< Daniel 11 >

1 Ní ọdún kìn-ín-ní Dariusi ará Media, mo dúró láti tì í lẹ́yìn àti láti dáàbò bò ó.)
jeg stod også ved hans side som hjelper og som vern i mederen Darius' første år.
2 “Ní ìsinsin yìí, mo sọ òtítọ́ fún ọ ọba mẹ́ta yóò dìde sí i ní Persia, àti ẹ̀kẹrin tí yóò jẹ́ ọlọ́rọ̀ ju gbogbo wọn lọ. Tí ó bá ti di alágbára nípa ọrọ̀ rẹ̀, yóò sì ru gbogbo wọn sókè lòdì sí ìjọba Giriki.
Og nu vil jeg kunngjøre dig hvad som visst og sant vil hende: Ennu skal det opstå tre konger i Persia, og den fjerde skal samle større rikdom enn alle de andre, og når han har vunnet stor makt ved sin rikdom, skal han opbyde alt mot Grekenlands rike.
3 Nígbà náà ni ọba alágbára kan yóò fi ara hàn, yóò ṣe àkóso pẹ̀lú agbára ńlá, yóò sì ṣe bí ó ti wù ú.
Så skal det opstå en veldig konge, og han skal herske med stor makt og gjøre som han vil.
4 Lẹ́yìn ìgbà tí ó bá fi ara hàn tán, ìjọba rẹ̀ yóò fọ́, yóò sì pín sí mẹ́rin ní orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé, ìjọba náà kò sì ṣọ́wọ́ àwọn ìran rẹ̀ tàbí kí ó ní agbára tí ó ń lò tẹ́lẹ̀, nítorí, a ó fa ìjọba rẹ̀ tu a ó sì fi fún àwọn mìíràn.
Men aldri så snart er han stått frem, så skal hans rike brytes i stykker og deles efter de fire verdenshjørner; det skal ikke tilfalle hans efterkommere og ikke være så mektig som da han rådet; for hans rike skal omstyrtes og tilfalle andre enn dem.
5 “Ọba ìhà gúúsù yóò di alágbára ṣùgbọ́n ọ̀kan lára àwọn aláṣẹ rẹ̀ yóò di alágbára jù ú lọ, yóò sì ṣe àkóso ìjọba rẹ̀ pẹ̀lú agbára ńlá.
Og Sydens konge skal bli mektig, og en av hans fyrster skal bli mektigere enn han og råde over et eget rike; hans rike skal være et stort rike.
6 Lẹ́yìn ọdún púpọ̀ wọn yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà, ọmọbìnrin ọba gúúsù yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ọba àríwá láti bá a dá májẹ̀mú àlàáfíà, ṣùgbọ́n òun kì yóò lè di agbára apá a rẹ̀ mú, bẹ́ẹ̀ ni òun kì yóò lè dádúró, ṣùgbọ́n a ó tẹrí i rẹ̀ ba àti àwọn tí ó mú un wá, àti ọmọ tí ó bí, àti ẹni tí ó ń mu lọ́kàn le ní gbogbo àkókò wọ̀nyí.
Og mange år efter skal de inngå forbund med hverandre; en datter av Sydens konge skal komme til Nordens konge for å skape vennskap mellem dem; men hun skal ikke lenge formå å utrette noget, og hverken han eller datteren som skulde hjelpe ham, skal holde stand, men hun og de som førte henne dit, og hennes far og han som tok imot henne, skal miste livet på den for hver av dem bestemte tid.
7 “Ọ̀kan lára àwọn ìdílé e rẹ̀, ọmọbìnrin ọba gúúsù yóò dìde láti gba ipò o rẹ̀. Yóò sì kọlu ogun ọba àríwá, yóò sì wó odi alágbára; yóò bá wọn jà yóò sì borí.
Men et av skuddene fra hennes røtter skal trede op på hans plass; og han skal dra mot fiendens hær og trenge inn i Nordens konges festninger og gjøre med dem som han vil, og ha overmakt.
8 Yóò gba òrìṣà wọn, ère dídá àti ohun èlò oníye lórí ti fàdákà àti ti wúrà, yóò sì kó wọn lọ sí Ejibiti. Fún ọdún díẹ̀ yóò fi ọba àríwá lọ́rùn sílẹ̀.
Endog deres guder med deres støpte billeder, med deres kostbare kar av sølv og gull, skal han føre bort til Egypten; siden skal han i nogen år la Nordens konge få være i fred.
9 Nígbà náà, ni ọba àríwá yóò gbógun ti ilẹ̀ ọba, gúúsù, ṣùgbọ́n yóò padà sí Orílẹ̀-èdè, òun fúnra rẹ̀.
Så skal Nordens konge dra mot Sydens konges rike, men måtte vende tilbake til sitt land igjen.
10 Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò múra ogun wọn yóò kó ogun ńlá jọ, èyí tí a ó gbá lọ bí àgbàrá omi ńlá, yóò sì gbá a lọ títí dé ìlú olódi rẹ̀.
Og hans sønner skal ruste sig til strid og samle en veldig krigshær, og den skal dra inn i landet og oversvømme og overskylle det; så skal den komme igjen, og krigen skal føres helt frem til hans festning.
11 “Nígbà náà ni ọba gúúsù yóò jáde pẹ̀lú ìbínú, yóò sì bá ọba àríwá jà, ẹni tí yóò kó ọmọ-ogun púpọ̀ jọ, ṣùgbọ́n ọba gúúsù yóò borí i wọn.
Da skal Sydens konge bli harm og dra ut og stride mot Nordens konge, og han skal stille op en stor hær, men den skal gis i hans hånd.
12 Nígbà tí a bá kó ogun náà lọ, ọba gúúsù yóò kún fún agbára, yóò sì pa ẹgbẹẹgbẹ̀rún ní ìpakúpa síbẹ̀ kì yóò ṣẹ́gun.
Når denne hær er sprengt, skal han bli overmodig; han skal felle titusener, men allikevel ikke få overmakten.
13 Nítorí ọba àríwá yóò lọ kó ogun mìíràn jọ, tí ó pọ̀ ju ti àkọ́kọ́ lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún, yóò jáde pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun tí ó ti dira ogun fún dáradára.
Og Nordens konge skal komme igjen og stille op en hær som er ennu større enn den første; og når nogen år er gått til ende, skal han komme med en stor hær og store forråd.
14 “Ní àkókò ìgbà náà, ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò dìde sí ọba gúúsù. Àwọn ọlọ̀tẹ̀ nínú àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò ṣọ̀tẹ̀ ní ìmúṣẹ ìran náà, ṣùgbọ́n wọn kì yóò borí.
Og i de tider skal mange reise sig mot Sydens konge, og voldsmenn av ditt eget folk skal også reise sig, så synet blir stadfestet; men de skal falle.
15 Nígbà náà ni ọba àríwá yóò wá yóò sì gbé ogun tì í, yóò sì kó ìlú olódi. Ogun ọba gúúsù kò ní ní agbára láti kọjú ìjà sí i; bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọ̀wọ́ ogun tó dára jù kò ní ní agbára láti dúró.
Og Nordens konge skal komme og opkaste en voll og innta en sterk festning, og Sydens makt skal ikke kunne holde stand, og enn ikke hans utvalgte mannskap har kraft til å holde stand.
16 Ẹni tí ó gbóguntì í yóò máa ṣe bí ó ti wù ú, kò sì ṣí ẹni tí yóò le è dojúkọ ọ́. Yóò sì fún ara rẹ̀ ní ibùjókòó ní ilẹ̀ tí ó dára, yóò sì ní agbára láti bà á jẹ́.
Og den som rykker mot ham, skal gjøre som han vil, og ingen skal kunne stå sig mot ham; han skal feste fot i det fagre land og føre ødeleggelse med sig.
17 Yóò pinnu láti wá pẹ̀lú agbára ìjọba rẹ̀, yóò sì ní májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú ọba gúúsù yóò sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ fún un láti fẹ́ ẹ ní ìyàwó nítorí kí ó lè gba ìjọba, ṣùgbọ́n ète rẹ̀ yìí kì yóò dúró tàbí ṣe ìrànlọ́wọ́ fún un.
Og han skal ta sig fore å komme med hele sitt rikes makt, men er villig til å inngå forlik, og det skal han også få i stand; og en kvinne, sin egen datter, skal han gi ham, forat hun skal volde ødeleggelse; men det skal ikke komme i stand og ikke lykkes for ham.
18 Nígbà náà ni yóò yí ara padà sí ilẹ̀ etí Òkun, yóò mú ọ̀pọ̀lọpọ̀, ṣùgbọ́n aláṣẹ kan yóò mú òpin bá àfojúdi rẹ̀, yóò sì yí àfojúdi rẹ̀ padà sí orí rẹ̀.
Så skal han vende sig mot øene og innta mange, men en hærfører skal gjøre ende på hans hån og endog la hans hån falle tilbake på ham selv.
19 Lẹ́yìn èyí, yóò sì yí padà sí ìlú olódi ti orílẹ̀-èdè òun fúnra rẹ̀, ṣùgbọ́n yóò kọsẹ̀ yóò sì ṣubú, a kì yóò sì rí i mọ́.
Da skal han vende sig mot festningene i sitt eget land, men han snubler og faller og er ikke mere til.
20 “Arọ́pò rẹ̀ yóò rán agbowó orí kan jáde láti fi ìdí ipò ọlá ọba múlẹ̀ ṣùgbọ́n ní ìwọ̀n ọdún díẹ̀, a ó pa á run, kì yóò jẹ́ nípa ìbínú tàbí nínú ogun.
Og på hans plass skal det opstå en som skal la en skattekrever dra gjennem rikets pryd; og nogen dager efter skal han omkomme, men ikke ved vrede, heller ikke i krig.
21 “Ẹni tí kò níláárí kan yóò rọ́pò rẹ̀, ẹni tí a kò tí ì fi ọlá ọba fún rí. Yóò sì gbógun sí ìjọba nígbà tí ọkàn àwọn ènìyàn balẹ̀ láìbẹ̀rù, yóò sì gbà á pẹ̀lú àrékérekè.
Og på hans plass skal det opstå et foraktelig menneske, som de ikke har overgitt kongedømmets herlighet; men han kommer uventende og tilegner sig kongedømmet ved list og svik.
22 Nígbà náà, ni a ó gbà ogunlọ́gọ̀ ogun kúrò níwájú u rẹ̀, pẹ̀lú òun àti ọmọ-aládé ti májẹ̀mú náà ni a ó parun.
Og de oversvømmende hærer skal oversvømmes av ham og tilintetgjøres, og likeså forbundsfyrsten;
23 Lẹ́yìn tí ó wá ṣe ìpinnu pẹ̀lú u rẹ̀, yóò hùwà ẹ̀tàn, pẹ̀lú ìwọ̀nba ènìyàn kékeré ni yóò gba ìjọba.
for efterat han har inngått forbund med ham, skal han fare frem med svik; han skal dra ut og få overmakten med få folk.
24 Nígbà tí àwọn agbègbè tí ó lọ́rọ̀ gidigidi wà láìbẹ̀rù ni yóò gbóguntì wọ́n, yóò ṣe ohun tí baba rẹ̀ tàbí baba ńlá rẹ̀ kò ṣe rí, yóò pín ìkógun ẹrù àti ọrọ̀ fún àwọn ọmọ lẹ́yìn in rẹ̀. Yóò pète àti bi àwọn ìlú olódi ṣubú, ṣùgbọ́n fún ìgbà díẹ̀ ni.
Uventende skal han falle inn i landets fruktbareste bygder og gjøre ting som hans fedre og hans fedres fedre ikke har gjort; hærfang og rov og gods skal han strø ut til sine folk, og mot faste byer skal han legge op onde råd, og det vil vare en tid.
25 “Pẹ̀lú ogun púpọ̀, yóò sì ru agbára rẹ̀ àti ìgboyà rẹ̀ sókè sí ọba gúúsù. Ọba gúúsù yóò dìde ogun pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ-ogun tí ó lágbára gidigidi, ṣùgbọ́n kò ní le è dúró, nítorí ọ̀tẹ̀ tí ó gbèrò sí i.
Han skal opbyde sin makt og sitt mot mot Sydens konge og komme med en stor hær; men Sydens konge skal også ruste sig til krig med en overmåte stor og sterk hær; men han skal ikke kunne holde stand; for det blir lagt op onde råd mot ham.
26 Àwọn tí ó jẹ nínú oúnjẹ ọba yóò gbìyànjú láti parun, a ó gbá ogun rẹ̀ dànù, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni yóò ṣubú sí ogun.
De som eter ved hans bord, skal felle ham; hans hær skal strømme frem, og det skal bli et stort mannefall.
27 Àwọn ọba méjèèjì, ọkàn wọn tẹ̀ sí búburú, wọn yóò jókòó lórí tábìlì kan, wọn yóò máa parọ́ sí ara wọn, ṣùgbọ́n kò ní yọrí sí nǹkan kan nítorí òpin yóò wá ní àsìkò tí a yàn.
Begge konger har ondt i sinne, og mens de sitter ved samme bord, skal de tale løgn; men det skal ikke lykkes, for ennu dryger det med enden, til den fastsatte tid kommer.
28 Ọba àríwá yóò padà sí ilẹ̀ rẹ̀ pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀, ṣùgbọ́n ọkàn rẹ̀ yóò lòdì sí májẹ̀mú mímọ́, yóò sì ṣiṣẹ́ lòdì sí i, yóò sì padà sí orílẹ̀-èdè òun fúnra rẹ̀.
Han skal vende tilbake til sitt land med meget gods, og han skal legge op råd mot den hellige pakt, og efterat han har utført dem, skal han vende tilbake til sitt land.
29 “Ní àsìkò tí a yàn, yóò gbógun sí gúúsù lẹ́ẹ̀kan sí i, ṣùgbọ́n ní ìgbà yí àyọríṣí yóò yàtọ̀ sí ti ìṣáájú.
Til fastsatt tid skal han atter dra mot Syden; men den siste gang skal det ikke gå som første gang;
30 Nítorí pé, ọkọ̀ ojú omi àwọn ilẹ̀ etídò ìwọ̀-oòrùn yóò takò ó, ọkàn rẹ̀ yóò sì pami. Nígbà náà, ni yóò padà, yóò sì bínú sí májẹ̀mú mímọ́, yóò sì padà, yóò sì fi ojúrere hàn sí àwọn tí ó kọ májẹ̀mú mímọ́ náà.
for skib fra Kittim skal komme imot ham, og han skal bli motfallen og vende om og la sin vrede gå ut over den hellige pakt; så skal han vende om og legge merke til dem som forlater den hellige pakt.
31 “Agbára ọmọ-ogun rẹ̀ yóò dìde láti ba ohun mímọ́ ilé olódi tẹmpili jẹ́, yóò sì pa ẹbọ ojoojúmọ́ rẹ́. Nígbà náà ni wọn yóò gbé ìríra tí ó fa ìsọdahoro kalẹ̀.
Og hærer som han sender ut, skal komme og vanhellige helligdommen, den faste borg, og avskaffe det stadige offer og stille op den ødeleggende vederstyggelighet.
32 Pẹ̀lú irú àwọn tí ń ṣe búburú sí májẹ̀mú ní yóò fi ọ̀rọ̀ ìpọ́nni mú ṣọ̀tẹ̀, ṣùgbọ́n, àwọn tí ó mọ Ọlọ́run wọn yóò mú ọkàn le. Wọn yóò sì máa ṣe iṣẹ́ agbára.
Og dem som synder mot pakten, skal han gjøre til hedninger ved glatte ord; men de av folket som kjenner sin Gud, skal stå fast og holde ut.
33 “Àwọn tí ó mòye yóò máa kọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀, ṣùgbọ́n fún ìgbà díẹ̀, wọn yóò máa ṣubú nípa idà tàbí kí a jó wọn tàbí ìgbèkùn tàbí nípa ìkógun.
Og de forstandige blandt folket skal lære mengden, og de skal falle ved sverd og bål og ved fangenskap og plyndring en tid lang.
34 Nígbà tí wọ́n bá ṣubú, wọn yóò rí ìrànlọ́wọ́ díẹ̀, ọ̀pọ̀ àwọn tó ṣe aláìṣòótọ́ yóò sì darapọ̀ mọ́ wọn.
Men mens de holder på å ligge under, skal de få en liten hjelp, og mange skal slå sig i lag med dem på skrømt.
35 Lára àwọn tí ó mòye yóò kọsẹ̀, nítorí kí a ba à tún wọn ṣe, wọ́n di mímọ́ àti aláìlábàwọ́n títí di ìgbà ìkẹyìn nítorí yóò sì wá ní àkókò tí a yàn.
Og nogen av de forstandige skal falle, sa de kan bli prøvd og renset og tvettet til endens tid; for ennu dryger det med enden, til den fastsatte tid kommer.
36 “Ọba yóò ṣe bí ó ti wù ú yóò sì gbé ara rẹ̀ ga, ju gbogbo òrìṣà lọ, yóò máa sọ àwọn ọ̀rọ̀ tí kò-ṣe-é-gbọ́-létí sí Ọlọ́run àwọn Ọlọ́run, yóò sì máa yege títí àkókò ìbínú yóò fi parí, nítorí ohun tí a ti pinnu yóò ṣẹlẹ̀.
Og kongen skal gjøre som han vil, og ophøie sig og heve sig over enhver gud, og mot gudenes Gud skal han tale forferdelige ord, og han skal ha fremgang, inntil vreden er til ende; for det som er fast besluttet, vil bli fullbyrdet.
37 Òun kò ní ka òrìṣà àwọn baba rẹ̀ sí tàbí èyí tí àwọn fẹ́, òun kò ní ka nǹkan kan sí, ṣùgbọ́n yóò gbé ara rẹ̀ ga ju gbogbo wọn lọ.
På sine fedres guder skal han ikke akte, heller ikke på kvinnenes lyst eller på nogen annen gud skal han akte; for han skal ophøie sig over alle.
38 Ṣùgbọ́n dípò wọn, yóò bu ọlá fún òrìṣà àwọn ìlú olódi: òrìṣà tí àwọn baba rẹ̀ kò mọ̀ ni yóò bu ọlá fún pẹ̀lú wúrà àti fàdákà, pẹ̀lú òkúta iyebíye àti ẹ̀bùn tí ó lówó lórí.
Men festningenes gud skal han ære i stedet; en gud som hans fedre ikke har kjent, skal han ære med gull og sølv og dyre stener og andre kostelige ting;
39 Yóò kọlu àwọn ìlú olódi tí ó lágbára pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ òrìṣà àjèjì, yóò sì bu ọláńlá fún ẹni tí ó jẹ́wọ́ rẹ̀. Yóò mú wọn ṣe alákòóso lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, yóò sì pín ilẹ̀ náà fún wọn gẹ́gẹ́ bí èrè.
og således skal han gjøre med de sterke festninger og med den fremmede gud: Dem som vedkjenner sig denne gud, skal han vise stor ære, og han skal sette dem til å råde over mange, og han skal dele ut jord til dem som lønn.
40 “Ní ìgbà ìkẹyìn, ọba gúúsù yóò gbé ogun de sí i, ọba àríwá yóò sì jáde bí ìjì láti kọlù ú pẹ̀lú u kẹ̀kẹ́ ogun àti ẹlẹ́ṣin àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkọ̀ ojú omi. Yóò gbógun wọ orílẹ̀-èdè púpọ̀, yóò sì bo wọn mọ́lẹ̀ bí ìkún omi.
Men i endens tid skal Sydens konge føre krig med ham, og Nordens konge skal storme frem mot ham med vogner og hestfolk og mange skib og falle inn i landene og oversvømme og overskylle dem.
41 Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì tún gbógun ti ilẹ̀ ológo náà pẹ̀lú, ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò ṣubú, ṣùgbọ́n Edomu, Moabu àti àwọn olórí Ammoni yóò bọ́ lọ́wọ́ rẹ̀.
Han skal også falle inn i det fagre land, og store skarer skal falle; men disse skal slippe unda hans makt: Edom og Moab og de ypperste av Ammons barn.
42 Yóò lo agbára rẹ̀ lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè; Ejibiti kì yóò là.
Og han skal utstrekke sin hånd mot andre land, og Egyptens land skal ikke slippe unda.
43 Yóò gba àkóso ìṣúra wúrà àti fàdákà àti gbogbo ọrọ̀ Ejibiti, pẹ̀lú ti Libia àti Kuṣi nígbà tí ó mú wọn tẹríba.
Han skal tilegne sig skattene av gull og av sølv og alle Egyptens kostelige ting, og libyere og etiopere skal være i hans følge.
44 Ṣùgbọ́n ìròyìn láti ìlà-oòrùn àti láti ìwọ̀-oòrùn yóò mú ìdáríjì bá a, yóò sì fi ìbínú ńlá jáde lọ láti parun, àti láti pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ run pátápátá.
Men tidender fra Østen og fra Norden skal forferde ham, og han skal dra ut i stor harme for å ødelegge og tilintetgjøre mange.
45 Yóò sì pàgọ́ ọ rẹ̀ láàrín Òkun kọjú sí àárín òkè mímọ́ ológo. Síbẹ̀ yóò wá sí òpin rẹ̀, ẹnìkan kò ní ràn án lọ́wọ́.
Og han skal slå op sine palasstelt mellem havet og helligdommens fagre berg; men så bærer det til enden med ham, og det er ingen som hjelper ham.

< Daniel 11 >