< Daniel 4 >

1 Nebukadnessari ọba, sí gbogbo ènìyàn, orílẹ̀ àti onírúurú èdè, tí ó ń gbé ní àgbáyé. Kí àlàáfíà máa pọ̀ sí i fún un yín. Kí ẹ ṣe rere tó pọ̀!
O NEBUKANEZA ke alii, i na kanaka a pau, a me na lahuikanaka, a me na olelo e, e noho ana ma ka honua a pau: E hoomahuahuaia ana ko oukou maluhia.
2 Ó jẹ́ ìdùnnú fún mi láti fi iṣẹ́ àmì àti ìyanu tí Ọlọ́run Ọ̀gá-Ògo ti ṣe fún mi hàn.
He mea pono i ko'u manao ke hoakaka aku i na hoailona, a me na hana mana a ke Akua kiekie i hana mai ai ia'u.
3 Báwo ni àmì rẹ̀ ti tóbi tó,
He manomano kona mau hoailona, a he kupaianaha hoi kana mau hana mana! O kona aupuni, he aupuni mau loa ia, a o kona alii ana, mai ia hanauna aku ia, a ia hanauna aku.
4 Èmi Nebukadnessari wà ní ààfin mi, pẹ̀lú ìtẹ́lọ́rùn àti àlàáfíà.
Owau, o Nebukaneza, ua noho maluhia au iloko o ko'u hale, a pomaikai no au ma kuu halealii;
5 Mo lá àlá kan èyí tí ó bà mí lẹ́rù. Nígbà tí mo wà lórí ibùsùn mi, ìran tí ó jáde lọ́kàn mi dẹ́rùbà mí.
Ua moe uhane au i ka moe, o ka'u mea ia i weliweli ai, a o na manao maluna o ko'u wahi moe a me ka lia ana o ko'u poo, o ka'u mau mea ia e pihoihoi ai.
6 Nígbà náà, ni mo pàṣẹ pé kí a mú gbogbo àwọn amòye Babeli wá, kí wọn wá sọ ìtumọ̀ àlá náà fún mi.
No ia mea, kauoha aku la au e alakaiia mai imua o'u ka poe naauao a pau o Babulona, i hoakaka mai lakou ia'u i ke ano o ka'u moe.
7 Nígbà tí àwọn apidán, àwọn apògèdè, àwọn awòràwọ̀ àti àwọn aláfọ̀ṣẹ wá, mo sọ àlá náà fún wọn, ṣùgbọ́n wọn kò le è sọ ìtumọ̀ àlá náà fún mi.
A hele mai no ka poe magoi, a me ka poe hoopiopio, a me ka poe Kaledea, a me ka poe kilokilo, a hoike aku au ia lakou i ka moe; aole i hiki ia lakou ke hai mai i kona mea hoike.
8 Ní ìkẹyìn Daniẹli wá síwájú mi, mo sì sọ àlá náà fún. (Ẹni tí à ń pè ní Belṣassari gẹ́gẹ́ bí orúkọ òrìṣà mi àti pé ẹ̀mí àwọn ọlọ́run mímọ́ wà nínú rẹ̀.)
Mahope iho, hele mai imua o'u o Dauiela, ka mea i kapaia o Beletesaza mamuli o ka inoa o ko'u akua, no ka mea, aia iloko ona ka uhane o na akua hemolele; a hai aku au ia ia i ka'u moe;
9 Mo wí pé, “Belṣassari, olórí àwọn amòye, èmi mọ̀ wí pé ẹ̀mí ọlọ́run mímọ́ wà nínú rẹ, kò sì ṣí àṣírí kan tí ó ṣòro jù fún ọ. Sọ àlá mi kí o sì túmọ̀ rẹ̀ fún mi.
E Beletesaza, e ka luna o na magoi, no ka mea, ua ike au aia iloko ou ka uhane o na akua hemolele, aole ou wahi hemahema ma ka mea i ike ole ia, e hai mai oe i ka moe a'u i ike ai a me kona ano.
10 Èyí ni ìran náà tí mo rí nígbà tí mo wà lórí ibùsùn mi, mo rí igi kan láàrín ayé, igi náà ga gidigidi.
Penei ka lia ana a ko'u poo maluna o ko'u wahi moe: aia hoi, ua ike au, he laau iwaenakonu o ka honua, a o kona kiekie, ua oi nui loa aku ia.
11 Igi náà tóbi, ó sì lágbára, orí rẹ̀ sì ń kan ọ̀run; a sì rí i títí dé òpin ayé.
Ulu ae la ua laau la a nui; o kona kiekie ua hiki aku ia i ka lani, a ua ike hoi ia ma na kihi a pau o ka honua.
12 Ewé rẹ̀ lẹ́wà, èso rẹ̀ sì pọ̀, ó sì ń pèsè oúnjẹ fún gbogbo ènìyàn. Abẹ́ ẹ rẹ̀ ni àwọn ẹranko igbó fi ṣe ibùgbé, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ń gbé ní ẹ̀ka rẹ̀, nínú rẹ̀ ni gbogbo alààyè ti ń jẹ.
O na lau ona ua maikai ia, a he nui no hoi kona hua, aia hoi maloko ona he ai na na mea a pau; ua hoomaluia na holoholona o ke kula malalo iho ona, ua kau mai hoi na manu o ka lewa maluna o kona mau lala, a ua hanaiia na mea io a pau i ko ua laau la.
13 “Lórí ibùsùn mi, mo rí ìran náà, olùṣọ́ kan dúró síwájú u mi, àní ẹni mímọ́ kan, ó ń bọ̀ wá láti ọ̀run
Ua ike au ma ka lia ana o kuu poo maluna iho o ko'u wahi moe, aia hoi, he mea kiai a he mea hemolele e iho mai ana mai ka lani mai:
14 ó kígbe sókè wí pé, ‘Gé igi náà kí o sì gé àwọn ẹ̀ka rẹ̀ kúrò; gbọn ewé rẹ̀ ká, kí o sì fọ́n èso rẹ̀ dànù. Jẹ́ kí àwọn ẹranko tí ó wà lábẹ́ rẹ̀ sá àti àwọn ẹyẹ tí ó wà ní ẹ̀ka rẹ̀ kúrò.
Kahea mai la oia me ka leo nui, a penei hoi kana olelo ana, E kua aku i ka laau, a e okioki i kona mau lala, e lulu aku i kona lau, a e hoohelelei hoi i kona hua; e haalele na holoholona i kona malu, a me na manu hoi i kona mau lala.
15 Ṣùgbọ́n fi kùkùté àti gbòǹgbò rẹ̀ tí a fi irin àti idẹ dè ṣẹ́kù sórí ilẹ̀ àti sí orí koríko igbó. “‘Jẹ́ kí ìrì ọ̀run sẹ̀ sí i lára, kí ó sì jẹ́ kí ìpín in rẹ̀ wà pẹ̀lú àwọn ẹranko igbó láàrín ilẹ̀ ayé.
Aka, e waiho i ke kumu okona aa ma ka lepo, me ke apo hao, a me ke keleawe, mawaena o na mea uliuli o ke kula; a e hoopuluia oia i ka hau o ka lani, o kona kuleana aia no ia me na holoholona ma ka mauu o ka honua.
16 Jẹ́ kí ọkàn rẹ̀ kí ó yí padà kúrò ní ti ènìyàn, kí a sì fún un ní ọkàn ẹranko, títí ìgbà méje yóò fi kọjá lórí i rẹ̀.
E hooliloia kona naau kanaka, a e haawiia ia ia ka naau holoholona; a hala ae na manawa ehiku maluna ona.
17 “‘Olùṣọ́ ni ó gbé ìpinnu náà jáde, àṣẹ sì wá láti ọ̀dọ̀ ẹni mímọ́, kí gbogbo alààyè le mọ̀ wí pé, Ọ̀gá-ògo ni olórí ìjọba ènìyàn, ó sì ń fi fún ẹnikẹ́ni tí ó wù ú, òun sì ń gbé onírẹ̀lẹ̀ lórí i wọn.’
O ka manao paa keia o na mea kiai, a o ke kauoha hoi a na mea hemolele; i ike ai ka poe e ola ana aia maluna o ke aupuni kanaka ka Mea kiekie e alii ana a haawi aku no oia ia mea na ka mea ana e makemake ai, a hoonoho maluna iho i na kanaka lalo loa.
18 “Èyí ni àlá tí èmi Nebukadnessari ọba lá. Ní ìsinsin yìí ìwọ Belṣassari, sọ ohun tí ó túmọ̀ sí fún mi, nítorí kò sí amòye kan ní ìjọba mi, tí ó lè sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi. Ṣùgbọ́n ìwọ lè sọ ìtumọ̀ rẹ̀, nítorí tí ẹ̀mí Ọlọ́run mímọ́ wà ní inú rẹ.”
Eia ka moe a'u a ke alii a Ne bukaneza i ike ai: ano e Beletesa za, e hai mai oe ia'u i ka hoike; no ka mea, aole e hiki i ka poe naauao a pau o ko'u aupuni ke hoakaka mai i ka hoike: aka, e hiki no ia oe, no ka mea, aia iloko ou ka uhane o na akua hemolele.
19 Nígbà náà ni Daniẹli (ẹni tí à ń pè ní Belṣassari) páyà gidigidi fún ìgbà díẹ̀, èrò inú rẹ̀ sì bà á lẹ́rù. Nígbà náà ni ọba wí pé, “Belṣassari, má ṣe jẹ́ kí àlá náà tàbí ìtumọ̀ rẹ̀ kí ó dẹ́rùbà ọ́.” Belṣassari sì dáhùn wí pé, “Olúwa mi, kí àlá yìí jẹ́ ti àwọn ọ̀tá a rẹ, kí ìtumọ̀ rẹ̀ sì jẹ́ ti àwọn aṣòdì sí.
Alaila pilipu iho la o Daniela i kapaia o Beletesaza i hookahi hora, a pono ole kona manao. Ekemu mai la ke alii, i mai, E Beletesaza, mai pilipu kou manao no ka moe, a me kona ano. I aku la o Beletesaza, E ko'u haku, i ka poe i hoino mai ia oe keia moe, a o ka hoohalike ana i kou poe enemi no ia.
20 Igi tí ìwọ rí, tí ó dàgbà, tí ó sì lágbára, tí orí rẹ̀ sì ń kan ọ̀run, tí ó lẹ́wà àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ èso, tí ó ń pèsè oúnjẹ fún gbogbo ènìyàn, tí ó ṣe ààbò lórí ẹranko igbó àti èyí tí ẹ̀ka rẹ̀ pèsè ààyè fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
O ka laau au i ike ai, he nui. a he ikaika, o kona kiekie i hiki aku i ka lani, a ua ikeia hoi ia e ko ka honua a pau;
21 Èyí tí ewé e rẹ̀ lẹ́wà, tí èso rẹ̀ si pọ̀, nínú èyí tí oúnjẹ sì wà fún gbogbo ẹ̀dá, lábẹ́ èyí tí àwọn ẹranko igbó ń gbé, lórí ẹ̀ka èyí ti àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ní ibùgbé wọn.
O na lau ona he maikai, a nui kona hua, a maloko ona he ai na na mea a pau; a i hoomaluhia ai na holoholona o ke kula malalo iho ona, a maluna o kona mau lala i kau ai na manu o ka lewa:
22 Ìwọ ọba ni igi náà, ìwọ ti dàgbà, o sì lágbára, títóbi i rẹ ga ó sì kan ọ̀run, ìjọba rẹ sì gbilẹ̀ títí dé òpin ayé.
O oe no ia, e ke alii, ua mahuahua oe a lilo i mea ikaika; no ka mea, ua mahuahua kou nui a hiki i ka lani, a o kou alii ana i ka welau o ka honua.
23 “Ìwọ ọba, rí ìránṣẹ́ ẹni mímọ́ kan, tí ó ń bọ̀ láti ọ̀run ó sì sọ pé, ‘Gé igi náà kí o sì run ún, ṣùgbọ́n fi kùkùté rẹ tí a dè pẹ̀lú irin àti idẹ sílẹ̀ nínú koríko igbó, nígbà tí gbòǹgbò rẹ̀ sì wà nínú ilẹ̀ kí o sì jẹ́ kí ìrì ọ̀run sẹ̀ sórí i rẹ̀, jẹ́ kí ìpín in rẹ̀ wà láàrín ẹranko búburú títí ìgbà méje yóò fi kọjá lórí i rẹ̀.’
A o kau ike ana, e ke alii, i ka mea kiai, he mea hemolele e iho mai ana, mai ka lani mai, e olelo ana, E kua aku i ka laau, a e hoopau ia ia; aka, e waiho i ke kumu o kona aa ma ka lepo, me ke apo hao a me ke keleawe, mawaena o na mea uliuli o ke kula; a e hoopuluia i ka hau o ka lani, o kona kuleana aia no ia me na holoholona o ke kula, a hala aku na manawa ehiku maluna iho ona;
24 “Èyí ni ìtumọ̀ àlá rẹ ọba àti àṣẹ tí Ọ̀gá-ògo mú wá sórí ọba olúwa mi.
Eia ka hoike ana, e ke alii e, a eia hoi ka manao paa o ka Mea kiekie, ka mea e kau mai ana maluna o kuu haku ke alii:
25 A ó lé ọ jáde kúrò láàrín ènìyàn, ìwọ yóò sì máa gbé láàrín ẹranko búburú, ìwọ yóò jẹ koríko bí i màlúù, ìrì ọ̀run yóò sì sẹ̀ sára rẹ. Ìgbà méje yóò sì kọjá lórí rẹ, títí ìwọ yóò fi mọ̀ wí pé Ọ̀gá-ògo ń jẹ ọba lórí ìjọba ènìyàn, ó sì ń fi fún ẹni tí ó bá wù ú.
E kipaku lakou ia oe mai na kanaka aku, a o kou wahi e noho ai aia no ia me na holoholona o ke kula, a e ai iho oe i ka weuweu e like me na bipi kauo, a e hoopuluia no hoi oe i ka hau o ka lani, a ha la na manawa ehiku maluna ou, a ike oe e alii ana ka Mea kiekie maluna o ke aupuni kanaka, a haawi aku no oia ia mea i kana mea e manao ai.
26 Bí wọ́n ṣe pàṣẹ pé kí wọn fi kùkùté àti gbòǹgbò igi náà sílẹ̀, èyí túmọ̀ sí wí pé a ó dá ìjọba rẹ padà fún ọ lẹ́yìn ìgbà tí o bá ti mọ̀ wí pé, Ọ̀run jẹ ọba.
A e like me ka mea i oleloia, e waihoia ke kumu o na aa o ua laau la; eia, a ike oe no na lani mai ke alii ana, alaila e paa ai ia oe kou aupuni.
27 Nítorí náà ọba, jẹ́ kí ìmọ̀ràn mi jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún ọ, kọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ sílẹ̀ kí o sì ṣe rere, àti ìwà búburú rẹ nípa ṣíṣe àánú fún àwọn tálákà. Ó lè jẹ́ pé nígbà náà ni ìwọ yóò ṣe rere.”
No ia mea, e ke alii e, e haliu oluolu mai oe i ko'u manao, a e huli oe mai kou hewa mai i ka pono, a mai kou lawehala ana i ka manawalea aku i ka poe hune; pela paha e hooloihiia mai ai kou manawa pono.
28 Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ṣẹlẹ̀ sí Nebukadnessari ọba.
A kau mai no keia mau mea a pau maluna o Nebukaneza ke alii.
29 Lẹ́yìn oṣù kejìlá, bí ọba ṣe ń rìn káàkiri lórí òrùlé ààfin ìjọba Babeli,
A pau na malama he umi kumamalua e holoholo ana no ia maluna o ka halealii o ke aupuni o Babulona;
30 ó sọ pé, “Èyí ha kọ́ ni Babeli ńlá tí mo kọ́ gẹ́gẹ́ bí ilé ọba, nípa agbára à mi àti fún ògo ọláńlá à mi?”
Olelo iho la ke alii, i iho la, Aole anei keia o Babulona nui ka mea a'u i kukulu ai i hale no ke aupuni, me ka ikaika o ko'u mana, a no ka hanohano o ko'u nani?
31 Bí ọba ṣe ń sọ ọ̀rọ̀ náà lọ́wọ́ ohùn kan wá láti ọ̀run, “Ìwọ Nebukadnessari ọba, ìwọ ni a ti pàṣẹ nípa rẹ̀, a ti gba ìjọba à rẹ kúrò ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.
Aia iloko o ko ke alii waha keia olelo, pae mai la ka leo mai ka lani mai, i mai la, E Nebukaneza, e ke alii e, ua olelo ia ia oe, Ua maalo ae ke aupuni mai ou aku.
32 A ó lé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, ìwọ yóò sì lọ máa gbé àárín àwọn ẹranko igbó; ìwọ yóò jẹ koríko bí i màlúù, ìgbà méje yóò kọjá lórí i rẹ títí ìwọ yóò fi mọ̀ wí pé, Ọ̀gá-ògo jẹ ọba lórí ìjọba ènìyàn àti pé ó ń fi fún ẹni tí ó bá wù ú.”
A e kipakuia no oe mai na kanaka aku, a o kou wahi e noho ai aia pu no ia me na holoholona o ke kula; a e hanaiia oe i ka mauu e like me na bipi kauo, a hala mai maluna ou na manawa ehiku; a ike oe o ka Mea kiekie oia ke alii ma ke aupuni o kanaka, a e haawiia no ia i kana mea e manao ai.
33 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ ni ohun tí a sọ nípa Nebukadnessari ṣẹlẹ̀ sí i. A lé e kúrò láàrín ènìyàn, ó sì ń jẹ koríko bí i màlúù, ìrì ọ̀run sì ń sẹ̀ sí ara rẹ̀, títí irun orí rẹ̀ fi gùn bí i ti ìyẹ́ ẹyẹ idì, tí èékánná rẹ̀ sì dàbí i ti ẹyẹ.
Ia hora no, ua ko ia olelo maluna o Nebukaneza: ua kipakuia oia mai na kanaka aku, na ai iho no ia i ka mauu e like me na bipi kauo, ua pulu kona kino i ka hau o ka laui, a loloa kona hulu e like me na hulu o ka aeto, a o kona mau maiuu ua like me na maiuu o na manu.
34 Ní òpin ìgbà náà, èmi, Nebukadnessari gbé ojú mi sókè sí ọ̀run, iyè mi sì sọjí. Mo fi ọpẹ́ fún Ọ̀gá-ògo; mo fi ọlá àti ògo fún ẹni tí ó wà láéláé.
I ka pau ana o ua mau la la, owau o Nebukaneza, ua leha ae au i kuu mau maka i ka lani, a hoi mai ia'u kuu ike; a hoomaikai aku au i ka Mea kiekie, hoonani aku au, a hoomana hoi i ka Mea e oia mau ana, ua mau loa kona alii ana, a o koua aupuni ia hanauna aku a ia hanauna aku.
35 Gbogbo àwọn ènìyàn ayé
A ua manaoia ko ka honua a pau he mea ole; ua hana no hoi oia e like me kona makemake mawaena o na puali o ka lani, a me ko ka honua; aole e hiki i kekahi ke hoopaa aku i kona lima, aole hoi e olelo aku ia ia, Heaha kau e hana nei?
36 Ní àkókò kan náà, iyè mi padà, ọlá àti ògo dídán mi padà tọ̀ mí wá fún ògo ìjọba mi. Àwọn ìgbìmọ̀ àti àwọn ọlọ́lá mi, wá mi rí, wọ́n sì dá mi padà sórí ìjọba mi, mo sì di alágbára ju ti ìṣáájú lọ.
Ia manawa no ua hoi mai ia'u kuu manao; a me ka hanohano o ko'u aupuni, ua hoi mai ia'u kuu nani a me kuu naauao; a launa mai ia'u kuu, poe kakaolelo, a me ko'u poe kaukaualii; ua paa hou au ma kuu aupuni, a ua hoonui hoi ia kuu hanohano.
37 Báyìí, èmi, Nebukadnessari fi ọpẹ́, mo sì gbé Ọlọ́run ga, mo sì fi ògo fún ọba ọ̀run, nítorí pé gbogbo nǹkan tí ó ṣe ló dára, gbogbo ọ̀nà rẹ̀ sì tọ́. Gbogbo àwọn tó sì ń rìn ní ìgbéraga ni ó le rẹ̀ sílẹ̀.
Ano owau o Nebukaneza ke hoonani aku nei au, ke hoolea aku hoi me ka mahalo i ke Alii o ka lani, o kana mau hana ua pau i ka oiaio, a o kona mau aoao ua pololei loa; a o ka poe e hele ana ma ka haaheo, e hiki no ia ia ke hoohaahaa iho ia lakou.

< Daniel 4 >