< Daniel 5 >
1 Belṣassari, ọba ṣe àsè ńlá fún ẹgbẹ̀rún kan nínú àwọn ọlọ́lá rẹ̀, ó sì mu wáìnì pẹ̀lú u wọn.
Împăratul Belșațar a făcut un mare ospăț pentru o mie dintre domnii lui și a băut vin înaintea celor o mie.
2 Bí Belṣassari ṣe ń mu wáìnì, ó pàṣẹ pé kí wọn kó kọ́ọ̀bù wúrà àti ti fàdákà wá, èyí tí Nebukadnessari baba rẹ̀ kó wá láti inú tẹmpili ní Jerusalẹmu, kí ọba àti àwọn ọlọ́lá rẹ̀, àwọn ìyàwó àti àwọn àlè rẹ̀ kí ó ba à le fi mu wáìnì.
Belșațar, în timp ce gusta vinul, a poruncit să aducă vasele de aur și argint pe care tatăl său Nebucadnețar le scosese din templul din Ierusalim; pentru ca împăratul și prinții lui, soțiile lui și concubinele lui, să bea din ele.
3 Wọ́n sì kó kọ́ọ̀bù wúrà àti fàdákà àti fàdákà èyí tí wọ́n kó jáde láti inú tẹmpili, ilé Ọlọ́run ní Jerusalẹmu, ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀, àwọn ìyàwó àti àwọn àlè rẹ̀, sì fi mu wáìnì.
Atunci au adus vasele din aur care au fost scoase din templul casei lui Dumnezeu din Ierusalim; și împăratul și prinții lui, soțiile lui și concubinele lui, au băut din ele.
4 Bí wọ́n ṣe ń mu wáìnì bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń yin òrìṣà wúrà àti fàdákà, ti idẹ, irin, igi àti òkúta.
Au băut vin și au lăudat dumnezeii din aur și din argint, din aramă, din fier, din lemn și din piatră.
5 Lójijì, ìka ọwọ́ ènìyàn jáde wá, ó sì ń kọ̀wé sára ẹfun ògiri ní ẹ̀gbẹ́ ibi tí fìtílà ń dúró ní ààfin ọba. Ọba ń wo ọwọ́ náà bí ó ṣe ń kọ ọ́.
În același moment au ieșit degetele unei mâini de om și au scris în partea opusă sfeșnicului pe tencuiala peretelui din palatul împăratului; și împăratul a văzut partea mâinii care scria.
6 Ojú ọba sì yí padà, ẹ̀rù sì bà á, tó bẹ́ẹ̀ tí orúnkún ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì rẹ̀ fi ń gbá ara wọn.
Atunci înfățișarea împăratului s-a schimbat și gândurile lui l-au tulburat, astfel încât i s-au dezlegat încheieturile coapselor sale și genunchii i s-au lovit unul de altul.
7 Ọba kígbe pé, kí wọn pe àwọn awòràwọ̀, àwọn onídán, àti àwọn aláfọ̀ṣẹ wá, ọba sì sọ fún àwọn amòye Babeli pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá lè ka àkọsílẹ̀ yìí kí ó sì sọ ìtumọ̀ rẹ̀, ẹni náà ni a ó fi aṣọ elése àlùkò wọ̀ àti ẹ̀gbà wúrà ni a ó fi sí ọrùn un rẹ̀, òun ni yóò sì ṣe olórí kẹta ní ìjọba à mi.”
Împăratul a strigat cu [voce] tare să aducă astrologii, caldeenii și ghicitorii. [Și] împăratul a vorbit și a spus înțelepților Babilonului: Oricine va citi această scriere și îmi va arăta interpretarea ei, va fi îmbrăcat cu stacojiu și [va avea] un lanț din aur la gâtul lui și va fi al treilea domnitor în împărăție.
8 Nígbà náà ni gbogbo àwọn amòye ọba wọ ilé, ṣùgbọ́n, wọn kò le è ka àkọsílẹ̀ náà tàbí sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún ọba.
Atunci au intrat toți înțelepții împăratului; dar nu au putut citi scrisul, nici să facă cunoscută împăratului interpretarea lui.
9 Nígbà náà ni Belṣassari ọba bínú gidigidi, ojú u rẹ̀ sì túbọ̀ dàrú sí i. Ẹ̀rù sì ba àwọn ìjòyè Belṣassari.
Atunci împăratul Belșațar s-a tulburat mult și înfățișarea lui s-a schimbat în el și domnii lui au fost înmărmuriți.
10 Nígbà tí ayaba gbọ́ ohùn ọba àti àwọn ọlọ́lá rẹ̀, ó wá ilé àsè wá. Ó wí pé, “Kí ọba kí ó pẹ́! Má ṣe jẹ́ kí inú rẹ bàjẹ́, má sì ṣe jẹ́ kí ojú u rẹ fàro.
[Și] împărăteasa, din cauza cuvintelor împăratului și a domnilor lui, a venit în casa banchetului [și] împărăteasa a vorbit și a spus: Împărate, să trăiești veșnic; să nu te tulbure gândurile tale, nici nu lăsa înfățișarea ta să fie schimbată;
11 Ọkùnrin kan wà ní ìjọba à rẹ, ẹni tí ẹ̀mí ọlọ́run mímọ́ ń gbé inú rẹ̀. Ní ìgbà ayé e baba à rẹ, òun ni ó ní ojú inú, òye àti ìmọ̀ bí i ti ọlọ́run òun ni ọba Nebukadnessari, baba rẹ̀ fi jẹ olórí àwọn apidán, awòràwọ̀, apògèdè àti aláfọ̀ṣẹ.
Este un om în împărăția ta, în care [este] duhul dumnezeilor sfinți; și în zilele tatălui tău lumină și înțelegere și înțelepciune, ca înțelepciunea dumnezeilor, s-a găsit în el; pe el împăratul Nebucadnețar tatăl tău, împăratul, [spun eu], tatăl tău l-a făcut stăpân al magilor, astrologilor, caldeenilor [și] ghicitorilor;
12 Ọkùnrin náà ni Daniẹli ẹni tí ọba ń pè ní Belṣassari, ó ní ẹ̀mí tí ó tayọ, ìmọ̀ àti òye, àti agbára láti túmọ̀ àlá, ó máa ń ṣe àlàyé àlá àti àwọn ọ̀rọ̀ tí ó bá da ojú rú, ránṣẹ́ pè é, yóò sì sọ nǹkan tí àkọsílẹ̀ ìwé náà túmọ̀ sí.”
Căci un duh ales și cunoaștere și înțelegere, interpretare de vise și arătare de vorbe grele și dezlegarea îndoielilor, s-au găsit în acest Daniel, pe care împăratul l-a numit Belteșațar; acum să fie chemat Daniel, iar el va arăta interpretarea.
13 Nígbà náà ni a mú Daniẹli wá síwájú ọba, ọba sì sọ fún un wí pé, “Ṣé ìwọ ni Daniẹli, ọ̀kan lára àwọn tí baba mi mú ní ìgbèkùn láti Juda!
Atunci Daniel a fost adus înaintea împăratului. [Și] împăratul a vorbit și i-a spus lui Daniel: [Ești] tu acel Daniel, care [ești] dintre copiii captivității lui Iuda, pe care împăratul, tatăl meu, i-a scos din Iudeea?
14 Mo ti gbọ́ wí pé ẹ̀mí ọlọ́run ń gbé inú rẹ àti wí pé ìwọ ní ojú inú, òye, àti ọgbọ́n tí ó tayọ.
Și am auzit despre tine, că duhul dumnezeilor [este] în tine și [că] lumină și înțelegere și aleasă înțelepciune se găsește în tine.
15 A ti mú àwọn amòye àti àwọn awòràwọ̀ wá sí iwájú mí kí wọn ba à le è wá ka àkọsílẹ̀ yìí kí wọn sì sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n wọn kò le è sọ ìtumọ̀ ohun tí ó jẹ́.
Și acum înțelepții, astrologii, au fost aduși înaintea mea, ca să citească această scriere și să îmi facă cunoscută interpretarea ei; dar nu au putut să arate interpretarea lucrului;
16 Ṣùgbọ́n mo ti gbọ́ wí pé, ìwọ lè sọ ìtumọ̀, àti wí pé o lè yanjú àwọn ìṣòro tó lágbára. Tí o bá lè ka àkọsílẹ̀ ìwé yìí kí o sì sọ ìtumọ̀ rẹ̀, a ó fi aṣọ elése àlùkò wọ̀ ọ́ pẹ̀lú ẹ̀gbà wúrà ni a ó fi sí ọ lọ́rùn, a ó sì fi ọ́ ṣe olórí kẹta ní ìjọba mi.”
Și am auzit despre tine, că poți face interpretări și să dezlegi îndoieli; acum dacă poți să citești scrisul și să îmi faci cunoscută interpretarea lui, vei fi îmbrăcat în stacojiu și vei avea un lanț din aur la gâtul tău și vei fi al treilea domnitor în împărăție.
17 Nígbà náà ni Daniẹli dá ọba lóhùn wí pé, “Fi ẹ̀bùn rẹ pamọ́ fún ara rẹ, tàbí kí o fún ẹlòmíràn. Síbẹ̀ èmi yóò ka àkọsílẹ̀ náà fún ọba, èmi yóò sì sọ ìtumọ̀ rẹ̀.
Atunci Daniel a răspuns și a zis înaintea împăratului: Să îți rămână ție darurile și dă răsplățile tale altuia; totuși voi citi scrierea împăratului și îi voi face cunoscută interpretarea.
18 “Ìwọ ọba, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo fún Nebukadnessari baba rẹ ní ìjọba, títóbi ògo àti ọlá.
Împărate, Dumnezeul cel preaînalt i-a dat lui Nebucadnețar tatăl tău o împărăție și maiestate și glorie și onoare;
19 Nítorí ipò ńlá tí a fi fún un, gbogbo ènìyàn orílẹ̀-èdè àti èdè gbogbo fi ń páyà tí wọ́n sì ń bẹ̀rù rẹ̀. Ó ń pa àwọn tí ó bá wù ú, ó sì ń dá àwọn tí ó bá wù ú sí, ó ń gbé àwọn tí ó bá wù ú ga, ó sì ń rẹ àwọn tí ó bá wù ú sílẹ̀.
Și pentru maiestatea pe care i-a dat-o, toate popoarele, națiunile și limbile, au tremurat și s-au temut înaintea lui; pe cine voia, ucidea; și pe cine voia, ținea în viață; și pe cine voia, înălța; și pe cine voia, umilea.
20 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn rẹ̀ ga, tí ó sì le koko. Ó bẹ̀rẹ̀ sí i hùwà ìgbéraga, a mú u kúrò lórí ìtẹ́ ọba rẹ̀, a sì gba ògo rẹ̀ kúrò.
Dar când i s-a înălțat inima și i s-a împietrit mintea în mândrie, a fost deposedat de tronul lui împărătesc și i-au luat gloria;
21 A lé e kúrò láàrín ènìyàn, a sì fún un ní ọkàn ẹranko; ó sì ń gbé pẹ̀lú àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì ń jẹ koríko bí i ti màlúù; ìrì ọ̀run ṣì sẹ̀ sí ara rẹ̀, títí tó fi mọ̀ pé, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo ń jẹ ọba lórí ìjọba ọmọ ènìyàn, òun sì ń fi fún ẹni tí ó bá wù ú.
Și a fost alungat dintre fiii oamenilor; și inima lui a fost făcută ca a fiarelor și locuința lui [a fost] cu măgarii sălbatici; l-au hrănit cu iarbă ca pe boi și trupul i-a fost udat cu roua cerului; până când a cunoscut că Dumnezeul cel preaînalt a domnit în împărăția oamenilor și [că] rânduiește peste ea pe oricine voiește.
22 “Ṣùgbọ́n ìwọ ọmọ rẹ̀, Belṣassari, ìwọ kò rẹ ara à rẹ sílẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ mọ nǹkan wọ̀nyí.
Și tu, Belșațar, fiul lui, nu ți-ai umilit inima, cu toate că ai cunoscut toate acestea;
23 Dípò èyí, ìwọ gbé ara à rẹ ga sí Olúwa ọ̀run, a mú ohun èlò inú tẹmpili rẹ̀ wá sí iwájú rẹ, ìwọ àti àwọn ìjòyè rẹ, àwọn ìyàwó ò rẹ àti àwọn àlè rẹ fi ń mu wáìnì. Ìwọ ń yin àwọn òrìṣà fàdákà àti wúrà, idẹ, irin, igi àti ti òkúta, èyí tí kò lè ríran, tí kò le è gbọ́rọ̀ tàbí ní òye nǹkan kan. Ṣùgbọ́n ìwọ kò bu ọlá fún Ọlọ́run ẹni tó ni ẹ̀mí rẹ lọ́wọ́, tí ó sì mọ gbogbo ọ̀nà rẹ.
Ci te-ai ridicat împotriva Domnului cerului; iar ei au adus vasele casei lui înaintea ta și tu și domnii tăi, soțiile tale și concubinele tale, ați băut vin din ele; și ai lăudat dumnezeii din argint și aur, din aramă, fier, lemn și piatră, care nu văd, nici nu aud, nici nu cunosc; și pe Dumnezeul în a cărui mână [este] suflarea ta și ale căruia [sunt] toate căile tale, tu, nu l-ai glorificat;
24 Nítorí náà, ó rán ọwọ́ tí ó kọ àkọlé yìí.
Atunci a fost trimisă partea de mână de la el; și această scriere a fost scrisă.
25 “Èyí ni àkọlé náà tí a kọ: Mene, mene, tekeli, peresini.
Și aceasta [este] scrierea care a fost scrisă, MENE, MENE, TEKEL, UFARSIN.
26 “Èyí ni nǹkan tí ọ̀rọ̀ náà túmọ̀ sí: “Mene: Ọlọ́run ti ṣírò ọjọ́ ìjọba rẹ. Ó sì ti mú u wá sí òpin.
Aceasta [este] interpretarea lucrului: MENE: Dumnezeu a numărat împărăția ta și a sfârșit-o.
27 “Tekeli: A ti gbé ọ lórí òsùwọ̀n, ìwọ kò sì tó ìwọ̀n.
TEKEL: Ești cântărit în balanțe și ești în lipsă.
28 “Peresini: A ti pín ìjọba rẹ a sì ti fi fún àwọn Media àti àwọn Persia.”
PERES: Împărăția ta este divizată și dată mezilor și perșilor.
29 Nígbà náà ni Belṣassari pàṣẹ pé kí a wọ Daniẹli ní aṣọ elése àlùkò, kí a sì fi ẹ̀gbà wúrà sí i lọ́rùn, a sì kéde rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí kẹta ní ìjọba rẹ̀.
Atunci Belșațar a poruncit și l-au îmbrăcat pe Daniel în stacojiu și [au pus] un lanț din aur la gâtul său și au făcut o proclamație referitoare la el, ca el să fie al treilea domnitor în împărăție.
30 Ní alẹ́ ọjọ́ náà ni a pa Belṣassari, ọba àwọn ara Kaldea.
În acea noapte a fost ucis Belșațar, împăratul caldeenilor.
31 Dariusi ará Media sì gba ìjọba nígbà tí ó di ọmọ ọdún méjìlélọ́gọ́ta.
Și Darius, medul, a luat împărăția, [fiind] aproape de șaizeci și doi de ani.