< Daniel 10 >

1 Ní ọdún kẹta Kirusi ọba Persia, a fi ìran kan hàn Daniẹli (ẹni tí à ń pè ní Belteṣassari). Òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ ìran náà, ó sì ní í ṣe pẹ̀lú àsìkò ìpọ́njú ńlá, òye ọ̀rọ̀ náà wá bá a nínú ìran.
La troisième année de Cyrus, roi de Perse, un message fut révélé à Daniel, dont le nom était Beltschatsar, et le message était vrai, même une grande guerre. Il comprit le message, et il eut l'intelligence de la vision.
2 Ní àsìkò náà, èmi Daniẹli ṣọ̀fọ̀ fún ọ̀sẹ̀ mẹ́ta.
En ces jours-là, moi, Daniel, je fus en deuil pendant trois semaines entières.
3 Èmi kì í jẹ oúnjẹ tí ó dára, èmi kò fi ẹran tàbí wáìnì kan ẹnu mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi òróró para títí ọ̀sẹ̀ mẹ́ta fi kọjá.
Je ne mangeais aucun mets agréable. Il n'est entré dans ma bouche ni viande ni vin. Je ne me suis pas oint du tout, jusqu'à ce que trois semaines entières soient accomplies.
4 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù àkọ́kọ́, bí mo ti dúró sí etí i bèbè odò ńlá Tigirisi,
Le vingt-quatrième jour du premier mois, comme j'étais au bord du grand fleuve, qui est Hiddékel,
5 mo wo òkè, mo rí ọkùnrin kan tí ó wọ aṣọ àlà, ẹ̀gbẹ́ ẹni tí a fi wúrà Upasi dáradára dì ní àmùrè.
je levai les yeux et je regardai. Et voici, c'était un homme vêtu de lin, et dont la taille était ornée d'or pur d'Uphaz.
6 Ara rẹ̀ dàbí berili, ojú u rẹ̀ dàbí mọ̀nàmọ́ná, ẹyin ojú u rẹ̀ dàbí iná àtẹ̀tàn, apá àti ẹsẹ̀ rẹ̀ dàbí ìtànná ìmọ́lẹ̀ tí o kún fún idẹ, àti ohùn rẹ̀ dàbí i ti ìjọ ènìyàn púpọ̀.
Son corps était semblable à du béryl, son visage avait l'aspect de l'éclair, et ses yeux étaient comme des torches enflammées. Ses bras et ses pieds étaient comme de l'airain poli. La voix de ses paroles était comme la voix d'une multitude.
7 Èmi Daniẹli, ni ẹnìkan tí ó rí ìran náà, àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú u mi, wọn kò rí i, ṣùgbọ́n ìpayà ńlá dà bò wọ́n, wọ́n sálọ wọ́n sì fi ara pamọ́.
Moi, Daniel, j'ai vu seul la vision, car les hommes qui étaient avec moi n'ont pas vu la vision, mais un grand tremblement est tombé sur eux, et ils ont fui pour se cacher.
8 Ó sì ku èmi nìkan, tí mo rí ìran ńlá yìí, kò sì ku okun kankan fún mi, ojú u mi sì rẹ̀wẹ̀sì gidigidi, n kò sì ní agbára mọ́.
Je restai donc seul et je vis cette grande vision. Je n'avais plus de force, car mon visage était d'une pâleur mortelle, et je n'avais plus de force.
9 Nígbà náà, ni mo gbọ́ tí ó ń sọ̀rọ̀, bí mo ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí i, mo sùn lọ fọnfọn, ní ìdojúbolẹ̀.
Mais j'ai entendu la voix de ses paroles. Quand j'entendis la voix de ses paroles, je tombai dans un profond sommeil, sur ma face, le visage tourné vers le sol.
10 Ọwọ́ kan kàn mí, ó gbé mi dìde ní ìwárìrì lórí ọwọ́ àti eékún mi.
Voici, une main me toucha, qui me mit à genoux et sur les paumes des mains.
11 Ó sọ pé, “Daniẹli ẹni tí a yàn fẹ́ gidigidi gba ọ̀rọ̀ tí mo fẹ́ bá ọ sọ yìí yẹ̀ wò dáradára, kí o sì dìde, nítorí tí a rán mi sí ọ.” Bí ó ṣe sọ èyí fún mi, mo dìde ní ìwárìrì.
Il me dit: « Daniel, homme bien-aimé, comprends les paroles que je te dis, et tiens-toi droit, car c'est maintenant que je suis envoyé vers toi. » Quand il m'eut dit cette parole, je me tins debout en tremblant.
12 Nígbà náà ni ó tẹ̀síwájú, pé, “Má ṣe bẹ̀rù Daniẹli. Láti ọjọ́ àkọ́kọ́ tí ìwọ ti fi ọkàn rẹ sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run rẹ, a gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ, mo sì wá nítorí ọ̀rọ̀ náà.
Alors il me dit: « Ne crains pas, Daniel, car dès le premier jour où tu as mis ton cœur à comprendre et à t'humilier devant ton Dieu, tes paroles ont été entendues. Je suis venu à cause de tes paroles.
13 Ṣùgbọ́n ọmọ-aládé ìjọba Persia dá mi dúró fún ọjọ́ mọ́kànlélógún. Nígbà náà ni Mikaeli, ọ̀kan lára ìjòyè àwọn ọmọ-aládé, wá láti ràn mi lọ́wọ́, nítorí a dá mi dúró níbẹ̀ pẹ̀lú ọba Persia.
Mais le prince du royaume de Perse m'a résisté vingt et un jours; et voici que Michel, l'un des principaux princes, est venu me secourir, parce que je suis resté là avec les rois de Perse.
14 Ní ìsinsin yìí mo wá láti ṣàlàyé ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú, nítorí ìran náà ń sọ nípa ọjọ́ iwájú.”
Maintenant, je suis venu pour vous faire comprendre ce qui arrivera à votre peuple dans la suite des temps, car la vision est encore pour de nombreux jours. »
15 Bí ó sì ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí fún mi, mo sì dorí kodò mo sì dákẹ́.
Lorsqu'il m'eut dit ces paroles, je fixai mon visage à terre et je restai muet.
16 Nígbà náà, ni ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kan ètè mi, mo la ẹnu mi, mo sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ ọ̀rọ̀, mo sọ fún ẹni tí ó dúró níwájú mi, “Ìrònú sì mú mi, nítorí ìran náà, olúwa mi, n kò sì ní okun.
Et voici que quelqu'un de semblable aux fils des hommes toucha mes lèvres. J'ouvris alors la bouche, je parlai et je dis à celui qui se tenait devant moi: « Mon seigneur, à cause de la vision, mes douleurs m'ont envahi, et je n'ai plus de force.
17 Ǹjẹ́ báwo ni èmi ìránṣẹ́ ẹ̀ rẹ ṣe lè bá ọ sọ̀rọ̀, olúwa mi? Agbára mi ti lọ, agbára káká ni mo fi ń mí.”
Car comment le serviteur de ce monseigneur pourrait-il parler avec ce monseigneur? Quant à moi, à l'instant même, je n'avais plus de force. Il n'y avait plus de souffle en moi. »
18 Ẹ̀wẹ̀, ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kàn mí, ó sì fún mi ní agbára.
Alors quelqu'un ayant l'apparence d'un homme me toucha de nouveau, et il me fortifia.
19 Ó sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ ọkùnrin olùfẹ́ gidigidi. Àlàáfíà ni fún ọ, mú ara le, àní mú ara le.” Nígbà tí ohun bá mi sọ̀rọ̀, a sì mú mi lára le. “Mo sì wí pé, kí olúwa mi kí ó máa sọ̀rọ̀, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ ti mú mi ní ara le.”
Il dit: « Homme bien-aimé, n'aie pas peur. Que la paix soit avec toi. Sois fort. Oui, sois fort. » Quand il m'a parlé, j'ai été fortifié, et j'ai dit: « Laisse parler mon seigneur, car tu m'as fortifié. »
20 Nígbà náà, ni ó wí pé, “Ṣé o mọ ìdí tí mo fi tọ̀ ọ́ wá? Láìpẹ́ èmi yóò yípadà lọ bá àwọn ọmọ-aládé Persia jà, nígbà tí mo bá lọ àwọn ọmọ-aládé Giriki yóò wá;
Puis il dit: « Savez-vous pourquoi je suis venu chez vous? Je vais maintenant retourner pour combattre le prince de Perse. Quand je sortirai, voici que viendra le prince de la Grèce.
21 ṣùgbọ́n ní àkọ́kọ́, èmi yóò sọ ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé òtítọ́ fún ọ. (Kò sí ẹni tí ó kún mi lọ́wọ́ fún nǹkan wọ̀nyí bí kò ṣe Mikaeli, ọmọ-aládé e yín.
Mais je vais te dire ce qui est inscrit dans l'écriture de la vérité. Il n'y a personne qui tienne avec moi contre ceux-ci, sinon Michel, ton prince.

< Daniel 10 >