< Colossians 1 >
1 Paulu, aposteli Jesu Kristi nípa ìfẹ́ Ọlọ́run àti Timotiu arákùnrin wa,
ⲁ̅ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⳿ⲡⲁⲡⲟⲥⲧⲟⲗⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲡⲉⲧⲉϩⲛⲁϥ ⳿ⲙⲫϯ ⲛⲉⲙ ⲧⲓⲙⲟⲑⲉⲟⲥ ⲡⲓⲥⲟⲛ.
2 Sí àwọn ẹni mímọ́ àti àwọn arákùnrin àti arábìnrin nínú Kristi tí wọ́n ń gbé ní ìlú Kolose: Oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà fún un yín láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa.
ⲃ̅⳿ⲛⲛⲓⲁⲅⲓⲟⲥ ⲉⲧϧⲉⲛ ⲕⲟⲗⲁⲥⲥⲁⲓⲥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲧⲟⲥ ⳿ⲛ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ⲉⲧϧⲉⲛ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⳿ⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲛⲉⲙ ⳿ⲧϩⲓⲣⲏⲛⲏ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲫϯ ⲡⲉⲛⲓⲱⲧ ⲛⲉⲙ ⲡⲉⲛ⳪ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ Ⲡⲭ̅ⲥ̅.
3 Nígbàkígbà tí a bá ń gbàdúrà fún un yín ni a máa ń dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run Baba Olúwa wa Jesu Kristi.
ⲅ̅ⲧⲉⲛϣⲉⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉⲛ ⲫϯ ⳿ⲫⲓⲱⲧ ⳿ⲙⲡⲉⲛϭ̅ ⲥ̅ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⳿ⲛⲥⲏⲟⲩ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲉⲛⲧⲱⲃϩ.
4 Nítorí a ti gbúròó ìgbàgbọ́ yín nínú Jesu Kristi, àti bí ẹ ti ṣe fẹ́ràn gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́.
ⲇ̅⳿ⲉⲁⲛⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲉⲡⲉⲧⲉⲛⲛⲁϩϯ ⲉⲧϧⲉⲛ Ⲡ⳪ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲉⲙ ϯⲁⲅⲁⲡⲏ ⲉⲧϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲛⲓⲁⲅⲓⲟⲥ ⲧⲏⲣⲟⲩ.
5 Ìgbàgbọ́ àti ìfẹ́ tí ń sàn nínú ìrètí tí a gbé pamọ́ fún un yín ní ọ̀run èyí tí ẹ̀yin sì ti gbọ́ tẹ́lẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ òtítọ́ ìyìnrere náà,
ⲉ̅ⲉⲑⲃⲉ ϯϩⲉⲗⲡⲓⲥ ⲉⲧⲭⲏ ϧⲁϫⲱⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲫⲏⲟⲩ⳿ⲓ ⲑⲏ ⲉⲧⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲉⲣϣⲟⲣⲡ ⳿ⲛⲥⲟⲑⲙⲉⲥ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲙⲉⲑⲙⲏⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ.
6 èyí tí ó ti dé ọ̀dọ̀ yín. Káàkiri àgbáyé ni ìyìnrere yìí ń so èso tí ó sì ń dàgbà, gẹ́gẹ́ bí ó ti ń ṣe láàrín yín láti ọjọ́ náà tí ẹ ti gbọ́ ọ, tí ẹ sì ní ìmọ̀ oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run nínú gbogbo òtítọ́ rẹ̀.
ⲋ̅ⲫⲁⲓ ⲉⲧϣⲟⲡ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲟⲛ ⲉⲧⲉϥϣⲟⲡ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲧⲏⲣϥ ⲉϥϯⲟⲩⲧⲁϩ ⲟⲩⲟϩ ⲉϥⲁⲓⲁⲓ ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲟⲛ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲓⲥϫⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲉⲧⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲥⲱⲧⲉⲙ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲥⲟⲩⲉⲛ ⲡⲓ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲑⲙⲏⲓ.
7 Ẹ̀yin ti kọ́ ọ lọ́dọ̀ Epafira, ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ wa olùfẹ́, ẹni tí ó jẹ́ olóòtítọ́ ìránṣẹ́ Kristi ní ipò wa.
ⲍ̅ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧⲁⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲉⲡⲁⲫⲣⲁ ⲡⲓⲙⲉⲛⲣⲓⲧ ⳿ⲛ⳿ϣⲫⲏⲣ ⳿ⲙⲃⲱⲕ ⳿ⲛⲧⲁⲛ ⲉⲧⲉ ⲟⲩⲡⲓⲥⲧⲟⲥ ⲡⲉ ⳿ⲛⲇⲓ⳿ⲁⲕⲱⲛ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ.
8 Ẹni ti ó sọ fún wa nípa ìfẹ́ yín nínú ẹ̀mí.
ⲏ̅ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲁϥⲧⲁⲙⲟⲛ ⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲁⲅⲁⲡⲏ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅.
9 Nítorí ìdí èyí, láti ọjọ́ tí a ti gbọ́ nípa yín, a kò sinmi láti máa gbàdúrà fún yin, tí a sì ń gbàdúrà pé kí Ọlọ́run fi ìmọ̀ ìfẹ́ rẹ̀ kún yín nípasẹ̀ ọgbọ́n àti òye gbogbo tí ń ṣe ti Ẹ̀mí.
ⲑ̅ⲉⲑⲃⲉⲫⲁⲓ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ϩⲱⲛ ⲓⲥϫⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲉⲧⲁⲛⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲛⲧⲉⲛⲭⲱ ⳿ⲛⲧⲟⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲁⲛ ⲉⲛⲧⲱⲃϩ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲉⲛⲉⲣⲉⲧⲓⲛ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛⲙⲟϩ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲥⲟⲩⲉⲛ ⲡⲉⲧⲉϩⲛⲁϥ ϧⲉⲛ ⲥⲟⲫⲓⲁ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲛⲉⲙ ⲕⲁϯ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲙⲡ͞ⲛⲁ̅ⲧⲓⲕⲟⲛ.
10 Àwa sì ń gbàdúrà yìí kí ẹ lè gbé irú ìgbé ayé tó yẹ fún Olúwa kí ẹ sì máa wu ú ní gbogbo ọ̀nà, kí ẹ sì máa so èso rere gbogbo, kí ẹ sì máa dàgbà nínú ìmọ̀ Ọlọ́run,
ⲓ̅ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲙⲟϣⲓ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲙ⳿ⲡϣⲁ ⳿ⲙⲠ⳪ ϧⲉⲛ ⲣⲁⲛⲁϥ ⲛⲓⲃⲉⲛ ϧⲉⲛ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲑⲛⲁⲛⲉⲩ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲧⲁⲟⲩ⳿ⲟ ⲟⲩⲧⲁϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲁⲓⲁⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
11 pé kí a lè fi ipa gbogbo sọ yín di alágbára gẹ́gẹ́ bí agbára rẹ̀ àti ògo rẹ̀, kí ó lè ṣe é ṣe fún un yín láti máa tẹ̀síwájú nínú sùúrù àti ìpamọ́ra pẹ̀lú ayọ̀.
ⲓ̅ⲁ̅ⲉⲣⲉⲧⲉⲛϫⲉⲙϫⲟⲙ ϧⲉⲛ ϫⲟⲙ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲕⲁⲧⲁ ⳿ⲡⲁⲙⲁϩⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉϥⲱⲟⲩ ϧⲉⲛ ϩⲩⲡⲟⲙⲟⲛⲏ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲙⲉⲧⲣⲉϥⲱⲟⲩ ⳿ⲛϩⲏⲧ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲣⲁϣⲓ.
12 Kí a máa dúpẹ́ nígbà gbogbo lọ́wọ́ Baba, ẹni tí ó kà yín láti jẹ́ alábápín nínú ogún àwọn ẹni mímọ́ nínú ìjọba ìmọ́lẹ̀.
ⲓ̅ⲃ̅ⲉⲣⲉⲧⲉⲛϣⲉⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉⲛ ⳿ⲫⲓⲱⲧ ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲁϥ⳿ⲑⲣⲉⲛⲉⲣ⳿ⲡⲉⲙ⳿ⲡϣⲁ ⳿ⲛ⳿ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉϯⲧⲟⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓ⳿ⲕⲗⲏⲣⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲁⲅⲓⲟⲥ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲟⲩⲱⲓⲛⲓ.
13 Nítorí tí ó ti já wa gbà kúrò nínú agbára òkùnkùn ó sì mú wa wá sí ìjọba Ọmọ tí ó fẹ́ràn.
ⲓ̅ⲅ̅ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲁϥⲛⲁϩⲙⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁ ⳿ⲡⲉⲣϣⲓϣⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡⲕⲁⲕⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲟⲩⲟⲑⲃⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉϯⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡϣⲏⲣⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲧⲉϥⲁⲅⲁⲡⲏ.
14 Nínú ẹni tí a ní ìràpadà, àti ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀.
ⲓ̅ⲇ̅ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲁⲛϭⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲱϯ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲟⲧϥ ⲡⲓⲭⲱ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲉⲛⲛⲟⲃⲓ.
15 Kristi ni àwòrán Ọlọ́run tí a kò le rí, àkọ́bí gbogbo ẹ̀dá.
ⲓ̅ⲉ̅ⲉⲧⲉ ⳿ⲧϩⲓⲕⲱⲛ ⳿ⲙⲫϯ ⲡⲉ ⲡⲓⲁⲑⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲡⲓϣⲟⲣⲡ ⳿ⲙⲙⲓⲥⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲥⲱⲛⲧ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
16 Nítorí nípa rẹ̀ ní a dá ohun gbogbo: àwọn ohun tí ń bẹ ní ọ̀run àti ní ayé, ohun tí a rí àti èyí tí a kò rí, wọn ìbá ṣe ìtẹ́, tàbí agbára, tàbí àṣẹ, nípasẹ̀ rẹ̀ ni a dá ohun gbogbo àti fún un.
ⲓ̅ⲋ̅ϫⲉ ⳿ⲛ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⲁⲩⲥⲱⲛⲧ ⳿ⲛϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲛⲏⲉⲧϧⲉⲛ ⲛⲓⲫⲏⲟⲩ⳿ⲓ ⲛⲉⲙ ⲛⲏⲉⲧϩⲓϫⲉⲛ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ ⲛⲏⲉⲧⲟⲩⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲛⲏⲉⲧⲉ⳿ⲛⲥⲉⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲁⲛ ⳿ⲓⲧⲉ ⲛⲓ⳿ⲑⲣⲟⲛⲟⲥ ⳿ⲓⲧⲉ ⲛⲓⲙⲉⲧϭ̅ ⲥ̅ ⳿ⲓⲧⲉ ⲛⲓⲁⲣⲭⲏ ⳿ⲓⲧⲉ ⲛⲓⲉⲝⲟⲩⲥⲓⲁ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲁⲩϣⲱⲡⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲟⲧϥ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲥⲟⲛⲧⲟⲩ ⳿ⲉⲣⲟϥ.
17 Ó ti wà ṣáájú kí ohunkóhun tó wà, nínú rẹ̀ ni a sì so ohun gbogbo papọ̀ ṣọ̀kan.
ⲓ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲉⲧϣⲟⲡ ϧⲁϫⲱϥ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲟⲩⲟϩ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲁⲩⲟϩⲓ ⳿ⲉⲣⲁⲧⲟⲩ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ.
18 Òun ni orí fún ara, èyí tí í ṣe ìjọ; òun ni ìbẹ̀rẹ̀ àti àkọ́bí nínú àwọn òkú, pé nínú ohun gbogbo kí òun lè ní ipò tí ó ga jùlọ nínú ohunkóhun.
ⲓ̅ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲡⲉ ⳿ⲧⲁⲫⲉ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲱⲙⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏⲥⲓⲁ ⲉⲧⲉ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲡⲉ ϯⲁⲣⲭⲏ ⳿ⲛϣⲟⲣⲡ ⳿ⲙⲙⲓⲥⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲏⲉⲑⲙⲱⲟⲩⲧ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥϣⲱⲡⲓ ⲉϥⲟⲓ ⳿ⲛϣⲟⲣⲡ ϧⲉⲛ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
19 Nítorí ìfẹ́ Ọlọ́run ni pé kí gbogbo ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ òun tìkára rẹ̀ lè máa gbé nínú rẹ̀.
ⲓ̅ⲑ̅ϫⲉ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⲁϥϯⲙⲁϯ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲙⲟϩ ⲧⲏⲣϥ ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ.
20 Àti nípasẹ̀ rẹ̀ láti bá ohun gbogbo làjà àwọn nǹkan tí ń bẹ láyé àti èyí tí ń bẹ ní ọ̀run, nípa mímú àlàáfíà wá nípasẹ̀ ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, tí a ta sílẹ̀ lórí igi àgbélébùú.
ⲕ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲟⲧϥ ⳿ⲉϩⲱⲧⲡ ⳿ⲛϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲉⲁϥⲁⲓⲧⲟⲩ ⳿ⲛϩⲓⲣⲏⲛⲏ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲥⲛⲟϥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉϥ ̇⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲟⲧϥ ⳿ⲓⲧⲉ ⲛⲏⲉⲧϩⲓϫⲉⲛ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ ⳿ⲓⲧⲉ ⲛⲏⲉⲧⲉ ⳿ⲛ⳿ϩⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲫⲏⲟⲩ⳿ⲓ.
21 Ẹ̀yin ya ara yín nípá kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run nígbà kan rí, ẹ jẹ́ ọ̀tá nínú ọkàn yín nítorí ìwà búburú yín.
ⲕ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ϩⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛⲟⲩⲥⲏⲟⲩ ⲛⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲟⲓ ⳿ⲛϣⲉⲙⲙⲟ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛϫⲁϫⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲉⲧⲉⲛⲙⲉⲩⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲓ⳿ϩⲃⲏⲟⲩⲓ ⲉⲧϩⲱⲟⲩ.
22 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó ti bá yín làjà nípa ara Kristi nípa ikú láti mú un yín lọ sí iwájú rẹ̀ ní mímọ́, aláìlábàwọ́n àti kúrò nínú ìdálẹ́bi,
ⲕ̅ⲃ̅ϯⲛⲟⲩ ⲇⲉ ⲁϥϩⲉⲧⲡ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲥⲱⲙⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲧⲉϥⲥⲁⲣⲝ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲡⲉϥⲙⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲁϩⲉ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲣⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲟⲩⲁⲃ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲟⲓ ⳿ⲛⲁⲧⲁϭⲛⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲁⲧⲁⲣⲓⲕⲓ ⳿ⲙⲡⲉϥ⳿ⲙⲑⲟ.
23 bí ẹ̀yin bá dúró nínú ìgbàgbọ́ yín, tí ẹ fi ẹsẹ̀ múlẹ̀, tí ẹ sì dúró ṣinṣin, láláìyẹsẹ̀ kúrò nínú ìrètí ti ìyìnrere ti ẹ̀yin ti gbọ́, èyí tí a ti wàásù rẹ̀ fún gbogbo ẹ̀dá lábẹ́ ọ̀run, àti èyí ti èmi Paulu ṣe ìránṣẹ́ fún.
ⲕ̅ⲅ̅ⲓⲥϫⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛϣⲟⲡ ⳿ⲙⲡⲓⲛⲁϩϯ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲧⲁϫⲣⲏ ⲟⲩⲧ ⳿ⲛⲥⲉⲛϯ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛϫⲟⲣ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲟⲓ ⳿ⲛⲁⲧⲕⲓⲙ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁ ϯ ϩⲉⲗⲡⲓⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲥⲟⲑⲙⲉϥ ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲁⲩϩⲓⲱⲓϣ ⳿ⲙⲙⲟϥ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲥⲱⲛⲧ ⲧⲏⲣϥ ⲉⲧⲥⲁⲡⲉⲥⲏⲧ ⳿ⲛ⳿ⲧⲫⲉ ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲁⲓϣⲱⲡⲓ ⲛⲁϥ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⳿ⲛⲇⲓ⳿ⲁⲕⲱⲛ.
24 Nísinsin yìí èmi ń yọ̀ nínú ìjìyà fún un yín. Inú mi sì dùn, nítorí mo ń ṣe ìrànlọ́wọ́ láti jẹ ìyà tó ṣẹ́kù nínú ìyà Kristi fún ara rẹ̀, èyí tí ì ṣe ìjọ.
ⲕ̅ⲇ̅ϯⲛⲟⲩ ⲇⲉ ϯⲣⲁϣⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲓ⳿ⲙⲕⲁⲩϩ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ϯϫⲱⲕ ⳿ⲛⲛⲓϭⲣⲟϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲛⲓϩⲟϫϩⲉϫ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ϧⲉⲛ ⲧⲁⲥⲁⲣⲝ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲉϥⲥⲱⲙⲁ ⲉⲧⲉ ϯⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏ ⲥⲓⲁ ⲧⲉ.
25 Nínú èyí tí a fi ṣe ìránṣẹ́ fún gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ìríjú Ọlọ́run tí a fi fún mi fún yín láti mú ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ṣẹ.
ⲕ̅ⲉ̅ⲑⲁⲓ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲉⲧⲁⲓϣⲱⲡⲓ ⲛⲁⲥ ⳿ⲛⲇⲓ⳿ⲁⲕⲱⲛ ⲕⲁⲧⲁ ϯⲟⲓⲕⲟⲛⲟⲙⲓⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲉⲧⲧⲟⲓ ⲛⲏⲓ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉϫⲱⲕ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
26 Ó ti pa àṣírí ìjìnlẹ̀ yìí mọ́ fún ayérayé àti láti ìrandíran. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn rẹ̀, ó ti fihàn fún àwọn ẹni mímọ́. (aiōn )
ⲕ̅ⲋ̅ⲡⲓⲙⲩⲥⲧⲏⲣⲓⲟⲛ ⲉⲧϩⲏⲡ ⲓⲥϫⲉⲛ ⳿ⲡⲉⲛⲉϩ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲅⲉⲛⲉ⳿ⲁ ϯⲛⲟⲩ ⲇⲉ ⲁϥⲟⲩⲟⲛϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲛⲓⲁⲅⲓⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲁϥ. (aiōn )
27 Àwọn ẹni tí Ọlọ́run yàn láti fihàn láàrín àwọn aláìkọlà nípa ọ̀rọ̀ ògo ohun ìjìnlẹ̀ yìí, èyí tí í ṣe Kristi ìrètí ògo nínú yín.
ⲕ̅ⲍ̅ⲛⲏⲉⲧⲁ ⲫϯ ⲟⲩⲱϣ ⳿ⲉⲧⲁⲙⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲁϣ ⲧⲉ ϯⲙⲉⲧⲣⲁⲙⲁ⳿ⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲁⲓⲙⲩⲥⲧⲏⲣⲓⲟⲛ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲉⲑⲛⲟⲥ ⲉⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲡⲉ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϯϩⲉⲗⲡⲓⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡⲱⲟⲩ.
28 Àwa ń wàásù rẹ̀, a ń gbani níyànjú a sì ń kọ olúkúlùkù ènìyàn ní ọgbọ́n gbogbo, kí a lè mú olúkúlùkù dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ní pípé nínú Kristi.
ⲕ̅ⲏ̅ⲫⲁⲓ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ⲉⲧⲉⲛϩⲓⲱⲓϣ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲉⲛ⳿ⲧⲥⲁⲃⲟ ⳿ⲛⲣⲱⲙⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲛϯ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲛⲣⲱⲙⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ ϧⲉⲛ ⲥⲟⲫⲓⲁ ⲛⲓⲃⲉⲛ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲛⲧⲁϩⲉ ⲣⲱⲙⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲉⲣⲁⲧⲟⲩ ⲉⲩϫⲏⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ Ⲡⲭ̅ⲥ̅.
29 Sí èyí sì ni èmi ń ṣe làálàá, ti mo sì ń làkàkà pẹ̀lú gbogbo agbára rẹ̀, èyí tó ń ṣiṣẹ́ nínú mi.
ⲕ̅ⲑ̅ⲫⲁⲓ ⳿ⲉϯϭⲓϧⲓⲥⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⲉⲓⲉⲣⲁⲅⲱⲛⲓⲍⲉⲥⲑⲉ ⲕⲁⲧⲁ ⲡⲉϥⲉⲣϩⲱⲃ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧ ϧⲉⲛ ⲟⲩϫⲟⲙ