< Daniel 4 >

1 Nebukadnessari ọba, sí gbogbo ènìyàn, orílẹ̀ àti onírúurú èdè, tí ó ń gbé ní àgbáyé. Kí àlàáfíà máa pọ̀ sí i fún un yín. Kí ẹ ṣe rere tó pọ̀!
Nebuchadnezzar, le roi, à tous les peuples, nations et langues, qui habitent sur toute la terre: Que la paix vous soit multipliée.
2 Ó jẹ́ ìdùnnú fún mi láti fi iṣẹ́ àmì àti ìyanu tí Ọlọ́run Ọ̀gá-Ògo ti ṣe fún mi hàn.
Il m'a semblé bon de montrer les signes et les prodiges que le Dieu Très-Haut a opérés à mon égard.
3 Báwo ni àmì rẹ̀ ti tóbi tó,
Comme ses signes sont grands! Comme ses merveilles sont puissantes! Son royaume est un royaume éternel. Sa domination s'étend de génération en génération.
4 Èmi Nebukadnessari wà ní ààfin mi, pẹ̀lú ìtẹ́lọ́rùn àti àlàáfíà.
Moi, Nabuchodonosor, je me reposais dans ma maison, et je prospérais dans mon palais.
5 Mo lá àlá kan èyí tí ó bà mí lẹ́rù. Nígbà tí mo wà lórí ibùsùn mi, ìran tí ó jáde lọ́kàn mi dẹ́rùbà mí.
J'ai vu un songe qui m'a effrayé; les pensées sur mon lit et les visions de ma tête m'ont troublé.
6 Nígbà náà, ni mo pàṣẹ pé kí a mú gbogbo àwọn amòye Babeli wá, kí wọn wá sọ ìtumọ̀ àlá náà fún mi.
J'ai donc pris l'ordre de faire venir devant moi tous les sages de Babylone, afin qu'ils me fassent connaître l'interprétation du songe.
7 Nígbà tí àwọn apidán, àwọn apògèdè, àwọn awòràwọ̀ àti àwọn aláfọ̀ṣẹ wá, mo sọ àlá náà fún wọn, ṣùgbọ́n wọn kò le è sọ ìtumọ̀ àlá náà fún mi.
Alors entrèrent les magiciens, les enchanteurs, les Chaldéens et les devins; je leur racontai le rêve, mais ils ne me firent pas connaître son interprétation.
8 Ní ìkẹyìn Daniẹli wá síwájú mi, mo sì sọ àlá náà fún. (Ẹni tí à ń pè ní Belṣassari gẹ́gẹ́ bí orúkọ òrìṣà mi àti pé ẹ̀mí àwọn ọlọ́run mímọ́ wà nínú rẹ̀.)
Mais enfin entra devant moi Daniel, qui s'appelait Belteshazzar, selon le nom de mon dieu, et qui avait en lui l'esprit des dieux saints. Je racontai le rêve devant lui, en disant,
9 Mo wí pé, “Belṣassari, olórí àwọn amòye, èmi mọ̀ wí pé ẹ̀mí ọlọ́run mímọ́ wà nínú rẹ, kò sì ṣí àṣírí kan tí ó ṣòro jù fún ọ. Sọ àlá mi kí o sì túmọ̀ rẹ̀ fún mi.
« Beltschatsar, maître des magiciens, parce que je sais que l'esprit des dieux saints est en toi et qu'aucun secret ne te trouble, dis-moi les visions de mon rêve que j'ai eu, et son interprétation.
10 Èyí ni ìran náà tí mo rí nígbà tí mo wà lórí ibùsùn mi, mo rí igi kan láàrín ayé, igi náà ga gidigidi.
Voici les visions de ma tête sur mon lit: J'ai vu, et voici, un arbre au milieu de la terre, et sa hauteur était grande.
11 Igi náà tóbi, ó sì lágbára, orí rẹ̀ sì ń kan ọ̀run; a sì rí i títí dé òpin ayé.
L'arbre croissait et était fort. Sa hauteur atteignait le ciel et sa vue jusqu'à l'extrémité de toute la terre.
12 Ewé rẹ̀ lẹ́wà, èso rẹ̀ sì pọ̀, ó sì ń pèsè oúnjẹ fún gbogbo ènìyàn. Abẹ́ ẹ rẹ̀ ni àwọn ẹranko igbó fi ṣe ibùgbé, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ń gbé ní ẹ̀ka rẹ̀, nínú rẹ̀ ni gbogbo alààyè ti ń jẹ.
Son feuillage était beau, il portait beaucoup de fruits, et il y avait en lui de la nourriture pour tous. Les animaux des champs avaient de l'ombre sous lui, les oiseaux du ciel habitaient dans ses branches, et toute chair s'en nourrissait.
13 “Lórí ibùsùn mi, mo rí ìran náà, olùṣọ́ kan dúró síwájú u mi, àní ẹni mímọ́ kan, ó ń bọ̀ wá láti ọ̀run
« J'ai vu dans les visions de ma tête sur mon lit, et voici qu'un saint observateur descendit du ciel.
14 ó kígbe sókè wí pé, ‘Gé igi náà kí o sì gé àwọn ẹ̀ka rẹ̀ kúrò; gbọn ewé rẹ̀ ká, kí o sì fọ́n èso rẹ̀ dànù. Jẹ́ kí àwọn ẹranko tí ó wà lábẹ́ rẹ̀ sá àti àwọn ẹyẹ tí ó wà ní ẹ̀ka rẹ̀ kúrò.
Il cria à haute voix et dit ceci: Abattez l'arbre et coupez ses branches! Secoue ses feuilles et disperse ses fruits! Que les animaux se retirent de dessous lui et les oiseaux de ses branches.
15 Ṣùgbọ́n fi kùkùté àti gbòǹgbò rẹ̀ tí a fi irin àti idẹ dè ṣẹ́kù sórí ilẹ̀ àti sí orí koríko igbó. “‘Jẹ́ kí ìrì ọ̀run sẹ̀ sí i lára, kí ó sì jẹ́ kí ìpín in rẹ̀ wà pẹ̀lú àwọn ẹranko igbó láàrín ilẹ̀ ayé.
Mais laisse le tronc de ses racines dans la terre, avec une bande de fer et de bronze, dans l'herbe tendre des champs, et qu'il soit mouillé de la rosée du ciel. Que sa part soit avec les animaux dans l'herbe de la terre.
16 Jẹ́ kí ọkàn rẹ̀ kí ó yí padà kúrò ní ti ènìyàn, kí a sì fún un ní ọkàn ẹranko, títí ìgbà méje yóò fi kọjá lórí i rẹ̀.
Que son cœur soit changé de celui de l'homme, et qu'un cœur d'animal lui soit donné. Et que sept temps passent sur lui.
17 “‘Olùṣọ́ ni ó gbé ìpinnu náà jáde, àṣẹ sì wá láti ọ̀dọ̀ ẹni mímọ́, kí gbogbo alààyè le mọ̀ wí pé, Ọ̀gá-ògo ni olórí ìjọba ènìyàn, ó sì ń fi fún ẹnikẹ́ni tí ó wù ú, òun sì ń gbé onírẹ̀lẹ̀ lórí i wọn.’
"'La sentence est prononcée par le décret des veilleurs et la demande par la parole des saints, afin que les vivants sachent que le Très-Haut règne sur le royaume des hommes, qu'il le donne à qui il veut et qu'il y établit le plus humble des hommes.''
18 “Èyí ni àlá tí èmi Nebukadnessari ọba lá. Ní ìsinsin yìí ìwọ Belṣassari, sọ ohun tí ó túmọ̀ sí fún mi, nítorí kò sí amòye kan ní ìjọba mi, tí ó lè sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi. Ṣùgbọ́n ìwọ lè sọ ìtumọ̀ rẹ̀, nítorí tí ẹ̀mí Ọlọ́run mímọ́ wà ní inú rẹ.”
« Moi, roi Nabuchodonosor, j'ai vu ce rêve; et toi, Belteshatsar, tu en donnes l'interprétation, car tous les sages de mon royaume ne sont pas capables de m'en donner l'interprétation; mais toi, tu le peux, car l'esprit des dieux saints est en toi. »
19 Nígbà náà ni Daniẹli (ẹni tí à ń pè ní Belṣassari) páyà gidigidi fún ìgbà díẹ̀, èrò inú rẹ̀ sì bà á lẹ́rù. Nígbà náà ni ọba wí pé, “Belṣassari, má ṣe jẹ́ kí àlá náà tàbí ìtumọ̀ rẹ̀ kí ó dẹ́rùbà ọ́.” Belṣassari sì dáhùn wí pé, “Olúwa mi, kí àlá yìí jẹ́ ti àwọn ọ̀tá a rẹ, kí ìtumọ̀ rẹ̀ sì jẹ́ ti àwọn aṣòdì sí.
Alors Daniel, dont le nom était Belteshazzar, fut frappé de mutisme pendant quelque temps, et ses pensées le troublaient. Le roi lui répondit: « Belteshazzar, ne te laisse pas troubler par le rêve ou l'interprétation. » Beltschatsar répondit: « Mon seigneur, que le songe soit pour ceux qui te haïssent, et son interprétation pour tes adversaires.
20 Igi tí ìwọ rí, tí ó dàgbà, tí ó sì lágbára, tí orí rẹ̀ sì ń kan ọ̀run, tí ó lẹ́wà àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ èso, tí ó ń pèsè oúnjẹ fún gbogbo ènìyàn, tí ó ṣe ààbò lórí ẹranko igbó àti èyí tí ẹ̀ka rẹ̀ pèsè ààyè fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
L'arbre que tu as vu, qui croissait et se fortifiait, dont la hauteur atteignait le ciel et la vue toute la terre,
21 Èyí tí ewé e rẹ̀ lẹ́wà, tí èso rẹ̀ si pọ̀, nínú èyí tí oúnjẹ sì wà fún gbogbo ẹ̀dá, lábẹ́ èyí tí àwọn ẹranko igbó ń gbé, lórí ẹ̀ka èyí ti àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ní ibùgbé wọn.
dont le feuillage était beau et les fruits abondants, et dans lequel il y avait de la nourriture pour tous, sous lequel vivaient les animaux des champs et sur les branches duquel avaient leur demeure les oiseaux du ciel,
22 Ìwọ ọba ni igi náà, ìwọ ti dàgbà, o sì lágbára, títóbi i rẹ ga ó sì kan ọ̀run, ìjọba rẹ sì gbilẹ̀ títí dé òpin ayé.
c'est toi, ô roi, qui as grandi et qui t'es fortifié, car ta grandeur s'est accrue et atteint le ciel, et ta domination l'extrémité de la terre.
23 “Ìwọ ọba, rí ìránṣẹ́ ẹni mímọ́ kan, tí ó ń bọ̀ láti ọ̀run ó sì sọ pé, ‘Gé igi náà kí o sì run ún, ṣùgbọ́n fi kùkùté rẹ tí a dè pẹ̀lú irin àti idẹ sílẹ̀ nínú koríko igbó, nígbà tí gbòǹgbò rẹ̀ sì wà nínú ilẹ̀ kí o sì jẹ́ kí ìrì ọ̀run sẹ̀ sórí i rẹ̀, jẹ́ kí ìpín in rẹ̀ wà láàrín ẹranko búburú títí ìgbà méje yóò fi kọjá lórí i rẹ̀.’
« Le roi vit un saint gardien descendre du ciel et dire: « Abattez l'arbre et détruisez-le; mais laissez la souche de ses racines dans la terre, avec une bande de fer et de bronze, dans l'herbe tendre des champs, et qu'elle soit mouillée de la rosée du ciel. Que sa part soit avec les animaux des champs, jusqu'à ce que sept temps passent sur lui.''
24 “Èyí ni ìtumọ̀ àlá rẹ ọba àti àṣẹ tí Ọ̀gá-ògo mú wá sórí ọba olúwa mi.
« Voici l'interprétation, ô roi, et c'est le décret du Très-Haut, qui est tombé sur mon seigneur le roi:
25 A ó lé ọ jáde kúrò láàrín ènìyàn, ìwọ yóò sì máa gbé láàrín ẹranko búburú, ìwọ yóò jẹ koríko bí i màlúù, ìrì ọ̀run yóò sì sẹ̀ sára rẹ. Ìgbà méje yóò sì kọjá lórí rẹ, títí ìwọ yóò fi mọ̀ wí pé Ọ̀gá-ògo ń jẹ ọba lórí ìjọba ènìyàn, ó sì ń fi fún ẹni tí ó bá wù ú.
Tu seras chassé des hommes et ta demeure sera avec les animaux des champs. On te fera manger de l'herbe comme les bœufs, tu seras mouillé de la rosée du ciel, et sept temps passeront sur toi, jusqu'à ce que tu saches que le Très-Haut règne sur le royaume des hommes et le donne à qui il veut.
26 Bí wọ́n ṣe pàṣẹ pé kí wọn fi kùkùté àti gbòǹgbò igi náà sílẹ̀, èyí túmọ̀ sí wí pé a ó dá ìjọba rẹ padà fún ọ lẹ́yìn ìgbà tí o bá ti mọ̀ wí pé, Ọ̀run jẹ ọba.
Alors qu'il a été ordonné de laisser la souche des racines de l'arbre, votre royaume vous sera assuré après que vous saurez que le Ciel règne.
27 Nítorí náà ọba, jẹ́ kí ìmọ̀ràn mi jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún ọ, kọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ sílẹ̀ kí o sì ṣe rere, àti ìwà búburú rẹ nípa ṣíṣe àánú fún àwọn tálákà. Ó lè jẹ́ pé nígbà náà ni ìwọ yóò ṣe rere.”
C'est pourquoi, ô roi, que mon conseil te soit agréable, et que tu effaces tes péchés par la justice, et tes iniquités par la miséricorde envers les pauvres. Peut-être y aura-t-il un prolongement de ta tranquillité. »
28 Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ṣẹlẹ̀ sí Nebukadnessari ọba.
Tout cela arriva au roi Nebucadnetsar.
29 Lẹ́yìn oṣù kejìlá, bí ọba ṣe ń rìn káàkiri lórí òrùlé ààfin ìjọba Babeli,
Au bout de douze mois, il se promenait dans le palais royal de Babylone.
30 ó sọ pé, “Èyí ha kọ́ ni Babeli ńlá tí mo kọ́ gẹ́gẹ́ bí ilé ọba, nípa agbára à mi àti fún ògo ọláńlá à mi?”
Le roi prit la parole et dit: « N'est-ce pas là la grande Babylone, que j'ai bâtie pour la résidence royale par la puissance de ma force et pour la gloire de ma majesté? »
31 Bí ọba ṣe ń sọ ọ̀rọ̀ náà lọ́wọ́ ohùn kan wá láti ọ̀run, “Ìwọ Nebukadnessari ọba, ìwọ ni a ti pàṣẹ nípa rẹ̀, a ti gba ìjọba à rẹ kúrò ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.
Comme cette parole était dans la bouche du roi, une voix vint du ciel et dit: « Roi Nebucadnetsar, c'est à toi qu'il est dit: Le royaume s'est éloigné de toi.
32 A ó lé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, ìwọ yóò sì lọ máa gbé àárín àwọn ẹranko igbó; ìwọ yóò jẹ koríko bí i màlúù, ìgbà méje yóò kọjá lórí i rẹ títí ìwọ yóò fi mọ̀ wí pé, Ọ̀gá-ògo jẹ ọba lórí ìjọba ènìyàn àti pé ó ń fi fún ẹni tí ó bá wù ú.”
Tu seras chassé des hommes, et ta demeure sera avec les animaux des champs. On te fera manger de l'herbe comme les bœufs. Sept temps passeront sur toi, jusqu'à ce que tu saches que le Très-Haut règne sur le royaume des hommes, et qu'il le donne à qui il veut.'"
33 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ ni ohun tí a sọ nípa Nebukadnessari ṣẹlẹ̀ sí i. A lé e kúrò láàrín ènìyàn, ó sì ń jẹ koríko bí i màlúù, ìrì ọ̀run sì ń sẹ̀ sí ara rẹ̀, títí irun orí rẹ̀ fi gùn bí i ti ìyẹ́ ẹyẹ idì, tí èékánná rẹ̀ sì dàbí i ti ẹyẹ.
Cela s'accomplit à l'heure même sur Nabuchodonosor. Il fut chassé des hommes et mangea de l'herbe comme les bœufs; et son corps fut mouillé de la rosée du ciel jusqu'à ce que ses cheveux eussent poussé comme des plumes d'aigle, et ses ongles comme des griffes d'oiseau.
34 Ní òpin ìgbà náà, èmi, Nebukadnessari gbé ojú mi sókè sí ọ̀run, iyè mi sì sọjí. Mo fi ọpẹ́ fún Ọ̀gá-ògo; mo fi ọlá àti ògo fún ẹni tí ó wà láéláé.
A la fin des jours, moi, Nabuchodonosor, j'ai levé les yeux vers le ciel, et mon intelligence m'est revenue; j'ai béni le Très-Haut, et j'ai loué et honoré celui qui vit éternellement, car sa domination est une domination éternelle, et son royaume de génération en génération.
35 Gbogbo àwọn ènìyàn ayé
Tous les habitants de la terre sont considérés comme des moins que rien; et il fait ce qu'il veut dans l'armée du ciel, et parmi les habitants de la terre; et personne ne peut arrêter sa main, ou lui demander: « Qu'est-ce que tu fais? »
36 Ní àkókò kan náà, iyè mi padà, ọlá àti ògo dídán mi padà tọ̀ mí wá fún ògo ìjọba mi. Àwọn ìgbìmọ̀ àti àwọn ọlọ́lá mi, wá mi rí, wọ́n sì dá mi padà sórí ìjọba mi, mo sì di alágbára ju ti ìṣáájú lọ.
En même temps, mon intelligence me revint; et pour la gloire de mon royaume, ma majesté et mon éclat me revinrent. Mes conseillers et mes seigneurs me recherchaient, et j'étais affermi dans mon royaume, et une grandeur excellente m'était ajoutée.
37 Báyìí, èmi, Nebukadnessari fi ọpẹ́, mo sì gbé Ọlọ́run ga, mo sì fi ògo fún ọba ọ̀run, nítorí pé gbogbo nǹkan tí ó ṣe ló dára, gbogbo ọ̀nà rẹ̀ sì tọ́. Gbogbo àwọn tó sì ń rìn ní ìgbéraga ni ó le rẹ̀ sílẹ̀.
Maintenant, moi, Nebucadnetsar, je loue, j'exalte et j'honore le roi des cieux, car toutes ses œuvres sont vérité, et ses voies justice; et ceux qui marchent dans l'orgueil, il est capable de les abaisser.

< Daniel 4 >