< Daniel 10 >

1 Ní ọdún kẹta Kirusi ọba Persia, a fi ìran kan hàn Daniẹli (ẹni tí à ń pè ní Belteṣassari). Òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ ìran náà, ó sì ní í ṣe pẹ̀lú àsìkò ìpọ́njú ńlá, òye ọ̀rọ̀ náà wá bá a nínú ìran.
Léta třetího Cýra krále Perského, zjeveno bylo slovo Danielovi, kterýž sloul jménem Baltazar, a pravé bylo slovo to, i uložený čas dlouhý, a rozum toho slova i smysl zjeven jemu u vidění.
2 Ní àsìkò náà, èmi Daniẹli ṣọ̀fọ̀ fún ọ̀sẹ̀ mẹ́ta.
V těch dnech já Daniel kvílil jsem za tři téhodny dnů.
3 Èmi kì í jẹ oúnjẹ tí ó dára, èmi kò fi ẹran tàbí wáìnì kan ẹnu mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi òróró para títí ọ̀sẹ̀ mẹ́ta fi kọjá.
Pokrmu pochotného jsem nejedl, ani maso ani víno nevešlo do úst mých, aniž jsem se mastí mazal, až se vyplnili dnové tří téhodnů.
4 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù àkọ́kọ́, bí mo ti dúró sí etí i bèbè odò ńlá Tigirisi,
Dne pak dvadcátého čtvrtého měsíce prvního, když jsem byl na břehu řeky veliké, to jest Hiddekel.
5 mo wo òkè, mo rí ọkùnrin kan tí ó wọ aṣọ àlà, ẹ̀gbẹ́ ẹni tí a fi wúrà Upasi dáradára dì ní àmùrè.
Pozdvih očí svých, viděl jsem, a aj, muž jeden oděný v roucho lněné, a bedra jeho přepásaná byla zlatem ryzím z Ufaz.
6 Ara rẹ̀ dàbí berili, ojú u rẹ̀ dàbí mọ̀nàmọ́ná, ẹyin ojú u rẹ̀ dàbí iná àtẹ̀tàn, apá àti ẹsẹ̀ rẹ̀ dàbí ìtànná ìmọ́lẹ̀ tí o kún fún idẹ, àti ohùn rẹ̀ dàbí i ti ìjọ ènìyàn púpọ̀.
Tělo pak jeho jako tarsis, a oblíčej jeho na pohledění jako blesk, a oči jeho podobné pochodním hořícím, a ramena jeho i nohy jeho na pohledění jako měď vypulerovaná, a zvuk slov jeho podobný zvuku množství.
7 Èmi Daniẹli, ni ẹnìkan tí ó rí ìran náà, àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú u mi, wọn kò rí i, ṣùgbọ́n ìpayà ńlá dà bò wọ́n, wọ́n sálọ wọ́n sì fi ara pamọ́.
Viděl jsem pak já Daniel sám vidění to, ale muži ti, kteříž se mnou byli, neviděli toho vidění, než hrůza veliká připadla na ně, až i utekli, aby se skryli.
8 Ó sì ku èmi nìkan, tí mo rí ìran ńlá yìí, kò sì ku okun kankan fún mi, ojú u mi sì rẹ̀wẹ̀sì gidigidi, n kò sì ní agbára mọ́.
Pročež já zůstal jsem sám, a viděl jsem vidění to veliké, ale nezůstalo i ve mně síly, a krása má změnila se, a porušila na mně, aniž jsem mohl zadržeti síly.
9 Nígbà náà, ni mo gbọ́ tí ó ń sọ̀rọ̀, bí mo ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí i, mo sùn lọ fọnfọn, ní ìdojúbolẹ̀.
Tedy slyšel jsem zvuk slov jeho, a uslyšav zvuk slov jeho, usnul jsem tvrdě na tváři své, na tváři své na zemi.
10 Ọwọ́ kan kàn mí, ó gbé mi dìde ní ìwárìrì lórí ọwọ́ àti eékún mi.
V tom aj, ruka dotkla se mne, a pozdvihla mne na kolena má a na dlaně rukou mých.
11 Ó sọ pé, “Daniẹli ẹni tí a yàn fẹ́ gidigidi gba ọ̀rọ̀ tí mo fẹ́ bá ọ sọ yìí yẹ̀ wò dáradára, kí o sì dìde, nítorí tí a rán mi sí ọ.” Bí ó ṣe sọ èyí fún mi, mo dìde ní ìwárìrì.
I řekl mi: Danieli, muži velmi milý, pozoruj slov, kteráž já mluviti budu tobě, a stůj na místě svém, nebo nyní poslán jsem k tobě. A když promluvil ke mně slovo to, stál jsem, třesa se.
12 Nígbà náà ni ó tẹ̀síwájú, pé, “Má ṣe bẹ̀rù Daniẹli. Láti ọjọ́ àkọ́kọ́ tí ìwọ ti fi ọkàn rẹ sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run rẹ, a gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ, mo sì wá nítorí ọ̀rọ̀ náà.
Pročež řekl mi: Nebojž se, Danieli; nebo od prvního dne, jakž jsi přiložil srdce své, abys rozuměl, a trápil se před Bohem svým, vyslyšána jsou slova tvá, a já přišel jsem příčinou slov tvých.
13 Ṣùgbọ́n ọmọ-aládé ìjọba Persia dá mi dúró fún ọjọ́ mọ́kànlélógún. Nígbà náà ni Mikaeli, ọ̀kan lára ìjòyè àwọn ọmọ-aládé, wá láti ràn mi lọ́wọ́, nítorí a dá mi dúró níbẹ̀ pẹ̀lú ọba Persia.
Ale kníže království Perského postavovalo se proti mně za jedenmecítma dnů, až aj, Michal, jeden přední z knížat, přišel mi na pomoc; protož jsem já zůstával tam při králích Perských.
14 Ní ìsinsin yìí mo wá láti ṣàlàyé ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú, nítorí ìran náà ń sọ nípa ọjọ́ iwájú.”
Již pak přišel jsem, aťbych oznámil, co potkati má lid tvůj v potomních dnech; nebo ještě vidění bude o těch dnech.
15 Bí ó sì ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí fún mi, mo sì dorí kodò mo sì dákẹ́.
A když mluvil ke mně ta slova, sklopiv tvář svou k zemi, oněměl jsem.
16 Nígbà náà, ni ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kan ètè mi, mo la ẹnu mi, mo sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ ọ̀rọ̀, mo sọ fún ẹni tí ó dúró níwájú mi, “Ìrònú sì mú mi, nítorí ìran náà, olúwa mi, n kò sì ní okun.
A aj, jako podobnost člověka dotkla se rtů mých, a otevřev ústa svá, mluvil jsem a řekl tomu, kterýž stál naproti mně: Pane můj, příčinou toho vidění obrátili se bolesti mé na mne, a aniž jsem síly zadržeti mohl.
17 Ǹjẹ́ báwo ni èmi ìránṣẹ́ ẹ̀ rẹ ṣe lè bá ọ sọ̀rọ̀, olúwa mi? Agbára mi ti lọ, agbára káká ni mo fi ń mí.”
Jakž tedy bude moci služebník Pána mého takový mluviti se Pánem mým takovým, poněvadž ve mně od toho času, ve mně, pravím, nezůstalo síly, ani dchnutí nepozůstalo ve mně?
18 Ẹ̀wẹ̀, ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kàn mí, ó sì fún mi ní agbára.
Pročež opět dotkl se mne na pohledění jako člověk, a posilnil mne.
19 Ó sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ ọkùnrin olùfẹ́ gidigidi. Àlàáfíà ni fún ọ, mú ara le, àní mú ara le.” Nígbà tí ohun bá mi sọ̀rọ̀, a sì mú mi lára le. “Mo sì wí pé, kí olúwa mi kí ó máa sọ̀rọ̀, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ ti mú mi ní ara le.”
A řekl: Neboj se, muži velmi milý, pokoj tobě, posilň se, posilň se, pravím. Když pak on mluvil se mnou, posilněn jsa, řekl jsem: Nechť mluví Pán můj, nebo jsi mne posilnil.
20 Nígbà náà, ni ó wí pé, “Ṣé o mọ ìdí tí mo fi tọ̀ ọ́ wá? Láìpẹ́ èmi yóò yípadà lọ bá àwọn ọmọ-aládé Persia jà, nígbà tí mo bá lọ àwọn ọmọ-aládé Giriki yóò wá;
I řekl: Víš-liž, proč jsem přišel k tobě? Nebo již navrátím se, abych bojoval s knížetem Perským. A já odcházím, a aj, kníže Řecké přitáhne.
21 ṣùgbọ́n ní àkọ́kọ́, èmi yóò sọ ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé òtítọ́ fún ọ. (Kò sí ẹni tí ó kún mi lọ́wọ́ fún nǹkan wọ̀nyí bí kò ṣe Mikaeli, ọmọ-aládé e yín.
Ale oznámímť to, což jest zapsáno v psání pravdomluvném; nebo ani jednoho není, ješto by sobě zmužile počínal se mnou v těch věcech, kromě Michala knížete vašeho.

< Daniel 10 >