< Daniel 11 >

1 Ní ọdún kìn-ín-ní Dariusi ará Media, mo dúró láti tì í lẹ́yìn àti láti dáàbò bò ó.)
Och jag stod vid hans sida såsom hans stöd och värn i medern Darejaves' första regeringsår.
2 “Ní ìsinsin yìí, mo sọ òtítọ́ fún ọ ọba mẹ́ta yóò dìde sí i ní Persia, àti ẹ̀kẹrin tí yóò jẹ́ ọlọ́rọ̀ ju gbogbo wọn lọ. Tí ó bá ti di alágbára nípa ọrọ̀ rẹ̀, yóò sì ru gbogbo wọn sókè lòdì sí ìjọba Giriki.
Och nu skall jag förkunna för dig vad visst är. Se, ännu tre konungar skola uppstå i Persien, och den fjärde skall förvärva sig större rikedomar än någon av de andra, och när han har blivit som starkast genom sina rikedomar, skall han uppbjuda all sin makt mot Javans rike.
3 Nígbà náà ni ọba alágbára kan yóò fi ara hàn, yóò ṣe àkóso pẹ̀lú agbára ńlá, yóò sì ṣe bí ó ti wù ú.
Sedan skall en väldig konung uppstå, och han skall härska med stor makt och göra vad han vill.
4 Lẹ́yìn ìgbà tí ó bá fi ara hàn tán, ìjọba rẹ̀ yóò fọ́, yóò sì pín sí mẹ́rin ní orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé, ìjọba náà kò sì ṣọ́wọ́ àwọn ìran rẹ̀ tàbí kí ó ní agbára tí ó ń lò tẹ́lẹ̀, nítorí, a ó fa ìjọba rẹ̀ tu a ó sì fi fún àwọn mìíràn.
Men knappt har han uppstått, så skall hans rike brista sönder och bliva delat efter himmelens förra väderstreck; och det skall icke tillfalla hans avkomlingar eller förbliva lika mäktigt som när han hade makten; ty hans rike skall omstörtas och tillfalla andra än dem.
5 “Ọba ìhà gúúsù yóò di alágbára ṣùgbọ́n ọ̀kan lára àwọn aláṣẹ rẹ̀ yóò di alágbára jù ú lọ, yóò sì ṣe àkóso ìjọba rẹ̀ pẹ̀lú agbára ńlá.
Och konungen i Söderlandet skall bliva mäktig, så ock en av hans furstar; ja, denne skall bliva en ännu mäktigare härskare än han själv, och hans herradöme skall bliva stort.
6 Lẹ́yìn ọdún púpọ̀ wọn yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà, ọmọbìnrin ọba gúúsù yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ọba àríwá láti bá a dá májẹ̀mú àlàáfíà, ṣùgbọ́n òun kì yóò lè di agbára apá a rẹ̀ mú, bẹ́ẹ̀ ni òun kì yóò lè dádúró, ṣùgbọ́n a ó tẹrí i rẹ̀ ba àti àwọn tí ó mú un wá, àti ọmọ tí ó bí, àti ẹni tí ó ń mu lọ́kàn le ní gbogbo àkókò wọ̀nyí.
Och efter några år skola de förbinda sig med varandra, och Söderlandskonungens dotter skall draga till konungen i Nordlandet för att komma åstad förlikning. Men hon skall icke kunna behålla den makt hon vinner, ej heller skall han och hans makt bliva beståndande; utan hon skall bliva given till pris, hon jämte dem som läto henne draga dit, både hennes fader och den man som i sin tid tog henne till sig.
7 “Ọ̀kan lára àwọn ìdílé e rẹ̀, ọmọbìnrin ọba gúúsù yóò dìde láti gba ipò o rẹ̀. Yóò sì kọlu ogun ọba àríwá, yóò sì wó odi alágbára; yóò bá wọn jà yóò sì borí.
Men av telningarna från hennes rot skall en stiga upp på hans plats; denne skall draga mot Nordlandskonungens här och tränga in i hans fäste och göra med folket vad han vill och behålla övermakten.
8 Yóò gba òrìṣà wọn, ère dídá àti ohun èlò oníye lórí ti fàdákà àti ti wúrà, yóò sì kó wọn lọ sí Ejibiti. Fún ọdún díẹ̀ yóò fi ọba àríwá lọ́rùn sílẹ̀.
Deras gudar och beläten och deras dyrbara håvor, både silver och guld, skall han ock föra såsom byte till Egypten. Sedan skall han i några år lämna Nordlandskonungen i ro.
9 Nígbà náà, ni ọba àríwá yóò gbógun ti ilẹ̀ ọba, gúúsù, ṣùgbọ́n yóò padà sí Orílẹ̀-èdè, òun fúnra rẹ̀.
Däremot skall denne tränga in i Söderlandskonungens rike, men han skall få vända tillbaka till sitt land igen.
10 Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò múra ogun wọn yóò kó ogun ńlá jọ, èyí tí a ó gbá lọ bí àgbàrá omi ńlá, yóò sì gbá a lọ títí dé ìlú olódi rẹ̀.
Och hans söner skola rusta sig till strid och samla en väldig krigs här; och den skall rycka fram och svämma över och utbreda sig; och den skall komma igen, och striden skall föras ända fram till hans fäste.
11 “Nígbà náà ni ọba gúúsù yóò jáde pẹ̀lú ìbínú, yóò sì bá ọba àríwá jà, ẹni tí yóò kó ọmọ-ogun púpọ̀ jọ, ṣùgbọ́n ọba gúúsù yóò borí i wọn.
Då skall konungen i Söderlandet resa sig i förbittring och draga ut och strida mot konungen i Nordlandet; och denne skall ställa upp en stor härskara, men den härskaran skall varda given i den andres hand.
12 Nígbà tí a bá kó ogun náà lọ, ọba gúúsù yóò kún fún agbára, yóò sì pa ẹgbẹẹgbẹ̀rún ní ìpakúpa síbẹ̀ kì yóò ṣẹ́gun.
När då härskaran är sin kos, växer hans övermod; men om han än han slagit ned tiotusenden, får han dock icke makten.
13 Nítorí ọba àríwá yóò lọ kó ogun mìíràn jọ, tí ó pọ̀ ju ti àkọ́kọ́ lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún, yóò jáde pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun tí ó ti dira ogun fún dáradára.
Konungen i Nordlandet skall ställa upp en ny härskara, större än den förra; och efter en tid av några år skall han komma med en stor krigshär och stora förråd.
14 “Ní àkókò ìgbà náà, ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò dìde sí ọba gúúsù. Àwọn ọlọ̀tẹ̀ nínú àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò ṣọ̀tẹ̀ ní ìmúṣẹ ìran náà, ṣùgbọ́n wọn kì yóò borí.
Vid samma tid skola många andra resa sig mot konungen i Söderlandet; våldsmän av ditt eget folk skola ock upphäva sig, för att synen skall fullbordas; men dessa skola falla.
15 Nígbà náà ni ọba àríwá yóò wá yóò sì gbé ogun tì í, yóò sì kó ìlú olódi. Ogun ọba gúúsù kò ní ní agbára láti kọjú ìjà sí i; bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọ̀wọ́ ogun tó dára jù kò ní ní agbára láti dúró.
Och konungen i Nordlandet skall rycka an och kasta upp vallar och intaga en välbefäst stad; och Söderlandets makt skall icke kunna hålla stånd, dess utvalda krigsfolk skall icke hava någon kraft till motstånd.
16 Ẹni tí ó gbóguntì í yóò máa ṣe bí ó ti wù ú, kò sì ṣí ẹni tí yóò le è dojúkọ ọ́. Yóò sì fún ara rẹ̀ ní ibùjókòó ní ilẹ̀ tí ó dára, yóò sì ní agbára láti bà á jẹ́.
Och han som rycker emot honom skall göra vad han vill, och ingen skall kunna stå emot honom; han skall sätta sig fast i "det härliga landet", och förstöring skall komma genom hans hand.
17 Yóò pinnu láti wá pẹ̀lú agbára ìjọba rẹ̀, yóò sì ní májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú ọba gúúsù yóò sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ fún un láti fẹ́ ẹ ní ìyàwó nítorí kí ó lè gba ìjọba, ṣùgbọ́n ète rẹ̀ yìí kì yóò dúró tàbí ṣe ìrànlọ́wọ́ fún un.
Han skall rycka an med hela sitt rikes makt; dock är han hågad för förlikning, och en sådan skall han komma åstad. En av sina döttrar skall han giva åt honom till hustru, henne till fördärv. Men detta skall icke hava något bestånd och icke vara honom till gagn.
18 Nígbà náà ni yóò yí ara padà sí ilẹ̀ etí Òkun, yóò mú ọ̀pọ̀lọpọ̀, ṣùgbọ́n aláṣẹ kan yóò mú òpin bá àfojúdi rẹ̀, yóò sì yí àfojúdi rẹ̀ padà sí orí rẹ̀.
Därefter skall han vända sig mot öländerna och intaga många; men en härförare skall göra slut på hans smädelser, ja, låta hans smädelser vända tillbaka över honom själv.
19 Lẹ́yìn èyí, yóò sì yí padà sí ìlú olódi ti orílẹ̀-èdè òun fúnra rẹ̀, ṣùgbọ́n yóò kọsẹ̀ yóò sì ṣubú, a kì yóò sì rí i mọ́.
Då skall han vända sig till sitt eget lands fästen; men han skall vackla och falla och sedan icke mer finnas till.
20 “Arọ́pò rẹ̀ yóò rán agbowó orí kan jáde láti fi ìdí ipò ọlá ọba múlẹ̀ ṣùgbọ́n ní ìwọ̀n ọdún díẹ̀, a ó pa á run, kì yóò jẹ́ nípa ìbínú tàbí nínú ogun.
Och på hans plats skall uppstå en annan, en som låter en fogde draga igenom det land som är hans rikes prydnad; men efter några dagar skall han störtas, dock icke genom vrede, ej heller i krig.
21 “Ẹni tí kò níláárí kan yóò rọ́pò rẹ̀, ẹni tí a kò tí ì fi ọlá ọba fún rí. Yóò sì gbógun sí ìjọba nígbà tí ọkàn àwọn ènìyàn balẹ̀ láìbẹ̀rù, yóò sì gbà á pẹ̀lú àrékérekè.
Och på hans plats skall uppstå en föraktlig man, åt vilken konungavärdighet icke var ämnad; oförtänkt skall han komma och bemäktiga sig riket genom ränker.
22 Nígbà náà, ni a ó gbà ogunlọ́gọ̀ ogun kúrò níwájú u rẹ̀, pẹ̀lú òun àti ọmọ-aládé ti májẹ̀mú náà ni a ó parun.
Och översvämmande härar skola svämmas bort för honom och krossas, så ock förbundets furste.
23 Lẹ́yìn tí ó wá ṣe ìpinnu pẹ̀lú u rẹ̀, yóò hùwà ẹ̀tàn, pẹ̀lú ìwọ̀nba ènìyàn kékeré ni yóò gba ìjọba.
Från den stund då man förbinder sig med honom skall han bedriva svek. Han skall draga åstad och få övermakten, med allenast litet folk.
24 Nígbà tí àwọn agbègbè tí ó lọ́rọ̀ gidigidi wà láìbẹ̀rù ni yóò gbóguntì wọ́n, yóò ṣe ohun tí baba rẹ̀ tàbí baba ńlá rẹ̀ kò ṣe rí, yóò pín ìkógun ẹrù àti ọrọ̀ fún àwọn ọmọ lẹ́yìn in rẹ̀. Yóò pète àti bi àwọn ìlú olódi ṣubú, ṣùgbọ́n fún ìgbà díẹ̀ ni.
Oförtänkt skall han falla in i landets bördigaste trakter, och skall göra ting som hans fäder och hans fäders fäder icke hade gjort; byte och rov och gods skall han strö ut åt sitt folk; och mot fästena skall han förehava anslag, intill en viss tid.
25 “Pẹ̀lú ogun púpọ̀, yóò sì ru agbára rẹ̀ àti ìgboyà rẹ̀ sókè sí ọba gúúsù. Ọba gúúsù yóò dìde ogun pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ-ogun tí ó lágbára gidigidi, ṣùgbọ́n kò ní le è dúró, nítorí ọ̀tẹ̀ tí ó gbèrò sí i.
Och han skall uppbjuda sin kraft; och sitt mod emot konungen i Söderlandet och komma med en stor här, men konungen i Söderlandet skall ock rusta sig till strid, med en mycket stor och talrik här; dock skall han icke kunna hålla stånd, för de anslags skull som göras mot honom.
26 Àwọn tí ó jẹ nínú oúnjẹ ọba yóò gbìyànjú láti parun, a ó gbá ogun rẹ̀ dànù, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni yóò ṣubú sí ogun.
De som äta hans bröd skola störta honom. Och hans här skall svämma över, och många skola bliva slagna och falla.
27 Àwọn ọba méjèèjì, ọkàn wọn tẹ̀ sí búburú, wọn yóò jókòó lórí tábìlì kan, wọn yóò máa parọ́ sí ara wọn, ṣùgbọ́n kò ní yọrí sí nǹkan kan nítorí òpin yóò wá ní àsìkò tí a yàn.
Båda konungarna skola hava ont i sinnet, där de sitta tillhopa vid samma bord, skola de tala lögn, men det skall icke hava någon framgång; ty ännu dröjer änden, intill den bestämda tiden.
28 Ọba àríwá yóò padà sí ilẹ̀ rẹ̀ pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀, ṣùgbọ́n ọkàn rẹ̀ yóò lòdì sí májẹ̀mú mímọ́, yóò sì ṣiṣẹ́ lòdì sí i, yóò sì padà sí orílẹ̀-èdè òun fúnra rẹ̀.
Han skall vända tillbaka till sitt land med stora förråd, och han skall lägga planer mot det heliga förbundet; och när han har fullbordat dem, skall han vända tillbaka till sitt land.
29 “Ní àsìkò tí a yàn, yóò gbógun sí gúúsù lẹ́ẹ̀kan sí i, ṣùgbọ́n ní ìgbà yí àyọríṣí yóò yàtọ̀ sí ti ìṣáájú.
På bestämd tid skall han sedan åter draga åstad mot Söderlandet, men denna senare gång skall det ej gå såsom den förra.
30 Nítorí pé, ọkọ̀ ojú omi àwọn ilẹ̀ etídò ìwọ̀-oòrùn yóò takò ó, ọkàn rẹ̀ yóò sì pami. Nígbà náà, ni yóò padà, yóò sì bínú sí májẹ̀mú mímọ́, yóò sì padà, yóò sì fi ojúrere hàn sí àwọn tí ó kọ májẹ̀mú mímọ́ náà.
Ty skepp från Kittim skola komma emot honom, och han skall förlora modet. Då skall han vända om och rikta sin vrede mot det heliga förbundet och giva den fritt lopp. Och när han har kommit hem, skall han lyssna till dem som hava övergivit det heliga förbundet.
31 “Agbára ọmọ-ogun rẹ̀ yóò dìde láti ba ohun mímọ́ ilé olódi tẹmpili jẹ́, yóò sì pa ẹbọ ojoojúmọ́ rẹ́. Nígbà náà ni wọn yóò gbé ìríra tí ó fa ìsọdahoro kalẹ̀.
Och härar, utsända av honom, skola komma och oskära helgedomens fäste och avskaffa det dagliga offret och ställa upp förödelsens styggelse.
32 Pẹ̀lú irú àwọn tí ń ṣe búburú sí májẹ̀mú ní yóò fi ọ̀rọ̀ ìpọ́nni mú ṣọ̀tẹ̀, ṣùgbọ́n, àwọn tí ó mọ Ọlọ́run wọn yóò mú ọkàn le. Wọn yóò sì máa ṣe iṣẹ́ agbára.
Och dem som hava kränkt förbundet skall han med hala ord locka till helt avfall; men de av folket, som känna sin Gud, skola stå fasta och hålla ut.
33 “Àwọn tí ó mòye yóò máa kọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀, ṣùgbọ́n fún ìgbà díẹ̀, wọn yóò máa ṣubú nípa idà tàbí kí a jó wọn tàbí ìgbèkùn tàbí nípa ìkógun.
Och de förståndiga bland folket skola lära många insikt; men de skola bliva hemsökta med svärd och eld, med fångenskap och plundring, till en tid;
34 Nígbà tí wọ́n bá ṣubú, wọn yóò rí ìrànlọ́wọ́ díẹ̀, ọ̀pọ̀ àwọn tó ṣe aláìṣòótọ́ yóò sì darapọ̀ mọ́ wọn.
dock skall under hemsökelsen en liten seger beskäras dem, och många skola då av skrymteri sluta sig till dem.
35 Lára àwọn tí ó mòye yóò kọsẹ̀, nítorí kí a ba à tún wọn ṣe, wọ́n di mímọ́ àti aláìlábàwọ́n títí di ìgbà ìkẹyìn nítorí yóò sì wá ní àkókò tí a yàn.
Hemsökelsen skall träffa somliga av de förståndiga, för att en luttring skall ske bland dem, så att de varda renade och tvagna till ändens tid; ty ännu dröjer denna, intill den bestämda tiden.
36 “Ọba yóò ṣe bí ó ti wù ú yóò sì gbé ara rẹ̀ ga, ju gbogbo òrìṣà lọ, yóò máa sọ àwọn ọ̀rọ̀ tí kò-ṣe-é-gbọ́-létí sí Ọlọ́run àwọn Ọlọ́run, yóò sì máa yege títí àkókò ìbínú yóò fi parí, nítorí ohun tí a ti pinnu yóò ṣẹlẹ̀.
Och konungen skall göra vad han vill och skall förhäva sig och uppträda stormodigt mot allt vad gud heter; ja, mot gudars Gud skall han tala sådant att man måste förundra sig. Och allt skall lyckas honom väl, till dess att vredens tid är ute, då när det har skett, som är oryggligt beslutet.
37 Òun kò ní ka òrìṣà àwọn baba rẹ̀ sí tàbí èyí tí àwọn fẹ́, òun kò ní ka nǹkan kan sí, ṣùgbọ́n yóò gbé ara rẹ̀ ga ju gbogbo wọn lọ.
På sina fäders gudar skall han icke akta, ej heller skall han akta på den som är kvinnors lust eller på någon annan Gud, utan han skall uppträda stormodigt mot dem alla.
38 Ṣùgbọ́n dípò wọn, yóò bu ọlá fún òrìṣà àwọn ìlú olódi: òrìṣà tí àwọn baba rẹ̀ kò mọ̀ ni yóò bu ọlá fún pẹ̀lú wúrà àti fàdákà, pẹ̀lú òkúta iyebíye àti ẹ̀bùn tí ó lówó lórí.
Men fästenas gud skall han i stället ära; en gud som hans fäder icke hava känt skall han ära med guld och silver och ädla stenar och andra dyrbara ting.
39 Yóò kọlu àwọn ìlú olódi tí ó lágbára pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ òrìṣà àjèjì, yóò sì bu ọláńlá fún ẹni tí ó jẹ́wọ́ rẹ̀. Yóò mú wọn ṣe alákòóso lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, yóò sì pín ilẹ̀ náà fún wọn gẹ́gẹ́ bí èrè.
Och mot starka fästen skall han med en främmande guds hjälp göra vad honom lyster; dem som erkänna denne skall han bevisa stor ära, han skall sätta dem att råda över många, och han skall utskifta jord åt dem till belöning.
40 “Ní ìgbà ìkẹyìn, ọba gúúsù yóò gbé ogun de sí i, ọba àríwá yóò sì jáde bí ìjì láti kọlù ú pẹ̀lú u kẹ̀kẹ́ ogun àti ẹlẹ́ṣin àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkọ̀ ojú omi. Yóò gbógun wọ orílẹ̀-èdè púpọ̀, yóò sì bo wọn mọ́lẹ̀ bí ìkún omi.
Men på ändens tid skall konungen i Söderlandet drabba samman med honom; och konungen i Nordlandet skall storma fram mot denne med vagnar och ryttare och många skepp, och skall falla in i främmande länder och svämma över och utbreda sig.
41 Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì tún gbógun ti ilẹ̀ ológo náà pẹ̀lú, ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò ṣubú, ṣùgbọ́n Edomu, Moabu àti àwọn olórí Ammoni yóò bọ́ lọ́wọ́ rẹ̀.
Han skall ock falla in i "det härliga landet", och många andra länder skola bliva hemsökta; men dessa skola komma undan hans hand: Edom och Moab och huvuddelen av Ammons barn.
42 Yóò lo agbára rẹ̀ lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè; Ejibiti kì yóò là.
Ja, han skall uträcka sin hand mot främmande länder, och Egyptens land skall icke slippa undan;
43 Yóò gba àkóso ìṣúra wúrà àti fàdákà àti gbogbo ọrọ̀ Ejibiti, pẹ̀lú ti Libia àti Kuṣi nígbà tí ó mú wọn tẹríba.
han skall bemäktiga sig skatter av guld och silver och allahanda dyrbara ting i Egypten; och libyer och etiopier skola följa honom åt.
44 Ṣùgbọ́n ìròyìn láti ìlà-oòrùn àti láti ìwọ̀-oòrùn yóò mú ìdáríjì bá a, yóò sì fi ìbínú ńlá jáde lọ láti parun, àti láti pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ run pátápátá.
Då skall han från öster och norr få höra rykten som förskräcka honom; och kan skall draga ut i stor vrede för att förgöra många och giva dem till spillo.
45 Yóò sì pàgọ́ ọ rẹ̀ láàrín Òkun kọjú sí àárín òkè mímọ́ ológo. Síbẹ̀ yóò wá sí òpin rẹ̀, ẹnìkan kò ní ràn án lọ́wọ́.
Och sina palatstält skall han slå upp mellan havet och helgedomens härliga berg. Men han går till sin undergång, och ingen skall finnas, som hjälper honom."

< Daniel 11 >