọlọ̀tẹ̀ wọ̀nyí kó ara wọn jọ wá sí ọ̀dọ̀ ọba, wọ́n sì wí fún un pé, “Ìwọ ọba rántí pé, ní ìbámu pẹ̀lú òfin àwọn Media àti Persia kò sí àṣẹ tàbí ìkéde tí ọba ṣe tí a le è yí i padà.”
Potem so se tisti možje zbrali h kralju in kralju rekli: »Vedi, oh kralj, da je postava Medijcev in Perzijcev: ›Da noben odlok niti nobeno pravilo, ki ga je osnoval kralj, ne more biti spremenjeno.‹«
16 Nígbà náà, ni ọba pàṣẹ, wọ́n sì mú Daniẹli, wọ́n sì sọ ọ́ sínú ihò kìnnìún. Ọba sì sọ fún Daniẹli pé, “Kí Ọlọ́run rẹ tí ìwọ ń sìn nígbà gbogbo kí ó gbà ọ́!”
Potem je kralj ukazal in privedli so Daniela ter ga vrgli v levji brlog. Kralj je torej spregovoril in Danielu rekel: »Tvoj Bog, ki mu nenehno služiš, on te bo osvobodil.«
17 A sì gbé òkúta kan wá, wọ́n sì fi dí ẹnu ihò náà, ọba sì dì í pa pẹ̀lú òrùka èdìdì rẹ̀ àti pẹ̀lú òrùka àwọn ọlọ́lá rẹ̀, nítorí kí a má ṣe yí ohunkóhun padà nítorí i Daniẹli.
Prinesen je bil kamen in položen na odprtino brloga in kralj ga je zapečatil s svojim lastnim pečatom in s pečati svojih gospodov, da se namen glede Daniela ne bi mogel spremeniti.
18 Nígbà náà ni ọba padà sí ààfin rẹ̀, ó sì lo gbogbo òru náà láì jẹun, kò sì gbọ́ orin kankan, bẹ́ẹ̀ ni kò sì le è sùn ní òru ọjọ́ náà.
Potem je kralj odšel v svojo palačo in noč prebil v postu niti predenj niso bili prineseni glasbeni instrumenti in njegovo spanje je odšlo od njega.
19 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù, ni ọba dìde ó sì sáré lọ sí ibi ihò kìnnìún náà.
Potem je kralj zelo zgodaj zjutraj vstal in v naglici odšel k levjemu brlogu.
20 Nígbà tí ó súnmọ́ ibi ihò náà ní ibi tí Daniẹli wà, ó pe Daniẹli pẹ̀lú ìtara pé, “Daniẹli, ìránṣẹ́ Ọlọ́run alààyè, ṣé Ọlọ́run rẹ tí ìwọ ń sìn tọ̀sán tòru, lè gbà ọ́ lọ́wọ́ kìnnìún bí?”
Ko je prišel k brlogu, je z žalostnim glasom zaklical k Danielu, in kralj je spregovoril ter Danielu rekel: »Oh Daniel, služabnik živega Boga, ali te je tvoj Bog, ki mu nenehno služiš, mogel osvoboditi pred levi?«
21 Daniẹli sì dáhùn wí pé, “Ọba kí ẹ pẹ́!
Potem je Daniel rekel kralju: »Oh kralj, živi na veke.
22 Ọlọ́run mi rán angẹli i rẹ̀, ó sì dí àwọn kìnnìún lẹ́nu. Wọn kò le è pa mí lára, nítorí a rí mi gẹ́gẹ́ bí aláìlẹ́ṣẹ̀ ní iwájú rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò hu ìwà ìbàjẹ́ kan níwájú rẹ ìwọ ọba.”
Moj Bog je poslal svojega angela in zaprl levom usta, da me niso poškodovali, ker je bila v meni najdena nedolžnost pred njim in tudi pred teboj, oh kralj, nisem storil nobene škode.«
23 Inú ọba dùn gidigidi, ó sì pàṣẹ kí a mú Daniẹli jáde wá láti inú ihò. Nígbà tí a mú Daniẹli jáde nínú ihò, kò sí ojú ọgbẹ́ kan ní ara rẹ̀, nítorí tí ó gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run rẹ̀.
Potem je bil kralj zaradi njega silno vesel in zapovedal, da naj Daniela izvlečejo iz brloga. Tako je bil Daniel vzet gor iz brloga in nobena vrsta poškodbe ni bila najdena na njem, ker je veroval v svojega Boga.
24 Ọba pàṣẹ pé, kí a mú àwọn alátakò Daniẹli wá, kí a jù wọ́n sí inú ihò kìnnìún, pẹ̀lú ìyàwó àti àwọn ọmọ wọn. Kí wọn tó dé ìsàlẹ̀ ihò, kìnnìún lágbára lórí i wọn, wọ́n sì fọ́ gbogbo egungun wọn.
In kralj je zapovedal in privedli so tiste može, ki so Daniela obtožili in jih vrgli v levji brlog, njih, njihove otroke in njihove žene. Levi so imeli oblast nad njimi in vse njihove kosti so zlomili na koščke, še preden so prileteli na dno brloga.
25 Nígbà náà ni Dariusi ọba kọ̀wé sí gbogbo ènìyàn orílẹ̀-èdè, àti gbogbo jákèjádò ilẹ̀ náà: “Kí ìre yín máa pọ̀ sí i!
Potem je kralj Darej napisal vsemu ljudstvu, narodom in jezikom, ki prebivajo na vsej zemlji: »Mir naj se vam pomnoži.
26 “Mo gbé àṣẹ kan jáde wí pé, ní gbogbo agbègbè ìjọba mi, gbogbo ènìyàn gbọdọ̀ bẹ̀rù, kí wọn kí ó sì bọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run Daniẹli.
Naredim odlok: ›Da v vsakem gospostvu mojega kraljestva ljudje trepetajo in se bojijo pred Danielovim Bogom, kajti on je živi Bog in neomajen na veke in njegovo kraljestvo tisto, ki ne bo uničeno in njegovo gospostvo bo celo do konca.
27 Ó ń yọ ni, ó sì ń gbani là;
On osvobaja in rešuje, dela [preroška] znamenja in čudeže v nebesih in na zemlji, ki je Daniela osvobodil pred oblastjo levov.‹«
28 Daniẹli sì ṣe rere ní àkókò ìjọba Dariusi àti àkókò ìjọba Kirusi ti Persia.
Tako je ta Daniel uspeval v Darejevem kraljevanju in v kraljevanju Perzijca Kira.

< Daniel 6 >