< Daniel 10 >

1 Ní ọdún kẹta Kirusi ọba Persia, a fi ìran kan hàn Daniẹli (ẹni tí à ń pè ní Belteṣassari). Òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ ìran náà, ó sì ní í ṣe pẹ̀lú àsìkò ìpọ́njú ńlá, òye ọ̀rọ̀ náà wá bá a nínú ìran.
Ⱪorǝx Parsⱪa sǝltǝnǝt ⱪilƣan üqinqi yili, Daniyal (yǝnǝ bir ismi Bǝltǝxasar bolƣan)ƣa bir hǝwǝr wǝⱨiy ⱪilindi. U hǝwǝr ixǝnqliktur — lekin naⱨayiti ⱪattiⱪ jǝng judunliri toƣrisididur. Daniyal bu hǝwǝrni qüxǝndi wǝ ƣayibanǝ alamǝt toƣrisida qüxǝnqigǝ igǝ boldi.
2 Ní àsìkò náà, èmi Daniẹli ṣọ̀fọ̀ fún ọ̀sẹ̀ mẹ́ta.
U qaƣda mǝnki Daniyal toluⱪ üq ⱨǝptǝ aⱨ-zar kɵtürüp matǝm tuttum.
3 Èmi kì í jẹ oúnjẹ tí ó dára, èmi kò fi ẹran tàbí wáìnì kan ẹnu mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi òróró para títí ọ̀sẹ̀ mẹ́ta fi kọjá.
Üq ⱨǝptigiqǝ ⱨeqⱪandaⱪ nazu-nemǝt yemidim, gɵx yemidim, xarab iqmidim wǝ tenimgǝ puraⱪliⱪ may sürmidim.
4 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù àkọ́kọ́, bí mo ti dúró sí etí i bèbè odò ńlá Tigirisi,
Birinqi ayning yigirmǝ tɵtinqi küni, mǝn uluƣ dǝrya, yǝni Dijlǝ dǝryasining boyida turup,
5 mo wo òkè, mo rí ọkùnrin kan tí ó wọ aṣọ àlà, ẹ̀gbẹ́ ẹni tí a fi wúrà Upasi dáradára dì ní àmùrè.
beximni kɵtürüp kɵzümni asmanƣa tiktim, kanap kiyip, beligǝ Ufazdiki sap altun kǝmǝr baƣliƣan bir adǝmni kɵrdüm.
6 Ara rẹ̀ dàbí berili, ojú u rẹ̀ dàbí mọ̀nàmọ́ná, ẹyin ojú u rẹ̀ dàbí iná àtẹ̀tàn, apá àti ẹsẹ̀ rẹ̀ dàbí ìtànná ìmọ́lẹ̀ tí o kún fún idẹ, àti ohùn rẹ̀ dàbí i ti ìjọ ènìyàn púpọ̀.
Uning teni seriⱪ yaⱪuttǝk julalinip, yüzliri qaⱪmaⱪtǝk yaltirlap, kɵzliri yenip turƣan ottǝk qaⱪnaytti; uning put-ⱪolliri parⱪirap turidiƣan mistǝk walildaytti; awazi zor bir top adǝmning awazidǝk jaranglaytti.
7 Èmi Daniẹli, ni ẹnìkan tí ó rí ìran náà, àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú u mi, wọn kò rí i, ṣùgbọ́n ìpayà ńlá dà bò wọ́n, wọ́n sálọ wọ́n sì fi ara pamọ́.
Ƣayibanǝ kɵrünüxni yalƣuz mǝnki Daniyalla kɵrdüm, yenimdikilǝr alamǝtni kɵrmigǝnidi. Əmma zor bir wǝⱨimǝ ularni besip, intayin titrǝp ketixti, mɵkünüwalƣudǝk yǝrni izdǝp ⱪeqip kǝtti.
8 Ó sì ku èmi nìkan, tí mo rí ìran ńlá yìí, kò sì ku okun kankan fún mi, ojú u mi sì rẹ̀wẹ̀sì gidigidi, n kò sì ní agbára mọ́.
U yǝrdǝ ɵzüm yalƣuz ⱪelip bu karamǝt ƣayibanǝ kɵrünüxni kɵrdüm. Ⱪilqǝ maƣdurum ⱪalmidi, qirayim ⱪattiⱪ ɵzgirip ɵlük adǝmdǝk bolup ⱪaldim, put-ⱪollirimda bir’azmu maƣdur ⱪalmidi.
9 Nígbà náà, ni mo gbọ́ tí ó ń sọ̀rọ̀, bí mo ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí i, mo sùn lọ fọnfọn, ní ìdojúbolẹ̀.
Lekin uning awazini anglidim. Uning awazini angliƣan ⱨaman yǝrgǝ yiⱪilip düm qüxtüm, ⱨoxumdin kǝttim.
10 Ọwọ́ kan kàn mí, ó gbé mi dìde ní ìwárìrì lórí ọwọ́ àti eékún mi.
Mana, tuyuⱪsiz bir ⱪol manga tǝgdi, meni xuan yɵlǝp yǝrgǝ tɵt putluⱪ ⱪilip turƣuzdi.
11 Ó sọ pé, “Daniẹli ẹni tí a yàn fẹ́ gidigidi gba ọ̀rọ̀ tí mo fẹ́ bá ọ sọ yìí yẹ̀ wò dáradára, kí o sì dìde, nítorí tí a rán mi sí ọ.” Bí ó ṣe sọ èyí fún mi, mo dìde ní ìwárìrì.
Xu zat manga: — Əy Daniyal, intayin sɵyülgǝn adǝm! Sɵzlirimni kɵngül ⱪoyup anglap qüxǝngin, ɵrǝ turƣin! Qünki mǝn sening yeningƣa ǝwǝtildim, — dedi. U bu sɵzni ⱪilixi bilǝn, mǝn titrigǝn ⱨalda ornumdin turdum.
12 Nígbà náà ni ó tẹ̀síwájú, pé, “Má ṣe bẹ̀rù Daniẹli. Láti ọjọ́ àkọ́kọ́ tí ìwọ ti fi ọkàn rẹ sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run rẹ, a gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ, mo sì wá nítorí ọ̀rọ̀ náà.
Xuning bilǝn u manga mundaⱪ dedi: — «Əy Daniyal, ⱪorⱪma; qünki sǝn Hudayingning aldida qüxinixkǝ erixixkǝ, ɵzüngni tɵwǝn tutuxⱪa kɵngül ⱪoyƣan birinqi kündin buyan sening dua-tilawiting ijabǝt ⱪilindi; eytⱪanliring üqün mǝn yeningƣa ǝwǝtildim.
13 Ṣùgbọ́n ọmọ-aládé ìjọba Persia dá mi dúró fún ọjọ́ mọ́kànlélógún. Nígbà náà ni Mikaeli, ọ̀kan lára ìjòyè àwọn ọmọ-aládé, wá láti ràn mi lọ́wọ́, nítorí a dá mi dúró níbẹ̀ pẹ̀lú ọba Persia.
Lekin, «Pars padixaⱨliⱪining ǝmiri» manga ⱪarxi qiⱪip yolumni yigirmǝ bir kün tosuwaldi. Mǝn Pars padixaⱨlirining yenida ɵzüm yalƣuz ⱪalƣaqⱪa, bax ǝmirlǝrdin biri Mikail manga yardǝm ⱪilƣili kǝldi.
14 Ní ìsinsin yìí mo wá láti ṣàlàyé ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú, nítorí ìran náà ń sọ nípa ọjọ́ iwájú.”
Mǝn sanga ahirⱪi zamanlarda hǝlⱪingning bexiƣa kelidiƣan ixlarni qüxǝndürgili kǝldim. Qünki bu ƣayibanǝ alamǝt kɵp künlǝr keyinki kǝlgüsi toƣrisididur».
15 Bí ó sì ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí fún mi, mo sì dorí kodò mo sì dákẹ́.
U manga bu gǝpni ⱪiliwatⱪanda, pǝⱪǝtla yǝrgǝ ⱪarƣinimqǝ zuwan sürǝlmǝy turup ⱪaldim.
16 Nígbà náà, ni ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kan ètè mi, mo la ẹnu mi, mo sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ ọ̀rọ̀, mo sọ fún ẹni tí ó dúró níwájú mi, “Ìrònú sì mú mi, nítorí ìran náà, olúwa mi, n kò sì ní okun.
Mana, goya adǝmgǝ ohxaydiƣan birsi ⱪolini uzitip lǝwlirimni silap ⱪoywidi, mǝn aƣzimni eqip aldimda turƣuqiƣa: — Tǝⱪsir, bu ƣayibanǝ kɵrünüxtin iq-iqimdin azablinimǝn, maƣdurumdin kǝttim.
17 Ǹjẹ́ báwo ni èmi ìránṣẹ́ ẹ̀ rẹ ṣe lè bá ọ sọ̀rọ̀, olúwa mi? Agbára mi ti lọ, agbára káká ni mo fi ń mí.”
Tǝⱪsirimning kǝminǝ ⱪulliri ⱪandaⱪmu sili tǝⱪsirim bilǝn sɵzlixixkǝ petinalayttim? Qünki ⱨazirla maƣdurum tügǝp, nǝpǝsim üzülidu, — dedim.
18 Ẹ̀wẹ̀, ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kàn mí, ó sì fún mi ní agbára.
Andin goya adǝmgǝ ohxaydiƣan biri meni yǝnǝ bir ⱪetim silap, maƣdur kirgüzdi
19 Ó sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ ọkùnrin olùfẹ́ gidigidi. Àlàáfíà ni fún ọ, mú ara le, àní mú ara le.” Nígbà tí ohun bá mi sọ̀rọ̀, a sì mú mi lára le. “Mo sì wí pé, kí olúwa mi kí ó máa sọ̀rọ̀, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ ti mú mi ní ara le.”
wǝ: — I intayin sɵyülgǝn adǝm, ⱪorⱪma! Sanga aman-hatirjǝmlik bolƣay. Ƣǝyrǝtlik bol, ǝmdi ƣǝyrǝtlik bol! — dedi. U xu sɵzni deyixi bilǝnla manga tehimu maƣdur kirdi. Mǝn: — Tǝⱪsir yǝnǝ sɵz ⱪilƣayla, qünki sili manga maƣdur kirgüzdila, — dedim.
20 Nígbà náà, ni ó wí pé, “Ṣé o mọ ìdí tí mo fi tọ̀ ọ́ wá? Láìpẹ́ èmi yóò yípadà lọ bá àwọn ọmọ-aládé Persia jà, nígbà tí mo bá lọ àwọn ọmọ-aládé Giriki yóò wá;
U mundaⱪ dedi: — «Mening ⱪexingƣa nemigǝ kǝlgǝnlikimni bilǝmsǝn? Mǝn ǝmdi ⱪaytip berip, «Parstiki ǝmir» bilǝn jǝng ⱪilimǝn; mǝn u yǝrgǝ barƣandin keyin, «Gretsiyǝdiki ǝmir» mǝydanƣa qiⱪidu.
21 ṣùgbọ́n ní àkọ́kọ́, èmi yóò sọ ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé òtítọ́ fún ọ. (Kò sí ẹni tí ó kún mi lọ́wọ́ fún nǹkan wọ̀nyí bí kò ṣe Mikaeli, ọmọ-aládé e yín.
Lekin mǝn berixtin awwal ⱨǝⱪiⱪǝtning kitabida pütülgǝn wǝⱨiylǝrni mǝn sanga bayan ⱪilimǝn. Bu ixlarda silǝrning ǝmiringlar Mikaildin baxⱪa, manga yardǝm beridiƣan ⱨeqkim yoⱪ.

< Daniel 10 >