< Amos 1 >

1 Àwọn ọ̀rọ̀ Amosi, ọ̀kan lára àwọn olùṣọ́-àgùntàn Tekoa; ohun tí o rí nípa Israẹli ní ọdún méjì ṣáájú ilẹ̀-rírì, nígbà tí Ussiah ọba Juda àti Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Israẹli.
Słowa Amosa, który był między pasterzami z Tekua, które widział o Izraelu za dni Uzyjasza, króla Judzkiego, i za dni Jeroboama, syna Joazowego, króla Izraelskiego, dwa lata przed trzęsieniem ziemi.
2 Ó wí pé, “Olúwa yóò bú jáde láti Sioni, ohùn rẹ̀ yóò sì sán bí àrá láti Jerusalẹmu wá; ibùgbé àwọn olùṣọ́-àgùntàn yóò sì ṣọ̀fọ̀, orí òkè Karmeli yóò sì rọ.”
i rzekł: Zaryczy Pan z Syonu, z Jeruzalemu wyda głos swój; i będą płakały mieszkania pasterzy, a wyschną pola najwyborniejsze.
3 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Damasku, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn fi ohun èlò ìpakà pa Gileadi. Pẹ̀lú ohun èlò irin tí ó ní eyín mímú,
Tak mówi Pan: Dla trzech występków Damaszku, owszem, dla czterech, nie przepuszczę mu, przeto, że młócili wozami żelaznemi Galaada;
4 Èmi yóò rán iná sí ilé Hasaeli, èyí ti yóò jó àwọn ààfin Beni-Hadadi run.
Ale poślę ogień na dom Hazaela, który pożre pałace Benadadowe.
5 Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdábùú Damasku; Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní àfonífojì Afeni run àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Beti-Edeni. Àwọn ará a Aramu yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kiri,” ni Olúwa wí.
Połamię też zaworę w Damaszku, a wykorzenię obywatela z doliny Awen, i tego, który trzyma sceptr z domu Heden; i pójdzie w niewolę lud Syryjski do Kir, mówi Pan.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gasa, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Gẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú, ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbèkùn. Ó sì tà wọ́n fún Edomu,
Tak mówi Pan: Dla trzech występków Gazy, owszem, dla czterech, nie przepuszczę im, przeto, że ich pojmawszy, w więzienie wieczne podawali Edomczykom;
7 Èmi yóò rán iná sí ara odi Gasa tí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run.
Ale poślę ogień na mur Gazy, który pożre pałace jej.
8 Èmi yóò ké àwọn olùgbé Aṣdodu kúrò, ti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Aṣkeloni mú. Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ekroni títí tí ìyókù Filistini yóò fi ṣègbé,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
Wykorzenię też obywatela z Azotu, i tego, który trzyma sceptr z Aszkalonu, i obrócę rękę moję przeciwko Akkaronowi, że zginie ostatek Filistynów, mówi panujący Pan.
9 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tire àní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbèkùn fún Edomu. Wọn kò sì náání májẹ̀mú ọbàkan,
Tak mówi Pan: Dla trzech występków Tyru, owszem, dla czterech, nie przepuszczę mu, przeto, że ich w więzienie wieczne podali Edomczykom, a nie wspomnieli na przymierze braterskie;
10 Èmi yóò rán iná sí ara odi Tire, tí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”
Ale poślę ogień na mur Tyrski, który pożre pałace jego.
11 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Edomu, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀, Ó sì gbé gbogbo àánú sọnù, ìbínú rẹ̀ sì ń faniya títí, ó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́,
Tak mówi Pan: Dla trzech występków Edoma, owszem, dla czterech, nie przepuszczę mu, przeto, że zepsowawszy w sobie wszelaką litość swoję prześladuje mieczem brata swego, a gniewem swym ustawicznie pała, owszem, zapalczywość jego rozsila się bez przestania;
12 Èmi yóò rán iná sí orí Temani, tí yóò jó gbogbo ààfin Bosra run.”
Ale poślę ogień na Teman, i pożre pałace w Bocra.
13 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni, àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.
Tak mówi Pan: Dla trzech występków synów Amonowych, owszem, dla czterech, nie przepuszczę mu, przeto, iż rozcinali brzemienne w Galaad, tylko aby rozszerzali granice swoje;
14 Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun, pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.
Ale rozniecę ogień na murze Rabby, który pożre pałace jego z krzykiem w dzień wojny, i z wichrem w dzień niepogody.
15 Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn, òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,” ni Olúwa wí.
I pójdzie król ich w niewolę, on i książęta jego z nim, mówi Pan.

< Amos 1 >