< Daniel 10 >

1 Ní ọdún kẹta Kirusi ọba Persia, a fi ìran kan hàn Daniẹli (ẹni tí à ń pè ní Belteṣassari). Òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ ìran náà, ó sì ní í ṣe pẹ̀lú àsìkò ìpọ́njú ńlá, òye ọ̀rọ̀ náà wá bá a nínú ìran.
Kóresnek, Perzsia királyának harmadik évében egy ige nyilvánittatott Dániélnek, a ki így neveztetett el: Béltsacczár, s igaz az ige és nagy az időszak; megértette az igét s nagy értése volt a látomásban.
2 Ní àsìkò náà, èmi Daniẹli ṣọ̀fọ̀ fún ọ̀sẹ̀ mẹ́ta.
Ama napokban én Dániél gyászoltam három teljes héten át;
3 Èmi kì í jẹ oúnjẹ tí ó dára, èmi kò fi ẹran tàbí wáìnì kan ẹnu mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi òróró para títí ọ̀sẹ̀ mẹ́ta fi kọjá.
kedvelt kenyeret nem ettem s hús és bor nem jött szájamba s kenni nem kentem magamat, mígnem letelt három teljes hét.
4 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù àkọ́kọ́, bí mo ti dúró sí etí i bèbè odò ńlá Tigirisi,
És az első hónap huszonnegyedik napján – és én voltam a nagy folyamnak, a Chiddékelnek partján -
5 mo wo òkè, mo rí ọkùnrin kan tí ó wọ aṣọ àlà, ẹ̀gbẹ́ ẹni tí a fi wúrà Upasi dáradára dì ní àmùrè.
fölemeltem szemeimet, és láttam s íme egy lenbe öltözött férfi s dereka átövezve úfázi aranynyal;
6 Ara rẹ̀ dàbí berili, ojú u rẹ̀ dàbí mọ̀nàmọ́ná, ẹyin ojú u rẹ̀ dàbí iná àtẹ̀tàn, apá àti ẹsẹ̀ rẹ̀ dàbí ìtànná ìmọ́lẹ̀ tí o kún fún idẹ, àti ohùn rẹ̀ dàbí i ti ìjọ ènìyàn púpọ̀.
teste pedig olyan, mint a tarsis s arcza mint a villám, látszata s szemei mint a tüzes fáklyák s karjai meg lábai mint a simitott réznek szine; szavainak hangja pedig olyan, mint zúgó tömegnek hangja.
7 Èmi Daniẹli, ni ẹnìkan tí ó rí ìran náà, àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú u mi, wọn kò rí i, ṣùgbọ́n ìpayà ńlá dà bò wọ́n, wọ́n sálọ wọ́n sì fi ara pamọ́.
És én, Dániél, egyedül láttam a látomást, de az emberek, kik velem voltak, nem látták a látomást; azonban nagy ijedség esett reájuk, elrejtőzve megszöktek.
8 Ó sì ku èmi nìkan, tí mo rí ìran ńlá yìí, kò sì ku okun kankan fún mi, ojú u mi sì rẹ̀wẹ̀sì gidigidi, n kò sì ní agbára mọ́.
S én egyedül maradtam s láttam ezt a nagy látomást s nem maradt bennem erő; s arczom fénye elváltozott rajtam torzulásig s nem tartottam meg erőt.
9 Nígbà náà, ni mo gbọ́ tí ó ń sọ̀rọ̀, bí mo ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí i, mo sùn lọ fọnfọn, ní ìdojúbolẹ̀.
S hallottam szavainak hangját; és a mint meghallottam szavainak hangját, mély álomban arczomra borultam s arczommal a földre.
10 Ọwọ́ kan kàn mí, ó gbé mi dìde ní ìwárìrì lórí ọwọ́ àti eékún mi.
S íme egy kéz érintett meg engem s megrázott, térdeimre s kezeim tenyerére állitva engem.
11 Ó sọ pé, “Daniẹli ẹni tí a yàn fẹ́ gidigidi gba ọ̀rọ̀ tí mo fẹ́ bá ọ sọ yìí yẹ̀ wò dáradára, kí o sì dìde, nítorí tí a rán mi sí ọ.” Bí ó ṣe sọ èyí fún mi, mo dìde ní ìwárìrì.
És szólt hozzám: Dániél, kedvelt férfiú, értsd meg a szavakat, a melyeket én hozzád szólok a állj fel, a hogy álltá1, mert most kiküldettem hozzád. S midőn beszéltem vele e szóval, fölálltam remegve.
12 Nígbà náà ni ó tẹ̀síwájú, pé, “Má ṣe bẹ̀rù Daniẹli. Láti ọjọ́ àkọ́kọ́ tí ìwọ ti fi ọkàn rẹ sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run rẹ, a gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ, mo sì wá nítorí ọ̀rọ̀ náà.
Ne félj, Dániél, mert az első naptól kezdve, hogy értésre adtad szivedet és arra, hogy bőjtölj Istened előtt, meghallgattattak szavaid s én eljöttem szavaidra.
13 Ṣùgbọ́n ọmọ-aládé ìjọba Persia dá mi dúró fún ọjọ́ mọ́kànlélógún. Nígbà náà ni Mikaeli, ọ̀kan lára ìjòyè àwọn ọmọ-aládé, wá láti ràn mi lọ́wọ́, nítorí a dá mi dúró níbẹ̀ pẹ̀lú ọba Persia.
És Perzsia királyságának vezére velem szemben állott huszonegy napig s íme Mikháél, a legelső vezérek egyike, jött segítésemre, és én ottmaradtam Perzsia királyai mellett.
14 Ní ìsinsin yìí mo wá láti ṣàlàyé ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú, nítorí ìran náà ń sọ nípa ọjọ́ iwájú.”
És jöttem, hogy megértessem veled azt, a mi érni fogja népedet az idők végén, mert még időkre szól a látomás.
15 Bí ó sì ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí fún mi, mo sì dorí kodò mo sì dákẹ́.
És midőn beszélt velem e szavak szerint, földre fordítottam arczomat s elnémultam.
16 Nígbà náà, ni ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kan ètè mi, mo la ẹnu mi, mo sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ ọ̀rọ̀, mo sọ fún ẹni tí ó dúró níwájú mi, “Ìrònú sì mú mi, nítorí ìran náà, olúwa mi, n kò sì ní okun.
S íme valaki, a ki ember fiához hasonlít, megérinti ajkaimat; s megnyitottam számat s beszéltem és szóltam ahhoz, a ki velem szemben állt: Uram, a látomás által fordulnak bennem fájdalmaim és nem tartottam meg erőt;
17 Ǹjẹ́ báwo ni èmi ìránṣẹ́ ẹ̀ rẹ ṣe lè bá ọ sọ̀rọ̀, olúwa mi? Agbára mi ti lọ, agbára káká ni mo fi ń mí.”
s hogyan lenne képes ez uramnak szolgája beszélni ez urammal? Hisz én – mostantól kezdve nem áll meg bennem erő, lélekzet sem maradt bennem.
18 Ẹ̀wẹ̀, ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kàn mí, ó sì fún mi ní agbára.
S újból megérintett engem valaki, a ki embernek látszott s erősitett engem,
19 Ó sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ ọkùnrin olùfẹ́ gidigidi. Àlàáfíà ni fún ọ, mú ara le, àní mú ara le.” Nígbà tí ohun bá mi sọ̀rọ̀, a sì mú mi lára le. “Mo sì wí pé, kí olúwa mi kí ó máa sọ̀rọ̀, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ ti mú mi ní ara le.”
s mondta: Ne félj, kedvelt férfiu, béke veled, erős meg erős légy. S midőn velem beszélt, megerősődtem és mondtam: Beszéljen uram, mert megerősitettél engem.
20 Nígbà náà, ni ó wí pé, “Ṣé o mọ ìdí tí mo fi tọ̀ ọ́ wá? Láìpẹ́ èmi yóò yípadà lọ bá àwọn ọmọ-aládé Persia jà, nígbà tí mo bá lọ àwọn ọmọ-aládé Giriki yóò wá;
Mondta: Tudod-e, miért jöttem te hozzád? Most pedig visszatérek, hogy harczoljak Perzaia vezérével; s a mint azzal végzek, íme Jáván vezére jön.
21 ṣùgbọ́n ní àkọ́kọ́, èmi yóò sọ ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé òtítọ́ fún ọ. (Kò sí ẹni tí ó kún mi lọ́wọ́ fún nǹkan wọ̀nyí bí kò ṣe Mikaeli, ọmọ-aládé e yín.
Azonban megjelentem neked, a mi föl van jegyezve az igazság irásában, és nincs egy sem, ki erősködik mellettem ezek ellenében, csak Mikháél, a ti vezértek.

< Daniel 10 >