< Colossians 4 >
1 Ẹyin ọ̀gá, ẹ máa fi èyí tí ó tọ́ tí ó sì dọ́gba fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ yín; kí ẹ sì mọ̀ pé ẹ̀yin pẹ̀lú ní Olúwa kan ní ọ̀run.
Páni spravedlivě a slušně s služebníky nakládejte, vědouce, že i vy Pána máte v nebesích.
2 Ẹ fi ara yín jì fún àdúrà gbígbà, kí ẹ ṣọ́ra kí ẹ sì máa dúpẹ́;
Na modlitbě buďte ustaviční, bdíce v tom s díků činěním,
3 ẹ máa gbàdúrà fún wa pẹ̀lú, kí Ọlọ́run lè ṣí ìlẹ̀kùn fún wa fún ọ̀rọ̀ náà, láti máa sọ ohun ìjìnlẹ̀ Kristi, nítorí èyí tí mo ṣe wà nínú ìdè pẹ̀lú.
Modléce se spolu i za nás, aby Bůh otevřel nám dvéře slova, k mluvení o tajemství Kristovu, pro něž i v vězení jsem,
4 Ẹ gbàdúrà pé kí èmi le è máa kéde rẹ̀ kedere gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ fún mi.
Abych je zjevoval, tak jakž mi náleží mluviti.
5 Ẹ jẹ́ ọlọ́gbọ́n ní ti bí ẹ ti ń ṣe pẹ̀lú àwọn tí ń bẹ lóde, kí ẹ sì máa ṣe ṣí àǹfààní tí ẹ bá nílò.
Choďtež v moudrosti před těmi, kteříž jsou vně, čas kupujíce.
6 Ẹ jẹ́ kí ọ̀rọ̀ yín kí ó dàpọ̀ mọ́ oore-ọ̀fẹ́ nígbà gbogbo, èyí tí a fi iyọ̀ dùn, kí ẹ̀yin kí ó le mọ́ bí ẹ̀yin ó tí máa dá olúkúlùkù ènìyàn lóhùn.
Řeč vaše vždycky budiž příjemná, ozdobená solí, tak abyste věděli, kterak byste měli jednomu každému odpovědíti.
7 Gbogbo bí nǹkan ti rí fún mi ní Tikiku yóò jẹ́ kí ẹ mọ̀. Òun jẹ́ arákùnrin olùfẹ́ àti olóòtítọ́ ìránṣẹ́ àti ẹlẹgbẹ́ nínú Olúwa,
O věcech mých o všech oznámí vám Tychikus, bratr milý, a věrný slouha, a spoluslužebník v Pánu.
8 ẹni tí èmí ń rán sí yín nítorí èyí kan náà, kí ẹ̀yin lè mọ́ bí a ti wà, kí òun kí ó lè tu ọkàn yín nínú.
Kteréhož jsem poslal k vám pro to samo, aby zvěděl, co se děje u vás, a potěšil srdcí vašich,
9 Òun sì ń bọ̀ pẹ̀lú Onesimu, arákùnrin olóòtítọ́ àti olùfẹ́, ẹni tí í ṣe ọ̀kan nínú yín. Àwọn ní yóò sọ ohun gbogbo tí à ń ṣe níhìn-ín yìí fún un yín.
S Onezimem, věrným a milým bratrem, kterýž jest tam od vás. Tiť vám všecko oznámí, co se děje u nás.
10 Aristarku, ẹlẹgbẹ́ mí nínú túbú kí i yín, àti Marku, ọmọ arábìnrin Barnaba. (Nípasẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ti gba àṣẹ; bí ó bá sì wá sí ọ̀dọ̀ yín, ẹ gbà á.)
Pozdravuje vás Aristarchus, spoluvězeň můj, a Marek, sestřenec Barnabášův, (o kterémž jsem vám poručil; přišel-li by k vám, přijmětež jej; )
11 Àti Jesu, ẹni tí à ń pè ní Justu, ẹni tí ń ṣe ti àwọn onílà. Àwọn wọ̀nyí nìkan ni olùbáṣiṣẹ́ mí fún ìjọba Ọlọ́run, àwọn ẹni tí ó tí jásí ìtùnú fún mi.
A Jezus, kterýž slove Justus, kteříž jsou Židé. Ti toliko jsou pomocníci moji v království Božím, kteříž byli mé potěšení.
12 Epafira, ẹni tí ń ṣe ọ̀kan nínú yín àti ìránṣẹ́ Kristi Jesu kí i yín. Òun fi ìwàyáàjà gbàdúrà nígbà gbogbo fún un yín, kí ẹ̀yin kí ó lè dúró ní pípé nínú ohun gbogbo nínú ìfẹ́ Ọlọ́run.
Pozdravuje vás Epafras, kterýž od vás jest, slouha Kristův, kterýž vždycky úsilně pracuje na modlitbách za vás, abyste stáli dokonalí a plní ve vší vůli Boží.
13 Nítorí mo jẹ́rìí rẹ̀ pé ó ń ṣiṣẹ́ kárakára fún yín, àti fún àwọn tí ó wà ní Laodikea, àti àwọn tí ó wà ní Hirapoli.
Nebo svědectví jemu vydávám, žeť vás velmi horlivě miluje, a též i ty, kteříž jsou v Laodicii, i kteříž jsou v Hierapoli.
14 Luku, arákùnrin wa ọ̀wọ́n, oníṣègùn, àti Dema ki í yín.
Pozdravuje vás Lukáš lékař milý a Démas.
15 Ẹ kí àwọn ará tí ó wà ní Laodikea, àti Nimpa, àti ìjọ tí ó wà ní ilé rẹ̀.
Pozdravte bratří Laodicenských, i Nymfy, i té církve, kteráž jest v domě jeho.
16 Nígbà tí a bá sì ka ìwé yìí ní àárín yín tan, kí ẹ mú kí a kà á pẹ̀lú nínú ìjọ Laodikea; ẹ̀yin pẹ̀lú sì ka èyí tí ó ti Laodikea wá.
A když bude přečten u vás tento list, spravtež to, ať jest i v Laodicenském zboru čten; a ten, kterýž jest psán z Laodicie, i vy také přečtěte.
17 Kí ẹ sì wí fún Arkippu pe, “Kíyèsi iṣẹ́ ìránṣẹ́ tí ìwọ ti gbà nínú Olúwa kí o sì ṣe é ní kíkún.”
A rcete Archippovi: Viz, abys služebnost, kterouž jsi přijal od Pána, vyplnil.
18 Ìkíni láti ọwọ́ èmi Paulu. Ẹ máa rántí ìdè mi. Kí oore-ọ̀fẹ́ kí ó wà pẹ̀lú yín.
Pozdravení mou rukou Pavlovou. Pamatujtež na mé vězení. Milost Boží s vámi. Amen.